< Isaiah 50 >
1 Ohun tí Olúwa wí nìyìí: “Níbo ni ìwé-ẹ̀rí ìkọ̀sílẹ̀ ìyá rẹ wà èyí tí mo fi lé e lọ? Tàbí èwo nínú àwọn olùyánilówó mi ni mo tà ọ́ fún? Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ ni a fi tà ọ́; nítorí àìṣedéédéé rẹ ni a fi lé ìyá rẹ lọ.
Így szól az Úr: Hol van anyátok elválólevele, a melylyel őt elbocsátám? vagy hol van egy kölcsönadóim közül, a kinek titeket eladtalak? Ímé, a ti vétkeitekért adattatok el, és bűneitekért bocsáttatott el anyátok!
2 Nígbà tí mo wá, èéṣe tí a kò fi rí ẹnìkan? Nígbà tí mo pè, èéṣe tí kò fi sí ẹnìkan láti dáhùn? Ọwọ́ mi a kúrú láti gbà ọ́? Èmi kò ha ní agbára láti gbà ọ́ bí? Nípa ìbáwí lásán, Èmi gbẹ omi òkun, Èmi yí àwọn odò sí aṣálẹ̀; àwọn ẹja wọn rà fún àìsí omi wọ́n sì kú fún òǹgbẹ.
Miért jöttem, holott nem volt ott senki? hívtam és nem felelt senki sem! vagy olyan rövid már a kezem, hogy meg nem válthat? vagy nincs bennem megszabadításra való erő? Ímé, én dorgálásommal kiszáraztom a tengert, a folyókat pusztává teszem, megbűzhödnek halaik, hogy nincsen víz, és szomjúságtól meghalnak.
3 Èmi fi òkùnkùn bo sánmọ̀ mo sì fi aṣọ ọ̀fọ̀ ṣe ìbòrí rẹ̀.”
Felöltöztetem az egeket sötétségbe, és gyászruhával födöm be azokat.
4 Olúwa Olódùmarè ti fún mi ni ahọ́n tí a fi iṣẹ́ rán, láti mọ àwọn ọ̀rọ̀ tí ó lè gbé àwọn aláàárẹ̀ ró. O jí mi láràárọ̀, o jí etí mi láti gbọ́ gẹ́gẹ́ bí ẹni tí à ń kọ́.
Az Úr Isten bölcs nyelvet adott én nékem, hogy tudjam erősítni a megfáradtat beszéddel, fölserkenti minden reggel, fölserkenti fülemet, hogy hallgassak, miként a tanítványok.
5 Olúwa Olódùmarè ti ṣí mi ní etí, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò ṣọ̀tẹ̀ rí; Èmi kò sì padà sẹ́yìn.
Az Úr Isten megnyitotta fülemet, és én nem voltam engedetlen, hátra nem fordultam.
6 Mo ṣí ẹ̀yìn mi sílẹ̀ fún àwọn tí ó ń nà mí, àti ẹ̀rẹ̀kẹ́ mi fún àwọn tí ń fa irùngbọ̀n mi; Èmi kò fi ojú mi pamọ́ kúrò lọ́wọ́ ẹlẹ́yà àti ìyọṣùtì sí.
Hátamat odaadám a verőknek, és orczámat a szaggatóknak, képemet nem födöztem be a gyalázás és köpdösés előtt.
7 Nítorí Olúwa Olódùmarè ràn mí lọ́wọ́, a kì yóò dójútì mí. Nítorí náà ni mo ṣe gbé ojú mi ró bí òkúta akọ èmi sì mọ pé, ojú kò ní tì mí.
És az Úr Isten megsegít engemet, azért nem szégyenülök meg, ezért olyanná tettem képemet, mint a kova, és tudtam, hogy szégyent nem vallok.
8 Ẹni tí ó dá mi láre wà nítòsí. Ta ni ẹni náà tí yóò fẹ̀sùn kàn mí? Jẹ́ kí a kojú ara wa! Ta ni olùfisùn mi? Jẹ́ kí ó kò mí lójú!
Közel van, a ki engem megigazít, ki perel én velem? Álljunk együtt elő! Kicsoda peresem? közelegjen hozzám!
9 Olúwa Olódùmarè ni ó ń ràn mí lọ́wọ́. Ta ni ẹni náà tí yóò dá mi lẹ́bi? Gbogbo wọn yóò gbó bí aṣọ; kòkòrò ni yóò sì jẹ wọn run.
Ímé, az Úr Isten megsegít engem, kicsoda kárhoztatna engem? Ímé, mindnyájan, mint a ruha megavulnak, moly emészti meg őket!
10 Ta ni nínú yín tí ó bẹ̀rù Olúwa tí ó sì ń gbọ́rọ̀ sí ìránṣẹ́ rẹ̀ lẹ́nu? Jẹ́ kí ẹni tí ń rìn ní òkùnkùn tí kò ní ìmọ́lẹ̀, kí ó gbẹ́kẹ̀lé orúkọ Olúwa kí o sì gbẹ́kẹ̀lé Ọlọ́run rẹ̀.
Ki féli közületek az Urat? és ki hallgat az ő szolgája szavára? ő, a ki sötétségben jár és nincs fényesség néki, bízzék az Úr nevében, és támaszkodjék Istenhez!
11 Ṣùgbọ́n ní àkókò yìí, gbogbo ẹ̀yin ti ń tanná tí ẹ sì ń fi pèsè iná ìléwọ́ fún ara yín, ẹ lọ, kí ẹ sì máa rìn nínú ìmọ́lẹ̀ iná yín, àti nínú ẹta iná tí ẹ ti dá. Èyí ni yóò jẹ́ tiyín láti ọwọ́ mi wá. Ẹ̀yin ó dùbúlẹ̀ nínú ìrora.
Ímé, ti mind, a kik tüzet gyujtotok, felövezvén magatokat tüzes nyilakkal, vettessetek tüzeteknek lángjába és a tüzes nyilakba, a melyeket meggyújtottatok! Kezemből jő ez rátok; fájdalomban fogtok feküdni!