< Isaiah 51 >

1 “Tẹ́tí sí mi, ẹ̀yin tí ó ń lépa òdodo àti ẹ̀yin tí ń wá Olúwa. Wo àpáta, nínú èyí tí a ti gé yín jáde àti ihò òkúta níbi tí a ti gbẹ́ yín jáde;
Here ye me, that suen that that is iust, and seken the Lord. Take ye hede to the stoon, fro whennys ye ben hewun doun, and to the caue of the lake, fro which ye ben kit doun.
2 ẹ wo Abrahamu baba yín, àti Sara, ẹni tó bí i yín. Nígbà tí mo pè é, òun nìkan ni, Èmi sì bùkún un, mo sì ṣọ́ ọ di ọ̀pọ̀lọpọ̀.
Take ye heede to Abraham, youre fadir, and to Sare, that childide you; for Y clepide hym oon, and Y blesside hym, and Y multipliede hym.
3 Dájúdájú, Olúwa yóò tu Sioni nínú yóò sì bojú àánú wo gbogbo ahoro rẹ̀; Òun yóò sọ gbogbo aṣálẹ̀ rẹ̀ di Edeni, àti aṣálẹ̀ rẹ̀ yóò rí bí ọgbà Olúwa. Ayọ̀ àti inú dídùn ni a ó rí nínú rẹ̀, ọpẹ́ àti ariwo orín kíkọ.
Therfor the Lord schal coumforte Sion, and he schal coumforte alle the fallyngis therof; and he schal sette the desert therof as delices, and the wildirnesse therof as a gardyn of the Lord; ioie and gladnesse schal be foundun therynne, the doyng of thankyngis and the vois of heriyng.
4 “Tẹ́tí sí mi, ẹ̀yin ènìyàn mi; gbọ́ tèmi, ẹ̀yin orílẹ̀-èdè mi. Òfin yóò ti ọ̀dọ̀ mi jáde wá; ìdájọ́ mi yóò di ìmọ́lẹ̀ sí àwọn orílẹ̀-èdè.
Mi puple, take ye heede to me, and, my lynage, here ye me; for whi a lawe schal go out fro me, and my doom schal reste in to the liyt of puplis.
5 Òdodo mi ń bọ̀ wá kíkankíkan, ìgbàlà mi ń bọ̀ lójú ọ̀nà, àti apá mi yóò sì mú ìdájọ́ wá sí àwọn orílẹ̀-èdè. Àwọn erékùṣù yóò wò mí wọn yóò sì dúró ní ìrètí fún apá mi.
My iust man is nyy, my sauyour is gon out, and myn armes schulen deme puplis; ilis schulen abide me, and schulen suffre myn arm.
6 Gbé ojú rẹ sókè sí àwọn ọ̀run, wo ilẹ̀ ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀; àwọn ọ̀run yóò pòórá bí èéfín, ilẹ̀ yóò sì gbó bí ẹ̀wù àwọn olùgbé inú rẹ̀ yóò kú gẹ́gẹ́ bí àwọn eṣinṣin. Ṣùgbọ́n ìgbàlà mi yóò wà títí láé, òdodo mi kì yóò yẹ̀ láé.
Reise youre iyen to heuene, and se ye vndur erthe bynethe; for whi heuenes schulen melte awei as smoke, and the erthe schal be al to-brokun as a cloth, and the dwelleris therof schulen perische as these thingis; but myn helthe schal be withouten ende, and my riytfulnesse schal not fayle.
7 “Ẹ gbọ́ mi, ẹ̀yin tí ó mọ ohun òtítọ́, ẹ̀yin ènìyàn tí ó ní òfin mi ní àyà yín. Ẹ má ṣe bẹ̀rù ẹ̀gàn àwọn ènìyàn tàbí kí ẹ̀rù èébú wọn já a yín láyà.
Ye puple, that knowen the iust man, here me, my lawe is in the herte of hem; nyle ye drede the schenschipe of men, and drede ye not the blasfemyes of hem.
8 Nítorí kòkòrò yóò mú wọn lá bí aṣọ, ìdin yóò sì mú wọn jẹ bí ẹ̀gbọ̀n òwú. Ṣùgbọ́n òdodo mi yóò wà títí ayérayé, àti ìgbàlà mi láti ìrandíran.”
For whi a worm schal ete hem so as a cloth, and a mouyte schal deuoure hem so as wolle; but myn helthe schal be withouten ende, and my riytfulnesse in to generaciouns of generaciouns.
9 Dìde, dìde! Kí o sì wọ ara rẹ ní agbára ìwọ apá Olúwa; dìde gẹ́gẹ́ bí i ti ọjọ́ ìgbà n nì, àti gẹ́gẹ́ bí i ti ìran àtijọ́. Ìwọ kọ́ lo ké Rahabu sí wẹ́wẹ́ tí o sì fa ẹ̀mí búburú ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ?
Rise thou, rise thou, arm of the Lord, be thou clothyd in strengthe; rise thou, as in elde daies, in generaciouns of worldis. Whether thou smytidist not the proude man, woundidist not the dragoun?
10 Ìwọ kọ́ ni ó gbẹ omi Òkun bí àti àwọn omi inú ọ̀gbun, tí o sì ṣe ọ̀nà nínú ìsàlẹ̀ Òkun tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn ẹni ìràpadà yóò fi le là á kọjá?
Whether thou driedist not the see, the watir of the greet depthe, which settidist the depthe of the see a weie, that men `that weren delyuered, schulden passe?
11 Àwọn ẹni ìràpadà Olúwa yóò padà wá. Wọn yóò wọ Sioni wá pẹ̀lú orin kíkọ; ayọ̀ ayérayé ni yóò sì bo orí wọn. Ayọ̀ àti inú dídùn yóò sì bà lé wọn ìbànújẹ́ àti ìtìjú yóò sì sá kúrò.
And now thei that ben ayenbouyt of the Lord schulen turne ayen, and schulen come heriynge in to Syon, and euerlastynge gladnesse on the heedis of hem; thei schulen holde ioie and gladnesse, sorewe and weilyng schal fle awei.
12 “Èmi, àní Èmi, èmi ni ẹni tí ó tù ọ́ nínú. Ta ni ọ́ tí o fi ń bẹ̀rù ènìyàn ẹlẹ́ran ara, àti ọmọ ènìyàn, tí ó jẹ́ koríko lásán,
`Y my silf schal coumforte you; what art thou, that thou drede of a deedli man, and of the sone of man, that schal wexe drie so as hei?
13 tí ìwọ sì gbàgbé Olúwa ẹlẹ́dàá rẹ, ẹni tí ó ta àwọn ọ̀run tí ó sì fi ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀, tí ẹ sì ń gbé nínú ìpayà lójoojúmọ́ nítorí ìbínú àwọn aninilára, tí wọ́n sì gbẹ́kẹ̀lé ìpanirun? Nítorí ibo ni ìbínú àwọn aninilára gbé wà?
And thou hast foryete `the Lord, thi creatour, that stretchide abrood heuenes, and foundide the erthe; and thou dreddist contynueli al dai of the face of his woodnesse, that dide tribulacioun to thee, and made redi for to leese. Where is now the woodnesse of the troblere?
14 Àwọn ẹlẹ́wọ̀n tí ń ṣojo la ó dá sílẹ̀ ní àìpẹ́ jọjọ wọn kò ní kú sínú túbú wọn, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò ní ṣe aláìní àkàrà.
Soone he schal come, goynge for to opene; and he schal not sle til to deth, nether his breed schal faile.
15 Nítorí Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ, tí ó ń ru Òkun sókè tó bẹ́ẹ̀ tí ìgbì rẹ̀ fi ń pariwo Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
Forsothe Y am thi Lord God, that disturble the see, and the wawis therof wexen greet; the Lord of oostis is my name.
16 Mo ti fi ọ̀rọ̀ mi sí ẹnu rẹ mo sì ti fi òjìji ọwọ́ mi bò ọ́, Èmi tí mo tẹ́ àwọn ọ̀run sí ààyè rẹ̀, ẹni tí ó fi ìpìlẹ̀ ilẹ̀ ayé lélẹ̀, àti ẹni tí ó sọ fún Sioni pé, ‘Ẹ̀yin ni ènìyàn mi.’”
Y haue put my wordis in thi mouth, and Y defendide thee in the schadewe of myn hond; that thou plaunte heuenes, and founde the erthe, and seie to Sion, Thou art my puple.
17 Jí, jí! Gbéra nílẹ̀ ìwọ Jerusalẹmu, ìwọ tí o ti mu láti ọwọ́ Olúwa ago ìbínú rẹ̀, ìwọ tí o ti fà á mu dé gẹ̀dẹ̀gẹ́dẹ̀ tí ó n mú kí ènìyàn ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n.
Be thou reisid, be thou reisid, rise thou, Jerusalem, that hast drunke of the hond of the Lord the cuppe of his wraththe; thou hast drunke `til to the botme of the cuppe of sleep, thou hast drunke of `til to the drastis.
18 Nínú gbogbo ọmọ tí ó bí kò sí ọ̀kankan tí ó lè tọ́ ọ ṣọ́nà nínú gbogbo ọmọ tí ó tọ́ kò sí èyí tí ó le fà á lọ́wọ́.
Noon is that susteyneth it, of alle the sones whiche it gendride; and noon is that takith the hond therof, of alle the sones whiche it nurshide.
19 Àjálù ìlọ́po ìlọ́po yìí ti dé bá ọ— ta ni yóò tù ọ́ nínú? Ìparun àti ìdahoro, ìyàn àti idà ta ni yó pẹ̀tù sí ọ lọ́kàn?
Twei thingis ben that camen to thee; who schal be sori on thee? distriyng, and defoulyng, and hungur, and swerd. Who schal coumforte thee?
20 Àwọn ọmọkùnrin rẹ ti dákú; wọ́n sùn sí oríta gbogbo òpópónà, gẹ́gẹ́ bí etu tí a dé mọ́nú àwọ̀n. Ìbínú Olúwa ti kún inú wọn fọ́fọ́ àti ìbáwí Ọlọ́run yín.
Thi sones ben cast forth, thei slepten in the heed of alle weies, as the beeste orix, takun bi a snare; thei ben ful of indignacioun of the Lord, of blamyng of thi God.
21 Nítorí náà ẹ gbọ́ èyí, ẹ̀yin tí a ti ṣẹ́ níṣẹ̀ẹ́, tí ọtí ń pa, ṣùgbọ́n kì í ṣe fún wáìnì.
Therfor, thou pore, and drunkun, not of wyn, here these thingis.
22 Ohun tí Olúwa Olódùmarè yín wí nìyìí, Ọlọ́run rẹ, ẹni tí ó ń pa ènìyàn rẹ̀ mọ́, “Kíyèsi i, mo ti mú un kúrò ní ọwọ́ rẹ ago tí ó mú ọ ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n; láti inú ago náà, ẹ̀kún ìbínú mi, ni ìwọ kì yóò mu mọ́.
Thi lordli gouernour, the Lord, and thi God, that fauyt for his puple, seith these thingis, Lo! Y haue take fro thyn hond the cuppe of sleep, the botme of the cuppe of myn indignacioun; Y schal not leie to, that thou drynke it ony more.
23 Èmi yóò fi lé àwọn apọ́nilójú rẹ lọ́wọ́, àwọn tí ó wí fún ọ pé, ‘Dọ̀bálẹ̀, tó bẹ́ẹ̀ tí a ó fi máa rìn lórí rẹ.’ Ìwọ náà ṣe ẹ̀yìn rẹ gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ gẹ́gẹ́ bí òpópónà láti máa rìn lórí i rẹ̀.”
And Y schal sette it in the hond of hem that maden thee low, and seiden to thi soule, Be thou bowid that we passe; and thou hast set thi bodi as erthe, and as a weye to hem that goen forth.

< Isaiah 51 >