< Isaiah 48 >

1 “Tẹ́tí sí èyí, ìwọ ilé e Jakọbu, ìwọ tí a ń pè pẹ̀lú orúkọ Israẹli tí o sì wá láti ẹ̀ka Juda, ìwọ tí ò ń búra ní orúkọ Olúwa tí o sì ń pe Ọlọ́run Israẹli ṣùgbọ́n kì í ṣe ní òtítọ́ àti òdodo,
“Ouça isto, casa de Jacob, vocês que são chamados pelo nome de Israel, e saíram das águas de Judá. Você jura pelo nome de Yahweh, e fazer menção ao Deus de Israel, mas não em verdade, nem em retidão...
2 ìwọ tí ò ń pe ara rẹ ní ọmọ ìlú mímọ́ n nì tí o sì gbẹ́kẹ̀lé Ọlọ́run Israẹli— Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
pois eles se dizem cidadãos da cidade santa, e contar com o Deus de Israel; Yahweh dos Exércitos é seu nome.
3 Èmi sọ àsọtẹ́lẹ̀ àwọn nǹkan ti tẹ́lẹ̀ lọ́jọ́ tó ti pẹ́, ẹnu mi ló ti kéde wọn, mo sì sọ wọ́n di mí mọ̀; lẹ́yìn náà lójijì mo gbé ìgbésẹ̀, wọ́n sì wá sí ìmúṣẹ.
Declarei as antigas coisas de outrora. Sim, eles saíram da minha boca, e eu os revelei. Eu as fiz de repente, e elas aconteceram.
4 Nítorí mo mọ bí ẹ ti jẹ́ olórí kunkun tó; àwọn iṣan ọrùn yín sì jẹ́ irin; bẹ́ẹ̀ ni iwájú yín idẹ ni.
Porque eu sabia que você é obstinado, e seu pescoço é um tendão de ferro, e sua testa de bronze;
5 Nítorí náà mo ti sọ nǹkan wọ̀nyí fún ọ ní ọjọ́ tí ó ti pẹ́; kí wọn ó tó ṣẹlẹ̀ mo ti kéde wọn fún un yín tó bẹ́ẹ̀ tí ìwọ kò fi lè sọ pé, ‘Àwọn ère mi ló ṣe wọ́n; àwọn ère igi àti òrìṣà irin ló fọwọ́sí i.’
therefore Eu o declarei de outrora; antes que isso acontecesse, eu mostrei a você; para não dizer: “Meu ídolo as fez”. Minha imagem gravada e minha imagem derretida os comandou”.
6 Ìwọ ti gbọ́ àwọn nǹkan wọ̀nyí; wo gbogbo wọn. Ǹjẹ́ o kò nígbà wọ́n bí? “Láti ìsinsin yìí lọ, Èmi yóò máa sọ fún ọ nípa nǹkan tuntun, àwọn nǹkan tí ó fi ara sin tí ìwọ kò mọ̀.
Você já ouviu falar. Agora veja tudo isso. E você, não vai declarar isso? “Eu lhes mostrei coisas novas a partir deste momento, mesmo coisas escondidas, que você não conhece.
7 A dá wọn ní àkókò yìí kì í ṣe láti ìgbà pípẹ́ ìwọ kò tí ì gbọ́ nípa wọn títí di òní. Nítorí náà, ìwọ kò lè sọ pé, ‘Bẹ́ẹ̀ ni, mo mọ̀ nípa wọn.’
Eles são criados agora, e não são de antigamente. Antes de hoje, você não os ouviu, para não dizer: “Eis que eu os conhecia”.
8 Ìwọ a ha ti gbọ́ tàbí ó ti yé ọ bí láti ìgbà àtijọ́ etí kò ti di yíyà. Ǹjẹ́ mo mọ̀ bí o ti jẹ́ alárékérekè tó; a ń pè ọ́ ní ọlọ̀tẹ̀ láti ìgbà ìbí rẹ.
Sim, você não ouviu. Sim, você não sabia. Sim, de outrora sua orelha não foi aberta, pois eu sabia que você lidava de forma muito traiçoeira, e foram chamados de transgressores do útero.
9 Nítorí orúkọ ara mi, mo dáwọ́ ìbínú mi dúró; nítorí ìyìn ara mi, mo fà á sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ rẹ, kí a má ba à ké ọ kúrò.
Por meu nome, vou adiar minha raiva, e por meus elogios, eu o retenho para vocês para que eu não o interrompa.
10 Wò ó, èmi ti tún ọ ṣe, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé kì í ṣe bí i fàdákà; Èmi ti dán ọ wò nínú ìléru ìpọ́njú.
Eis que eu vos refinei, mas não como prata. Eu o escolhi no forno da aflição.
11 Nítorí orúkọ mi, nítorí orúkọ mi, mo ṣe èyí. Báwo ni mo ṣe lè jẹ́ kí a ba orúkọ mi jẹ́. Èmi kì yóò fi ògo mi fún ẹlòmíràn.
Para meu próprio bem, por meu próprio bem, eu o farei; como meu nome seria profanado? Eu não darei minha glória a outro.
12 “Tẹ́tí sí mi, ìwọ Jakọbu Israẹli ẹni tí mo pè. Èmi ni ẹni náà; Èmi ni ẹni àkọ́kọ́ àti ẹni ìgbẹ̀yìn.
“Escuta-me, ó Jacob, e Israel, meu chamado: Eu sou ele. Eu sou o primeiro. Eu também sou o último.
13 Ọwọ́ mi pàápàá ni ó fi àwọn ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀, àti ọwọ́ ọ̀tún mi ni ó tẹ àwọn ọ̀run; nígbà tí mo pè wọ́n, gbogbo wọn dìde sókè papọ̀.
Sim, minha mão lançou os alicerces da terra, e minha mão direita se espalhou pelos céus. quando eu os chamo, eles se levantam juntos.
14 “Gbogbo yín, ẹ péjọ kí ẹ sì gbọ́. Ta nínú wọn ni ó ti sọ nǹkan wọ̀nyí. Olúwa ti fẹ́ ẹ, yóò sì ṣe ìfẹ́ rẹ̀ ní Babiloni, apá rẹ̀ ni yóò sì wà ní ará àwọn ará Kaldea.
“Reúnam-se, todos vocês, e ouçam! Quem entre eles declarou estas coisas? Aquele que Yahweh ama fará o que gosta para a Babilônia, e seu braço será contra os caldeus.
15 Èmi, àní Èmi ló ti sọ̀rọ̀; bẹ́ẹ̀ ni, mo ti pè é. Èmi yóò mú un wá, òun yóò sì ṣe àṣeyọrí nínú ìrìnàjò rẹ̀.
Eu, até mesmo eu, já falei. Sim, eu o chamei. Eu o trouxe e ele deve fazer seu caminho prosperar.
16 “Ẹ súnmọ́ ọ̀dọ̀ mi kí ẹ sì dẹtí sí èyí: “Láti ìgbà ìkéde àkọ́kọ́ èmi kò sọ̀rọ̀ ní ìkọ̀kọ̀; ní àsìkò tí ó sì ṣẹlẹ̀, Èmi wà níbẹ̀.” Àti ní àkókò yìí, Olúwa Olódùmarè ni ó ti rán mi, pẹ̀lú ẹ̀mí rẹ̀.
“Aproxime-se de mim e ouça isto: “Desde o início, não tenho falado em segredo; desde o momento em que isso aconteceu, eu estava lá”. Agora o Senhor Yahweh me enviou com seu Espírito.
17 Èyí ni ohun tí Olúwa wí, Olùdáǹdè rẹ, Ẹni Mímọ́ Israẹli: “Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ, tí ó kọ́ ọ ní ohun tí ó dára fún ọ, tí ó tọ́ ọ ṣọ́nà tí ó yẹ kí o máa rìn.
Yahweh, seu Redentor, o Santo de Israel, diz: “Eu sou Yahweh, seu Deus”, que lhe ensina a lucrar, que o conduz pelo caminho que você deve seguir.
18 Bí ó bá ṣe pé ìwọ bá ti tẹ́tí sílẹ̀ sí àṣẹ mi, àlàáfíà rẹ kì bá ti dàbí ì ti odò, àti òdodo rẹ bí ìgbì Òkun.
Oh, que vocês tinham ouvido meus mandamentos! Então sua paz teria sido como um rio e sua retidão como as ondas do mar.
19 Àwọn ọmọ rẹ ìbá ti dàbí iyanrìn, àwọn ọmọ yín bí i hóró ọkà tí a kò lè kà tán; orúkọ wọn ni a kì yóò ké kúrò tàbí kí a pa wọ́n run níwájú mi.”
Sua descendência também teria sido como a areia e os descendentes de seu corpo como seus grãos. Seu nome não seria cortado nem destruído de antes de mim”.
20 Fi Babeli sílẹ̀, sá fún àwọn ará Babeli, ṣe ìfilọ̀ èyí pẹ̀lú ariwo ayọ̀ kí o sì kéde rẹ̀. Rán an jáde lọ sí òpin ilẹ̀ ayé; wí pé, “Olúwa ti dá ìránṣẹ́ rẹ̀ Jakọbu nídè.”
Deixe a Babilônia! Fugir dos caldeus! Com uma voz de canto, anunciem isto, dizer isso até o fim do mundo; dizem: “Javé redimiu seu servo Jacob!”
21 Òrùngbẹ kò gbẹ wọ́n nígbà tí ó kó wọn kọjá nínú aginjù; ó jẹ́ kí omi ó sàn fún wọn láti inú àpáta; ó fọ́ àpáta omi sì tú jáde.
Eles não tiveram sede quando ele os conduziu através dos desertos. Ele fez com que as águas saíssem da rocha para eles. Ele também dividiu a rocha e as águas jorraram para fora.
22 “Kò sí àlàáfíà,” ni Olúwa wí, “Fún àwọn ìkà.”
“Não há paz”, diz Yahweh, “para os ímpios”.

< Isaiah 48 >