< Isaiah 48 >

1 “Tẹ́tí sí èyí, ìwọ ilé e Jakọbu, ìwọ tí a ń pè pẹ̀lú orúkọ Israẹli tí o sì wá láti ẹ̀ka Juda, ìwọ tí ò ń búra ní orúkọ Olúwa tí o sì ń pe Ọlọ́run Israẹli ṣùgbọ́n kì í ṣe ní òtítọ́ àti òdodo,
Ecoutez ceci, maison de Jacob, vous qui vous réclamez du nom d’Israël, qui êtes issus de la source de Juda, qui jurez par le nom de l’Eternel et invoquez le Dieu d’Israël non toutefois avec sincérité et droiture!
2 ìwọ tí ò ń pe ara rẹ ní ọmọ ìlú mímọ́ n nì tí o sì gbẹ́kẹ̀lé Ọlọ́run Israẹli— Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
Car ils se désignent d’après la Ville sainte et s’appuient sur le Dieu d’Israël, sur Celui qui s’appelle Eternel-Cebaot!
3 Èmi sọ àsọtẹ́lẹ̀ àwọn nǹkan ti tẹ́lẹ̀ lọ́jọ́ tó ti pẹ́, ẹnu mi ló ti kéde wọn, mo sì sọ wọ́n di mí mọ̀; lẹ́yìn náà lójijì mo gbé ìgbésẹ̀, wọ́n sì wá sí ìmúṣẹ.
Les choses passées, je les ai annoncées longtemps d’avance. Une fois énoncées par ma bouche et prédites par moi, soudain je les ai réalisées et elles se sont accomplies,
4 Nítorí mo mọ bí ẹ ti jẹ́ olórí kunkun tó; àwọn iṣan ọrùn yín sì jẹ́ irin; bẹ́ẹ̀ ni iwájú yín idẹ ni.
parce que je savais que tu es opiniâtre, que ta nuque est une barre de fer et que ton front est d’airain.
5 Nítorí náà mo ti sọ nǹkan wọ̀nyí fún ọ ní ọjọ́ tí ó ti pẹ́; kí wọn ó tó ṣẹlẹ̀ mo ti kéde wọn fún un yín tó bẹ́ẹ̀ tí ìwọ kò fi lè sọ pé, ‘Àwọn ère mi ló ṣe wọ́n; àwọn ère igi àti òrìṣà irin ló fọwọ́sí i.’
D’Avance donc je t’ai informé, instruit des événements non encore arrivés, pour que tu ne dises pas: "Mon idole les a accomplis, mes statues de pierre et de métal les ont ordonnés."
6 Ìwọ ti gbọ́ àwọn nǹkan wọ̀nyí; wo gbogbo wọn. Ǹjẹ́ o kò nígbà wọ́n bí? “Láti ìsinsin yìí lọ, Èmi yóò máa sọ fún ọ nípa nǹkan tuntun, àwọn nǹkan tí ó fi ara sin tí ìwọ kò mọ̀.
Tu l’as entendu vois tout cela de tes propres yeux; et à présent ne parlerez-vous donc pas? Désormais je te révélerai des faits nouveaux, des faits encore cachés que tu ne connais pas,
7 A dá wọn ní àkókò yìí kì í ṣe láti ìgbà pípẹ́ ìwọ kò tí ì gbọ́ nípa wọn títí di òní. Nítorí náà, ìwọ kò lè sọ pé, ‘Bẹ́ẹ̀ ni, mo mọ̀ nípa wọn.’
des faits qui se produisent maintenant, qui n’ont pas existé plus tôt; avant ce jour tu n’en as rien su, tu ne saurais dire: "Je les connaissais!"
8 Ìwọ a ha ti gbọ́ tàbí ó ti yé ọ bí láti ìgbà àtijọ́ etí kò ti di yíyà. Ǹjẹ́ mo mọ̀ bí o ti jẹ́ alárékérekè tó; a ń pè ọ́ ní ọlọ̀tẹ̀ láti ìgbà ìbí rẹ.
Non, tu n’en as rien entendu, rien connu; jamais ton oreille n’en a été frappée, parce que je savais que grande est ta perfidie et que tu as reçu ce nom: Infidèle dès le berceau.
9 Nítorí orúkọ ara mi, mo dáwọ́ ìbínú mi dúró; nítorí ìyìn ara mi, mo fà á sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ rẹ, kí a má ba à ké ọ kúrò.
Pour l’honneur de mon nom je retiens longtemps ma colère, en faveur de ma gloire je la comprime, pour ne pas te perdre.
10 Wò ó, èmi ti tún ọ ṣe, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé kì í ṣe bí i fàdákà; Èmi ti dán ọ wò nínú ìléru ìpọ́njú.
Certes, je t’ai éprouvée mais non comme on éprouve l’argent, je t’ai fait passer par le creuset du malheur.
11 Nítorí orúkọ mi, nítorí orúkọ mi, mo ṣe èyí. Báwo ni mo ṣe lè jẹ́ kí a ba orúkọ mi jẹ́. Èmi kì yóò fi ògo mi fún ẹlòmíràn.
C’Est pour moi, pour moi que je le fais, car pourquoi mon honneur serait-il terni? Cet honneur, je ne le prête à nul autre!
12 “Tẹ́tí sí mi, ìwọ Jakọbu Israẹli ẹni tí mo pè. Èmi ni ẹni náà; Èmi ni ẹni àkọ́kọ́ àti ẹni ìgbẹ̀yìn.
Ecoute-moi, Jacob, et toi Israël, mon prédestiné! Je suis toujours le même, je suis le Premier comme je suis le Dernier.
13 Ọwọ́ mi pàápàá ni ó fi àwọn ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀, àti ọwọ́ ọ̀tún mi ni ó tẹ àwọn ọ̀run; nígbà tí mo pè wọ́n, gbogbo wọn dìde sókè papọ̀.
C’Est ma main qui a fondé la terre, ma droite qui a étendu les cieux. Je leur adresse mon appel: aussitôt ils se présentent.
14 “Gbogbo yín, ẹ péjọ kí ẹ sì gbọ́. Ta nínú wọn ni ó ti sọ nǹkan wọ̀nyí. Olúwa ti fẹ́ ẹ, yóò sì ṣe ìfẹ́ rẹ̀ ní Babiloni, apá rẹ̀ ni yóò sì wà ní ará àwọn ará Kaldea.
Assemblez-vous tous et écoutez! Qui parmi eux a annoncé ces choses? Il est aimé du Seigneur, il accomplit sa volonté contre Babel et manifeste sa puissance contre la Chaldée.
15 Èmi, àní Èmi ló ti sọ̀rọ̀; bẹ́ẹ̀ ni, mo ti pè é. Èmi yóò mú un wá, òun yóò sì ṣe àṣeyọrí nínú ìrìnàjò rẹ̀.
Moi, moi j’ai prononcé, je l’ai appelé, je l’ai amené, et il réussira dans son entreprise.
16 “Ẹ súnmọ́ ọ̀dọ̀ mi kí ẹ sì dẹtí sí èyí: “Láti ìgbà ìkéde àkọ́kọ́ èmi kò sọ̀rọ̀ ní ìkọ̀kọ̀; ní àsìkò tí ó sì ṣẹlẹ̀, Èmi wà níbẹ̀.” Àti ní àkókò yìí, Olúwa Olódùmarè ni ó ti rán mi, pẹ̀lú ẹ̀mí rẹ̀.
Approchez de moi, écoutez ceci! Dès le début, je n’ai point parlé en secret; du jour où l’événement s’est réalisé, j’étais présent. Et maintenant, dit le prophète, le Seigneur, l’Eternel m’envoie, et son inspiration est en moi.
17 Èyí ni ohun tí Olúwa wí, Olùdáǹdè rẹ, Ẹni Mímọ́ Israẹli: “Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ, tí ó kọ́ ọ ní ohun tí ó dára fún ọ, tí ó tọ́ ọ ṣọ́nà tí ó yẹ kí o máa rìn.
Ainsi parle l’Eternel, ton libérateur, le Saint d’Israël: "Je suis l’Eternel, ton Dieu, qui t’instruis pour ton bien, qui te dirige dans la voie que tu dois suivre.
18 Bí ó bá ṣe pé ìwọ bá ti tẹ́tí sílẹ̀ sí àṣẹ mi, àlàáfíà rẹ kì bá ti dàbí ì ti odò, àti òdodo rẹ bí ìgbì Òkun.
Ah! Si seulement tu obéissais à mes ordres, ta prospérité serait comme le fleuve, et ton bonheur comme les flots de la mer;
19 Àwọn ọmọ rẹ ìbá ti dàbí iyanrìn, àwọn ọmọ yín bí i hóró ọkà tí a kò lè kà tán; orúkọ wọn ni a kì yóò ké kúrò tàbí kí a pa wọ́n run níwájú mi.”
ta postérité serait nombreuse comme le sable, le fruit de tes entrailles comme les galets, et ton nom ne serait ni effacé ni aboli devant moi."
20 Fi Babeli sílẹ̀, sá fún àwọn ará Babeli, ṣe ìfilọ̀ èyí pẹ̀lú ariwo ayọ̀ kí o sì kéde rẹ̀. Rán an jáde lọ sí òpin ilẹ̀ ayé; wí pé, “Olúwa ti dá ìránṣẹ́ rẹ̀ Jakọbu nídè.”
Sortez de Babel, échappez-vous de Chaldée! Avec des accents joyeux, annoncez, proclamez la nouvelle, propagez-la jusqu’aux extrémités de la terre! Dites: L’Eternel a délivré son serviteur Jacob!
21 Òrùngbẹ kò gbẹ wọ́n nígbà tí ó kó wọn kọjá nínú aginjù; ó jẹ́ kí omi ó sàn fún wọn láti inú àpáta; ó fọ́ àpáta omi sì tú jáde.
Et ils n’ont pas souffert de la soif dans les lieux arides où il les a conduits; il a fait pour eux ruisseler l’eau du rocher, il a fendu le granit et les sources ont jailli!"
22 “Kò sí àlàáfíà,” ni Olúwa wí, “Fún àwọn ìkà.”
Point de paix, dit l’Eternel, pour les méchants!

< Isaiah 48 >