< Isaiah 49 >
1 Tẹ́tí sí mi, ẹ̀yin erékùṣù: gbọ́ èyí, ẹ̀yin orílẹ̀-èdè jíjìnnà réré: kí a tó bí mi Olúwa ti pè mí; láti ìgbà bíbí mi ni ó ti dá orúkọ mi.
Kuulkaat minua, te luodot, ja te kaukaiset kansat, ottakaat vaari: Herra on minun äidin kohdusta kutsunut, hän muisti minun nimeni, kuin minä vielä äitini kohdussa olin,
2 Ó ṣe ẹnu mi bí idà tí a pọ́n, ní abẹ́ òjìji ọwọ́ rẹ̀ ni ó ti pa mí mọ́: ó ṣe mí ní ọfà tí a ti dán, ó sì fi mí pamọ́ sínú àpò rẹ̀.
Ja teki minun suuni niinkuin terävän miekan, kätensä varjolla hän minua peitti; ja pani minun kiiltaväksi nuoleksi; pisti minun viineensä,
3 Ó sọ fún mi pé, “Ìránṣẹ́ mi ni ìwọ í ṣe, Israẹli nínú ẹni tí n ó ti fi ògo mi hàn.”
Ja sanoi minulle: sinä olet minun palveliani; Israel, sinussa minä kunnioitetaan.
4 Ṣùgbọ́n èmi sọ pé, “Mo ti ṣe wàhálà lórí asán; mo ti lo gbogbo ipá mi lórí asán àti ìmúlẹ̀mófo. Síbẹ̀síbẹ̀ ohun tí ó tọ́ sí mi ṣì wà lọ́wọ́ Olúwa, èrè mi sì ń bẹ pẹ̀lú Ọlọ́run mi.”
Mutta minä sanoin: hukkaan minä työtä tein, turhaan ja tyhjään minä tässä kulutin väkeni; kuitenkin on minun asiani Herran kanssa, ja minun työni on minun Jumalani kanssa.
5 Nísinsin yìí Olúwa wí pé ẹni tí ó mọ̀ mí láti inú wá láti jẹ́ ìránṣẹ́ rẹ̀ láti mú Jakọbu padà tọ̀ mí wá àti láti kó Israẹli jọ sọ́dọ̀ ara rẹ̀, nítorí pé a bọ̀wọ̀ fún mi ní ojú Olúwa Ọlọ́run mi sì ti jẹ́ agbára mi,
Ja nyt sanoo Herra, joka loi minun äidin kohdusta itsellensä palveliaksi, palauttamaan Jakobin hänelle, ettei Israel hukkuisi: sentähden olen minä kaunis Herran edessä, ja minun Jumalani on minun väkevyyteni.
6 Òun wí pé: “Ó jẹ́ ohun kékeré fún ọ láti jẹ́ ìránṣẹ́ mi láti mú ẹ̀yà Jakọbu padà bọ̀ sípò àti láti mú àwọn ti Israẹli tí mo ti pamọ́. Èmi yóò sì fi ọ́ ṣe ìmọ́lẹ̀ fún àwọn kèfèrí, kí ìwọ kí ó lè mú ìgbàlà mi wá sí òpin ilẹ̀ ayé.”
Ja hän sanoi: vähä se on, ettäs olet minun palveliani, korjaamassa Jakobin sukukuntia, ja tuomassa jälleen Israelin hajoitettuja; mutta minä panin sinun myös pakanain valkeudeksi, olemaan minun autuuteni hamaan maailman ääriin.
7 Ohun tí Olúwa wí nìyìí, Olùdáǹdè àti Ẹni Mímọ́ Israẹli— sí ẹni náà tí a gàn tí a sì kórìíra lọ́wọ́ àwọn orílẹ̀-èdè, sí ìránṣẹ́ àwọn aláṣẹ: “Àwọn ọba yóò rí ọ wọn yóò sì dìde sókè, àwọn ọmọ ọba yóò rí i wọn yóò sì wólẹ̀, nítorí Olúwa ẹni tí í ṣe olóòtítọ́, Ẹni Mímọ́ Israẹli tí ó ti yàn ọ́.”
Näin puhuu Herra Israelin lunastaja, hänen Pyhänsä, ylönkatsotuille sieluille, sille kansalle, josta me kauhistumme, sille palvelialle, joka tuimain herrain alla on: kuningasten pitää näkemän ja nouseman, päämiesten pitää rukoileman Herran tähden, joka uskollinen on, Israelin Pyhän tähden, joka sinun valinnut on.
8 Ohun tí Olúwa wí nìyìí: “Ní àkókò ojúrere mi, èmi yóò dá ọ lóhùn, àti ní ọjọ́ ìgbàlà, èmi yóò ràn ọ́ lọ́wọ́; Èmi yóò pa ọ́ mọ́, n ó sì ṣe ọ́ láti jẹ́ májẹ̀mú fún àwọn ènìyàn, láti mú ilẹ̀ padà bọ̀ sípò àti láti ṣe àtúnpín ogún rẹ̀ tí ó ti dahoro,
Näin sanoo Herra: minä olen sinun rukoukses otollisella ajalla kuullut, ja olen autuuden päivänä sinua auttanut; ja olen varjellut sinua, ja liitoksi kansain sekaan olen sinun säätänyt, korjaamaan maata, ja haaskatuita perimisiä omistamaan,
9 láti sọ fún àwọn ìgbèkùn pé, ‘Ẹ jáde wá,’ àti fún àwọn tí ó wà nínú òkùnkùn pé, ‘Ẹ gba òmìnira!’ “Wọn yóò máa jẹ ní ẹ̀bá ọ̀nà àti koríko tútù lórí òkè aláìléwéko.
Sanomaan vangituille: menkäät ulos, ja jotka pimiässä ovat: tulkaat edes, että he teiden ohessa heitänsä elättäisivät, ja saisivat joka kukkulalla elatuksensa.
10 Ebi kì yóò pa wọ́n bẹ́ẹ̀ ni òǹgbẹ kì yóò gbẹ wọ́n, tàbí kí ooru inú aṣálẹ̀ tàbí oòrùn kí ó pa wọ́n. Ẹni tí ó ṣàánú fún wọn ni yóò máa tọ́ wọn, tí yóò sì mú wọn lọ sí ibi orísun omi.
Ei heidän pidä isooman eikä janooman, ei helle eikä aurinko pidä heitä polttaman; sillä heidän armahtajansa johdattaa heitä, ja vie heitä vesilähteille.
11 Èmi yóò sọ gbogbo àwọn òkè ńlá mi di ojú ọ̀nà àti gbogbo òpópónà mi ni a ó gbé sókè.
Ja minä panen kaikki vuoreni tieksi, ja minun polkuni pitää korotettaman.
12 Kíyèsi i, wọn yóò wá láti ọ̀nà jíjìn àwọn díẹ̀ láti àríwá àti àwọn díẹ̀ láti ìwọ̀-oòrùn, àwọn díẹ̀ láti ẹkùn Siene.”
Katso, nämät tulevat kaukaa, ja katso, nämät pohjan puolesta, nämät etelän puolesta, ja muut Sinimin maalta.
13 Ẹ hó fún ayọ̀, ẹyin ọ̀run; yọ̀, ìwọ ilẹ̀ ayé; bú sórin, ẹ̀yin òkè ńlá! Nítorí Olúwa tu àwọn ènìyàn rẹ̀ nínú yóò sì ṣàánú fún àwọn ẹni tí a ń pọ́n lójú.
Iloitkaat te taivaat, riemuitse sinä maa, kiittäkäät te vuoret ihastuksella; sillä Herra on kansaansa lohduttanut, ja on raadollisiansa armahtanut.
14 Ṣùgbọ́n Sioni sọ pé, “Olúwa ti kọ̀ mí sílẹ̀, Olúwa ti gbàgbé è mi.”
Mutta Zion sanoo: Herra hylkäsi minun, Herra unohti minun.
15 “Ǹjẹ́ abiyamọ ha le gbàgbé ọmọ ọmú rẹ̀ kí ó má sì ṣàánú fún ọmọ rẹ̀ tí ó ti bí? Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òun le gbàgbé, Èmi kì yóò gbàgbé rẹ!
Unohtaako vaimo lapsukaisensa, niin ettei hän armahda kohtunsa poikaa? ja vaikka hän unohtais, niin en minä kuitenkaan sinua unohda.
16 Kíyèsi i, mo ti kọ ọ́ sí àtẹ́lẹwọ́ mi ògiri rẹ wà níwájú mi nígbà gbogbo.
Katso, käsiini olen minä sinun pyhältänyt; sinun muuris ovat alati minun silmäini edessä.
17 Àwọn ọmọ rẹ ti kánjú padà, àti àwọn tí ó sọ ọ́ dahoro ti padà lẹ́yìn rẹ.
Sinun rakentajas rientävät; mutta sinun kukistajas ja hävittäjäs pitää pakeneman sinusta pois.
18 Gbójú rẹ sókè kí o sì wò yíká; gbogbo àwọn ọmọkùnrin rẹ kórajọ wọ́n sì wá sọ́dọ̀ rẹ. Níwọ́n ìgbà tí mo bá wà láààyè,” ni Olúwa wí, “Ìwọ yóò wọ gbogbo wọ́n gẹ́gẹ́ bí ohun ọ̀ṣọ́; ìwọ yóò wọ̀ wọ́n gẹ́gẹ́ bí ìyàwó.
Nosta silmäs ympäri ja katso, kaikki nämät kootut tulevat sinun tykös. Niin totta kuin minä elän, sanoo Herra, sinun pitää kaikilla näillä niinkuin kaunistuksella itses puettaman, ja sinä käärit ne ympärilles niinkuin morsian;
19 “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a tí run ọ́, a sì sọ ọ́ di ahoro tí gbogbo ilẹ̀ rẹ sì di ìparun, ní ìsinsin yìí, ìwọ yóò kéré jù fún àwọn ènìyàn rẹ, bẹ́ẹ̀ ni àwọn tí ó jẹ ọ́ run ni yóò wà láti ọ̀nà jíjìn réré.
Sillä sinun autio, hävitetty ja turmeltu maas pitää silloin ahdas oleman asuakses, kuin sinun raatelias sinusta kauvas pakenevat,
20 Àwọn ọmọ tí a bí ní àkókò ọ̀fọ̀ rẹ yóò sọ ní etígbọ̀ọ́ rẹ, ‘Ibi yìí ti kéré jù fún wa; ẹ fún wa láyè sí i tí a ó máa gbé.’
Niin että sinun hedelmättömyytes lapset pitää vielä korviis sanoman: ahdas on minulla sia, istu puolees, että minäkin asuisin sinun tykönäs.
21 Nígbà náà ni ìwọ yóò sọ ní ọkàn rẹ pé, ‘Ta ló bí àwọn yìí fún mi? Mo ti ṣọ̀fọ̀ mo sì yàgàn; a sọ mi di àtìpó a sì kọ̀ mí sílẹ̀. Ta ló wo àwọn yìí dàgbà? A fi èmi nìkan sílẹ̀, ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí níbo ni wọ́n ti wá?’”
Mutta sinä olet sanova sydämessäs: kuka nämät minulle synnytti? sillä minä olen hedelmätöin, yksinäinen, ajettu pois ja syösty ulos. Kuka nämät on minulle kasvattanut? katso, minä olen yksinäni jätetty, kussa nämät silloin olivat?
22 Ohun tí Olúwa Olódùmarè wí nìyìí, “Kíyèsi i, Èmi yóò ké sí àwọn aláìkọlà, Èmi yóò gbé àsíá mi sókè sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ènìyàn; wọn yóò kó àwọn ọmọkùnrin yín wá ní apá wọn wọn yóò sì gbé àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin ní èjìká wọn.
Näin sanoo Herra, Herra: katso, minä nostan käteni pakanain puoleen, ja korotan lippuni kansain puoleen, niin he tuovat edes helmassansa sinun poikias, ja sinun tyttäriäs hartioilla kannetaan.
23 Àwọn ọba ni yóò jẹ́ alágbàtọ́ baba fún ọ, àwọn ayaba wọn ni yóò sì jẹ́ ìyá-alágbàtọ́. Wọn yóò foríbalẹ̀ ní iwájú rẹ̀ pẹ̀lú ojú wọn dídàbolẹ̀; wọn yóò máa lá erùpẹ̀ lẹ́bàá ẹsẹ̀ rẹ. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa; gbogbo àwọn tí wọ́n ní ìrètí nínú mi ni a kì yóò jákulẹ̀.”
Ja kuninkaat pitää oleman sinun holhojas, ja heidän kuningattarensa sinun imettäjäs, heidän pitää lankeeman kasvoillensa maahan sinun edessäs, ja nuoleskelemaan sinun jalkais tomua. Silloin sinä tiedät, että minä olen Herra, ja ettei kenkään tule häpiään, joka minua toivoo.
24 Ǹjẹ́ a le gba ìkógun lọ́wọ́ jagunjagun, tàbí kí á gba ìgbèkùn lọ́wọ́ akíkanjú?
Otetaanko saalis väkevältä pois? taitaako joku päästää hurskaan vangit?
25 Ṣùgbọ́n ohun tí Olúwa wí nìyìí: “Bẹ́ẹ̀ ni, a ó gba àwọn ìgbèkùn lọ́wọ́ àwọn jagunjagun, àti ìkógun lọ́wọ́ àwọn akíkanjú; ẹni tí ó bá ọ jà ni èmi ó bá jà, àti àwọn ọmọ rẹ ni èmi ó gbàlà.
Sillä näin sanoo Herra: nyt pitää vangit väkevältä otettaman pois, ja tuimain saalis irralle pääsemän; ja minä tahdon riidellä sinun riitaveljeis kanssa, ja varjella sinun lapsias.
26 Èmi yóò mú kí àwọn aninilára rẹ̀ jẹ ẹran-ara wọn; wọn yóò mu ẹ̀jẹ̀ ara wọn yó bí ẹni mu wáìnì. Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn yóò mọ̀ pé, Èmi, Olúwa, èmi ni Olùgbàlà rẹ, Olùdáǹdè rẹ, Alágbára kan ṣoṣo ti Jakọbu.”
Ja minä annan sinun hävittäjäs syödä omaa lihaansa, ja heidän pitää juopuman omasta verestänsä, niinkuin makiasta viinasta; ja kaikki liha pitää tietämän, että minä olen Herra, sinun auttajas ja sinun lunastajas, Jakobin väkevä.