< Isaiah 49 >
1 Tẹ́tí sí mi, ẹ̀yin erékùṣù: gbọ́ èyí, ẹ̀yin orílẹ̀-èdè jíjìnnà réré: kí a tó bí mi Olúwa ti pè mí; láti ìgbà bíbí mi ni ó ti dá orúkọ mi.
Ascultaţi-mă insule; şi daţi ascultare, voi popoare de departe; DOMNUL m-a chemat din pântece; din adâncurile mamei mele a amintit de numele meu.
2 Ó ṣe ẹnu mi bí idà tí a pọ́n, ní abẹ́ òjìji ọwọ́ rẹ̀ ni ó ti pa mí mọ́: ó ṣe mí ní ọfà tí a ti dán, ó sì fi mí pamọ́ sínú àpò rẹ̀.
Şi mi-a făcut gura ca o sabie ascuţită; în umbra mâinii lui m-a ascuns şi m-a făcut o săgeată lustruită; în tolba lui m-a ascuns;
3 Ó sọ fún mi pé, “Ìránṣẹ́ mi ni ìwọ í ṣe, Israẹli nínú ẹni tí n ó ti fi ògo mi hàn.”
Şi mi-a spus: Israele, tu eşti servitorul meu în care voi fi glorificat.
4 Ṣùgbọ́n èmi sọ pé, “Mo ti ṣe wàhálà lórí asán; mo ti lo gbogbo ipá mi lórí asán àti ìmúlẹ̀mófo. Síbẹ̀síbẹ̀ ohun tí ó tọ́ sí mi ṣì wà lọ́wọ́ Olúwa, èrè mi sì ń bẹ pẹ̀lú Ọlọ́run mi.”
Atunci am spus: Am ostenit în zadar, mi-am cheltuit puterea pentru nimic şi în zadar, totuşi judecata mea este la DOMNUL şi lucrarea mea la Dumnezeul meu.
5 Nísinsin yìí Olúwa wí pé ẹni tí ó mọ̀ mí láti inú wá láti jẹ́ ìránṣẹ́ rẹ̀ láti mú Jakọbu padà tọ̀ mí wá àti láti kó Israẹli jọ sọ́dọ̀ ara rẹ̀, nítorí pé a bọ̀wọ̀ fún mi ní ojú Olúwa Ọlọ́run mi sì ti jẹ́ agbára mi,
Şi acum, spune DOMNUL care m-a format din pântece să fiu servitorul său, să aduc pe Iacob din nou la el: Deşi Israel nu este adunat, totuşi voi fi glorios în ochii DOMNULUI şi Dumnezeul meu va fi tăria mea.
6 Òun wí pé: “Ó jẹ́ ohun kékeré fún ọ láti jẹ́ ìránṣẹ́ mi láti mú ẹ̀yà Jakọbu padà bọ̀ sípò àti láti mú àwọn ti Israẹli tí mo ti pamọ́. Èmi yóò sì fi ọ́ ṣe ìmọ́lẹ̀ fún àwọn kèfèrí, kí ìwọ kí ó lè mú ìgbàlà mi wá sí òpin ilẹ̀ ayé.”
Iar el a spus: Este un lucru uşor să fii servitorul meu pentru a ridica triburile lui Iacob şi a restaura pe cei păstraţi ai lui Israel, de asemenea te voi da ca o lumină neamurilor, ca să fii salvarea mea până la capătul pământului.
7 Ohun tí Olúwa wí nìyìí, Olùdáǹdè àti Ẹni Mímọ́ Israẹli— sí ẹni náà tí a gàn tí a sì kórìíra lọ́wọ́ àwọn orílẹ̀-èdè, sí ìránṣẹ́ àwọn aláṣẹ: “Àwọn ọba yóò rí ọ wọn yóò sì dìde sókè, àwọn ọmọ ọba yóò rí i wọn yóò sì wólẹ̀, nítorí Olúwa ẹni tí í ṣe olóòtítọ́, Ẹni Mímọ́ Israẹli tí ó ti yàn ọ́.”
Astfel spune DOMNUL, Răscumpărătorul lui Israel [şi] Cel Sfânt al său, celui pe care omul îl dispreţuieşte, celui pe care naţiunea îl detestă, unui servitor al conducătorilor: Împăraţi vor vedea şi se vor ridica, prinţi de asemenea se vor închina, datorită DOMNULUI care este credincios [şi] Celui Sfânt al lui Israel, iar el te va alege pe tine.
8 Ohun tí Olúwa wí nìyìí: “Ní àkókò ojúrere mi, èmi yóò dá ọ lóhùn, àti ní ọjọ́ ìgbàlà, èmi yóò ràn ọ́ lọ́wọ́; Èmi yóò pa ọ́ mọ́, n ó sì ṣe ọ́ láti jẹ́ májẹ̀mú fún àwọn ènìyàn, láti mú ilẹ̀ padà bọ̀ sípò àti láti ṣe àtúnpín ogún rẹ̀ tí ó ti dahoro,
Astfel spune DOMNUL: La timpul îndurării te-am auzit, şi în ziua salvării te-am ajutat; şi te voi păstra şi te voi da ca legământ al poporului, pentru a întemeia pământul, să faci să moştenească moştenirile pustiite;
9 láti sọ fún àwọn ìgbèkùn pé, ‘Ẹ jáde wá,’ àti fún àwọn tí ó wà nínú òkùnkùn pé, ‘Ẹ gba òmìnira!’ “Wọn yóò máa jẹ ní ẹ̀bá ọ̀nà àti koríko tútù lórí òkè aláìléwéko.
Ca să spui prizonierilor: Mergeţi înainte; celor ce sunt în întuneric: Arătaţi-vă. Vor paşte pe lângă drumuri şi păşunile lor vor fi în toate locurile înalte.
10 Ebi kì yóò pa wọ́n bẹ́ẹ̀ ni òǹgbẹ kì yóò gbẹ wọ́n, tàbí kí ooru inú aṣálẹ̀ tàbí oòrùn kí ó pa wọ́n. Ẹni tí ó ṣàánú fún wọn ni yóò máa tọ́ wọn, tí yóò sì mú wọn lọ sí ibi orísun omi.
Nu vor flămânzi nici nu vor înseta; nici căldura nici soarele nu îi vor lovi, căci cel ce are milă de ei îi va conduce, pe lângă izvoarele de apă îi va călăuzi.
11 Èmi yóò sọ gbogbo àwọn òkè ńlá mi di ojú ọ̀nà àti gbogbo òpópónà mi ni a ó gbé sókè.
Şi toţi munţii mei îi voi face o cale şi drumurile mele mari vor fi înălţate.
12 Kíyèsi i, wọn yóò wá láti ọ̀nà jíjìn àwọn díẹ̀ láti àríwá àti àwọn díẹ̀ láti ìwọ̀-oòrùn, àwọn díẹ̀ láti ẹkùn Siene.”
Iată, aceştia vor veni de departe; şi, iată, aceştia din nord şi din vest şi aceştia din ţara lui Sinim.
13 Ẹ hó fún ayọ̀, ẹyin ọ̀run; yọ̀, ìwọ ilẹ̀ ayé; bú sórin, ẹ̀yin òkè ńlá! Nítorí Olúwa tu àwọn ènìyàn rẹ̀ nínú yóò sì ṣàánú fún àwọn ẹni tí a ń pọ́n lójú.
Cântaţi, cerurilor; şi bucură-te, pământule; şi izbucniţi în cântare, munţilor, fiindcă DOMNUL a mângâiat poporul lui şi va avea milă de cei nenorociţi ai lui.
14 Ṣùgbọ́n Sioni sọ pé, “Olúwa ti kọ̀ mí sílẹ̀, Olúwa ti gbàgbé è mi.”
Dar Sionul a spus: DOMNUL m-a părăsit şi Domnul meu m-a uitat.
15 “Ǹjẹ́ abiyamọ ha le gbàgbé ọmọ ọmú rẹ̀ kí ó má sì ṣàánú fún ọmọ rẹ̀ tí ó ti bí? Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òun le gbàgbé, Èmi kì yóò gbàgbé rẹ!
Poate o femeie să îşi uite copilul sugar, încât să nu aibă milă de fiul pântecelui ei? Da, ei pot uita, totuşi eu nu te voi uita.
16 Kíyèsi i, mo ti kọ ọ́ sí àtẹ́lẹwọ́ mi ògiri rẹ wà níwájú mi nígbà gbogbo.
Iată, te-am gravat pe palmele mâinii mele; zidurile tale sunt întotdeauna înaintea mea.
17 Àwọn ọmọ rẹ ti kánjú padà, àti àwọn tí ó sọ ọ́ dahoro ti padà lẹ́yìn rẹ.
Copiii tăi se vor grăbi; nimicitorii tăi şi cei ce te-au risipit vor pleca de la tine.
18 Gbójú rẹ sókè kí o sì wò yíká; gbogbo àwọn ọmọkùnrin rẹ kórajọ wọ́n sì wá sọ́dọ̀ rẹ. Níwọ́n ìgbà tí mo bá wà láààyè,” ni Olúwa wí, “Ìwọ yóò wọ gbogbo wọ́n gẹ́gẹ́ bí ohun ọ̀ṣọ́; ìwọ yóò wọ̀ wọ́n gẹ́gẹ́ bí ìyàwó.
Ridică-ţi ochii de jur împrejur şi priveşte, toţi aceştia se adună [şi] vin la tine. Precum eu trăiesc, spune DOMNUL, cu siguranţă te vei înveşmânta cu ei toţi, precum cu un ornament şi îi vei lega de tine, precum o mireasă.
19 “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a tí run ọ́, a sì sọ ọ́ di ahoro tí gbogbo ilẹ̀ rẹ sì di ìparun, ní ìsinsin yìí, ìwọ yóò kéré jù fún àwọn ènìyàn rẹ, bẹ́ẹ̀ ni àwọn tí ó jẹ ọ́ run ni yóò wà láti ọ̀nà jíjìn réré.
Fiindcă locurile tale risipite şi pustiite şi ţara nimicirii tale, vor fi acum prea înguste din cauza locuitorilor şi cei ce te-au înghiţit vor fi departe.
20 Àwọn ọmọ tí a bí ní àkókò ọ̀fọ̀ rẹ yóò sọ ní etígbọ̀ọ́ rẹ, ‘Ibi yìí ti kéré jù fún wa; ẹ fún wa láyè sí i tí a ó máa gbé.’
Copiii pe care îi vei avea, după ce i-ai pierdut pe ceilalţi, vor spune din nou în urechile tale: Locul este prea strâmt pentru mine, dă-mi loc ca să locuiesc.
21 Nígbà náà ni ìwọ yóò sọ ní ọkàn rẹ pé, ‘Ta ló bí àwọn yìí fún mi? Mo ti ṣọ̀fọ̀ mo sì yàgàn; a sọ mi di àtìpó a sì kọ̀ mí sílẹ̀. Ta ló wo àwọn yìí dàgbà? A fi èmi nìkan sílẹ̀, ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí níbo ni wọ́n ti wá?’”
Atunci vei spune în inima ta: Cine mi-a născut pe aceştia, văzând că mi-am pierdut copiii şi sunt pustiită, o captivă şi mişcându-mă încoace şi încolo? Şi cine i-a crescut pe aceştia? Iată, am fost lăsată singură; aceştia, unde au fost?
22 Ohun tí Olúwa Olódùmarè wí nìyìí, “Kíyèsi i, Èmi yóò ké sí àwọn aláìkọlà, Èmi yóò gbé àsíá mi sókè sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ènìyàn; wọn yóò kó àwọn ọmọkùnrin yín wá ní apá wọn wọn yóò sì gbé àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin ní èjìká wọn.
Astfel spune Domnul DUMNEZEU: Iată, îmi voi înălţa mâna către neamuri şi voi ridica steagul meu către popor şi ei îţi vor aduce fiii pe braţe şi fiicele tale vor fi purtate pe umeri.
23 Àwọn ọba ni yóò jẹ́ alágbàtọ́ baba fún ọ, àwọn ayaba wọn ni yóò sì jẹ́ ìyá-alágbàtọ́. Wọn yóò foríbalẹ̀ ní iwájú rẹ̀ pẹ̀lú ojú wọn dídàbolẹ̀; wọn yóò máa lá erùpẹ̀ lẹ́bàá ẹsẹ̀ rẹ. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa; gbogbo àwọn tí wọ́n ní ìrètí nínú mi ni a kì yóò jákulẹ̀.”
Şi împăraţi vor fi părinţii tăi îngrijitori şi împărătesele lor mamele tale îngrijitoare, ţi se vor prosterna cu faţa la pământ şi vor linge praful piciorului tău; şi vei cunoaşte că eu sunt DOMNUL, fiindcă nu vor fi ruşinaţi cei ce mă aşteaptă.
24 Ǹjẹ́ a le gba ìkógun lọ́wọ́ jagunjagun, tàbí kí á gba ìgbèkùn lọ́wọ́ akíkanjú?
Va fi luată prada de la cel puternic, sau captivul legiuit eliberat?
25 Ṣùgbọ́n ohun tí Olúwa wí nìyìí: “Bẹ́ẹ̀ ni, a ó gba àwọn ìgbèkùn lọ́wọ́ àwọn jagunjagun, àti ìkógun lọ́wọ́ àwọn akíkanjú; ẹni tí ó bá ọ jà ni èmi ó bá jà, àti àwọn ọmọ rẹ ni èmi ó gbàlà.
Dar astfel spune DOMNUL: Chiar captivii celui puternic vor fi duşi şi prada tiranului va fi eliberată, căci mă voi certa cu cel ce se ceartă cu tine şi îţi voi salva copiii.
26 Èmi yóò mú kí àwọn aninilára rẹ̀ jẹ ẹran-ara wọn; wọn yóò mu ẹ̀jẹ̀ ara wọn yó bí ẹni mu wáìnì. Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn yóò mọ̀ pé, Èmi, Olúwa, èmi ni Olùgbàlà rẹ, Olùdáǹdè rẹ, Alágbára kan ṣoṣo ti Jakọbu.”
Şi voi hrăni pe cei ce te oprimă cu propria lor carne; şi se vor îmbăta cu propriul sânge, precum cu vin dulce, şi toată făptura va cunoaşte că eu, DOMNUL, sunt Salvatorul tău şi Răscumpărătorul tău, Cel puternic al lui Iacob.