< Isaiah 48 >
1 “Tẹ́tí sí èyí, ìwọ ilé e Jakọbu, ìwọ tí a ń pè pẹ̀lú orúkọ Israẹli tí o sì wá láti ẹ̀ka Juda, ìwọ tí ò ń búra ní orúkọ Olúwa tí o sì ń pe Ọlọ́run Israẹli ṣùgbọ́n kì í ṣe ní òtítọ́ àti òdodo,
Écoutez, maison de Jacob, vous qui portez le nom d'Israël, qui sortez de Juda et qui jurez au nom du Seigneur Dieu d'Israël, qui faites mention de tout cela, mais non dans la vérité et la justice;
2 ìwọ tí ò ń pe ara rẹ ní ọmọ ìlú mímọ́ n nì tí o sì gbẹ́kẹ̀lé Ọlọ́run Israẹli— Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
Qui gardez le nom de la ville sainte, et qui vous appuyez sur le Dieu d'Israël; le Seigneur des armées est son nom.
3 Èmi sọ àsọtẹ́lẹ̀ àwọn nǹkan ti tẹ́lẹ̀ lọ́jọ́ tó ti pẹ́, ẹnu mi ló ti kéde wọn, mo sì sọ wọ́n di mí mọ̀; lẹ́yìn náà lójijì mo gbé ìgbésẹ̀, wọ́n sì wá sí ìmúṣẹ.
Je vous ai déjà fait connaître les choses des premiers temps: elles sont sorties de ma bouche, et tout s'est fait comme vous l'aviez entendu; j'ai agi soudain, et les faits sont advenus.
4 Nítorí mo mọ bí ẹ ti jẹ́ olórí kunkun tó; àwọn iṣan ọrùn yín sì jẹ́ irin; bẹ́ẹ̀ ni iwájú yín idẹ ni.
Je sais que tu es dur; ton cou est un nerf de fer, et tu as un front d'airain.
5 Nítorí náà mo ti sọ nǹkan wọ̀nyí fún ọ ní ọjọ́ tí ó ti pẹ́; kí wọn ó tó ṣẹlẹ̀ mo ti kéde wọn fún un yín tó bẹ́ẹ̀ tí ìwọ kò fi lè sọ pé, ‘Àwọn ère mi ló ṣe wọ́n; àwọn ère igi àti òrìṣà irin ló fọwọ́sí i.’
Aussi t'ai-je prédit les choses longtemps avant qu'elles te fussent arrivées, et je te les ai fait connaître afin que tu ne puisses dire: Ce sont mes idoles qui m'ont fait ceci; et que tu ne puisses dire: Ce sont mes sculptures ou mes statues en fonte qui m'ont ordonné cela.
6 Ìwọ ti gbọ́ àwọn nǹkan wọ̀nyí; wo gbogbo wọn. Ǹjẹ́ o kò nígbà wọ́n bí? “Láti ìsinsin yìí lọ, Èmi yóò máa sọ fún ọ nípa nǹkan tuntun, àwọn nǹkan tí ó fi ara sin tí ìwọ kò mọ̀.
Tout ce que vous avez entendu autrefois, vous ne le connaissiez pas; mais je vais vous faire connaître des choses nouvelles, des choses présentes, et qui sont sur le point d'arriver. Et vous n'avez point dit:
7 A dá wọn ní àkókò yìí kì í ṣe láti ìgbà pípẹ́ ìwọ kò tí ì gbọ́ nípa wọn títí di òní. Nítorí náà, ìwọ kò lè sọ pé, ‘Bẹ́ẹ̀ ni, mo mọ̀ nípa wọn.’
Maintenant tout s'accomplit; quant à ceci, ce n'est pas une prédiction d'autrefois, et tu n'en as pas entendu parler les jours précédents; ne dis donc pas: Assurément je connais ces choses.
8 Ìwọ a ha ti gbọ́ tàbí ó ti yé ọ bí láti ìgbà àtijọ́ etí kò ti di yíyà. Ǹjẹ́ mo mọ̀ bí o ti jẹ́ alárékérekè tó; a ń pè ọ́ ní ọlọ̀tẹ̀ láti ìgbà ìbí rẹ.
Tu ne les connais pas, tu n'en as rien su; je ne t'ai point ouvert les oreilles dès le commencement; car je savais qu'étant traître tu trahirais, et que dès le sein de ta mère tu serais appelé violateur de ma loi.
9 Nítorí orúkọ ara mi, mo dáwọ́ ìbínú mi dúró; nítorí ìyìn ara mi, mo fà á sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ rẹ, kí a má ba à ké ọ kúrò.
Mais à cause de mon nom je te montrerai ma colère; puis j'accomplirai devant toi mes merveilles afin que je ne t'extermine pas.
10 Wò ó, èmi ti tún ọ ṣe, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé kì í ṣe bí i fàdákà; Èmi ti dán ọ wò nínú ìléru ìpọ́njú.
Voilà que je t'ai vendu, non à prix d'argent; mais je t'ai retiré d'une fournaise de misère.
11 Nítorí orúkọ mi, nítorí orúkọ mi, mo ṣe èyí. Báwo ni mo ṣe lè jẹ́ kí a ba orúkọ mi jẹ́. Èmi kì yóò fi ògo mi fún ẹlòmíràn.
A cause de moi, j'agirai ainsi pour toi; car mon nom a été profané, et je ne donnerai pas ma gloire à un autre.
12 “Tẹ́tí sí mi, ìwọ Jakọbu Israẹli ẹni tí mo pè. Èmi ni ẹni náà; Èmi ni ẹni àkọ́kọ́ àti ẹni ìgbẹ̀yìn.
Ecoute-moi donc, Jacob; écoute-moi, Israël, que j'appelle à moi: Je suis le premier, et je suis pour l'éternité.
13 Ọwọ́ mi pàápàá ni ó fi àwọn ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀, àti ọwọ́ ọ̀tún mi ni ó tẹ àwọn ọ̀run; nígbà tí mo pè wọ́n, gbogbo wọn dìde sókè papọ̀.
Et ma main a fondé la terre, et ma droite a affermi le ciel. Je les appellerai, et ils se présenteront à la fois;
14 “Gbogbo yín, ẹ péjọ kí ẹ sì gbọ́. Ta nínú wọn ni ó ti sọ nǹkan wọ̀nyí. Olúwa ti fẹ́ ẹ, yóò sì ṣe ìfẹ́ rẹ̀ ní Babiloni, apá rẹ̀ ni yóò sì wà ní ará àwọn ará Kaldea.
Et ils se rassembleront tous, et ils m'écouteront. Qui a fait connaître ces choses à tes idoles? Par amour pour toi, j'ai fait contre Babylone ce que tu désirais, afin d'exterminer la race des Chaldéens.
15 Èmi, àní Èmi ló ti sọ̀rọ̀; bẹ́ẹ̀ ni, mo ti pè é. Èmi yóò mú un wá, òun yóò sì ṣe àṣeyọrí nínú ìrìnàjò rẹ̀.
J'ai parlé, j'ai appelé, je l'ai conduit et je lui ai préparé la voie.
16 “Ẹ súnmọ́ ọ̀dọ̀ mi kí ẹ sì dẹtí sí èyí: “Láti ìgbà ìkéde àkọ́kọ́ èmi kò sọ̀rọ̀ ní ìkọ̀kọ̀; ní àsìkò tí ó sì ṣẹlẹ̀, Èmi wà níbẹ̀.” Àti ní àkókò yìí, Olúwa Olódùmarè ni ó ti rán mi, pẹ̀lú ẹ̀mí rẹ̀.
Approchez-vous de moi, écoutez ce que je vais vous dire: Dès le commencement je n'ai point parlé en secret; quand les choses ont été résolues, j'étais là, et maintenant le Seigneur Maître m'a envoyé, et avec lui son Esprit.
17 Èyí ni ohun tí Olúwa wí, Olùdáǹdè rẹ, Ẹni Mímọ́ Israẹli: “Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ, tí ó kọ́ ọ ní ohun tí ó dára fún ọ, tí ó tọ́ ọ ṣọ́nà tí ó yẹ kí o máa rìn.
Voici ce que dit le Seigneur, qui t'a délivré, le Saint d'Israël: Je suis ton Dieu, je t'ai montré comment tu trouverais la voie où tu dois marcher.
18 Bí ó bá ṣe pé ìwọ bá ti tẹ́tí sílẹ̀ sí àṣẹ mi, àlàáfíà rẹ kì bá ti dàbí ì ti odò, àti òdodo rẹ bí ìgbì Òkun.
Et si tu avais été docile à mes commandements, ta paix aurait été comme un fleuve, et la justice comme les vagues de la mer.
19 Àwọn ọmọ rẹ ìbá ti dàbí iyanrìn, àwọn ọmọ yín bí i hóró ọkà tí a kò lè kà tán; orúkọ wọn ni a kì yóò ké kúrò tàbí kí a pa wọ́n run níwájú mi.”
Et ta race aurait été comme le sable, et les fruits de tes entrailles comme la poussière des champs; et maintenant tu ne seras pas entièrement détruit, et ton nom ne périra pas devant moi.
20 Fi Babeli sílẹ̀, sá fún àwọn ará Babeli, ṣe ìfilọ̀ èyí pẹ̀lú ariwo ayọ̀ kí o sì kéde rẹ̀. Rán an jáde lọ sí òpin ilẹ̀ ayé; wí pé, “Olúwa ti dá ìránṣẹ́ rẹ̀ Jakọbu nídè.”
Sortez de Babylone, fuyez loin des Chaldéens; poussez un cri d'allégresse; écoutez ces paroles, publiez-les jusqu'aux extrémités de la terre, et dites: Le Seigneur a délivré son serviteur Jacob.
21 Òrùngbẹ kò gbẹ wọ́n nígbà tí ó kó wọn kọjá nínú aginjù; ó jẹ́ kí omi ó sàn fún wọn láti inú àpáta; ó fọ́ àpáta omi sì tú jáde.
Et s'ils ont soif, il les guidera à travers le désert; il fera jaillir pour eux l'eau des rochers; la pierre s'ouvrira, des eaux en couleront, et mon peuple boira.
22 “Kò sí àlàáfíà,” ni Olúwa wí, “Fún àwọn ìkà.”
Mais pour les impies, il n'y a point de joie, dit le Seigneur.