< Isaiah 49 >
1 Tẹ́tí sí mi, ẹ̀yin erékùṣù: gbọ́ èyí, ẹ̀yin orílẹ̀-èdè jíjìnnà réré: kí a tó bí mi Olúwa ti pè mí; láti ìgbà bíbí mi ni ó ti dá orúkọ mi.
Sanglak rhoek loh kamah taengkah he hnatun uh saeh lamtah khohla lamkah namtu rhoek loh hnatung uh saeh. BOEIPA loh kai he bungko khuiah ng'khue coeng tih a nu bung khuiah ni ka ming a sum coeng.
2 Ó ṣe ẹnu mi bí idà tí a pọ́n, ní abẹ́ òjìji ọwọ́ rẹ̀ ni ó ti pa mí mọ́: ó ṣe mí ní ọfà tí a ti dán, ó sì fi mí pamọ́ sínú àpò rẹ̀.
Ka ka he cunghang haat bangla a khueh tih a kut dongkah hlipkhup ah kai n'thuh. Kai he thaltang la n'khueh tih amah kah liva dongah a meet tangtae la kai n'thuh.
3 Ó sọ fún mi pé, “Ìránṣẹ́ mi ni ìwọ í ṣe, Israẹli nínú ẹni tí n ó ti fi ògo mi hàn.”
Kai taengah tah, “Kamah kah sal tah Israel nang, namah dongah ni ka ko ka hang eh.
4 Ṣùgbọ́n èmi sọ pé, “Mo ti ṣe wàhálà lórí asán; mo ti lo gbogbo ipá mi lórí asán àti ìmúlẹ̀mófo. Síbẹ̀síbẹ̀ ohun tí ó tọ́ sí mi ṣì wà lọ́wọ́ Olúwa, èrè mi sì ń bẹ pẹ̀lú Ọlọ́run mi.”
Tedae kai loh a poeyoek la ka ti coeng. A hinghong la ka kohnue tih ka thadueng khaw a honghi coeng. Ka tiktamnah he BOEIPA taengah, ka thaphu te ka Pathen taengah ka bawt.
5 Nísinsin yìí Olúwa wí pé ẹni tí ó mọ̀ mí láti inú wá láti jẹ́ ìránṣẹ́ rẹ̀ láti mú Jakọbu padà tọ̀ mí wá àti láti kó Israẹli jọ sọ́dọ̀ ara rẹ̀, nítorí pé a bọ̀wọ̀ fún mi ní ojú Olúwa Ọlọ́run mi sì ti jẹ́ agbára mi,
Bungko khui lamloh amah kah sal la kai aka hlinsai BOEIPA loh Jakob te amah taengla mael sak ham neh Israel te amah taengla coi ham te a thui coeng. Te dongah BOEIPA mikhmuh ah ka thangpom uh tih ka Pathen tah ka sarhi la om.
6 Òun wí pé: “Ó jẹ́ ohun kékeré fún ọ láti jẹ́ ìránṣẹ́ mi láti mú ẹ̀yà Jakọbu padà bọ̀ sípò àti láti mú àwọn ti Israẹli tí mo ti pamọ́. Èmi yóò sì fi ọ́ ṣe ìmọ́lẹ̀ fún àwọn kèfèrí, kí ìwọ kí ó lè mú ìgbàlà mi wá sí òpin ilẹ̀ ayé.”
Jakob koca te thoh ham neh Israel a kueinah tih mael puei ham khaw kamah kah sal la na om te rhaemaih. Nang tah diklai khobawt duela kamah kah khangnah a om sak ham neh namtom rhoek kah vangnah la kang khueh ni,” a ti.
7 Ohun tí Olúwa wí nìyìí, Olùdáǹdè àti Ẹni Mímọ́ Israẹli— sí ẹni náà tí a gàn tí a sì kórìíra lọ́wọ́ àwọn orílẹ̀-èdè, sí ìránṣẹ́ àwọn aláṣẹ: “Àwọn ọba yóò rí ọ wọn yóò sì dìde sókè, àwọn ọmọ ọba yóò rí i wọn yóò sì wólẹ̀, nítorí Olúwa ẹni tí í ṣe olóòtítọ́, Ẹni Mímọ́ Israẹli tí ó ti yàn ọ́.”
Israel aka tlan tih anih kah a cim Yahovah loh hinglu kah a hnaep taengah, namtom kah a tuei taengah, aka taemrhai rhoek kah sal taengah, “Manghai rhoek loh a hmuh uh vaengah mangpa rhoek khaw thoo uh vetih a bawk uh bitni. Israel kah a cim BOEIPA tah a uepom dongah ni nang n'coelh.
8 Ohun tí Olúwa wí nìyìí: “Ní àkókò ojúrere mi, èmi yóò dá ọ lóhùn, àti ní ọjọ́ ìgbàlà, èmi yóò ràn ọ́ lọ́wọ́; Èmi yóò pa ọ́ mọ́, n ó sì ṣe ọ́ láti jẹ́ májẹ̀mú fún àwọn ènìyàn, láti mú ilẹ̀ padà bọ̀ sípò àti láti ṣe àtúnpín ogún rẹ̀ tí ó ti dahoro,
BOEIPA loh, “Kolonah tue vaengah nang kan doo tih khangnah khohnin ah nang kan bom. Nang te kang kueinah vetih aka pong tangtae khohmuen aka thoh ham neh rho aka pang pilnam patai la nang te kang khueh ni.
9 láti sọ fún àwọn ìgbèkùn pé, ‘Ẹ jáde wá,’ àti fún àwọn tí ó wà nínú òkùnkùn pé, ‘Ẹ gba òmìnira!’ “Wọn yóò máa jẹ ní ẹ̀bá ọ̀nà àti koríko tútù lórí òkè aláìléwéko.
Amih hmaisuep ah a khih rhoek te, 'Ha pawk uh lamtah ha mop uh,’ ti nah. Longpuei ah luem uh vetih caphoei cuk boeih te amih kah rhamtlim la poeh ni.
10 Ebi kì yóò pa wọ́n bẹ́ẹ̀ ni òǹgbẹ kì yóò gbẹ wọ́n, tàbí kí ooru inú aṣálẹ̀ tàbí oòrùn kí ó pa wọ́n. Ẹni tí ó ṣàánú fún wọn ni yóò máa tọ́ wọn, tí yóò sì mú wọn lọ sí ibi orísun omi.
Lamlum uh pawt vetih halthi uh mahpawh. Amih te unghae neh khomik loh do mahpawh. Amih aka haidam loh amih te a hmaithawn vetih tuisih tui taengla a khool ni.
11 Èmi yóò sọ gbogbo àwọn òkè ńlá mi di ojú ọ̀nà àti gbogbo òpópónà mi ni a ó gbé sókè.
Kamah kah tlang boeih te long la ka khueh vetih ka longpuei te ka pomsang ni.
12 Kíyèsi i, wọn yóò wá láti ọ̀nà jíjìn àwọn díẹ̀ láti àríwá àti àwọn díẹ̀ láti ìwọ̀-oòrùn, àwọn díẹ̀ láti ẹkùn Siene.”
Khohla lamkah rhoek te ha pawk uh ni ke. Tlangpuei lamkah rhoek neh tuitun lamkah ke khaw, Sinim kho lamkah rhoek khaw.
13 Ẹ hó fún ayọ̀, ẹyin ọ̀run; yọ̀, ìwọ ilẹ̀ ayé; bú sórin, ẹ̀yin òkè ńlá! Nítorí Olúwa tu àwọn ènìyàn rẹ̀ nínú yóò sì ṣàánú fún àwọn ẹni tí a ń pọ́n lójú.
Vaan rhoek loh tamhoe uh lamtah diklai khaw omngaih saeh. Tlang rhoek khaw tamlung neh rhong la rhong uh saeh. BOEIPA loh a pilnam te a hloep tih mangdaeng rhoek te a haidam coeng.
14 Ṣùgbọ́n Sioni sọ pé, “Olúwa ti kọ̀ mí sílẹ̀, Olúwa ti gbàgbé è mi.”
Zion loh, “Yahovah loh kai n'hnoo tih ka Boeipa loh kai n'hnilh coeng,” a ti.
15 “Ǹjẹ́ abiyamọ ha le gbàgbé ọmọ ọmú rẹ̀ kí ó má sì ṣàánú fún ọmọ rẹ̀ tí ó ti bí? Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òun le gbàgbé, Èmi kì yóò gbàgbé rẹ!
Huta loh a ca cahni te a hnilh a? A bungko khuikah a ca te a haidam ta. Te rhoek loh hnilh uh mai cakhaw kai long he nang kan hnilh mahpawh.
16 Kíyèsi i, mo ti kọ ọ́ sí àtẹ́lẹwọ́ mi ògiri rẹ wà níwájú mi nígbà gbogbo.
Kutpha dongah nang kan tarhit coeng tih na vongtung khaw kamah hmaiah om yoeyah coeng he.
17 Àwọn ọmọ rẹ ti kánjú padà, àti àwọn tí ó sọ ọ́ dahoro ti padà lẹ́yìn rẹ.
Na ca rhoek loh namah n'koengloeng uh paitok tih namah lamkah aka thoeng rhoek loh nang n'khah uh.
18 Gbójú rẹ sókè kí o sì wò yíká; gbogbo àwọn ọmọkùnrin rẹ kórajọ wọ́n sì wá sọ́dọ̀ rẹ. Níwọ́n ìgbà tí mo bá wà láààyè,” ni Olúwa wí, “Ìwọ yóò wọ gbogbo wọ́n gẹ́gẹ́ bí ohun ọ̀ṣọ́; ìwọ yóò wọ̀ wọ́n gẹ́gẹ́ bí ìyàwó.
Na mik te huel kilkoel lamtah hmu van lah. Amih te boeih coi uh thae tih nang taengla ha pawk uh coeng. Kai, hingnah BOEIPA kah olphong ni. Amih boeih te kamrhui bangla na vah vetih na langa bangla na hlaengtang ni.
19 “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a tí run ọ́, a sì sọ ọ́ di ahoro tí gbogbo ilẹ̀ rẹ sì di ìparun, ní ìsinsin yìí, ìwọ yóò kéré jù fún àwọn ènìyàn rẹ, bẹ́ẹ̀ ni àwọn tí ó jẹ ọ́ run ni yóò wà láti ọ̀nà jíjìn réré.
Namah kah imrhong neh na ponah kho na pong sak. Khosa taeng lamloh n'daengdaeh pawn vetih nang aka yoop rhoek khaw lakhla uh bitni.
20 Àwọn ọmọ tí a bí ní àkókò ọ̀fọ̀ rẹ yóò sọ ní etígbọ̀ọ́ rẹ, ‘Ibi yìí ti kéré jù fún wa; ẹ fún wa láyè sí i tí a ó máa gbé.’
Nang hlangmoeng ca rhoek na hna khuiah, “Kai ham a hmuen caek coeng tih kamah ham han thoeih lamtah kho ka sa eh?,” a ti uh ni.
21 Nígbà náà ni ìwọ yóò sọ ní ọkàn rẹ pé, ‘Ta ló bí àwọn yìí fún mi? Mo ti ṣọ̀fọ̀ mo sì yàgàn; a sọ mi di àtìpó a sì kọ̀ mí sílẹ̀. Ta ló wo àwọn yìí dàgbà? A fi èmi nìkan sílẹ̀, ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí níbo ni wọ́n ti wá?’”
Te vaengah na thinko nen tah, “Kai aka cun te unim? Kai dueidah laemhong neh pumhong he a hliphen tih n'rhoe sut. Te dongah te rhoek aka puel sak te unim? Kai kamah bueng ka sueng vaengah melae amih eh?,” na ti ni.
22 Ohun tí Olúwa Olódùmarè wí nìyìí, “Kíyèsi i, Èmi yóò ké sí àwọn aláìkọlà, Èmi yóò gbé àsíá mi sókè sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ènìyàn; wọn yóò kó àwọn ọmọkùnrin yín wá ní apá wọn wọn yóò sì gbé àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin ní èjìká wọn.
Ka Boeipa Yahovah loh he ni a thui. Namtom taengah ka kut ka thueng vetih pilnam hamla ka rholik ka thoh pah ni. Te vaengah tah na ca rhoek te poehla neh ham pawk puei uh vetih na tanu rhoek te laengpang dongah a poeh uh ni.
23 Àwọn ọba ni yóò jẹ́ alágbàtọ́ baba fún ọ, àwọn ayaba wọn ni yóò sì jẹ́ ìyá-alágbàtọ́. Wọn yóò foríbalẹ̀ ní iwájú rẹ̀ pẹ̀lú ojú wọn dídàbolẹ̀; wọn yóò máa lá erùpẹ̀ lẹ́bàá ẹsẹ̀ rẹ. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa; gbogbo àwọn tí wọ́n ní ìrètí nínú mi ni a kì yóò jákulẹ̀.”
Manghai rhoek te nang aka kaem la, a boeinu rhoek khaw nang aka khut la om uh ni. Nang taengah a talung neh diklai la bakop uh vetih na kho dongkah laipi a laem uh ni. Te vaengah kai Yahovah neh kai aka lamtawn rhoek loh yah a poh pawt te na ming uh ni.
24 Ǹjẹ́ a le gba ìkógun lọ́wọ́ jagunjagun, tàbí kí á gba ìgbèkùn lọ́wọ́ akíkanjú?
Hlangrhalh kah hnorhawt te a loh vetih aka dueng kah tamna te a loeih khaming a?
25 Ṣùgbọ́n ohun tí Olúwa wí nìyìí: “Bẹ́ẹ̀ ni, a ó gba àwọn ìgbèkùn lọ́wọ́ àwọn jagunjagun, àti ìkógun lọ́wọ́ àwọn akíkanjú; ẹni tí ó bá ọ jà ni èmi ó bá jà, àti àwọn ọmọ rẹ ni èmi ó gbàlà.
Tedae BOEIPA loh, “Hlangrhalh tamna khaw a loh pah vetih hlanghaeng a dang khaw a khong pah ni. Na lungawn taengah kai loh kang rhoe vetih na ca rhoek te kamah loh ka khang ni.
26 Èmi yóò mú kí àwọn aninilára rẹ̀ jẹ ẹran-ara wọn; wọn yóò mu ẹ̀jẹ̀ ara wọn yó bí ẹni mu wáìnì. Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn yóò mọ̀ pé, Èmi, Olúwa, èmi ni Olùgbàlà rẹ, Olùdáǹdè rẹ, Alágbára kan ṣoṣo ti Jakọbu.”
Nang aka vuelvaek rhoek te a saa ka cah vetih a thii te thingtui bangla rhuihmil uh ni. Te vaengah pumsa boeih loh kai tah nang kah khangkung Yahovah neh nang aka tlan Jakob kah samrhang la a ming uh ni.