< Isaiah 51 >

1 “Tẹ́tí sí mi, ẹ̀yin tí ó ń lépa òdodo àti ẹ̀yin tí ń wá Olúwa. Wo àpáta, nínú èyí tí a ti gé yín jáde àti ihò òkúta níbi tí a ti gbẹ́ yín jáde;
Toenghaih hnukah pazui moe, Angraeng pakrong kaminawk, ka lok hae tahngai oh; na aah o ih lungsong hoi na takaeh o ih tangqom to khen oh;
2 ẹ wo Abrahamu baba yín, àti Sara, ẹni tó bí i yín. Nígbà tí mo pè é, òun nìkan ni, Èmi sì bùkún un, mo sì ṣọ́ ọ di ọ̀pọ̀lọpọ̀.
nam pa Abraham hoi nangcae cunkung Sarah to khen oh; tangsuek naah loe anih khue ni ka kawk, toe tahamhoihaih ka paek pongah, anih loe kating ai ah pung.
3 Dájúdájú, Olúwa yóò tu Sioni nínú yóò sì bojú àánú wo gbogbo ahoro rẹ̀; Òun yóò sọ gbogbo aṣálẹ̀ rẹ̀ di Edeni, àti aṣálẹ̀ rẹ̀ yóò rí bí ọgbà Olúwa. Ayọ̀ àti inú dídùn ni a ó rí nínú rẹ̀, ọpẹ́ àti ariwo orín kíkọ.
Angraeng mah Zion to mongsak tih; kamro ahmuennawk boih doeh mongsak tih; anih ih praezaek to Eden baktiah angcoengsak ueloe, anih ih long karoem ahmuen to Angraeng ih takha baktiah angcoengsak tih; athung ah loe anghoehaih, oephaih, anghoe lok thuihaih hoi laasakhaih loknawk to om tih.
4 “Tẹ́tí sí mi, ẹ̀yin ènìyàn mi; gbọ́ tèmi, ẹ̀yin orílẹ̀-èdè mi. Òfin yóò ti ọ̀dọ̀ mi jáde wá; ìdájọ́ mi yóò di ìmọ́lẹ̀ sí àwọn orílẹ̀-èdè.
Kai ih kaminawk, ka lok hae tahngai oh; Aw ka caengnawk, kai khaeah naa patueng oh; patuk ih toenghaih lok loe kai khae hoiah tacawt tih, ka toenghaih loe prae kaminawk hanah aanghaih ah om tih.
5 Òdodo mi ń bọ̀ wá kíkankíkan, ìgbàlà mi ń bọ̀ lójú ọ̀nà, àti apá mi yóò sì mú ìdájọ́ wá sí àwọn orílẹ̀-èdè. Àwọn erékùṣù yóò wò mí wọn yóò sì dúró ní ìrètí fún apá mi.
Ka toenghaih loe zoi boeh, ka pahlonghaih doeh longh li boeh, ka ban mah kaminawk to lokcaek tih; tuipui thung ih prae kaminawk mah kai to zing o ueloe, ka ban thacakhaih to oep o tih.
6 Gbé ojú rẹ sókè sí àwọn ọ̀run, wo ilẹ̀ ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀; àwọn ọ̀run yóò pòórá bí èéfín, ilẹ̀ yóò sì gbó bí ẹ̀wù àwọn olùgbé inú rẹ̀ yóò kú gẹ́gẹ́ bí àwọn eṣinṣin. Ṣùgbọ́n ìgbàlà mi yóò wà títí láé, òdodo mi kì yóò yẹ̀ láé.
Van ah na mik padai o tahang ah loe long ah khen o tathuk ah; van loe hmaikhue baktiah anghmaa ving tih, long doeh kahni baktiah prawn ueloe, athung ah kaom kaminawk loe taksae baktiah dueh o tih.
7 “Ẹ gbọ́ mi, ẹ̀yin tí ó mọ ohun òtítọ́, ẹ̀yin ènìyàn tí ó ní òfin mi ní àyà yín. Ẹ má ṣe bẹ̀rù ẹ̀gàn àwọn ènìyàn tàbí kí ẹ̀rù èébú wọn já a yín láyà.
Toenghaih panoek kaminawk hoi palung thungah ka patuk ih lok suem kaminawk, ka lok hae tahngai oh; kaminawk mah zoehhaih to zii o hmah, nihcae mah kasae thuihaih pongah doeh tasoeh o hmah.
8 Nítorí kòkòrò yóò mú wọn lá bí aṣọ, ìdin yóò sì mú wọn jẹ bí ẹ̀gbọ̀n òwú. Ṣùgbọ́n òdodo mi yóò wà títí ayérayé, àti ìgbàlà mi láti ìrandíran.”
Karaa mah nihcae to kahni baktiah caa king ueloe, langkawk mah nihcae to tuumui baktiah caa tih; toe ka toenghaih loe dungzan khoek to cak poe tih, ka pahlonghaih doeh caanawk ih adung khoek to om poe tih.
9 Dìde, dìde! Kí o sì wọ ara rẹ ní agbára ìwọ apá Olúwa; dìde gẹ́gẹ́ bí i ti ọjọ́ ìgbà n nì, àti gẹ́gẹ́ bí i ti ìran àtijọ́. Ìwọ kọ́ lo ké Rahabu sí wẹ́wẹ́ tí o sì fa ẹ̀mí búburú ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ?
Aw Angraeng ih ban nang, Angthawk ah, anglawt ah loe thacakhaih hoiah om ah; canghnii ih ni kalaem baktih, adung kangquem baktiah, angthawk ah. Rahab to takroek pat moe, pahui pui ahmaa caasakkung loe nang na ai maw?
10 Ìwọ kọ́ ni ó gbẹ omi Òkun bí àti àwọn omi inú ọ̀gbun, tí o sì ṣe ọ̀nà nínú ìsàlẹ̀ Òkun tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn ẹni ìràpadà yóò fi le là á kọjá?
Tuipui hoi kathuk parai tuinawk kangsakkung loe nang na ai maw? Kathuk tuipui nuiah akrang tangcae kaminawk caehhaih loklam sahkung loe nang na ai maw?
11 Àwọn ẹni ìràpadà Olúwa yóò padà wá. Wọn yóò wọ Sioni wá pẹ̀lú orin kíkọ; ayọ̀ ayérayé ni yóò sì bo orí wọn. Ayọ̀ àti inú dídùn yóò sì bà lé wọn ìbànújẹ́ àti ìtìjú yóò sì sá kúrò.
To pongah Angraeng mah akrang tangcae kaminawk to amlaem o let ueloe, laasakhaih hoiah Zion ah akun o tih; nihcae loe dungzan anghoehaih lumuek to angmuek o tih; oephaih hoi anghoehaih to hnu o tih; to naah palungsethaih hoi qahhaih loe cawn ving tih boeh.
12 “Èmi, àní Èmi, èmi ni ẹni tí ó tù ọ́ nínú. Ta ni ọ́ tí o fi ń bẹ̀rù ènìyàn ẹlẹ́ran ara, àti ọmọ ènìyàn, tí ó jẹ́ koríko lásán,
Nangcae pathloepkung loe Kai, kaimah hae boeh ni; kadueh thaih kami, phroh baktiah azaem thaih kami capa to maw na zit o?
13 tí ìwọ sì gbàgbé Olúwa ẹlẹ́dàá rẹ, ẹni tí ó ta àwọn ọ̀run tí ó sì fi ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀, tí ẹ sì ń gbé nínú ìpayà lójoojúmọ́ nítorí ìbínú àwọn aninilára, tí wọ́n sì gbẹ́kẹ̀lé ìpanirun? Nítorí ibo ni ìbínú àwọn aninilára gbé wà?
Vannawk payuengkung, long angdoethaih sahkung, nang sahkung Angraeng to na pahnet ving boeh; pacaekthlaekkung mah kai hae hum tih boeh, tiah palung thung hoiah na poek o moe, ni thokkruek zithaih hoiah kho na sak o; pacaekthlaek kami palungphuihaih loe naa ah maw oh?
14 Àwọn ẹlẹ́wọ̀n tí ń ṣojo la ó dá sílẹ̀ ní àìpẹ́ jọjọ wọn kò ní kú sínú túbú wọn, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò ní ṣe aláìní àkàrà.
Thongkrah kaminawk loe thongim thungah dueh o mak ai, zok doeh amthlam o mak ai, anih loe loih phrat tih.
15 Nítorí Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ, tí ó ń ru Òkun sókè tó bẹ́ẹ̀ tí ìgbì rẹ̀ fi ń pariwo Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
Kai loe tuipui mah hangh hanah, tuipui angthawksakkung Angraeng na Sithaw ah ka oh; Anih ih ahmin loe misatuh kaminawk ih Angraeng, tiah oh.
16 Mo ti fi ọ̀rọ̀ mi sí ẹnu rẹ mo sì ti fi òjìji ọwọ́ mi bò ọ́, Èmi tí mo tẹ́ àwọn ọ̀run sí ààyè rẹ̀, ẹni tí ó fi ìpìlẹ̀ ilẹ̀ ayé lélẹ̀, àti ẹni tí ó sọ fún Sioni pé, ‘Ẹ̀yin ni ènìyàn mi.’”
Vannawk angmah ih ahmuen ah suemkung, long angdoethaih ahmuen sahkung, Zion khaeah, Nangcae loe kai ih kami ah na oh o, tiah thuih hanah, na pakha ah ka loknawk to ka suek moe, ka ban hoiah kang pakaa boeh.
17 Jí, jí! Gbéra nílẹ̀ ìwọ Jerusalẹmu, ìwọ tí o ti mu láti ọwọ́ Olúwa ago ìbínú rẹ̀, ìwọ tí o ti fà á mu dé gẹ̀dẹ̀gẹ́dẹ̀ tí ó n mú kí ènìyàn ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n.
Angraeng ban ih palungphuihaih boengloeng kanae Aw Jerusalem, anglawt lai ah, angthawk ah loe angdoe ah; tasoehhaih boengloeng to na naek boeh; anaengnawk doeh na naek boih boeh.
18 Nínú gbogbo ọmọ tí ó bí kò sí ọ̀kankan tí ó lè tọ́ ọ ṣọ́nà nínú gbogbo ọmọ tí ó tọ́ kò sí èyí tí ó le fà á lọ́wọ́.
Angmah tapen ih capanawk thungah hoiah angmah han loklam patuekkung mi doeh om o ai; angmah pacah ih capanawk thungah doeh, anih ban hoiah zae kami om o ai.
19 Àjálù ìlọ́po ìlọ́po yìí ti dé bá ọ— ta ni yóò tù ọ́ nínú? Ìparun àti ìdahoro, ìyàn àti idà ta ni yó pẹ̀tù sí ọ lọ́kàn?
Patangkhanghaih hnetto ah kaom, caaknaek khaa pongah kami amrohaih ah kaom sumsen hoi duekhaih to na nuiah phak naah, mi mah maw na qah haih tih? Kawbangmaw kang pathloep thai han?
20 Àwọn ọmọkùnrin rẹ ti dákú; wọ́n sùn sí oríta gbogbo òpópónà, gẹ́gẹ́ bí etu tí a dé mọ́nú àwọ̀n. Ìbínú Olúwa ti kún inú wọn fọ́fọ́ àti ìbáwí Ọlọ́run yín.
Na capanawk loe tha zok o sut boeh moe, thaang pongah aman sathar baktiah, lamkrung kruekah angsongh o; nihcae loe Angraeng palungphuihaih hoi na Sithaw thuitaekhaih to amhah o sut boeh.
21 Nítorí náà ẹ gbọ́ èyí, ẹ̀yin tí a ti ṣẹ́ níṣẹ̀ẹ́, tí ọtí ń pa, ṣùgbọ́n kì í ṣe fún wáìnì.
To pongah pacaekthlaekhaih tongh kami, misurtui hoi nae ai ah mu paquih kami, vaihi tahngai ah;
22 Ohun tí Olúwa Olódùmarè yín wí nìyìí, Ọlọ́run rẹ, ẹni tí ó ń pa ènìyàn rẹ̀ mọ́, “Kíyèsi i, mo ti mú un kúrò ní ọwọ́ rẹ ago tí ó mú ọ ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n; láti inú ago náà, ẹ̀kún ìbínú mi, ni ìwọ kì yóò mu mọ́.
angmah ih kaminawk khenzawnkung, na Sithaw, na Angraeng Sithaw mah, Khenah, na ban pong ih tasoehhaih boengloeng, palung ka phuihaih boengloeng pong ih anaengnawk to na naek let han ai ah, na ban thung hoiah ka lak ving boeh:
23 Èmi yóò fi lé àwọn apọ́nilójú rẹ lọ́wọ́, àwọn tí ó wí fún ọ pé, ‘Dọ̀bálẹ̀, tó bẹ́ẹ̀ tí a ó fi máa rìn lórí rẹ.’ Ìwọ náà ṣe ẹ̀yìn rẹ gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ gẹ́gẹ́ bí òpópónà láti máa rìn lórí i rẹ̀.”
na nuiah caeh kaminawk hanah, loklam baktiah na takpum to long ah baih pae ah, na nuiah ka caeh o thai hanah, long ah tabok oh, tiah kathui, nangcae pacaekthlaek kaminawk ban ah to boengloeng to ka suek pae han, tiah a thuih.

< Isaiah 51 >