< Isaiah 48 >

1 “Tẹ́tí sí èyí, ìwọ ilé e Jakọbu, ìwọ tí a ń pè pẹ̀lú orúkọ Israẹli tí o sì wá láti ẹ̀ka Juda, ìwọ tí ò ń búra ní orúkọ Olúwa tí o sì ń pe Ọlọ́run Israẹli ṣùgbọ́n kì í ṣe ní òtítọ́ àti òdodo,
Slyštež to, dome Jákobův, kteříž se nazýváte jménem Izraelovým, a z vod Judových jste pošli, kteříž přisaháte ve jménu Hospodinovu, a Boha Izraelského připomínáte, však ne v pravdě, ani v spravedlnosti,
2 ìwọ tí ò ń pe ara rẹ ní ọmọ ìlú mímọ́ n nì tí o sì gbẹ́kẹ̀lé Ọlọ́run Israẹli— Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
Ačkoli od města svatého se jmenujete, a na Boha Izraelského, jehož jméno jest Hospodin zástupů, zpoléháte.
3 Èmi sọ àsọtẹ́lẹ̀ àwọn nǹkan ti tẹ́lẹ̀ lọ́jọ́ tó ti pẹ́, ẹnu mi ló ti kéde wọn, mo sì sọ wọ́n di mí mọ̀; lẹ́yìn náà lójijì mo gbé ìgbésẹ̀, wọ́n sì wá sí ìmúṣẹ.
Předešlé věci zdávna jsem oznamoval, a což vyšlo z úst mých, i což jsem ohlašoval, brzce jsem činíval, a stávalo se.
4 Nítorí mo mọ bí ẹ ti jẹ́ olórí kunkun tó; àwọn iṣan ọrùn yín sì jẹ́ irin; bẹ́ẹ̀ ni iwájú yín idẹ ni.
Věděl jsem, že jsi zatvrdilý, a houžev železná šíje tvá, a čelo tvé ocelivé.
5 Nítorí náà mo ti sọ nǹkan wọ̀nyí fún ọ ní ọjọ́ tí ó ti pẹ́; kí wọn ó tó ṣẹlẹ̀ mo ti kéde wọn fún un yín tó bẹ́ẹ̀ tí ìwọ kò fi lè sọ pé, ‘Àwọn ère mi ló ṣe wọ́n; àwọn ère igi àti òrìṣà irin ló fọwọ́sí i.’
A protožť jsem oznamoval z dávna, prvé než přicházelo, ohlašovalť jsem, abys neříkal: Modla má učinila ty věci, a rytina má neb slitina má přikázala to.
6 Ìwọ ti gbọ́ àwọn nǹkan wọ̀nyí; wo gbogbo wọn. Ǹjẹ́ o kò nígbà wọ́n bí? “Láti ìsinsin yìí lọ, Èmi yóò máa sọ fún ọ nípa nǹkan tuntun, àwọn nǹkan tí ó fi ara sin tí ìwọ kò mọ̀.
Slýchals o tom, pohlediž na to na všecko, vy pak, nebudete-liž toho oznamovati? Již nyní ohlašujiť nové a tajné věci, o nichž jsi ty nic nevěděl.
7 A dá wọn ní àkókò yìí kì í ṣe láti ìgbà pípẹ́ ìwọ kò tí ì gbọ́ nípa wọn títí di òní. Nítorí náà, ìwọ kò lè sọ pé, ‘Bẹ́ẹ̀ ni, mo mọ̀ nípa wọn.’
Nyní stvořeny jsou, a ne předešlého času, o nichž jsi před tímto dnem nic neslyšel, abys neřekl: Aj, věděl jsem o tom.
8 Ìwọ a ha ti gbọ́ tàbí ó ti yé ọ bí láti ìgbà àtijọ́ etí kò ti di yíyà. Ǹjẹ́ mo mọ̀ bí o ti jẹ́ alárékérekè tó; a ń pè ọ́ ní ọlọ̀tẹ̀ láti ìgbà ìbí rẹ.
Anobrž aniž jsi slyšel, ani věděl, aniž se to tehdáž doneslo ucha tvého; nebo jsem věděl, že sobě velmi nevážně počínati budeš, a že jsi převrácenec hned od života matky.
9 Nítorí orúkọ ara mi, mo dáwọ́ ìbínú mi dúró; nítorí ìyìn ara mi, mo fà á sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ rẹ, kí a má ba à ké ọ kúrò.
Pro jméno své poshovím s prchlivostí svou, a pro chválu svou poukrotím hněvu proti tobě, abych tě nevyplénil.
10 Wò ó, èmi ti tún ọ ṣe, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé kì í ṣe bí i fàdákà; Èmi ti dán ọ wò nínú ìléru ìpọ́njú.
Aj, přepálím tě, ačkoli ne jako stříbro, přeberu tě v peci ssoužení.
11 Nítorí orúkọ mi, nítorí orúkọ mi, mo ṣe èyí. Báwo ni mo ṣe lè jẹ́ kí a ba orúkọ mi jẹ́. Èmi kì yóò fi ògo mi fún ẹlòmíràn.
Pro sebe, pro sebe učiním to. Nebo jakž by mohlo v lehkost vydáno býti? Slávy své zajisté jinému nedám.
12 “Tẹ́tí sí mi, ìwọ Jakọbu Israẹli ẹni tí mo pè. Èmi ni ẹni náà; Èmi ni ẹni àkọ́kọ́ àti ẹni ìgbẹ̀yìn.
Slyš mne, Jákobe a Izraeli, povolaný můj: Já jsem, já první, já jsem i poslední.
13 Ọwọ́ mi pàápàá ni ó fi àwọn ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀, àti ọwọ́ ọ̀tún mi ni ó tẹ àwọn ọ̀run; nígbà tí mo pè wọ́n, gbogbo wọn dìde sókè papọ̀.
Má zajisté ruka založila zemi, a pravice má dlaní rozměřila nebesa; povolal jsem jich, a hned se postavily.
14 “Gbogbo yín, ẹ péjọ kí ẹ sì gbọ́. Ta nínú wọn ni ó ti sọ nǹkan wọ̀nyí. Olúwa ti fẹ́ ẹ, yóò sì ṣe ìfẹ́ rẹ̀ ní Babiloni, apá rẹ̀ ni yóò sì wà ní ará àwọn ará Kaldea.
Shromažďte se vy všickni, a slyšte. Kdo z nich oznámil tyto věci: Hospodin miluje jej, onť vykoná vůli jeho proti Babylonu, a rámě jeho proti Kaldejským?
15 Èmi, àní Èmi ló ti sọ̀rọ̀; bẹ́ẹ̀ ni, mo ti pè é. Èmi yóò mú un wá, òun yóò sì ṣe àṣeyọrí nínú ìrìnàjò rẹ̀.
Já, já mluvil jsem, protož povolám ho; přivedu jej, a šťastnou bude míti cestu svou.
16 “Ẹ súnmọ́ ọ̀dọ̀ mi kí ẹ sì dẹtí sí èyí: “Láti ìgbà ìkéde àkọ́kọ́ èmi kò sọ̀rọ̀ ní ìkọ̀kọ̀; ní àsìkò tí ó sì ṣẹlẹ̀, Èmi wà níbẹ̀.” Àti ní àkókò yìí, Olúwa Olódùmarè ni ó ti rán mi, pẹ̀lú ẹ̀mí rẹ̀.
Přistupte ke mně, slyšte to: Nemluvíval jsem z počátku v skrytě; od toho času, v kterémž se to dálo, přítomen jsem byl. A nyní Panovník Hospodin poslal mne a duch jeho.
17 Èyí ni ohun tí Olúwa wí, Olùdáǹdè rẹ, Ẹni Mímọ́ Israẹli: “Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ, tí ó kọ́ ọ ní ohun tí ó dára fún ọ, tí ó tọ́ ọ ṣọ́nà tí ó yẹ kí o máa rìn.
Toto praví Hospodin vykupitel tvůj, Svatý Izraelský: Já Hospodin Bůh tvůj učím tě, abys prospěch bral, a vodím tě po cestě, po kteréž bys chodil.
18 Bí ó bá ṣe pé ìwọ bá ti tẹ́tí sílẹ̀ sí àṣẹ mi, àlàáfíà rẹ kì bá ti dàbí ì ti odò, àti òdodo rẹ bí ìgbì Òkun.
Ó kdybys byl šetřil přikázaní mých, bylť by jako potok pokoj tvůj, a spravedlnost tvá jako vlny mořské.
19 Àwọn ọmọ rẹ ìbá ti dàbí iyanrìn, àwọn ọmọ yín bí i hóró ọkà tí a kò lè kà tán; orúkọ wọn ni a kì yóò ké kúrò tàbí kí a pa wọ́n run níwájú mi.”
A bylo by jako písku semene tvého, a plodu života tvého jako štěrku jeho, aniž by vyťato, ani vyhlazeno bylo jméno jeho před oblíčejem mým.
20 Fi Babeli sílẹ̀, sá fún àwọn ará Babeli, ṣe ìfilọ̀ èyí pẹ̀lú ariwo ayọ̀ kí o sì kéde rẹ̀. Rán an jáde lọ sí òpin ilẹ̀ ayé; wí pé, “Olúwa ti dá ìránṣẹ́ rẹ̀ Jakọbu nídè.”
Vyjděte z Babylona, utecte od Kaldejských, hlasem zvučným zvěstujte, ohlašujte to, rozneste to až do končin země. Rcete: Vykoupil Hospodin služebníka svého Jákoba.
21 Òrùngbẹ kò gbẹ wọ́n nígbà tí ó kó wọn kọjá nínú aginjù; ó jẹ́ kí omi ó sàn fún wọn láti inú àpáta; ó fọ́ àpáta omi sì tú jáde.
Nebudouť žízniti, když je po pustinách povede, vody z skály vyvede jim; nebo rozetne skálu, aby tekly vody.
22 “Kò sí àlàáfíà,” ni Olúwa wí, “Fún àwọn ìkà.”
Nemajíť žádného pokoje, praví Hospodin, bezbožní.

< Isaiah 48 >