< Isaiah 50 >

1 Ohun tí Olúwa wí nìyìí: “Níbo ni ìwé-ẹ̀rí ìkọ̀sílẹ̀ ìyá rẹ wà èyí tí mo fi lé e lọ? Tàbí èwo nínú àwọn olùyánilówó mi ni mo tà ọ́ fún? Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ ni a fi tà ọ́; nítorí àìṣedéédéé rẹ ni a fi lé ìyá rẹ lọ.
Ko te kupu tenei a Ihowa, Kei hea ianei te pukapuka whakarere o to koutou whaea, i whakarerea ai ia e ahau? Ko wai ranei te tangata, i ahau ana moni, i hokona atu ai koutou e ahau ki a ia? Nana, he kino no koutou i hokona atu ai koutou, na a kout ou mahi whanoke ano i whakarerea ai to koutou whaea.
2 Nígbà tí mo wá, èéṣe tí a kò fi rí ẹnìkan? Nígbà tí mo pè, èéṣe tí kò fi sí ẹnìkan láti dáhùn? Ọwọ́ mi a kúrú láti gbà ọ́? Èmi kò ha ní agbára láti gbà ọ́ bí? Nípa ìbáwí lásán, Èmi gbẹ omi òkun, Èmi yí àwọn odò sí aṣálẹ̀; àwọn ẹja wọn rà fún àìsí omi wọ́n sì kú fún òǹgbẹ.
Na te aha i taku haerenga mai i kore ai he tangata, he aha i taku karangatanga i kore ai tetahi e oho ake? kua mutua koia toku ringa, te tau ai te araarai? kua kore ranei he kaha moku hei whakaora? Nana, maku, ma taku kupu riri, ka maroke ai te m oana, ka meinga ai nga awa hei koraha: piro ana o ratou ika i te waikore, ka mate hoki i te matewai.
3 Èmi fi òkùnkùn bo sánmọ̀ mo sì fi aṣọ ọ̀fọ̀ ṣe ìbòrí rẹ̀.”
E whakakakahu ana ahau i nga rangi ki te mangu, uhia iho te taratara hei hipoki mo ratou.
4 Olúwa Olódùmarè ti fún mi ni ahọ́n tí a fi iṣẹ́ rán, láti mọ àwọn ọ̀rọ̀ tí ó lè gbé àwọn aláàárẹ̀ ró. O jí mi láràárọ̀, o jí etí mi láti gbọ́ gẹ́gẹ́ bí ẹni tí à ń kọ́.
Kua homai ki ahau e te Ariki, e Ihowa, he arero matau, kia mohio ai ahau ki te ata ngarahu atu i te korero ki te tangata e mauiui ana. E whakaara ana ia i tenei ata, i tenei ata, e whakaara ana i toku taringa ki te whakarongo kia pera me ta te hu nga mohio.
5 Olúwa Olódùmarè ti ṣí mi ní etí, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò ṣọ̀tẹ̀ rí; Èmi kò sì padà sẹ́yìn.
Kua oti te whakatuwhera e te Ariki, e Ihowa toku taringa, kihai hoki ahau i tutu, kihai i hoki whakamuri.
6 Mo ṣí ẹ̀yìn mi sílẹ̀ fún àwọn tí ó ń nà mí, àti ẹ̀rẹ̀kẹ́ mi fún àwọn tí ń fa irùngbọ̀n mi; Èmi kò fi ojú mi pamọ́ kúrò lọ́wọ́ ẹlẹ́yà àti ìyọṣùtì sí.
Tukua atu ana e ahau toku tuara ki nga kaiwhiu, oku paparinga ki nga kaihutihuti; ko toku kanohi kihai i huna kei whakama, kei tuwhaina.
7 Nítorí Olúwa Olódùmarè ràn mí lọ́wọ́, a kì yóò dójútì mí. Nítorí náà ni mo ṣe gbé ojú mi ró bí òkúta akọ èmi sì mọ pé, ojú kò ní tì mí.
No te mea ka awhinatia mai ahau e te Ariki, e Ihowa; koia ahau te whakama ai; koia i whakamarotia ai e ahau toku kanohi ano he kiripaka; e mohio ana hoki ahau e kore ahau e whakama.
8 Ẹni tí ó dá mi láre wà nítòsí. Ta ni ẹni náà tí yóò fẹ̀sùn kàn mí? Jẹ́ kí a kojú ara wa! Ta ni olùfisùn mi? Jẹ́ kí ó kò mí lójú!
E tata ana te kaiwhakatikatika moku; ko wai hei whawhai ki ahau? kia tu ngatahi taua: ko wai he hoariri moku? kia tata mai ia ki ahau.
9 Olúwa Olódùmarè ni ó ń ràn mí lọ́wọ́. Ta ni ẹni náà tí yóò dá mi lẹ́bi? Gbogbo wọn yóò gbó bí aṣọ; kòkòrò ni yóò sì jẹ wọn run.
Nana, ko te Ariki, ko Ihowa, hei awhina moku; ko wai hei whakahe i ahau? Nana, ka tawhitotia katoatia ratou ano he kakahu, ka pau ratou i te purehurehu.
10 Ta ni nínú yín tí ó bẹ̀rù Olúwa tí ó sì ń gbọ́rọ̀ sí ìránṣẹ́ rẹ̀ lẹ́nu? Jẹ́ kí ẹni tí ń rìn ní òkùnkùn tí kò ní ìmọ́lẹ̀, kí ó gbẹ́kẹ̀lé orúkọ Olúwa kí o sì gbẹ́kẹ̀lé Ọlọ́run rẹ̀.
Ko wai o koutou e wehi ana i a Ihowa, e rongo ana ki te reo o tana pononga; ko te tangata e haere ana i te pouri, kahore hoki he whakamarama, kia okioki ia ki te ingoa o Ihowa, kia taupuhipuhi atu ki tona Atua.
11 Ṣùgbọ́n ní àkókò yìí, gbogbo ẹ̀yin ti ń tanná tí ẹ sì ń fi pèsè iná ìléwọ́ fún ara yín, ẹ lọ, kí ẹ sì máa rìn nínú ìmọ́lẹ̀ iná yín, àti nínú ẹta iná tí ẹ ti dá. Èyí ni yóò jẹ́ tiyín láti ọwọ́ mi wá. Ẹ̀yin ó dùbúlẹ̀ nínú ìrora.
Nana, e koutou katoa e tahu na i te ahi, e whitiki na i a koutou ki nga rama muramura; haere i te marama o ta koutou ahi, i nga rama muramura hoki i whakangihaia na e koutou. Tenei ta toku ringa mo koutou, ka takoto iho koutou me te tangi ano.

< Isaiah 50 >