< Isaiah 46 >

1 Beli tẹrí i rẹ̀ ba, Nebo bẹ̀rẹ̀ mọ́lẹ̀; àwọn ère wọn ni àwọn ẹranko rù. Àwọn ère tí wọ́n ń rù káàkiri ti di àjàgà sí wọn lọ́rùn, ẹrù fún àwọn tí àárẹ̀ mú.
KE kukuli nei o Bela, ke kulou nei o Nebo, Aia hoi ko lakou akuakii maluna o na holoholona a me na mea laka; Ua kaumaha loa ko oukou mea lawe, He ukana kaumaha i ka mea i maloeloe.
2 Wọ́n bẹ̀rẹ̀ wọ́n sì foríbalẹ̀ papọ̀; wọn kò lè gba ẹrù náà, àwọn pẹ̀lú ni a kó lọ ní ìgbèkùn.
Kulou no lakou, a kukuli pu no hoi ilalo; Aole hiki ia lakou ke hookuu i ka ukana, Ua hele no lakou iloko o ke pio ana.
3 “Tẹ́tí sí mi, ìwọ ilé Jakọbu, gbogbo ẹ̀yin tí ó ṣẹ́kù nínú ilé Israẹli, ìwọ tí mo ti gbéró láti ìgbà tí o ti wà nínú oyún, tí mo sì ti ń pọ̀n láti ìgbà tí a ti bí ọ.
E hoolohe mai oukou ia'u, e ko ka hale o Iakoba, A me ke koena a pau o ko ka hale o ka Iseraela, Ka poe i laweia e au mai ka opu mai, A kaikaiia hoi mai ka hanau ana mai.
4 Pẹ̀lúpẹ̀lú sí àwọn arúgbó àti ewú orí yín, Èmi ni ẹni náà, Èmi ni ẹni tí yóò gbé ọ ró. Èmi ti mọ ọ́, èmi yóò sì gbé ọ; Èmi yóò dì ọ́ mú èmi ó sì gbà ọ́ sílẹ̀.
A hiki i kou wa elemakule, owau no ia, A i ka wa e poohina'i, na'u no oe e lawe. Ua hana no owau, a na'a hoi e halihali; Na'u no e lawe, a na'u hoi e hoopakele.
5 “Ta ni ìwọ yóò fi mí wé tàbí ta ni èmi yóò bá dọ́gba? Ta ni ìwọ yóò fi ṣe àkàwé mi tí àwa yóò jọ fi ara wé ara?
Me wai oukou e hoohalike ai ia'u, a me ka hoopili ia'u? Me wai hoi maua e like ai?
6 Ọ̀pọ̀ da wúrà sílẹ̀ nínú àpò wọn wọ́n sì wọn fàdákà lórí òsùwọ̀n; wọ́n bẹ alágbẹ̀dẹ lọ́wẹ̀ láti fi wọ́n ṣe òrìṣà, wọn sì tẹríba láti sìn ín.
Ninini aku lakou i ke gula mawaho o ka eke, A kaupaona hoi i ke kala ma ka mea kaulike, A hoolimalima hoi i ka mea hana gula, A hana iho la oia ia mea, i akuakii; Kulou no lakou, a moe hoomana aku la,
7 Wọ́n gbé e lé èjìká wọn, wọ́n rù wọ́n, wọ́n sì gbé e sí ààyè rẹ̀ níbẹ̀ ni ó sì dúró sí. Láti ibẹ̀ náà kò le è paradà. Bí ènìyàn tilẹ̀ pariwo lé e lórí, òun kò le è dáhùn; òun kò lè gbà á nínú ìyọnu rẹ̀.
Kaikai no lakou ia ia ma ka poohiwi, Lawe lakou ia ia, a hooku ia ia ma kona wahi, a ku no ia; Aole ia e neenee, mai kona wahi ae: Oia, kahea aku kekahi ia ia, aole nae ia e ekemu mai, Aole hoi e hoopakele ia ia i kona popilikia.
8 “Rántí èyí, fi í sí ọkàn rẹ, fi sí ọkàn rẹ, ẹ̀yin ọlọ̀tẹ̀.
E hoomanao oukou i keia, a e hookanaka hoi; E hooeueu i ka manao, e ka poe hana hewa.
9 Rántí àwọn nǹkan àtẹ̀yìnwá, àwọn ti àtijọ́-tijọ́; Èmi ni Ọlọ́run, kò sì sí ẹlòmíràn; Èmi ni Ọlọ́run, kò sí ẹlòmíràn bí ì mi.
E hoomanao i na mea kahiko o kela wa mamua; No ka mea, owau no ke Akua, aohe mea e ae, Owau no ke Akua, aohe mea like me au,
10 Mo fi òpin hàn láti ìbẹ̀rẹ̀ wá, láti àtètèkọ́ṣe, ohun tí ó sì ń bọ̀ wá. Mo wí pé, Ète mi yóò dúró, àti pé èmi yóò ṣe ohun tí ó wù mí.
E hai ana i ka hope, mai kinohi mai, E hai ana hoi, mai kahiko loa mai, i na mea i hana ole ia, Me ka olelo iho, E kupaa ana ko'u manao, A e hana no hoi au i ko'u makemake a pau.
11 Láti ìlà-oòrùn wá ni mo ti pe ẹyẹ ajẹran wá; láti ọ̀nà jíjìn réré, ọkùnrin kan tí yóò mú ète mi ṣẹ. Ohun tí mo ti sọ, òun ni èmi yóò mú ṣẹ; èyí tí mo ti gbèrò, òun ni èmi yóò ṣe.
Hea aku no wau i ka manu huhu, mai ka hikina mai, I ke kanaka hoi a'u i manao ai, mai ka aina mamao aku; Oia, ua olelo no wau, a na'u hoi ia e hana; Ua manao no wau, a e hana io no hoi au ia.
12 Gbọ́ tèmi, ẹ̀yin alágídí ọkàn, ìwọ tí ó jìnnà sí òdodo.
E hoolohe mai oukou ia'u, e na mea i paakiki ka naau, Ka poe mamao loa aku i ka pono.
13 Èmi ń mú òdodo mi bọ̀ nítòsí, kò tilẹ̀ jìnnà rárá; àti ìgbàlà mi ni a kì yóò dádúró. Èmi yóò fún Sioni ní ìgbàlà ògo mi fún Israẹli.
Ke lawe aku nei au i ko'u pono a kokoke, Aole ia e mamao aku, aole hoi e hookaulua iho ko'u hoola: E haawi aku no au i ke ola ma Ziona, me ka Iseraela, ko'u mea e nani ai.

< Isaiah 46 >