< Isaiah 5 >

1 Èmi yóò kọrin fún ẹni tí mo fẹ́ràn orin kan nípa ọgbà àjàrà rẹ̀. Olùfẹ́ mi ní ọgbà àjàrà kan ní ẹ̀gbẹ́ òkè ẹlẹ́tù lójú.
Je chanterai pour mon bien-aimé le cantique que mon bien-aimé chante à ma vigne. Mon bien-aimé avait une vigne, sur une éminence, en un lieu fertile.
2 Ó tu ilẹ̀ rẹ̀, ó ṣa òkúta ibẹ̀ kúrò ó sì gbin àyànfẹ́ àjàrà sí i. Ó kọ́ ilé ìṣọ́ sí inú rẹ̀ ó sì ṣe ìfúntí kan síbẹ̀ pẹ̀lú. Lẹ́yìn náà, ó ń retí èso àjàrà dáradára, ṣùgbọ́n èso búburú ni ó ti ibẹ̀ wá.
Et je l'ai entourée d'une haie, et je l'ai palissadée, et je l'ai plantée du plant de Sorec; et au milieu j'ai bâti une tour, où j'ai creusé un cellier; et j'ai compté qu'elle me donnerait du raisin, mais elle a produit des épines.
3 “Ní ìsinsin yìí ẹ̀yin olùgbé Jerusalẹmu àti ẹ̀yin ènìyàn Juda ẹ ṣe ìdájọ́ láàrín èmi àti ọgbà àjàrà mi.
Et maintenant, vous, habitants de Jérusalem, et toi, homme de Juda, jugez entre moi et ma vigne.
4 Kín ni ó kù tí n ò bá túnṣe sí ọgbà àjàrà mi. Ju èyí tí mo ti ṣe lọ? Nígbà tí mo ń wá èso dáradára, èéṣe tí ó fi so kíkan?
Que ferai-je encore pour ma vigne que je n'aie point déjà fait? J'avais compté qu'elle me donnerait du raisin, mais elle a produit des épines.
5 Ní ìsinsin yìí, èmi yóò wí fún ọ ohun tí n ó ṣe sí ọgbà àjàrà mi. Èmi yóò gé igi inú rẹ̀ kúrò, a ó sì pa á run, Èmi yóò wó ògiri rẹ̀ lulẹ̀ yóò sì di ìtẹ̀mọ́lẹ̀.
Or je vais maintenant vous déclarer ce que je ferai ' à ma vigne. Je lui arracherai sa baie, et elle sera mise au pillage; j'abattrai son mur, et elle sera foulée aux pieds.
6 Èmi yóò sì sọ ọ́ di ahoro láì kọ ọ́ láì ro ó, ẹ̀wọ̀n àti ẹ̀gún ni yóò hù níbẹ̀. Èmi yóò sì pàṣẹ fún kurukuru láti má ṣe rọ̀jò sórí i rẹ̀.”
Et j'abandonnerai ma vigne, et elle ne sera plus ni taillée ni bêchée; et sur elle s'élèveront des épines comme sur une terre aride, et j'ordonnerai aux nuées de ne jamais l'arroser de pluie.
7 Ọgbà àjàrà Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni ilé Israẹli àwọn ọkùnrin Juda sì ni àyànfẹ́ ọgbà rẹ̀. Ó retí ìdájọ́ ẹ̀tọ́ ṣùgbọ́n, ìtàjẹ̀ sílẹ̀ ni ó rí. Òun ń retí òdodo ṣùgbọ́n ó gbọ́ ẹkún ìpayínkeke.
Or la vigne du Seigneur Dieu des armées, c'est la maison d'Israël, et l'homme de Juda est mon nouveau plant bien-aimé. J'ai compté qu'il ferait la justice, et il a fait l'iniquité; et ce n'est pas la voix de l'équité, mais des cris que j'y entends.
8 Ègbé ni fún àwọn tí ń kọ́lé mọ́lé tí ó sì ń ra ilẹ̀ mọ́lẹ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí ààyè kò ṣẹ́kù tí ó sì nìkan gbé lórí ilẹ̀.
Malheur à ceux qui joignent maison à maison, qui rapprochent leur champ d'un autre champ, afin de prendre quelque chose au voisin! est-ce que vous habiterez seuls la terre?
9 Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti sọ ọ́ sí mi létí: “Ó dájú pé àwọn ilé ńlá ńlá yóò di ahoro, àwọn ilé dáradára yóò wà láìní olùgbé.
Ces choses sont venues aux oreilles du Seigneur Dieu des armées. Si nombreuses que soient vos maisons, elles seront désertes; quoique grandes et belles, ceux qui les habitent ne seront plus.
10 Ọgbà àjàrà sáré oko mẹ́wàá yóò mú ìkòkò wáìnì kan wá, nígbà tí òsùwọ̀n homeri kan yóò mú agbọ̀n irúgbìn kan wá.”
Où labourent dix paires de bœufs, on ne récoltera qu'une mesure; et celui qui sème six artabes, n'en retirera que trois mesures.
11 Ègbé ni fún àwọn tí wọ́n dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ láti lépa ọtí líle, tí wọ́n sì mu ún títí alẹ́ fi lẹ́ títí wọ́n fi gbinájẹ pẹ̀lú wáìnì.
Malheur à ceux qui se lèvent le matin pour boire, et qui boivent jusqu'au soir! car le vin les brûlera.
12 Wọ́n ní dùùrù àti ohun èlò orin olókùn níbi àsè wọn, ṣaworo òun fèrè àti wáìnì, ṣùgbọ́n wọn kò ka iṣẹ́ Olúwa sí, wọn kò sí bọ̀wọ̀ fún iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀.
Au son des cithares, des harpes, des tambours et des flûtes, ils boivent du vin; mais les œuvres du Seigneur, ils ne les considèrent pas; les œuvres de ses mains, ils n'y font pas attention.
13 Nítorí náà àwọn ènìyàn mi yóò lọ sí ìgbèkùn nítorí òye kò sí fún wọn, ebi ni yóò pa àwọn ọlọ́lá wọn kú; ẹgbàágbèje wọn ni òǹgbẹ yóò sì gbẹ.
Aussi mon peuple est-il devenu captif, parce qu'il n'a pas connu le Seigneur; et la faim et la soif en ont fait périr une multitude.
14 Nítorí náà isà òkú ti ń dátọ́mì gidigidi, ó sì ti ya ẹnu rẹ̀ sílẹ̀ gbagada, nínú rẹ̀ ni àwọn gbajúmọ̀ àti mẹ̀kúnnù yóò sọ̀kalẹ̀ sí pẹ̀lú ọlá àti ògo wọn. (Sheol h7585)
Et l'enfer s'en est dilaté l'âme, et il a ouvert sa bouche pour n'en point laisser échapper; et les grands, et les riches, et les hommes en honneur, et les hommes de pestilence, y descendront. (Sheol h7585)
15 Báyìí, ènìyàn yóò di ìrẹ̀sílẹ̀ àti ọmọ ènìyàn ni a sọ di onírẹ̀lẹ̀ ojú agbéraga ni a sì rẹ̀ sílẹ̀.
Et l'homme sera humilié, et le guerrier méprisé, et les yeux hautains se baisseront.
16 Ṣùgbọ́n Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni a ó gbéga nípa ẹ̀tọ́ rẹ̀, Ọlọ́run ẹni mímọ́ yóò sì fi ara rẹ̀ hàn ní mímọ́ nípa òdodo rẹ̀.
Et le Seigneur sera exalté dans son jugement, et le Dieu saint sera glorifié dans sa justice.
17 Nígbà náà ni àwọn àgùntàn yóò máa jẹ́ ko ní ibùgbé e wọn, àwọn ọ̀dọ́-àgùntàn yóò máa jẹ nínú ahoro àwọn ọlọ́rọ̀.
Et ceux qu'on aura pillés brouteront en paix comme des taureaux, et les agneaux iront paître dans les champs déserts de ceux qu'on aura emmenés.
18 Ègbé ni fún àwọn tí ń fi ohun asán fa ẹ̀ṣẹ̀, àti àwọn tí o dàbí ẹni pé wọ́n ń fi okùn kẹ̀kẹ́ ẹ̀sìn fa ẹsẹ̀,
Malheur à ceux qui traînent leurs péchés comme avec un long câble, et leurs iniquités comme avec la courroie du joug d'une génisse,
19 sí àwọn tí ó sọ pé, “Jẹ́ kí Ọlọ́run ṣe kíákíá, jẹ́ kí ó yára ṣiṣẹ́ rẹ̀ kí a lè rí i, jẹ́ kí ó súnmọ́ bí jẹ́ kí ètò ẹni mímọ́ Israẹli kí ó dé, kí àwa kí ó le mọ̀ ọ́n.”
Et qui disent: Que bientôt advienne ce qu'il doit faire, afin que nous le voyions; que s'accomplisse la volonté du saint d'Israël, afin que nous la connaissions!
20 Ègbé ni fún àwọn tí ń pe ibi ní rere, àti rere ní ibi, tí ń fi òkùnkùn ṣe ìmọ́lẹ̀ àti ìmọ́lẹ̀ ṣe òkùnkùn, tí ń fi ìkorò ṣe adùn àti adùn ṣe ìkorò.
Malheur à ceux qui appellent mal le bien, et bien le mal; qui donnent aux ténèbres le nom de lumière, et à la lumière le nom de ténèbres; qui tiennent pour amer le doux et pour doux l'amer!
21 Ègbé ni fún àwọn tí ó gbọ́n lójú ara wọn tí wọ́n jáfáfá lójú ara wọn.
Malheur à ceux qui sont sages à leur sens et savants à leurs yeux!
22 Ègbé ni fún àwọn akọni nínú wáìnì mímu àti àwọn akíkanjú nínú àdàlú ọtí,
Malheur à vos puissants qui boivent le vin, et à vos riches qui se préparent une boisson fermentée;
23 tí wọ́n dá ẹlẹ́bi sílẹ̀ nítorí àbẹ̀tẹ́lẹ̀, tí wọn sì du aláre ní ẹ̀tọ́.
A ceux qui justifient l'impie à prix d'argent, et qui ne rendent pas justice au juste!
24 Nítorí náà, gẹ́gẹ́ bí ahọ́n iná ṣe ń jó àgékù koríko run àti bí koríko ṣe rẹlẹ̀ wẹ̀sì nínú iná, bẹ́ẹ̀ ni egbò wọn yóò jẹrà tí òdodo wọn yóò sì fẹ́ lọ bí eruku: nítorí pé wọ́n ti kọ òfin Olúwa àwọn ọmọ-ogun sílẹ̀ wọ́n sì gan ọ̀rọ̀ Ẹni mímọ́ Israẹli.
A cause de cela, comme le chaume est mis en feu par un charbon embrasé, et consumé par une flamme légère, ainsi leur racine sera réduite en cendres, et leur fleur s'envolera en poussière; car ils n'ont pas voulu de la loi du Seigneur des armées, mais ils ont irrité la parole du Saint d'Israël.
25 Nítorí náà, ìbínú Olúwa gbóná si àwọn ènìyàn rẹ̀, ó ti gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè, ó sì lù wọ́n bolẹ̀. Àwọn òkè sì wárìrì, òkú wọn sì dàbí ààtàn ní àárín ìgboro. Pẹ̀lú gbogbo èyí, ìbínú rẹ̀ kò yí kúrò, ṣùgbọ́n ọ̀wọ́ rẹ̀ sì ná jáde síbẹ̀.
Et le Seigneur des armées a été transporté de colère contre son peuple, et il a étendu sa main sur eux, et il les a frappés. Et les montagnes ont frémi, et les cadavres des hommes ont, comme de la boue, couvert les chemins. Et au milieu de ces fléaux, sa fureur ne s'est point détournée, et sa main est encore levée.
26 Yóò sì gbé ọ̀págun sókè sí àwọn orílẹ̀-èdè tí ó jìnnà, yóò sì kọ sí wọn tí ó wà ní ìpẹ̀kun ilẹ̀. Sì kíyèsi, wọ́n yóò yára wá kánkán.
C'est pourquoi il fera signe aux nations lointaines, et il sifflera pour les appeler des extrémités de la terre, et voilà qu'elles accourent au plus vite.
27 Kò sí ẹni tí yóò rẹ̀ nínú wọn, tàbí tí yóò kọsẹ̀, kò sí ẹni tí yóò tòògbé tàbí tí yóò sùn; bẹ́ẹ̀ ni àmùrè ẹ̀gbẹ́ wọn kì yóò tú, bẹ́ẹ̀ ni okùn sálúbàtà wọn kì yóò ja.
Elles ne sentiront ni la faim ni la fatigue; elles ne reposeront point la nuit; elles ne dormiront point; elles ne dénoueront pas la ceinture de leurs reins, et les cordons de leurs sandales ne seront point déliés.
28 Àwọn ọfà wọn múná, gbogbo ọrun wọn sì le; pátákò àwọn ẹṣin wọn le bí òkúta akọ, àwọn àgbá kẹ̀kẹ́ wọn sì dàbí ìjì líle.
Leurs traits sont acérés, leurs arcs tendus; les pieds de leurs chevaux sont fermes comme le roc, les roues de leurs chars sont comme un tourbillon.
29 Bíbú wọn dàbí tí kìnnìún, wọ́n bú bí ẹgbọrọ kìnnìún, wọ́n ń kọ bí wọ́n ti di ẹran ọdẹ wọn mú tí wọn sì gbé e lọ láìsí ẹni tí yóò gbà á là.
Elles frémissent comme des lions; elles s'élancent comme des lionceaux. Ce peuple pillera, rugira comme une bête fauve, et il renversera tout, et nul ne pourra lui ravir sa proie.
30 Ní ọjọ́ náà, wọn yóò hó lé e lórí gẹ́gẹ́ bí i rírú omi Òkun. Bí ènìyàn bá sì wo ilẹ̀, yóò rí òkùnkùn àti ìbànújẹ́; pẹ̀lúpẹ̀lú ìmọ́lẹ̀ yóò di òkùnkùn pẹ̀lú kurukuru rẹ̀.
Et en ce jour il criera contre Israël, comme la voix d'une mer agitée; et ils tourneront leurs yeux vers la terre, et dans leur détresse ils n'y verront que d'affreuses ténèbres.

< Isaiah 5 >