< Isaiah 50 >
1 Ohun tí Olúwa wí nìyìí: “Níbo ni ìwé-ẹ̀rí ìkọ̀sílẹ̀ ìyá rẹ wà èyí tí mo fi lé e lọ? Tàbí èwo nínú àwọn olùyánilówó mi ni mo tà ọ́ fún? Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ ni a fi tà ọ́; nítorí àìṣedéédéé rẹ ni a fi lé ìyá rẹ lọ.
Pǝrwǝrdigar mundaⱪ dǝydu: — Mǝn ⱪoyuwǝtkǝn ananglarning talaⱪ heti ⱪeni? Manga ⱪǝrz bǝrgüqilǝrning ⱪaysisiƣa silǝrni setiwǝtkǝnmǝn? Mana, silǝr ɵz gunaⱨliringlar arⱪiliⱪ ɵz-ɵzünglarni setiwǝtkǝnsilǝr; Silǝrning asiyliⱪliringlar tüpǝylidin ananglar ⱪoyuwetilgǝnidi.
2 Nígbà tí mo wá, èéṣe tí a kò fi rí ẹnìkan? Nígbà tí mo pè, èéṣe tí kò fi sí ẹnìkan láti dáhùn? Ọwọ́ mi a kúrú láti gbà ọ́? Èmi kò ha ní agbára láti gbà ọ́ bí? Nípa ìbáwí lásán, Èmi gbẹ omi òkun, Èmi yí àwọn odò sí aṣálẹ̀; àwọn ẹja wọn rà fún àìsí omi wọ́n sì kú fún òǹgbẹ.
Mǝn silǝrdinmu soraymǝn: Mǝn kǝlginimdǝ, nemixⱪa ⱨeq adǝm qiⱪmidi? Mǝn qaⱪirƣinimda, nemixⱪa ⱨeqkim «Mana mǝn» dǝp jawab bǝrmidi? Ⱨɵrlükkǝ qiⱪirixⱪa ⱪolum ⱪisⱪiliⱪ ⱪilamdu? Ⱪutⱪuzƣudǝk küqüm yoⱪmidu? Mana, Mǝn bir ǝyiblǝpla dengizni ⱪurutup, Dǝryalarni qɵlgǝ aylanduruwetimǝn; Su bolmiƣaqⱪa ularning beliⱪliri sesip ketidu, Ussuzluⱪtin ɵlidu;
3 Èmi fi òkùnkùn bo sánmọ̀ mo sì fi aṣọ ọ̀fọ̀ ṣe ìbòrí rẹ̀.”
Asmanlarni ⱪariliⱪ bilǝn kiydürimǝn, Ularning kiyim-keqǝklirini [ⱪara] bɵzdin ⱪilimǝn».
4 Olúwa Olódùmarè ti fún mi ni ahọ́n tí a fi iṣẹ́ rán, láti mọ àwọn ọ̀rọ̀ tí ó lè gbé àwọn aláàárẹ̀ ró. O jí mi láràárọ̀, o jí etí mi láti gbọ́ gẹ́gẹ́ bí ẹni tí à ń kọ́.
«Rǝb Pǝrwǝrdigar mening japa qǝkkǝnlǝrning kɵnglini yasaxni bilixim üqün manga tǝlim-tǝrbiyǝ alƣuqilarning tilini tǝⱪdim ⱪildi; U meni ⱨǝr sǝⱨǝr oyƣitip turidu, Tǝrbiyilǝngǝnlǝrning ⱪatarida mening ⱪuliⱪimni oyƣitidu.
5 Olúwa Olódùmarè ti ṣí mi ní etí, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò ṣọ̀tẹ̀ rí; Èmi kò sì padà sẹ́yìn.
Rǝb Pǝrwǝrdigar ⱪuliⱪimni aqti; Mǝn bolsam itaǝtsizlik ⱪilmidim, Yaki yolidin bax tartmidim.
6 Mo ṣí ẹ̀yìn mi sílẹ̀ fún àwọn tí ó ń nà mí, àti ẹ̀rẹ̀kẹ́ mi fún àwọn tí ń fa irùngbọ̀n mi; Èmi kò fi ojú mi pamọ́ kúrò lọ́wọ́ ẹlẹ́yà àti ìyọṣùtì sí.
Dümbǝmni sawiƣuqilarƣa, Mǝngzlirimni tük yulƣuqilarƣa tutup bǝrdim; Horluⱪ ⱨǝm tükürüxlǝrdin yüzümni ⱪaqurmidim;
7 Nítorí Olúwa Olódùmarè ràn mí lọ́wọ́, a kì yóò dójútì mí. Nítorí náà ni mo ṣe gbé ojú mi ró bí òkúta akọ èmi sì mọ pé, ojú kò ní tì mí.
Biraⱪ Rǝb Pǝrwǝrdigar yardimimdǝ bolidu; Xunga mǝn yǝrgǝ ⱪarap ⱪalmaymǝn; Xunga mǝn [niyitimni ⱪǝt’iy ⱪilip] yüzümni almastǝk qing ⱪildim; Hijilliⱪⱪa ⱪaldurulmaydiƣanliⱪimni bilimǝn.
8 Ẹni tí ó dá mi láre wà nítòsí. Ta ni ẹni náà tí yóò fẹ̀sùn kàn mí? Jẹ́ kí a kojú ara wa! Ta ni olùfisùn mi? Jẹ́ kí ó kò mí lójú!
Meni Aⱪliƣuqi yenimdidur; Kim manga ǝrz-xikayǝt ⱪilalisun? Bar bolsa birliktǝ dǝwalixayli; Kim mening üstümdin ǝyiblimǝkqi bolsa, Aldimƣa kǝlsun!
9 Olúwa Olódùmarè ni ó ń ràn mí lọ́wọ́. Ta ni ẹni náà tí yóò dá mi lẹ́bi? Gbogbo wọn yóò gbó bí aṣọ; kòkòrò ni yóò sì jẹ wọn run.
Manga yardǝmdǝ bolƣuqi Pǝrwǝrdigardur; Əmdi meni ǝrz ⱪilalaydiƣan kimkǝn? Ularning ⱨǝmmisi bir tal kiyimdǝk ǝskirǝp ketidu; Pǝrwanilǝr ularni yutuwetidu».
10 Ta ni nínú yín tí ó bẹ̀rù Olúwa tí ó sì ń gbọ́rọ̀ sí ìránṣẹ́ rẹ̀ lẹ́nu? Jẹ́ kí ẹni tí ń rìn ní òkùnkùn tí kò ní ìmọ́lẹ̀, kí ó gbẹ́kẹ̀lé orúkọ Olúwa kí o sì gbẹ́kẹ̀lé Ọlọ́run rẹ̀.
— «Aranglarda Pǝrwǝrdigardin ⱪorⱪidiƣan, Uning ⱪulining sɵzigǝ itaǝt ⱪilidiƣan kim bar? Ⱪarangƣuluⱪta mangidiƣan, yoruⱪluⱪi bolmiƣan kixi bolsa, Pǝrwǝrdigarning namiƣa ixinip hatirjǝmlǝnsun, Hudasiƣa yɵlǝnsun!
11 Ṣùgbọ́n ní àkókò yìí, gbogbo ẹ̀yin ti ń tanná tí ẹ sì ń fi pèsè iná ìléwọ́ fún ara yín, ẹ lọ, kí ẹ sì máa rìn nínú ìmọ́lẹ̀ iná yín, àti nínú ẹta iná tí ẹ ti dá. Èyí ni yóò jẹ́ tiyín láti ọwọ́ mi wá. Ẹ̀yin ó dùbúlẹ̀ nínú ìrora.
Mana, ɵzliri üqün ot yaⱪidiƣan, Ətrapinglarni mǝx’ǝllǝr bilǝn oraydiƣan ⱨǝmminglar! Ⱪeni, ɵz otunglarning nurida, Ɵzünglar yaⱪⱪan mǝx’ǝllǝr arisida menginglar; Biraⱪ silǝr xuni ⱪolumdin alisilǝrki: — «Azab-ⱨǝsrǝt iqidǝ yatisilǝr!».