< Isaiah 48 >
1 “Tẹ́tí sí èyí, ìwọ ilé e Jakọbu, ìwọ tí a ń pè pẹ̀lú orúkọ Israẹli tí o sì wá láti ẹ̀ka Juda, ìwọ tí ò ń búra ní orúkọ Olúwa tí o sì ń pe Ọlọ́run Israẹli ṣùgbọ́n kì í ṣe ní òtítọ́ àti òdodo,
[Yahweh says], “You descendants [MTY] of Jacob, who are [also] descendants of Judah and are now called [the people of] Israel, Listen to me! You make solemn promises using my name, Yahweh, and you request that I, the God to whom you Israeli people belong, [will hear you], but you do not do it sincerely.
2 ìwọ tí ò ń pe ara rẹ ní ọmọ ìlú mímọ́ n nì tí o sì gbẹ́kẹ̀lé Ọlọ́run Israẹli— Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
You say that you live in the holy city [of Jerusalem], and [you insincerely say] that you are relying on me, the God to whom you [people of] Israel belong, the one who is the Commander of the armies of angels.
3 Èmi sọ àsọtẹ́lẹ̀ àwọn nǹkan ti tẹ́lẹ̀ lọ́jọ́ tó ti pẹ́, ẹnu mi ló ti kéde wọn, mo sì sọ wọ́n di mí mọ̀; lẹ́yìn náà lójijì mo gbé ìgbésẹ̀, wọ́n sì wá sí ìmúṣẹ.
Long ago I [MTY] predicted what would happen [DOU]. And then suddenly, I caused those things to happen.
4 Nítorí mo mọ bí ẹ ti jẹ́ olórí kunkun tó; àwọn iṣan ọrùn yín sì jẹ́ irin; bẹ́ẹ̀ ni iwájú yín idẹ ni.
I knew that you people are very stubborn; I knew that your heads are [MET] [as hard as] iron or brass [DOU].
5 Nítorí náà mo ti sọ nǹkan wọ̀nyí fún ọ ní ọjọ́ tí ó ti pẹ́; kí wọn ó tó ṣẹlẹ̀ mo ti kéde wọn fún un yín tó bẹ́ẹ̀ tí ìwọ kò fi lè sọ pé, ‘Àwọn ère mi ló ṣe wọ́n; àwọn ère igi àti òrìṣà irin ló fọwọ́sí i.’
That is why I told you those things long ago. Long before they occurred, I announced that they would occur, in order that [when they happened] you could not say ‘Our idols did it; our statue made of wood and our idol made of metal caused them to happen.’
6 Ìwọ ti gbọ́ àwọn nǹkan wọ̀nyí; wo gbogbo wọn. Ǹjẹ́ o kò nígbà wọ́n bí? “Láti ìsinsin yìí lọ, Èmi yóò máa sọ fún ọ nípa nǹkan tuntun, àwọn nǹkan tí ó fi ara sin tí ìwọ kò mọ̀.
You have heard those things [that I predicted] and now you have seen that they have all occurred, so why do you not admit it [RHQ]? Now I will tell you new things, things that you have not known previously.
7 A dá wọn ní àkókò yìí kì í ṣe láti ìgbà pípẹ́ ìwọ kò tí ì gbọ́ nípa wọn títí di òní. Nítorí náà, ìwọ kò lè sọ pé, ‘Bẹ́ẹ̀ ni, mo mọ̀ nípa wọn.’
I am causing them to happen now; they are not things I did long ago. So you cannot say, ‘We already knew about those things.’
8 Ìwọ a ha ti gbọ́ tàbí ó ti yé ọ bí láti ìgbà àtijọ́ etí kò ti di yíyà. Ǹjẹ́ mo mọ̀ bí o ti jẹ́ alárékérekè tó; a ń pè ọ́ ní ọlọ̀tẹ̀ láti ìgbà ìbí rẹ.
[I will tell you about] things that you have never heard about or understood before. Even long ago you did not pay attention to me [IDM]. I know that you act very deceitfully/treacherously; you have rebelled against me since you first became a nation [MTY].
9 Nítorí orúkọ ara mi, mo dáwọ́ ìbínú mi dúró; nítorí ìyìn ara mi, mo fà á sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ rẹ, kí a má ba à ké ọ kúrò.
But, for my own sake, in order that I will be honored, I will not punish [MTY] you immediately and I will not completely get rid of you.
10 Wò ó, èmi ti tún ọ ṣe, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé kì í ṣe bí i fàdákà; Èmi ti dán ọ wò nínú ìléru ìpọ́njú.
I have purified you, but not the way [people refine] silver. Instead, I have caused you to suffer very much [to get rid of your impure behavior], like [MET] [people put metal in a very hot] furnace [to get rid of the impurities].
11 Nítorí orúkọ mi, nítorí orúkọ mi, mo ṣe èyí. Báwo ni mo ṣe lè jẹ́ kí a ba orúkọ mi jẹ́. Èmi kì yóò fi ògo mi fún ẹlòmíràn.
But for my [MTY] own sake I will delay punishing you more; I will do it for my own sake in order that my reputation will not be damaged [RHQ]. I will not allow any [person or any idol] to be honored as I [deserve to be] honored.”
12 “Tẹ́tí sí mi, ìwọ Jakọbu Israẹli ẹni tí mo pè. Èmi ni ẹni náà; Èmi ni ẹni àkọ́kọ́ àti ẹni ìgbẹ̀yìn.
“You descendants [MTY] of Jacob, you people of Israel whom I have chosen, listen to me! [Only] I am God; I am the one who begins everything and who causes everything to end.
13 Ọwọ́ mi pàápàá ni ó fi àwọn ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀, àti ọwọ́ ọ̀tún mi ni ó tẹ àwọn ọ̀run; nígbà tí mo pè wọ́n, gbogbo wọn dìde sókè papọ̀.
I [SYN] am the one who laid the foundation of the earth. I stretched out the sky with my hand. And when I tell [the stars] to appear, they all do what I tell them.
14 “Gbogbo yín, ẹ péjọ kí ẹ sì gbọ́. Ta nínú wọn ni ó ti sọ nǹkan wọ̀nyí. Olúwa ti fẹ́ ẹ, yóò sì ṣe ìfẹ́ rẹ̀ ní Babiloni, apá rẹ̀ ni yóò sì wà ní ará àwọn ará Kaldea.
All of you, gather together and listen to me. None of your idols has [RHQ] told this to you: I, Yahweh, have chosen [Cyrus] to assist me, and he will do to Babylon what I want him to do, and his army will get rid of [the army of] Babylonia.
15 Èmi, àní Èmi ló ti sọ̀rọ̀; bẹ́ẹ̀ ni, mo ti pè é. Èmi yóò mú un wá, òun yóò sì ṣe àṣeyọrí nínú ìrìnàjò rẹ̀.
I have said it; I have summoned [Cyrus]. I have appointed him, and he will accomplish everything that he attempts to do.
16 “Ẹ súnmọ́ ọ̀dọ̀ mi kí ẹ sì dẹtí sí èyí: “Láti ìgbà ìkéde àkọ́kọ́ èmi kò sọ̀rọ̀ ní ìkọ̀kọ̀; ní àsìkò tí ó sì ṣẹlẹ̀, Èmi wà níbẹ̀.” Àti ní àkókò yìí, Olúwa Olódùmarè ni ó ti rán mi, pẹ̀lú ẹ̀mí rẹ̀.
Come close to me and listen to what I say. Long ago [MTY] I told you plainly/clearly [LIT] [what would happen], and when those things occurred, I was [causing them to happen].” And now Yahweh the Lord and his Spirit have sent me [to give you a message].
17 Èyí ni ohun tí Olúwa wí, Olùdáǹdè rẹ, Ẹni Mímọ́ Israẹli: “Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ, tí ó kọ́ ọ ní ohun tí ó dára fún ọ, tí ó tọ́ ọ ṣọ́nà tí ó yẹ kí o máa rìn.
This is what Yahweh, the one who saves you, the Holy God of [us] Israelis, says: “I am Yahweh, your God; I teach you what is important for you [to know]; I direct you and lead you to the roads that you should walk on [MET].
18 Bí ó bá ṣe pé ìwọ bá ti tẹ́tí sílẹ̀ sí àṣẹ mi, àlàáfíà rẹ kì bá ti dàbí ì ti odò, àti òdodo rẹ bí ìgbì Òkun.
I wish that you had paid attention to my commands! If you had done that, things would have gone well for you like [SIM] a river that flows gently; you would have been successful again and again, like [SIM] waves that come without ceasing.
19 Àwọn ọmọ rẹ ìbá ti dàbí iyanrìn, àwọn ọmọ yín bí i hóró ọkà tí a kò lè kà tán; orúkọ wọn ni a kì yóò ké kúrò tàbí kí a pa wọ́n run níwájú mi.”
Your descendants would have been [as many as] [MET] the grains of sand [on the seashore] [which no one can count]. I would not have needed to get rid of you; the country of [MTY] [Israel] would not have been destroyed.”
20 Fi Babeli sílẹ̀, sá fún àwọn ará Babeli, ṣe ìfilọ̀ èyí pẹ̀lú ariwo ayọ̀ kí o sì kéde rẹ̀. Rán an jáde lọ sí òpin ilẹ̀ ayé; wí pé, “Olúwa ti dá ìránṣẹ́ rẹ̀ Jakọbu nídè.”
[However, now I tell you], leave Babylon! Flee from [being slaves of the people of] Babylonia! Proclaim this message joyfully; send it to the most remote/distant places on the earth: Yahweh freed the people of Israel [from being slaves in Egypt].
21 Òrùngbẹ kò gbẹ wọ́n nígbà tí ó kó wọn kọjá nínú aginjù; ó jẹ́ kí omi ó sàn fún wọn láti inú àpáta; ó fọ́ àpáta omi sì tú jáde.
They were not thirsty when he led them through the desert, because he split open the rock and caused water to gush/flow out for them [to drink].
22 “Kò sí àlàáfíà,” ni Olúwa wí, “Fún àwọn ìkà.”
“But things will not go well [like that] for wicked people,” says Yahweh.