< Isaiah 50 >
1 Ohun tí Olúwa wí nìyìí: “Níbo ni ìwé-ẹ̀rí ìkọ̀sílẹ̀ ìyá rẹ wà èyí tí mo fi lé e lọ? Tàbí èwo nínú àwọn olùyánilówó mi ni mo tà ọ́ fún? Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ ni a fi tà ọ́; nítorí àìṣedéédéé rẹ ni a fi lé ìyá rẹ lọ.
Yahvé dit: « Où est l'acte de divorce de ta mère, par lequel je l'ai répudiée? Ou à lequel de mes créanciers t'ai-je vendu? Voici, vous avez été vendus pour vos iniquités, et ta mère a été répudiée pour tes transgressions.
2 Nígbà tí mo wá, èéṣe tí a kò fi rí ẹnìkan? Nígbà tí mo pè, èéṣe tí kò fi sí ẹnìkan láti dáhùn? Ọwọ́ mi a kúrú láti gbà ọ́? Èmi kò ha ní agbára láti gbà ọ́ bí? Nípa ìbáwí lásán, Èmi gbẹ omi òkun, Èmi yí àwọn odò sí aṣálẹ̀; àwọn ẹja wọn rà fún àìsí omi wọ́n sì kú fún òǹgbẹ.
Pourquoi, quand je suis venu, n'y avait-il personne? Quand j'ai appelé, pourquoi n'y avait-il personne pour répondre? Ma main est-elle raccourcie au point de ne pas pouvoir racheter? Ou n'ai-je pas le pouvoir de délivrer? Voici, à ma réprimande, je dessèche la mer. Je fais des rivières un désert. Leurs poissons puent parce qu'il n'y a pas d'eau, et meurent de soif.
3 Èmi fi òkùnkùn bo sánmọ̀ mo sì fi aṣọ ọ̀fọ̀ ṣe ìbòrí rẹ̀.”
Je revêts les cieux d'obscurité. Je fais du sac leur couverture. »
4 Olúwa Olódùmarè ti fún mi ni ahọ́n tí a fi iṣẹ́ rán, láti mọ àwọn ọ̀rọ̀ tí ó lè gbé àwọn aláàárẹ̀ ró. O jí mi láràárọ̀, o jí etí mi láti gbọ́ gẹ́gẹ́ bí ẹni tí à ń kọ́.
Le Seigneur Yahvé m'a donné la langue de ceux qui sont enseignés, afin que je sache comment soutenir par des paroles celui qui est fatigué. Il se réveille matin après matin, il éveille mon oreille pour entendre comme ceux qui sont enseignés.
5 Olúwa Olódùmarè ti ṣí mi ní etí, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò ṣọ̀tẹ̀ rí; Èmi kò sì padà sẹ́yìn.
Le Seigneur Yahvé a ouvert mon oreille. Je n'étais pas rebelle. Je n'ai pas fait demi-tour.
6 Mo ṣí ẹ̀yìn mi sílẹ̀ fún àwọn tí ó ń nà mí, àti ẹ̀rẹ̀kẹ́ mi fún àwọn tí ń fa irùngbọ̀n mi; Èmi kò fi ojú mi pamọ́ kúrò lọ́wọ́ ẹlẹ́yà àti ìyọṣùtì sí.
J'ai donné mon dos à ceux qui me battaient, et mes joues à ceux qui ont arraché les poils. Je n'ai pas caché mon visage de la honte et des crachats.
7 Nítorí Olúwa Olódùmarè ràn mí lọ́wọ́, a kì yóò dójútì mí. Nítorí náà ni mo ṣe gbé ojú mi ró bí òkúta akọ èmi sì mọ pé, ojú kò ní tì mí.
Car le Seigneur Yahvé m'aidera. C'est pourquoi je n'ai pas été confondu. C'est pourquoi j'ai posé mon visage comme un silex, et je sais que je ne serai pas déçu.
8 Ẹni tí ó dá mi láre wà nítòsí. Ta ni ẹni náà tí yóò fẹ̀sùn kàn mí? Jẹ́ kí a kojú ara wa! Ta ni olùfisùn mi? Jẹ́ kí ó kò mí lójú!
Celui qui me justifie est proche. Qui va porter plainte contre moi? Levons-nous ensemble. Qui est mon adversaire? Laissez-le s'approcher de moi.
9 Olúwa Olódùmarè ni ó ń ràn mí lọ́wọ́. Ta ni ẹni náà tí yóò dá mi lẹ́bi? Gbogbo wọn yóò gbó bí aṣọ; kòkòrò ni yóò sì jẹ wọn run.
Voici que le Seigneur Yahvé me vient en aide! Qui est celui qui me condamnera? Voici qu'ils vieilliront tous comme un vêtement. Les mites vont les manger.
10 Ta ni nínú yín tí ó bẹ̀rù Olúwa tí ó sì ń gbọ́rọ̀ sí ìránṣẹ́ rẹ̀ lẹ́nu? Jẹ́ kí ẹni tí ń rìn ní òkùnkùn tí kò ní ìmọ́lẹ̀, kí ó gbẹ́kẹ̀lé orúkọ Olúwa kí o sì gbẹ́kẹ̀lé Ọlọ́run rẹ̀.
Qui parmi vous craint Yahvé et obéit à la voix de son serviteur? Celui qui marche dans les ténèbres et n'a pas de lumière, qu'il se confie au nom de Yahvé, et s'en remettre à son Dieu.
11 Ṣùgbọ́n ní àkókò yìí, gbogbo ẹ̀yin ti ń tanná tí ẹ sì ń fi pèsè iná ìléwọ́ fún ara yín, ẹ lọ, kí ẹ sì máa rìn nínú ìmọ́lẹ̀ iná yín, àti nínú ẹta iná tí ẹ ti dá. Èyí ni yóò jẹ́ tiyín láti ọwọ́ mi wá. Ẹ̀yin ó dùbúlẹ̀ nínú ìrora.
Voici, vous tous qui allumez un feu, qui se parent de torches autour de vous, marcher dans la flamme de ton feu, et parmi les torches que vous avez allumées. Vous aurez ceci de ma main: tu te coucheras dans la tristesse.