< Isaiah 48 >

1 “Tẹ́tí sí èyí, ìwọ ilé e Jakọbu, ìwọ tí a ń pè pẹ̀lú orúkọ Israẹli tí o sì wá láti ẹ̀ka Juda, ìwọ tí ò ń búra ní orúkọ Olúwa tí o sì ń pe Ọlọ́run Israẹli ṣùgbọ́n kì í ṣe ní òtítọ́ àti òdodo,
Słuchajcie tego, domu Jakuba, którzy jesteście nazywani imieniem Izraela i pochodzicie z wód Judy, którzy przysięgacie na imię PANA i wspominacie Boga Izraela, ale nie w prawdzie ani w sprawiedliwości;
2 ìwọ tí ò ń pe ara rẹ ní ọmọ ìlú mímọ́ n nì tí o sì gbẹ́kẹ̀lé Ọlọ́run Israẹli— Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
Nazywacie się od miasta świętego i opieracie się na Bogu Izraela, jego imię to PAN zastępów.
3 Èmi sọ àsọtẹ́lẹ̀ àwọn nǹkan ti tẹ́lẹ̀ lọ́jọ́ tó ti pẹ́, ẹnu mi ló ti kéde wọn, mo sì sọ wọ́n di mí mọ̀; lẹ́yìn náà lójijì mo gbé ìgbésẹ̀, wọ́n sì wá sí ìmúṣẹ.
Rzeczy przeszłe zapowiadałem od dawna, z moich ust wyszły i ogłaszałem je, wykonywałem je od razu i nastąpiły.
4 Nítorí mo mọ bí ẹ ti jẹ́ olórí kunkun tó; àwọn iṣan ọrùn yín sì jẹ́ irin; bẹ́ẹ̀ ni iwájú yín idẹ ni.
Ponieważ wiedziałem, że jesteś uparty i że twoja szyja jest ścięgnem żelaznym, a twoje czoło – miedziane;
5 Nítorí náà mo ti sọ nǹkan wọ̀nyí fún ọ ní ọjọ́ tí ó ti pẹ́; kí wọn ó tó ṣẹlẹ̀ mo ti kéde wọn fún un yín tó bẹ́ẹ̀ tí ìwọ kò fi lè sọ pé, ‘Àwọn ère mi ló ṣe wọ́n; àwọn ère igi àti òrìṣà irin ló fọwọ́sí i.’
Oznajmiałem ci od dawna, ogłosiłem to, zanim nastąpiło, abyś nie powiedział: Mój bożek to uczynił, mój rzeźbiony posąg i mój odlewany posąg to nakazał.
6 Ìwọ ti gbọ́ àwọn nǹkan wọ̀nyí; wo gbogbo wọn. Ǹjẹ́ o kò nígbà wọ́n bí? “Láti ìsinsin yìí lọ, Èmi yóò máa sọ fún ọ nípa nǹkan tuntun, àwọn nǹkan tí ó fi ara sin tí ìwọ kò mọ̀.
Słyszałeś o tym, spójrz na to wszystko. Czy wy tego nie opowiecie? Teraz już ogłaszam nowe i tajemne rzeczy, o których nie wiedziałeś.
7 A dá wọn ní àkókò yìí kì í ṣe láti ìgbà pípẹ́ ìwọ kò tí ì gbọ́ nípa wọn títí di òní. Nítorí náà, ìwọ kò lè sọ pé, ‘Bẹ́ẹ̀ ni, mo mọ̀ nípa wọn.’
Teraz są stworzone, a nie od dawna, [rzeczy], o których przed tym dniem nic nie słyszałeś, byś nie powiedział: Oto wiedziałem o tym.
8 Ìwọ a ha ti gbọ́ tàbí ó ti yé ọ bí láti ìgbà àtijọ́ etí kò ti di yíyà. Ǹjẹ́ mo mọ̀ bí o ti jẹ́ alárékérekè tó; a ń pè ọ́ ní ọlọ̀tẹ̀ láti ìgbà ìbí rẹ.
Ani nie słyszałeś, ani nie wiedziałeś, ani twoje ucho nie było otwarte w tym czasie, bo wiedziałem, że postąpisz przewrotnie i że nazwano cię przestępcą od łona matki.
9 Nítorí orúkọ ara mi, mo dáwọ́ ìbínú mi dúró; nítorí ìyìn ara mi, mo fà á sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ rẹ, kí a má ba à ké ọ kúrò.
Ze względu na moje imię powściągam swój gniew i ze względu na moją chwałę powstrzymam swój gniew na ciebie, aby cię nie wytępić.
10 Wò ó, èmi ti tún ọ ṣe, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé kì í ṣe bí i fàdákà; Èmi ti dán ọ wò nínú ìléru ìpọ́njú.
Oto wytapiałem cię, ale nie jak srebro; wybrałem cię w piecu utrapienia.
11 Nítorí orúkọ mi, nítorí orúkọ mi, mo ṣe èyí. Báwo ni mo ṣe lè jẹ́ kí a ba orúkọ mi jẹ́. Èmi kì yóò fi ògo mi fún ẹlòmíràn.
Ze względu na siebie, na siebie samego, to uczynię, bo jakże miałoby być splugawione [moje imię]? Przecież mojej chwały nie oddam innemu.
12 “Tẹ́tí sí mi, ìwọ Jakọbu Israẹli ẹni tí mo pè. Èmi ni ẹni náà; Èmi ni ẹni àkọ́kọ́ àti ẹni ìgbẹ̀yìn.
Słuchaj mnie, Jakubie i Izraelu, mój wezwany: Ja jestem, ja jestem pierwszy i ja jestem ostatni.
13 Ọwọ́ mi pàápàá ni ó fi àwọn ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀, àti ọwọ́ ọ̀tún mi ni ó tẹ àwọn ọ̀run; nígbà tí mo pè wọ́n, gbogbo wọn dìde sókè papọ̀.
To moja ręka założyła ziemię i moja prawica zmierzyła niebiosa. Gdy na nie zawołam, zaraz staną.
14 “Gbogbo yín, ẹ péjọ kí ẹ sì gbọ́. Ta nínú wọn ni ó ti sọ nǹkan wọ̀nyí. Olúwa ti fẹ́ ẹ, yóò sì ṣe ìfẹ́ rẹ̀ ní Babiloni, apá rẹ̀ ni yóò sì wà ní ará àwọn ará Kaldea.
Zbierzcie się wszyscy i słuchajcie. Któż spośród nich to opowiedział? PAN go umiłował, on wykona jego wolę na Babilonie i jego ramię [będzie] przeciw Chaldejczykom.
15 Èmi, àní Èmi ló ti sọ̀rọ̀; bẹ́ẹ̀ ni, mo ti pè é. Èmi yóò mú un wá, òun yóò sì ṣe àṣeyọrí nínú ìrìnàjò rẹ̀.
Ja, ja mówiłem i ja go wezwałem; przyprowadziłem go i powiedzie mu się jego droga.
16 “Ẹ súnmọ́ ọ̀dọ̀ mi kí ẹ sì dẹtí sí èyí: “Láti ìgbà ìkéde àkọ́kọ́ èmi kò sọ̀rọ̀ ní ìkọ̀kọ̀; ní àsìkò tí ó sì ṣẹlẹ̀, Èmi wà níbẹ̀.” Àti ní àkókò yìí, Olúwa Olódùmarè ni ó ti rán mi, pẹ̀lú ẹ̀mí rẹ̀.
Zbliżcie się do mnie i słuchajcie tego; od początku nie mówiłem w skrytości; ale od tego czasu, kiedy to się działo, tam byłem. A teraz Pan BÓG posłał mnie, i jego Duch.
17 Èyí ni ohun tí Olúwa wí, Olùdáǹdè rẹ, Ẹni Mímọ́ Israẹli: “Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ, tí ó kọ́ ọ ní ohun tí ó dára fún ọ, tí ó tọ́ ọ ṣọ́nà tí ó yẹ kí o máa rìn.
Tak mówi PAN, twój Odkupiciel, Święty Izraela: Ja jestem PANEM, twoim Bogiem, który cię uczy tego, co jest pożyteczne, i prowadzi cię drogą, którą masz chodzić.
18 Bí ó bá ṣe pé ìwọ bá ti tẹ́tí sílẹ̀ sí àṣẹ mi, àlàáfíà rẹ kì bá ti dàbí ì ti odò, àti òdodo rẹ bí ìgbì Òkun.
O gdybyś zważał na moje przykazania, twój pokój byłby jak rzeka i twoja sprawiedliwość jak fale morskie.
19 Àwọn ọmọ rẹ ìbá ti dàbí iyanrìn, àwọn ọmọ yín bí i hóró ọkà tí a kò lè kà tán; orúkọ wọn ni a kì yóò ké kúrò tàbí kí a pa wọ́n run níwájú mi.”
Twoje potomstwo byłoby jak piasek i płód twego łona jak jego ziarnko; jego imię nie zostałoby wytępione ani zgładzone sprzed mego oblicza.
20 Fi Babeli sílẹ̀, sá fún àwọn ará Babeli, ṣe ìfilọ̀ èyí pẹ̀lú ariwo ayọ̀ kí o sì kéde rẹ̀. Rán an jáde lọ sí òpin ilẹ̀ ayé; wí pé, “Olúwa ti dá ìránṣẹ́ rẹ̀ Jakọbu nídè.”
Wyjdźcie z Babilonu, uciekajcie od Chaldejczyków. Głosem śpiewu to obwieszczajcie, rozgłaszajcie to, zwiastujcie to aż do krańców ziemi; mówcie: PAN odkupił swego sługę Jakuba.
21 Òrùngbẹ kò gbẹ wọ́n nígbà tí ó kó wọn kọjá nínú aginjù; ó jẹ́ kí omi ó sàn fún wọn láti inú àpáta; ó fọ́ àpáta omi sì tú jáde.
Nie zaznali pragnienia, gdy ich prowadził przez pustynię. Sprawił, że wody trysnęły dla nich ze skał. Rozszczepił skałę i wypłynęły wody.
22 “Kò sí àlàáfíà,” ni Olúwa wí, “Fún àwọn ìkà.”
Nie ma pokoju dla niegodziwych, mówi PAN.

< Isaiah 48 >