< Isaiah 49 >

1 Tẹ́tí sí mi, ẹ̀yin erékùṣù: gbọ́ èyí, ẹ̀yin orílẹ̀-èdè jíjìnnà réré: kí a tó bí mi Olúwa ti pè mí; láti ìgbà bíbí mi ni ó ti dá orúkọ mi.
Dumngegkayo kaniak, dakayo nga isla! Ket ipangagyo, dakayo a tattao nga adda iti adayo. Inawagannak ni Yahweh sipud pannakaiyanakko babaen iti naganko, idi impasngaynak ti inak ditoy lubong.
2 Ó ṣe ẹnu mi bí idà tí a pọ́n, ní abẹ́ òjìji ọwọ́ rẹ̀ ni ó ti pa mí mọ́: ó ṣe mí ní ọfà tí a ti dán, ó sì fi mí pamọ́ sínú àpò rẹ̀.
Inaramidna a kasla natadem a kampilan ti ngiwatko; inlemmengnak iti anniniwan ti imana; inaramidnak a maysa a napasileng a pana; inlemmengnak iti tagubanna.
3 Ó sọ fún mi pé, “Ìránṣẹ́ mi ni ìwọ í ṣe, Israẹli nínú ẹni tí n ó ti fi ògo mi hàn.”
Kinunana kaniak, “Sika ti adipenko, Israel, a pangipakitaak iti dayagko.”
4 Ṣùgbọ́n èmi sọ pé, “Mo ti ṣe wàhálà lórí asán; mo ti lo gbogbo ipá mi lórí asán àti ìmúlẹ̀mófo. Síbẹ̀síbẹ̀ ohun tí ó tọ́ sí mi ṣì wà lọ́wọ́ Olúwa, èrè mi sì ń bẹ pẹ̀lú Ọlọ́run mi.”
Uray no impagarupko nga awan serbi ti inaramidko, a nagbannogak iti awan kaes-eskanna, Uray no kasta, ti hustisiak ket adda kenni Yahweh, ken ti gunggonak ket adda iti Diosko.
5 Nísinsin yìí Olúwa wí pé ẹni tí ó mọ̀ mí láti inú wá láti jẹ́ ìránṣẹ́ rẹ̀ láti mú Jakọbu padà tọ̀ mí wá àti láti kó Israẹli jọ sọ́dọ̀ ara rẹ̀, nítorí pé a bọ̀wọ̀ fún mi ní ojú Olúwa Ọlọ́run mi sì ti jẹ́ agbára mi,
Ket ita nagsaon ni Yahweh, isuna a nangsukog kaniak sipud pannakaiyanakko nga agbalin nga adipenna, tapno maisubli manen kenkuana ni Jacob, ken tapno maisubli ti Israel kenkuana. Napadayawanak iti imatang ni Yahweh, ket ti Diosko ti nagbalin a pigsak.
6 Òun wí pé: “Ó jẹ́ ohun kékeré fún ọ láti jẹ́ ìránṣẹ́ mi láti mú ẹ̀yà Jakọbu padà bọ̀ sípò àti láti mú àwọn ti Israẹli tí mo ti pamọ́. Èmi yóò sì fi ọ́ ṣe ìmọ́lẹ̀ fún àwọn kèfèrí, kí ìwọ kí ó lè mú ìgbàlà mi wá sí òpin ilẹ̀ ayé.”
Kunana a, “Bassit unay a banag para kenka ti agbalin nga adipenko a mangipasdek manen kadagiti tribu ni Jacob, ken mangisubli kadagiti nakalasat iti Israel. Pagbalinenkanto a silaw kadagiti Hentil, tapno agbalinka a mangisalakanko agingga kadagiti pungto ti daga.”
7 Ohun tí Olúwa wí nìyìí, Olùdáǹdè àti Ẹni Mímọ́ Israẹli— sí ẹni náà tí a gàn tí a sì kórìíra lọ́wọ́ àwọn orílẹ̀-èdè, sí ìránṣẹ́ àwọn aláṣẹ: “Àwọn ọba yóò rí ọ wọn yóò sì dìde sókè, àwọn ọmọ ọba yóò rí i wọn yóò sì wólẹ̀, nítorí Olúwa ẹni tí í ṣe olóòtítọ́, Ẹni Mímọ́ Israẹli tí ó ti yàn ọ́.”
Kastoy ti kuna ni Yahweh, a Mannubbot ti Israel, a Nasantoan, iti daydiay naumsi ti biagna a kinagura dagiti nasion, ken adipen dagiti agtuturay, “Makitadakanto dagiti ari ket tumakderda, ken makitadakanto dagiti prinsipe ket agtameddanto gapu kenni Yahweh a napudno, ken Nasantoan ti Israel, a nangpili kenka.”
8 Ohun tí Olúwa wí nìyìí: “Ní àkókò ojúrere mi, èmi yóò dá ọ lóhùn, àti ní ọjọ́ ìgbàlà, èmi yóò ràn ọ́ lọ́wọ́; Èmi yóò pa ọ́ mọ́, n ó sì ṣe ọ́ láti jẹ́ májẹ̀mú fún àwọn ènìyàn, láti mú ilẹ̀ padà bọ̀ sípò àti láti ṣe àtúnpín ogún rẹ̀ tí ó ti dahoro,
Kastoy ti kuna ni Yahweh, “Inton dumteng ti kanito nga ingkeddengko a pangipakitaak iti kinasayaatko kenka, sungbatankayto, ken iti aldaw ti pannakaisalakan, tulongankanto; salaknibankanto, ken itedkanto a kas tulag kadagiti tattao, a mangbangon manen iti daga, tapno ited manen ti langalang a tawid.
9 láti sọ fún àwọn ìgbèkùn pé, ‘Ẹ jáde wá,’ àti fún àwọn tí ó wà nínú òkùnkùn pé, ‘Ẹ gba òmìnira!’ “Wọn yóò máa jẹ ní ẹ̀bá ọ̀nà àti koríko tútù lórí òkè aláìléwéko.
Ibagamto kadagiti balud, 'Rummuarkayo;' kadagiti adda iti nasipnget a pagbaludan, 'Agparangkayo.' Agarabdanto iti igid dagiti dalan, ken kadagiti amin a tapaw ti langalang a turod ti pakaipasturandanto.
10 Ebi kì yóò pa wọ́n bẹ́ẹ̀ ni òǹgbẹ kì yóò gbẹ wọ́n, tàbí kí ooru inú aṣálẹ̀ tàbí oòrùn kí ó pa wọ́n. Ẹni tí ó ṣàánú fún wọn ni yóò máa tọ́ wọn, tí yóò sì mú wọn lọ sí ibi orísun omi.
Saandanto a mabisin wenno mawaw; wenno mapudotan iti init, ta idalanto ida ti mangngaasi kadakuada; iturongnanto ida kadagiti ubbog ti danum.
11 Èmi yóò sọ gbogbo àwọn òkè ńlá mi di ojú ọ̀nà àti gbogbo òpópónà mi ni a ó gbé sókè.
Ket pagbalinekto a kalsada dagiti amin a bantayko, ken pagbalinekto a patad dagiti kalsadak.”
12 Kíyèsi i, wọn yóò wá láti ọ̀nà jíjìn àwọn díẹ̀ láti àríwá àti àwọn díẹ̀ láti ìwọ̀-oòrùn, àwọn díẹ̀ láti ẹkùn Siene.”
Kitaem, aggapunto dagitoy iti adayo, adda naggapu iti amianan ken iti laud; ken naggapu dagiti dadduma iti daga ti Sinim.
13 Ẹ hó fún ayọ̀, ẹyin ọ̀run; yọ̀, ìwọ ilẹ̀ ayé; bú sórin, ẹ̀yin òkè ńlá! Nítorí Olúwa tu àwọn ènìyàn rẹ̀ nínú yóò sì ṣàánú fún àwọn ẹni tí a ń pọ́n lójú.
Agkantakayo, O langlangit, ken agrag-oka, O daga, agkantakayo, dakayo a banbantay! Ta liwliwaen ni Yahweh dagiti tattaona, ket kaasiannanto dagiti agsagsagaba.
14 Ṣùgbọ́n Sioni sọ pé, “Olúwa ti kọ̀ mí sílẹ̀, Olúwa ti gbàgbé è mi.”
Ngem kinuna ti Sion, “Binaybay-annak ni Yahweh, ken linipatnak ti Apo.”
15 “Ǹjẹ́ abiyamọ ha le gbàgbé ọmọ ọmú rẹ̀ kí ó má sì ṣàánú fún ọmọ rẹ̀ tí ó ti bí? Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òun le gbàgbé, Èmi kì yóò gbàgbé rẹ!
“Malipatan kadi ti babai ti maladagana, a paspasusoenna iti barukongna, isu a saanna a kaasian ti impasngayna nga anakna? Wen, mabalin a malipatanda, ngem saankayonto a malipatan.
16 Kíyèsi i, mo ti kọ ọ́ sí àtẹ́lẹwọ́ mi ògiri rẹ wà níwájú mi nígbà gbogbo.
Kitaem, inkitikitko ti naganyo kadagiti dakulapko; adda a kanayon iti sangoanak dagiti padermo.
17 Àwọn ọmọ rẹ ti kánjú padà, àti àwọn tí ó sọ ọ́ dahoro ti padà lẹ́yìn rẹ.
Agdardaras nga agsubli dagiti annakmo, kabayatan nga umad-adayo dagiti nangdadael kenka.
18 Gbójú rẹ sókè kí o sì wò yíká; gbogbo àwọn ọmọkùnrin rẹ kórajọ wọ́n sì wá sọ́dọ̀ rẹ. Níwọ́n ìgbà tí mo bá wà láààyè,” ni Olúwa wí, “Ìwọ yóò wọ gbogbo wọ́n gẹ́gẹ́ bí ohun ọ̀ṣọ́; ìwọ yóò wọ̀ wọ́n gẹ́gẹ́ bí ìyàwó.
Kumitaka iti aglawlawmo ket makitam, aguummongda amin nga um-umay kenka. Iti isapatak—kastoy ti pakaammo ni Yahweh—nga usaremto dagitoy a kasla alahas; isuotmonto dagitoy, a kas iti maysa a nobia.
19 “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a tí run ọ́, a sì sọ ọ́ di ahoro tí gbogbo ilẹ̀ rẹ sì di ìparun, ní ìsinsin yìí, ìwọ yóò kéré jù fún àwọn ènìyàn rẹ, bẹ́ẹ̀ ni àwọn tí ó jẹ ọ́ run ni yóò wà láti ọ̀nà jíjìn réré.
Uray no naglangalang ken nabaybay-anka, maysa a nadadael a daga, ita agbalinka a bassit unay para kadagiti agnanaed, ket maidayonto dagiti nangdadael kenka.
20 Àwọn ọmọ tí a bí ní àkókò ọ̀fọ̀ rẹ yóò sọ ní etígbọ̀ọ́ rẹ, ‘Ibi yìí ti kéré jù fún wa; ẹ fún wa láyè sí i tí a ó máa gbé.’
Kunaento kenka dagiti ubbing a maiyanak iti tiempo ti pannakaulilak 'Nailet unay daytoy a lugar para kadakami, iyaramidannakami iti siled tapno makapagnaedkami ditoy.'
21 Nígbà náà ni ìwọ yóò sọ ní ọkàn rẹ pé, ‘Ta ló bí àwọn yìí fún mi? Mo ti ṣọ̀fọ̀ mo sì yàgàn; a sọ mi di àtìpó a sì kọ̀ mí sílẹ̀. Ta ló wo àwọn yìí dàgbà? A fi èmi nìkan sílẹ̀, ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí níbo ni wọ́n ti wá?’”
Ket damagemto iti bagim, “Siasino ti nangipasngay kadagitoy nga ubbing para kaniak? Naulilaak iti annak ken saanakon a makaanak, naipanaw kas balud ken naisina. Siasino ti nangpadakkel kadagitoy nga ubbing? Kitaem, nabatiak nga agmaymaysa; sadino ti naggapuan dagitoy?'”
22 Ohun tí Olúwa Olódùmarè wí nìyìí, “Kíyèsi i, Èmi yóò ké sí àwọn aláìkọlà, Èmi yóò gbé àsíá mi sókè sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ènìyàn; wọn yóò kó àwọn ọmọkùnrin yín wá ní apá wọn wọn yóò sì gbé àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin ní èjìká wọn.
Kastoy ti kuna ni Yahweh nga Apo, “Kitaem, Ingatokto ti imak kadagiti nasion; ingatokto ti banderak a pagilasinan dagiti tattao. Ubbaendanto nga iyeg dagiti annakmo a lallaki ken sallabayendanto dagiti annakmo a babbai.
23 Àwọn ọba ni yóò jẹ́ alágbàtọ́ baba fún ọ, àwọn ayaba wọn ni yóò sì jẹ́ ìyá-alágbàtọ́. Wọn yóò foríbalẹ̀ ní iwájú rẹ̀ pẹ̀lú ojú wọn dídàbolẹ̀; wọn yóò máa lá erùpẹ̀ lẹ́bàá ẹsẹ̀ rẹ. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa; gbogbo àwọn tí wọ́n ní ìrètí nínú mi ni a kì yóò jákulẹ̀.”
Dagitinto ari ti pannakaamam, ken dagitinto reynada ti mangaywan kenka; agkurnodanto kenka a nakadekket ti rupada iti daga ket dilpatandanto ti tapok kadagiti sakam; ket maammoamto a siak ni Yahweh; dagiti a makauray kaniak ket saanto a maibabain.”
24 Ǹjẹ́ a le gba ìkógun lọ́wọ́ jagunjagun, tàbí kí á gba ìgbèkùn lọ́wọ́ akíkanjú?
Maala kadi dagiti nasamsam manipud kadagiti mannakigubat, wenno maispal kadi dagiti balud manipud iti nauyong nga agturay?
25 Ṣùgbọ́n ohun tí Olúwa wí nìyìí: “Bẹ́ẹ̀ ni, a ó gba àwọn ìgbèkùn lọ́wọ́ àwọn jagunjagun, àti ìkógun lọ́wọ́ àwọn akíkanjú; ẹni tí ó bá ọ jà ni èmi ó bá jà, àti àwọn ọmọ rẹ ni èmi ó gbàlà.
Ngem kastoy ti kuna ni Yahweh, “Wen, maitalawto dagiti balud manipud kadagiti mannakigubat ken maisublinto dagiti sinamsam gapu ta karangetkonto ti kabusormo ken isalakanko dagiti annakmo.
26 Èmi yóò mú kí àwọn aninilára rẹ̀ jẹ ẹran-ara wọn; wọn yóò mu ẹ̀jẹ̀ ara wọn yó bí ẹni mu wáìnì. Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn yóò mọ̀ pé, Èmi, Olúwa, èmi ni Olùgbàlà rẹ, Olùdáǹdè rẹ, Alágbára kan ṣoṣo ti Jakọbu.”
Ket ipakankonto kadagiti mangparparigat kenka ti bukodda a lasag; ken mabartekdanto iti bukodda a dara, a kasla la daytoy ket arak; ket maammoanto ti amin a sangkataoan a siak, a ni Yahweh, ti Mangisalakanmo ken ti Mannubbotmo, ti Mannakabalin a Dios ni Jacob.”

< Isaiah 49 >