< Isaiah 47 >

1 “Sọ̀kalẹ̀, jókòó nínú eruku, wúńdíá ọmọbìnrin Babeli; jókòó ní ilẹ̀ láìsí ìtẹ́, ọmọbìnrin àwọn ará Babeli. A kì yóò pè ọ́ ní aláìlókun àti ẹlẹgẹ́ mọ́.
Descends, assieds-toi sur la poussière, Vierge fille de Babylone, assieds-toi à terre, il n'y a plus de trône pour la fille des Chaldéens, car tu ne te feras, plus appeler, la délicate et la voluptueuse.
2 Mú òkúta-ọlọ kí o sì lọ ìyẹ̀fun; mú ìbòjú rẹ kúrò. Ká aṣọ ẹsẹ̀ rẹ sókè, ká aṣọ itan, kí o sì la odò wọ̀n-ọn-nì kọjá.
Mets la main aux meules, et fais moudre la farine; délie tes tresses, déchausse-toi, découvre tes jambes et passe les fleuves.
3 Ìhòhò rẹ ni a ó sí síta àti ìtìjú rẹ ni a ó ṣí sílẹ̀. Èmi yóò sì gba ẹ̀san, Èmi kì yóò sì dá ẹnìkan sí.”
Ta honte sera découverte, et ton opprobre sera vu; je prendrai vengeance, je n'irai point contre toi en homme.
4 Olùràpadà wa Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀ òun ni Ẹni Mímọ́ Israẹli.
Quant à notre Rédempteur, son Nom [est] l'Eternel des armées, le Saint d'Israël.
5 “Jókòó ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́, lọ sínú òkùnkùn, ọmọbìnrin àwọn ará Babeli; a kì yóò pè ọ́ ní ọbabìnrin àwọn ilẹ̀ ọba mọ́.
Assieds-toi sans dire mot, et entre dans les ténèbres, fille des Chaldéens, car tu ne te feras plus appeler, la Dame des Royaumes.
6 Inú bí mi sí àwọn ènìyàn mi tí mo sì ba ogún mi jẹ́, mo fi wọ́n lé ọ lọ́wọ́, Ìwọ kò sì síjú àánú wò wọ́n. Lórí àwọn arúgbó pẹ̀lú ní o gbé àjàgà tí ó wúwo lé.
J'ai été embrasé de colère contre mon peuple, j'ai profané mon héritage, c'est pourquoi je les ai livrés entre tes mains, [mais] tu n'as point usé de miséricorde envers eux, tu as grièvement appesanti ton joug sur le vieillard;
7 Ìwọ wí pé, ‘Èmi yóò tẹ̀síwájú títí láé— ọbabìnrin ayérayé!’ Ṣùgbọ́n ìwọ kò kíyèsi nǹkan wọ̀nyí tàbí kí o ronú nípa ohun tí ó lè ṣẹlẹ̀.
Et tu as dit; je serai Dame à toujours, tellement que tu n'as point mis ces choses-là dans ton cœur; tu ne t'es point souvenue de ce qui en arriverait.
8 “Nísinsin yìí, tẹ́tí sílẹ̀, ìwọ oníwọ̀ra ẹ̀dá tí o kẹ̀tẹ̀ǹfẹ̀ nínú ààbò rẹ tí o sì ń sọ fún ara rẹ pé, ‘Èmi ni, kò sì ṣí ẹlòmíràn lẹ́yìn mi. Èmi kì yóò di opó tàbí kí n pàdánù àwọn ọmọ.’
Maintenant donc écoute ceci, toi voluptueuse; qui habites en assurance, qui dis en ton cœur; c'est moi, et il n'y en as point d'autre que moi; je ne deviendrai point veuve, et je ne saurai point ce que c'est que d'être privée d'enfants.
9 Méjèèjì yìí ni yóò wá sórí rẹ láìpẹ́ jọjọ, ní ọjọ́ kan náà: pípàdánù ọmọ àti dídi opó. Wọn yóò wá sórí rẹ ní ẹ̀kúnrẹ́rẹ́, pẹ̀lúpẹ̀lú àwọn ìṣe oṣó rẹ àti àwọn èpè rẹ tí ko lágbára.
C'est que ces deux choses t'arriveront en un moment, en un même jour, la privation d'enfants et le veuvage; elles sont venues sur toi dans tout leur entier, pour le grand nombre de tes sortilèges, et pour la grande abondance de tes enchantements.
10 Ìwọ ti ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú ìwà ìkà rẹ ó sì ti wí pé, ‘Kò sí ẹni tí ó rí mi?’ Ọgbọ́n àti òye rẹ ti ṣì ọ́ lọ́nà nígbà tí o wí fún ara rẹ pé, ‘Èmi ni, kò sí ẹlòmíràn lẹ́yìn mi.’
Et tu t'es confiée en ta malice, et as dit; Il n'y a personne qui me voie; ta sagesse et ta science est celle qui t'a fait égarer; tellement que tu as dit en ton cœur; C'est moi, et il n'y en a point d'autre que moi.
11 Ìparun yóò dé bá ọ bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì yóò mọ ọ̀nà láti ré e kúrò. Àjálù kan yóò ṣubú lù ọ́ tí o kì yóò le è fi ètùtù ré kúrò; òfò kan tí o kò le faradà ni yóò wá lójijì sí oríì rẹ.
C'est pourquoi le mal viendra sur toi, et tu ne sauras point quand il sera près d'arriver, et le malheur qui tombera sur toi sera tel, que tu ne le pourras point détourner; et la ruine éclatante, laquelle tu ne sauras point, viendra subitement sur toi.
12 “Tẹ̀síwájú nígbà náà, pẹ̀lú àfọ̀ṣẹ rẹ àti pẹ̀lú ìwà oṣó rẹ gbogbo, tí o ti ń ṣiṣẹ́ fún láti ìgbà èwe rẹ wá. Bóyá o le è ṣàṣeyọrí, bóyá o le è dá rúgúdù sílẹ̀.
Tiens-toi maintenant avec tes enchantements, et avec le grand nombre de tes sortilèges, après lesquels tu as travaillé dès ta jeunesse; peut-être que tu en pourras avoir quelque profit; peut-être que tu en seras renforcée
13 Gbogbo ìmọ̀ràn tí o ti gbà ni ó ti sọ ọ́ di akúrẹtẹ̀! Jẹ́ kí àwọn awòràwọ̀ rẹ bọ́ síwájú, àwọn awòràwọ̀ tí wọ́n sọ àsọtẹ́lẹ̀ láti oṣù dé oṣù, jẹ́ kí wọ́n gbà ọ́ lọ́wọ́ ohun tí ó ń bọ̀ wá bá ọ.
Tu t'es lassée à force de demander des conseils. Que les spectateurs des cieux qui contemplent les étoiles, et qui font [leurs] prédictions selon les lunes, comparaissent maintenant, et qu'ils te délivrent des choses qui viendront sur toi.
14 Lóòótọ́ wọ́n dàbí ìṣẹ́pẹ́ igi; iná ni yóò jó wọn dànù. Wọn kò kúkú lè gba ara wọn là lọ́wọ́ agbára iná náà. Kò sí èédú láti mú ara ẹnikẹ́ni gbóná níhìn-ín kò sí iná tí ènìyàn le jókòó tì.
Voici, ils sont devenus comme de la paille, le feu les a brûlés; ils ne délivreront point leur âme de la puissance de la flamme; il n'y a point de charbons pour se chauffer, et il n'y a point de lueur [de feu] pour s'asseoir vis-à-vis.
15 Gbogbo ohun tí wọ́n lè ṣe fún ọ nìyìí gbogbo èyí ní o tí ṣíṣẹ́ pẹ̀lú u rẹ̀ tí o sì ti ń rù kiri láti ìgbà èwe. Ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn ń lọ nínú àṣìṣe rẹ̀; kò sí ẹyọ ẹnìkan tí ó lè gbà ọ́.
Tels te sont devenus ceux après lesquels tu as travaillé, et avec lesquels tu as trafiqué dès ta jeunesse; chacun s'en est fui en son quartier comme un vagabond; il n'y a personne qui te délivre.

< Isaiah 47 >