< Isaiah 46 >

1 Beli tẹrí i rẹ̀ ba, Nebo bẹ̀rẹ̀ mọ́lẹ̀; àwọn ère wọn ni àwọn ẹranko rù. Àwọn ère tí wọ́n ń rù káàkiri ti di àjàgà sí wọn lọ́rùn, ẹrù fún àwọn tí àárẹ̀ mú.
Bel bolsa tiz pükti, Nébo éngishiwatidu; Ularning mebudliri ulaghlarning zémmisige, kalilarning zimmisige chüshti; Siler kötürgen nersiliringlar emdi ulaghlargha artilghan bolup, Halsiz ulaghlargha éghir yük bolidu!
2 Wọ́n bẹ̀rẹ̀ wọ́n sì foríbalẹ̀ papọ̀; wọn kò lè gba ẹrù náà, àwọn pẹ̀lú ni a kó lọ ní ìgbèkùn.
Ular éngishidu, birlikte tiz pükishidu; Ular mushu yükni qutquzalmaydu, Belki özliri esirge chüshidu.
3 “Tẹ́tí sí mi, ìwọ ilé Jakọbu, gbogbo ẹ̀yin tí ó ṣẹ́kù nínú ilé Israẹli, ìwọ tí mo ti gbéró láti ìgbà tí o ti wà nínú oyún, tí mo sì ti ń pọ̀n láti ìgbà tí a ti bí ọ.
I Yaqupning jemeti, Shundaqla Israil jemetining qaldisi, Ananglarning qorsiqidiki chaghdin tartip üstümge artilghanlar, Baliyatqudiki chaghdin tartip kötürülüp kelgenler, — Manga qulaq sélinglar!
4 Pẹ̀lúpẹ̀lú sí àwọn arúgbó àti ewú orí yín, Èmi ni ẹni náà, Èmi ni ẹni tí yóò gbé ọ ró. Èmi ti mọ ọ́, èmi yóò sì gbé ọ; Èmi yóò dì ọ́ mú èmi ó sì gbà ọ́ sílẹ̀.
Siler qérighuchimu Men yenila shundaqturmen, Chéchinglar aqarghuchimu Men silerni yüdüp yürimen; Silerni yasighan Mendurmen, silerni kötürimen; Silerni yüdüp qutquzimen.
5 “Ta ni ìwọ yóò fi mí wé tàbí ta ni èmi yóò bá dọ́gba? Ta ni ìwọ yóò fi ṣe àkàwé mi tí àwa yóò jọ fi ara wé ara?
Emdi Méni kimge oxshatmaqchi, Yaki kimni Manga teng qilmaqchisiler? Uni Manga oxshash dep, Siler kimni Men bilen sélishturmaqchisiler?
6 Ọ̀pọ̀ da wúrà sílẹ̀ nínú àpò wọn wọ́n sì wọn fàdákà lórí òsùwọ̀n; wọ́n bẹ alágbẹ̀dẹ lọ́wẹ̀ láti fi wọ́n ṣe òrìṣà, wọn sì tẹríba láti sìn ín.
Ular bolsa hemyanidin altunni chéchip bérip, Kümüshnimu tarazigha salidu, Bir zergerni yalliwalidu, U bir mebudni yasap béridu; Ular yiqilidu, derweqe choqunidu!
7 Wọ́n gbé e lé èjìká wọn, wọ́n rù wọ́n, wọ́n sì gbé e sí ààyè rẹ̀ níbẹ̀ ni ó sì dúró sí. Láti ibẹ̀ náà kò le è paradà. Bí ènìyàn tilẹ̀ pariwo lé e lórí, òun kò le è dáhùn; òun kò lè gbà á nínú ìyọnu rẹ̀.
Ular uni mürisige artidu, Uni kötürüp, öz ornigha qoyidu; Andin u ashu yerde öre turidu; U ornidin qozghilalmaydu; Birsi uninggha yélinip tileydu, Lékin u jawab bermeydu; U kishini awarichilikidin qutquzmaydu.
8 “Rántí èyí, fi í sí ọkàn rẹ, fi sí ọkàn rẹ, ẹ̀yin ọlọ̀tẹ̀.
Mushu ishlarni ésinglarda tutunglar; Shundaqla özünglarni heqiqiy erkeklerdek körsitinglar; I, itaetsizler, Buni ésinglargha keltürünglar;
9 Rántí àwọn nǹkan àtẹ̀yìnwá, àwọn ti àtijọ́-tijọ́; Èmi ni Ọlọ́run, kò sì sí ẹlòmíràn; Èmi ni Ọlọ́run, kò sí ẹlòmíràn bí ì mi.
Ilgiriki ishlarni, yeni qedimdin bolghan ishlarni ésinglargha keltürünglar; Chünki Men Tengridurmen, bashqa biri yoqtur; Men Xudadurmen, Manga oxshashlar yoqtur;
10 Mo fi òpin hàn láti ìbẹ̀rẹ̀ wá, láti àtètèkọ́ṣe, ohun tí ó sì ń bọ̀ wá. Mo wí pé, Ète mi yóò dúró, àti pé èmi yóò ṣe ohun tí ó wù mí.
Men: «Méning békitkinim orunlinidu, Könglümge barliq pükkenlerni emelge ashurmay qoymaymen» dep, Ishning netijisini bashtila, Aldin’ala téxi qilinmighan ishlarni ayan qilip éytquchidurmen;
11 Láti ìlà-oòrùn wá ni mo ti pe ẹyẹ ajẹran wá; láti ọ̀nà jíjìn réré, ọkùnrin kan tí yóò mú ète mi ṣẹ. Ohun tí mo ti sọ, òun ni èmi yóò mú ṣẹ; èyí tí mo ti gbèrò, òun ni èmi yóò ṣe.
Künchiqishtin yirtquch bir qushni, Yeni könglümge pükkinimni ada qilghuchi bir ademni yiraq yurttin chaqirghuchidurmen. Berheq, Men söz qilghan, Berheq, Men uni choqum emelge ashurimen; Buni niyet qilghanmen, Berheq, Men uni wujudqa chiqirimen.
12 Gbọ́ tèmi, ẹ̀yin alágídí ọkàn, ìwọ tí ó jìnnà sí òdodo.
I heqqaniyliqtin yiraq ketken jahillar, Manga qulaq sélinglar: —
13 Èmi ń mú òdodo mi bọ̀ nítòsí, kò tilẹ̀ jìnnà rárá; àti ìgbàlà mi ni a kì yóò dádúró. Èmi yóò fún Sioni ní ìgbàlà ògo mi fún Israẹli.
Men heqqaniyliqimni yéqin qilimen, U yiraqlashmaydu; Shuningdek Méning nijatim hem kéchikmeydu; Men Zion’gha nijat yetküzüp, Israilgha julaliq-güzellikimni tiklep bérimen».

< Isaiah 46 >