< Isaiah 51 >

1 “Tẹ́tí sí mi, ẹ̀yin tí ó ń lépa òdodo àti ẹ̀yin tí ń wá Olúwa. Wo àpáta, nínú èyí tí a ti gé yín jáde àti ihò òkúta níbi tí a ti gbẹ́ yín jáde;
« Écoutez-moi, vous qui poursuivez la justice, vous qui cherchez Yahvé. Regardez la roche dans laquelle vous avez été taillé, et à la carrière d'où vous avez été extrait.
2 ẹ wo Abrahamu baba yín, àti Sara, ẹni tó bí i yín. Nígbà tí mo pè é, òun nìkan ni, Èmi sì bùkún un, mo sì ṣọ́ ọ di ọ̀pọ̀lọpọ̀.
Regarde vers Abraham, ton père, et à Sarah qui t'a porté; car quand il n'était qu'un, je l'ai appelé, Je l'ai béni, et l'a rendu nombreux.
3 Dájúdájú, Olúwa yóò tu Sioni nínú yóò sì bojú àánú wo gbogbo ahoro rẹ̀; Òun yóò sọ gbogbo aṣálẹ̀ rẹ̀ di Edeni, àti aṣálẹ̀ rẹ̀ yóò rí bí ọgbà Olúwa. Ayọ̀ àti inú dídùn ni a ó rí nínú rẹ̀, ọpẹ́ àti ariwo orín kíkọ.
Car Yahvé a réconforté Sion. Il a réconforté toutes ses ruines, et a fait de son désert un Eden, et son désert comme le jardin de Yahvé. La joie et l'allégresse se trouveront en eux, l'action de grâce, et la voix de la mélodie.
4 “Tẹ́tí sí mi, ẹ̀yin ènìyàn mi; gbọ́ tèmi, ẹ̀yin orílẹ̀-èdè mi. Òfin yóò ti ọ̀dọ̀ mi jáde wá; ìdájọ́ mi yóò di ìmọ́lẹ̀ sí àwọn orílẹ̀-èdè.
« Écoutez-moi, mon peuple; et écoute-moi, ma nation, car une loi sortira de moi, et j'établirai ma justice comme une lumière pour les peuples.
5 Òdodo mi ń bọ̀ wá kíkankíkan, ìgbàlà mi ń bọ̀ lójú ọ̀nà, àti apá mi yóò sì mú ìdájọ́ wá sí àwọn orílẹ̀-èdè. Àwọn erékùṣù yóò wò mí wọn yóò sì dúró ní ìrètí fún apá mi.
Ma justice est proche. Mon salut s'est éteint, et mes bras jugeront les peuples. Les îles vont m'attendre, et ils feront confiance à mon bras.
6 Gbé ojú rẹ sókè sí àwọn ọ̀run, wo ilẹ̀ ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀; àwọn ọ̀run yóò pòórá bí èéfín, ilẹ̀ yóò sì gbó bí ẹ̀wù àwọn olùgbé inú rẹ̀ yóò kú gẹ́gẹ́ bí àwọn eṣinṣin. Ṣùgbọ́n ìgbàlà mi yóò wà títí láé, òdodo mi kì yóò yẹ̀ láé.
Levez vos yeux vers les cieux, et regarder la terre en dessous; car les cieux s'évanouiront comme de la fumée, et la terre s'usera comme un vêtement. Ses habitants mourront de la même façon, mais mon salut sera éternel, et ma justice ne sera pas abolie.
7 “Ẹ gbọ́ mi, ẹ̀yin tí ó mọ ohun òtítọ́, ẹ̀yin ènìyàn tí ó ní òfin mi ní àyà yín. Ẹ má ṣe bẹ̀rù ẹ̀gàn àwọn ènìyàn tàbí kí ẹ̀rù èébú wọn já a yín láyà.
« Écoutez-moi, vous qui connaissez la justice, le peuple dans le cœur duquel se trouve ma loi. Ne craignez pas les reproches des hommes, et ne vous laissez pas démonter par leurs insultes.
8 Nítorí kòkòrò yóò mú wọn lá bí aṣọ, ìdin yóò sì mú wọn jẹ bí ẹ̀gbọ̀n òwú. Ṣùgbọ́n òdodo mi yóò wà títí ayérayé, àti ìgbàlà mi láti ìrandíran.”
Car la teigne les dévorera comme un vêtement, et le ver les mangera comme de la laine; mais ma justice sera éternelle, et mon salut à toutes les générations. »
9 Dìde, dìde! Kí o sì wọ ara rẹ ní agbára ìwọ apá Olúwa; dìde gẹ́gẹ́ bí i ti ọjọ́ ìgbà n nì, àti gẹ́gẹ́ bí i ti ìran àtijọ́. Ìwọ kọ́ lo ké Rahabu sí wẹ́wẹ́ tí o sì fa ẹ̀mí búburú ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ?
Réveille-toi, réveille-toi, revêts-toi de force, bras de Yahvé! Réveillé, comme dans les jours d'autrefois, les générations des temps anciens. N'est-ce pas vous qui avez coupé Rahab en morceaux, qui a percé le monstre?
10 Ìwọ kọ́ ni ó gbẹ omi Òkun bí àti àwọn omi inú ọ̀gbun, tí o sì ṣe ọ̀nà nínú ìsàlẹ̀ Òkun tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn ẹni ìràpadà yóò fi le là á kọjá?
N'est-ce pas toi qui as asséché la mer, les eaux de la grande profondeur; qui a fait des profondeurs de la mer un passage pour les rachetés?
11 Àwọn ẹni ìràpadà Olúwa yóò padà wá. Wọn yóò wọ Sioni wá pẹ̀lú orin kíkọ; ayọ̀ ayérayé ni yóò sì bo orí wọn. Ayọ̀ àti inú dídùn yóò sì bà lé wọn ìbànújẹ́ àti ìtìjú yóò sì sá kúrò.
Les rachetés par Yahvé reviendront, et venez en chantant à Sion. Une joie éternelle sera sur leurs têtes. Ils obtiendront l'allégresse et la joie. Le chagrin et les soupirs s'en iront.
12 “Èmi, àní Èmi, èmi ni ẹni tí ó tù ọ́ nínú. Ta ni ọ́ tí o fi ń bẹ̀rù ènìyàn ẹlẹ́ran ara, àti ọmọ ènìyàn, tí ó jẹ́ koríko lásán,
« C'est moi, moi aussi, qui vous réconforte. Qui es-tu, pour avoir peur de l'homme qui va mourir, et du fils de l'homme qui sera réduit à l'état d'herbe?
13 tí ìwọ sì gbàgbé Olúwa ẹlẹ́dàá rẹ, ẹni tí ó ta àwọn ọ̀run tí ó sì fi ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀, tí ẹ sì ń gbé nínú ìpayà lójoojúmọ́ nítorí ìbínú àwọn aninilára, tí wọ́n sì gbẹ́kẹ̀lé ìpanirun? Nítorí ibo ni ìbínú àwọn aninilára gbé wà?
As-tu oublié Yahvé, ton créateur? qui a étendu les cieux, et a posé les fondations de la terre? Vivez-vous dans la peur continuellement toute la journée à cause de la fureur de l'oppresseur, quand il se prépare à détruire? Où est la fureur de l'oppresseur?
14 Àwọn ẹlẹ́wọ̀n tí ń ṣojo la ó dá sílẹ̀ ní àìpẹ́ jọjọ wọn kò ní kú sínú túbú wọn, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò ní ṣe aláìní àkàrà.
L'exilé captif sera rapidement libéré. Il ne mourra pas et ne descendra pas dans la fosse. Son pain ne manquera pas.
15 Nítorí Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ, tí ó ń ru Òkun sókè tó bẹ́ẹ̀ tí ìgbì rẹ̀ fi ń pariwo Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
Car je suis Yahvé ton Dieu, qui remue la mer. pour que ses vagues rugissent. Yahvé des Armées est son nom.
16 Mo ti fi ọ̀rọ̀ mi sí ẹnu rẹ mo sì ti fi òjìji ọwọ́ mi bò ọ́, Èmi tí mo tẹ́ àwọn ọ̀run sí ààyè rẹ̀, ẹni tí ó fi ìpìlẹ̀ ilẹ̀ ayé lélẹ̀, àti ẹni tí ó sọ fún Sioni pé, ‘Ẹ̀yin ni ènìyàn mi.’”
J'ai mis mes paroles dans ta bouche et je t'ai couvert de l'ombre de ma main, pour que je puisse planter les cieux, et poser les fondations de la terre, et dis à Sion: « Tu es mon peuple. »
17 Jí, jí! Gbéra nílẹ̀ ìwọ Jerusalẹmu, ìwọ tí o ti mu láti ọwọ́ Olúwa ago ìbínú rẹ̀, ìwọ tí o ti fà á mu dé gẹ̀dẹ̀gẹ́dẹ̀ tí ó n mú kí ènìyàn ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n.
Réveillez-vous, réveillez-vous! Debout, Jérusalem, vous qui avez bu de la main de Yahvé la coupe de sa colère. Vous avez bu le bol de la coupe de l'étourdissement, et l'a vidée.
18 Nínú gbogbo ọmọ tí ó bí kò sí ọ̀kankan tí ó lè tọ́ ọ ṣọ́nà nínú gbogbo ọmọ tí ó tọ́ kò sí èyí tí ó le fà á lọ́wọ́.
Il n'y a personne pour la guider parmi tous les fils qu'elle a mis au monde; et il n'y a personne qui la prenne par la main parmi tous les fils qu'elle a élevés.
19 Àjálù ìlọ́po ìlọ́po yìí ti dé bá ọ— ta ni yóò tù ọ́ nínú? Ìparun àti ìdahoro, ìyàn àti idà ta ni yó pẹ̀tù sí ọ lọ́kàn?
Ces deux choses vous sont arrivées. qui sera en deuil avec vous? la désolation et la destruction, et la famine et l'épée. Comment puis-je te réconforter?
20 Àwọn ọmọkùnrin rẹ ti dákú; wọ́n sùn sí oríta gbogbo òpópónà, gẹ́gẹ́ bí etu tí a dé mọ́nú àwọ̀n. Ìbínú Olúwa ti kún inú wọn fọ́fọ́ àti ìbáwí Ọlọ́run yín.
Tes fils se sont évanouis. Ils se trouvent à la tête de toutes les rues, comme une antilope dans un filet. Ils sont pleins de la colère de Yahvé, la réprimande de votre Dieu.
21 Nítorí náà ẹ gbọ́ èyí, ẹ̀yin tí a ti ṣẹ́ níṣẹ̀ẹ́, tí ọtí ń pa, ṣùgbọ́n kì í ṣe fún wáìnì.
C'est pourquoi, maintenant, écoutez ceci, vous qui êtes affligés, et ivres, mais pas avec du vin:
22 Ohun tí Olúwa Olódùmarè yín wí nìyìí, Ọlọ́run rẹ, ẹni tí ó ń pa ènìyàn rẹ̀ mọ́, “Kíyèsi i, mo ti mú un kúrò ní ọwọ́ rẹ ago tí ó mú ọ ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n; láti inú ago náà, ẹ̀kún ìbínú mi, ni ìwọ kì yóò mu mọ́.
Ton Seigneur Yahvé, votre Dieu qui plaide la cause de son peuple, dit, « Voici que j'ai retiré de ta main la coupe de l'étourdissement, même le bol de la coupe de ma colère. Vous ne le boirez plus.
23 Èmi yóò fi lé àwọn apọ́nilójú rẹ lọ́wọ́, àwọn tí ó wí fún ọ pé, ‘Dọ̀bálẹ̀, tó bẹ́ẹ̀ tí a ó fi máa rìn lórí rẹ.’ Ìwọ náà ṣe ẹ̀yìn rẹ gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ gẹ́gẹ́ bí òpópónà láti máa rìn lórí i rẹ̀.”
Je le mettrai dans la main de ceux qui vous affligent, qui ont dit à ton âme: « Incline-toi, pour que nous puissions marcher sur toi ». et vous avez posé votre dos sur le sol, comme une rue pour ceux qui la traversent. »

< Isaiah 51 >