< Isaiah 5 >

1 Èmi yóò kọrin fún ẹni tí mo fẹ́ràn orin kan nípa ọgbà àjàrà rẹ̀. Olùfẹ́ mi ní ọgbà àjàrà kan ní ẹ̀gbẹ́ òkè ẹlẹ́tù lójú.
[Now] I will sing a song about my dear friend, and about his vineyard. The vineyard was on a very fertile hillside.
2 Ó tu ilẹ̀ rẹ̀, ó ṣa òkúta ibẹ̀ kúrò ó sì gbin àyànfẹ́ àjàrà sí i. Ó kọ́ ilé ìṣọ́ sí inú rẹ̀ ó sì ṣe ìfúntí kan síbẹ̀ pẹ̀lú. Lẹ́yìn náà, ó ń retí èso àjàrà dáradára, ṣùgbọ́n èso búburú ni ó ti ibẹ̀ wá.
My friend plowed the ground and cleared away the stones. Then he planted very good grapevines on that ground. In the middle of the vineyard, he built a watchtower, and he dug a (winepress/pit for squeezing the grapes). Then he waited [each year] to harvest some good grapes, but the vines produced [only] sour grapes.
3 “Ní ìsinsin yìí ẹ̀yin olùgbé Jerusalẹmu àti ẹ̀yin ènìyàn Juda ẹ ṣe ìdájọ́ láàrín èmi àti ọgbà àjàrà mi.
Now [this is what Yahweh says]: “You people of Jerusalem and [other places in] Judah, I [am like the friend, and you are like] my vineyard; [so] you judge which of us [has done what is right].
4 Kín ni ó kù tí n ò bá túnṣe sí ọgbà àjàrà mi. Ju èyí tí mo ti ṣe lọ? Nígbà tí mo ń wá èso dáradára, èéṣe tí ó fi so kíkan?
What more could I have done for you than what I have already done? I expected you to be doing good deeds [MET], so it is disgusting that [RHQ] you were [doing only evil things] like the vineyard that produced only sour grapes!
5 Ní ìsinsin yìí, èmi yóò wí fún ọ ohun tí n ó ṣe sí ọgbà àjàrà mi. Èmi yóò gé igi inú rẹ̀ kúrò, a ó sì pa á run, Èmi yóò wó ògiri rẹ̀ lulẹ̀ yóò sì di ìtẹ̀mọ́lẹ̀.
[So], I will now tell you what I will do to [Judah, the place that is like] my vineyard. I will cut down the hedges, and they will be destroyed. I will tear down the walls [of the cities] and allow [wild animals] to trample the land.
6 Èmi yóò sì sọ ọ́ di ahoro láì kọ ọ́ láì ro ó, ẹ̀wọ̀n àti ẹ̀gún ni yóò hù níbẹ̀. Èmi yóò sì pàṣẹ fún kurukuru láti má ṣe rọ̀jò sórí i rẹ̀.”
I will cause it to become a wasteland where the vines are not pruned and the ground is not hoed. It will be a place where briers and thorns [DOU] grow. And I will command that no rain will fall on it.”
7 Ọgbà àjàrà Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni ilé Israẹli àwọn ọkùnrin Juda sì ni àyànfẹ́ ọgbà rẹ̀. Ó retí ìdájọ́ ẹ̀tọ́ ṣùgbọ́n, ìtàjẹ̀ sílẹ̀ ni ó rí. Òun ń retí òdodo ṣùgbọ́n ó gbọ́ ẹkún ìpayínkeke.
The nation of Israel is [like] [MET] the vineyard of the Commander of the armies of angels. The people of Judah are [like] the garden that was pleasing to him. He expected you to be doing what is just/fair, but instead, [what he saw was people] murdering [MTY] others. [He expected that you would be doing] righteous deeds, but instead, he heard cries from people who were being [attacked] violently.
8 Ègbé ni fún àwọn tí ń kọ́lé mọ́lé tí ó sì ń ra ilẹ̀ mọ́lẹ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí ààyè kò ṣẹ́kù tí ó sì nìkan gbé lórí ilẹ̀.
Terrible things will happen to you who continually [illegally] acquire houses and fields. You force one family after another to leave their homes until you are the only ones [HYP] [still] living in the land.
9 Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti sọ ọ́ sí mi létí: “Ó dájú pé àwọn ilé ńlá ńlá yóò di ahoro, àwọn ilé dáradára yóò wà láìní olùgbé.
[But] I heard the Commander of the armies of angels solemnly declare this: “[Some day], many of those huge houses will be empty/deserted; no one will be living in those beautiful mansions.
10 Ọgbà àjàrà sáré oko mẹ́wàá yóò mú ìkòkò wáìnì kan wá, nígbà tí òsùwọ̀n homeri kan yóò mú agbọ̀n irúgbìn kan wá.”
The vines on ten acres of land will not produce enough grapes to make (six gallons/22 liters) [of juice/wine], and ten baskets of seed will produce only one basket [of grain].”
11 Ègbé ni fún àwọn tí wọ́n dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ láti lépa ọtí líle, tí wọ́n sì mu ún títí alẹ́ fi lẹ́ títí wọ́n fi gbinájẹ pẹ̀lú wáìnì.
Terrible things will happen to those who get up early [each] morning to begin drinking alcoholic drinks, and who stay awake until late at night [drinking a lot of wine] until they are completely drunk.
12 Wọ́n ní dùùrù àti ohun èlò orin olókùn níbi àsè wọn, ṣaworo òun fèrè àti wáìnì, ṣùgbọ́n wọn kò ka iṣẹ́ Olúwa sí, wọn kò sí bọ̀wọ̀ fún iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀.
They have [big parties and provide lots of] wine. At their parties, there are [people playing] harps and lyres and tambourines and flutes, but they never think about what Yahweh does or appreciate what he has created.
13 Nítorí náà àwọn ènìyàn mi yóò lọ sí ìgbèkùn nítorí òye kò sí fún wọn, ebi ni yóò pa àwọn ọlọ́lá wọn kú; ẹgbàágbèje wọn ni òǹgbẹ yóò sì gbẹ.
So, my people will be (exiled/taken to other countries) [far away] because they do not know [about me]. Those who are [now very important and] honored will starve, and the other people will die from thirst.
14 Nítorí náà isà òkú ti ń dátọ́mì gidigidi, ó sì ti ya ẹnu rẹ̀ sílẹ̀ gbagada, nínú rẹ̀ ni àwọn gbajúmọ̀ àti mẹ̀kúnnù yóò sọ̀kalẹ̀ sí pẹ̀lú ọlá àti ògo wọn. (Sheol h7585)
[It is as though] [PRS] the place where the dead people are is eagerly looking for more Israeli people, opening its mouth to swallow them, and a huge number of people will be thrown into that place, including their leaders as well as a noisy crowd of people who enjoy living in Jerusalem. (Sheol h7585)
15 Báyìí, ènìyàn yóò di ìrẹ̀sílẹ̀ àti ọmọ ènìyàn ni a sọ di onírẹ̀lẹ̀ ojú agbéraga ni a sì rẹ̀ sílẹ̀.
[Yahweh] will get rid of a huge number of people; and he will humble [many more] people who [now] are proud/arrogant.
16 Ṣùgbọ́n Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni a ó gbéga nípa ẹ̀tọ́ rẹ̀, Ọlọ́run ẹni mímọ́ yóò sì fi ara rẹ̀ hàn ní mímọ́ nípa òdodo rẹ̀.
But the Commander of the armies of angels will be exalted/praised because of his acting justly. God will show that he is holy by doing righteous/just deeds.
17 Nígbà náà ni àwọn àgùntàn yóò máa jẹ́ ko ní ibùgbé e wọn, àwọn ọ̀dọ́-àgùntàn yóò máa jẹ nínú ahoro àwọn ọlọ́rọ̀.
Then lambs and fat sheep will [be able to] find good grass to eat, [even] among the ruins [of the houses of rich people].
18 Ègbé ni fún àwọn tí ń fi ohun asán fa ẹ̀ṣẹ̀, àti àwọn tí o dàbí ẹni pé wọ́n ń fi okùn kẹ̀kẹ́ ẹ̀sìn fa ẹsẹ̀,
Some people constantly tell lies, and [it is as though] they are dragging behind them the wrong things that they have done. Terrible things will happen to them!
19 sí àwọn tí ó sọ pé, “Jẹ́ kí Ọlọ́run ṣe kíákíá, jẹ́ kí ó yára ṣiṣẹ́ rẹ̀ kí a lè rí i, jẹ́ kí ó súnmọ́ bí jẹ́ kí ètò ẹni mímọ́ Israẹli kí ó dé, kí àwa kí ó le mọ̀ ọ́n.”
They [make fun of God and] say [to him, ] “Go ahead, do something [to punish us]! We want to see what you will do. You, the Holy One of Israel, should do what you are planning to do, because we want to know what it is.”
20 Ègbé ni fún àwọn tí ń pe ibi ní rere, àti rere ní ibi, tí ń fi òkùnkùn ṣe ìmọ́lẹ̀ àti ìmọ́lẹ̀ ṣe òkùnkùn, tí ń fi ìkorò ṣe adùn àti adùn ṣe ìkorò.
Terrible things will happen to those who say that evil is good, and that good is evil, that darkness is light and that light is darkness, that what is bitter is sweet and what is sweet is bitter.
21 Ègbé ni fún àwọn tí ó gbọ́n lójú ara wọn tí wọ́n jáfáfá lójú ara wọn.
Terrible things will happen to those who think that they are wise and that they (are very clever/know everything).
22 Ègbé ni fún àwọn akọni nínú wáìnì mímu àti àwọn akíkanjú nínú àdàlú ọtí,
Terrible things will happen to those who [think that] [IRO] they are great/heroes because they are able to drink [lots of] wine, and boast about being able to mix good alcoholic drinks.
23 tí wọ́n dá ẹlẹ́bi sílẹ̀ nítorí àbẹ̀tẹ́lẹ̀, tí wọn sì du aláre ní ẹ̀tọ́.
If people offer them bribes in order that they will enable wicked people not to be punished, they accept those bribes, and they cause people who are innocent to be punished.
24 Nítorí náà, gẹ́gẹ́ bí ahọ́n iná ṣe ń jó àgékù koríko run àti bí koríko ṣe rẹlẹ̀ wẹ̀sì nínú iná, bẹ́ẹ̀ ni egbò wọn yóò jẹrà tí òdodo wọn yóò sì fẹ́ lọ bí eruku: nítorí pé wọ́n ti kọ òfin Olúwa àwọn ọmọ-ogun sílẹ̀ wọ́n sì gan ọ̀rọ̀ Ẹni mímọ́ Israẹli.
Therefore, just like [SIM] fires burn up stubble and dry grass shrivels up and quickly burns in flames, [it will be as though] those people have roots that will rot and have flowers that will wither. [That will happen] because they rejected the laws of the Commander of the armies of angels; they have despised the messages of the Holy One of Israel.
25 Nítorí náà, ìbínú Olúwa gbóná si àwọn ènìyàn rẹ̀, ó ti gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè, ó sì lù wọ́n bolẹ̀. Àwọn òkè sì wárìrì, òkú wọn sì dàbí ààtàn ní àárín ìgboro. Pẹ̀lú gbogbo èyí, ìbínú rẹ̀ kò yí kúrò, ṣùgbọ́n ọ̀wọ́ rẹ̀ sì ná jáde síbẹ̀.
That is why Yahweh is [extremely] angry [with his people]; [it is as though] his hand is raised [and he is ready to smash them]. [When he does that], the mountains will shake, and the corpses of people will be scattered in the streets like [SIM] manure. But even when that happens, Yahweh will still be very angry; he will be ready to punish his people [MET] again.
26 Yóò sì gbé ọ̀págun sókè sí àwọn orílẹ̀-èdè tí ó jìnnà, yóò sì kọ sí wọn tí ó wà ní ìpẹ̀kun ilẹ̀. Sì kíyèsi, wọ́n yóò yára wá kánkán.
Yahweh will send a signal to summon [armies of] nations far away; [it is as though] he will whistle [to summon those soldiers who are] in very remote places on the earth. They will come very swiftly [DOU] [to Jerusalem].
27 Kò sí ẹni tí yóò rẹ̀ nínú wọn, tàbí tí yóò kọsẹ̀, kò sí ẹni tí yóò tòògbé tàbí tí yóò sùn; bẹ́ẹ̀ ni àmùrè ẹ̀gbẹ́ wọn kì yóò tú, bẹ́ẹ̀ ni okùn sálúbàtà wọn kì yóò ja.
They will not get tired or stumble. They will not [stop to] rest or to sleep. None of their belts will be loose, and none of them will have sandals with broken straps, [so they will all be ready to fight in battles].
28 Àwọn ọfà wọn múná, gbogbo ọrun wọn sì le; pátákò àwọn ẹṣin wọn le bí òkúta akọ, àwọn àgbá kẹ̀kẹ́ wọn sì dàbí ìjì líle.
Their arrows will be sharp, and their bows will be ready [to shoot those arrows in a battle]. [Because their horses pull the chariots fast], sparks will shoot out from their hooves, and the wheels of the chariots will spin like a whirlwind.
29 Bíbú wọn dàbí tí kìnnìún, wọ́n bú bí ẹgbọrọ kìnnìún, wọ́n ń kọ bí wọ́n ti di ẹran ọdẹ wọn mú tí wọn sì gbé e lọ láìsí ẹni tí yóò gbà á là.
They will roar like [very strong] lions [DOU] that growl and [then] pounce on the animals they want to kill and carry them off, and no one is able to rescue them.
30 Ní ọjọ́ náà, wọn yóò hó lé e lórí gẹ́gẹ́ bí i rírú omi Òkun. Bí ènìyàn bá sì wo ilẹ̀, yóò rí òkùnkùn àti ìbànújẹ́; pẹ̀lúpẹ̀lú ìmọ́lẹ̀ yóò di òkùnkùn pẹ̀lú kurukuru rẹ̀.
[Similarly, your enemies] will roar when they see the people they are about to kill, like [SIM] the sea roars. [On that day], if someone looks across the land, he will see [only people who are in] darkness and distressed; [it will be as though] even the sunlight is hidden by dark clouds.

< Isaiah 5 >