< Isaiah 45 >
1 “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún ẹni òróró rẹ̀, sí Kirusi, ọwọ́ ọ̀tún ẹni tí mo dì mú láti dojú àwọn orílẹ̀-èdè bolẹ̀ níwájú rẹ̀ àti láti gba ohun ìjà àwọn ọba lọ́wọ́ wọn, láti ṣí àwọn ìlẹ̀kùn níwájú rẹ̀ tí ó fi jẹ́ pé a kì yóò ti àwọn ẹnu-ọ̀nà.
Аша ворбеште Домнул кэтре унсул Сэу, кэтре Чирус, пе каре-л цине де мынэ ка сэ добоаре нямуриле ынаинтя луй ши сэ дезлеӂе брыул ымпэрацилор, сэ-й дескидэ порциле, ка сэ ну се май ынкидэ:
2 Èmi yóò lọ síwájú rẹ, Èmi ó sì tẹ́ àwọn òkè ńlá pẹrẹsẹ Èmi yóò fọ gbogbo ẹnu-ọ̀nà idẹ èmi ó sì gé ọ̀pá irin.
„Еу вой мерӂе ынаинтя та, вой нетези друмуриле мунтоасе, вой сфэрыма ушиле де арамэ ши вой рупе зэвоареле де фер.
3 Èmi yóò sì fún ọ ní àwọn ọrọ̀ ibi òkùnkùn, ọrọ̀ tí a kó pamọ́ sí àwọn ibi tí ó fi ara sin, tó bẹ́ẹ̀ tí ìwọ yóò fi mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ẹni tí ó pè ọ́ pẹ̀lú orúkọ rẹ.
Ыць вой да вистиерий аскунсе, богэций ынгропате, ка сэ штий кэ Еу сунт Домнул, каре те кем пе нуме, Думнезеул луй Исраел.
4 Nítorí Jakọbu ìránṣẹ́ mi àti Israẹli ẹni tí mo yàn, Mo pè ọ́ pẹ̀lú orúkọ rẹ, mo sì gbé oyè kan kà ọ́ lórí bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ kò gbà mí.
Дин драгосте пентру робул Меу Иаков ши пентру Исраел, алесул Меу, те-ам кемат пе нуме, ць-ам ворбит ку бунэвоинцэ, ынаинте ка ту сэ Мэ куношть.
5 Èmi ni Olúwa, àti pé kò sí ẹlòmíràn; yàtọ̀ sí èmi kò sí ọlọ́run kan, Èmi yóò fún ọ ní okun, bí o kò tilẹ̀ tí ì gbà mí,
Еу сунт Домнул, ши ну май есте алтул; афарэ де Мине, ну есте Думнезеу. Еу те-ам ынчинс ынаинте ка ту сэ Мэ куношть,
6 tí o fi jẹ́ pé láti ìlà-oòrùn títí dé ibi ìwọ̀ rẹ̀ kí ènìyàn le mọ̀, kò sí ẹnìkan lẹ́yìn mi. Èmi ni Olúwa, lẹ́yìn mi kò sí ẹlòmíràn mọ́.
ка сэ се штие, де ла рэсэритул соарелуй пынэ ла апусул соарелуй, кэ, афарэ де Мине ну есте Думнезеу: Еу сунт Домнул, ши ну есте алтул.
7 Mo dá ìmọ́lẹ̀, mo sì dá òkùnkùn, Mo mú àlàáfíà wá, Mo sì dá àjálù; Èmi Olúwa ni ó ṣe nǹkan wọ̀nyí.
Еу ынтокмеск лумина ши фак ынтунерикул, Еу дау пропэширя ши адук рестриштя, Еу, Домнул, фак тоате ачесте лукрурь.
8 “Ìwọ ọ̀run lókè rọ òjò òdodo sílẹ̀; jẹ́ kí àwọsánmọ̀ kí ó rọ̀ ọ́ sílẹ̀. Jẹ́ kí ilẹ̀ kí ó yanu gbagada, jẹ́ kí ìgbàlà kí ó dìde sókè, jẹ́ kí òdodo kí ó dàgbà pẹ̀lú rẹ̀; Èmi Olúwa ni ó ti dá a.
Сэ пикуре черуриле де сус ши сэ плоуэ норий неприхэниря! Сэ се дескидэ пэмынтул, сэ дя дин ел мынтуиря ши сэ ясэ тотодатэ дин ел избэвиря! Еу, Домнул, фак ачесте лукрурь.
9 “Ègbé ni fún ènìyàn tí ó ń bá Ẹlẹ́dàá rẹ̀ jà, ẹni tí òun jẹ́ àpáàdì kan láàrín àwọn àpáàdì tí ó wà lórí ilẹ̀. Ǹjẹ́ amọ̀ lè sọ fún amọ̀kòkò, pé: ‘Kí ni ohun tí ò ń ṣe?’ Ǹjẹ́ iṣẹ́ rẹ lè sọ pé, ‘Òun kò ní ọwọ́?’ ()
Вай де чине се чартэ ку Фэкэторул сэу! Ун чоб динтре чобуриле пэмынтулуй! Оаре лутул зиче ел челуй че-л фэцуеште: ‘Че фачь?’ ши лукраря та зиче еа деспре тине: ‘Ел н-аре мынь’?
10 Ègbé ni fún ẹni tí ó sọ fún baba rẹ̀ pé, ‘Kí ni o bí?’ tàbí sí ìyá rẹ̀, ‘Kí ni ìwọ ti bí?’
Вай де чине зиче татэлуй сэу: ‘Пентру че м-ай нэскут?’ ши мамей сале: ‘Пентру че м-ай фэкут?’”
11 “Ohun tí Olúwa wí nìyìí, Ẹni Mímọ́ Israẹli, àti Ẹlẹ́dàá rẹ̀. Nípa ohun tí ó ń bọ̀, ǹjẹ́ o ń bi mí léèrè nípa àwọn ọmọ mi, tàbí kí o pàṣẹ fún mi nípa iṣẹ́ ọwọ́ mi bí?
Аша ворбеште Домнул, Сфынтул луй Исраел ши Фэкэторул сэу: „Вря чинева сэ Мэ ынтребе асупра вииторулуй, сэ-Мь порунчяскэ пентру копиий Мей ши пентру лукраря мынилор Меле?
12 Èmi ni ẹni tí ó dá ilẹ̀ ayé tí ó sì da ọmọ ènìyàn sórí i rẹ̀. Ọwọ́ mi ni ó ti ta àwọn ọ̀run; mo sì kó àwọn àgbájọ ìràwọ̀ rẹ̀ síta.
Еу ам фэкут пэмынтул ши ам фэкут пе ом пе ел; Еу, ку мыниле Меле, ам ынтинс черуриле ши ам ашезат тоатэ оштиря лор.
13 Èmi yóò gbé Kirusi sókè nínú òdodo mi. Èmi yóò mú kí gbogbo ọ̀nà rẹ̀ kí ó tọ́. Òun yóò tún ìlú mi kọ́ yóò sì tú àwọn àtìpó mi sílẹ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe fún owó tàbí ẹ̀bùn kan, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.”
Еу ам ридикат пе Чирус ын дрептатя Мя ши вой нетези тоате кэрэриле луй. Ел Ымь ва зиди ярэшь четатя ши ва да друмул приншилор Мей де рэзбой, фэрэ прец де рэскумпэраре ши фэрэ дарурь”, зиче Домнул оштирилор.
14 Ohun tí Olúwa wí nìyìí: “Àwọn èròjà ilẹ̀ Ejibiti àti àwọn ọjà ilẹ̀ Kuṣi, àti àwọn Sabeani— wọn yóò wá sọ́dọ̀ rẹ wọn yóò sì jẹ́ tìrẹ; wọn yóò máa wọ́ tẹ̀lé ọ lẹ́yìn, wọn yóò máa wá lọ́wọ̀ọ̀wọ́. Wọn yóò máa foríbalẹ̀ níwájú rẹ̀, wọn yóò sì máa bẹ̀bẹ̀ níwájú rẹ pé, ‘Nítòótọ́ Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ kò sì ṣí ẹlòmíràn; kò sí ọlọ́run mìíràn.’”
Аша ворбеште Домнул: „Кыштигуриле Еӂиптулуй ши негоцул Етиопией ши ал сабеенилор, оамень де статурэ ыналтэ, вор трече ла тине ши вор фи але тале. Попоареле ачестя вор мерӂе дупэ тине, вор трече ынлэнцуите, се вор ынкина ынаинтя та ши-ць вор зиче, ругынду-те: ‘Нумай ла тине Се афлэ Думнезеу ши ну есте алт Думнезеу афарэ де Ел.’”
15 Nítòótọ́ ìwọ jẹ́ Ọlọ́run tí ó fi ara rẹ̀ pamọ́, Ìwọ Ọlọ́run àti Olùgbàlà Israẹli,
Дар Ту ешть ун Думнезеу каре Те аскунзь, Ту, Думнезеул луй Исраел, Мынтуиторуле!
16 Gbogbo àwọn tí ó ń gbẹ́ ère ni ojú yóò tì wọn yóò sì kan àbùkù; gbogbo wọn ni yóò bọ́ sínú àbùkù papọ̀.
Тоць сунт рушинаць ши улуиць, тоць плякэ плинь де окарэ, фэуриторий идолилор.
17 Ṣùgbọ́n Israẹli ni a ó gbàlà láti ọwọ́ Olúwa pẹ̀lú ìgbàlà ayérayé; a kì yóò kàn yín lábùkù tàbí kí a dójútì yín, títí ayé àìnípẹ̀kun.
Дар Исраел ва фи мынтуит де Домнул ку о мынтуире вешникэ. Вой ну вець фи нич рушинаць, нич ынфрунтаць ын вечь.
18 Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa wí, ẹni tí ó dá àwọn ọ̀run, Òun ni Ọlọ́run; ẹni tí ó mọ tí ó sì dá ayé, Òun ló ṣe é; Òun kò dá a láti wà lófo, ṣùgbọ́n ó ṣe é kí a lè máa gbé ibẹ̀, Òun wí pé: “Èmi ni Olúwa, kò sì ṣí ẹlòmíràn.
Кэч аша ворбеште Домнул, Фэкэторул черурилор, сингурул Думнезеу, каре а ынтокмит пэмынтул, л-а фэкут ши л-а ынтэрит, л-а фэкут ну ка сэ фие пустиу, чи л-а ынтокмит ка сэ фие локуит: „Еу сунт Домнул, ши ну есте алтул!
19 Èmi kò sọ̀rọ̀ níbi tí ó fi ara sin, láti ibìkan ní ilẹ̀ òkùnkùn, Èmi kò tí ì sọ fún àwọn ìran Jakọbu pé, ‘Ẹ wá mi lórí asán.’ Èmi Olúwa sọ òtítọ́, Mo sì sọ èyí tí ó tọ̀nà.
Еу н-ам ворбит ын аскунс, ынтр-ун колц ынтунекос ал пэмынтулуй. Еу н-ам зис семинцей луй Иаков: ‘Кэутаци-Мэ ын задар!’ Еу, Домнул, спун че есте адевэрат, вестеск че есте дрепт.
20 “Ẹ kó ara yín jọ kí ẹ sì wá; ẹ kórajọ, ẹ̀yin ìsáǹsá láti àwọn orílẹ̀-èdè wá. Aláìmọ̀kan ni àwọn tí ó ń ru ère igi káàkiri, tí wọ́n gbàdúrà sí àwọn òrìṣà tí kò le gba ni.
Стрынӂеци-вэ, вениць ши апропияци-вэ ымпреунэ, вой, чей скэпаць динтре нямурь! Н-ау ничо причепере чей че ышь дук идолул де лемн ши кямэ пе ун думнезеу каре ну поате сэ-й мынтуяскэ.
21 Jẹ́ kí a mọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀, fihàn wá, jẹ́ kí wọn jọ dámọ̀ràn papọ̀. Ta ló ti sọ èyí lọ́jọ́ tí o ti pẹ́, ta ló ti wí èyí láti àtètèkọ́ṣe? Kì í ha á ṣe Èmi, Olúwa? Àti pé kò sí Ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn mi, Ọlọ́run olódodo àti olùgbàlà; kò sí ẹlòmíràn àfi èmi.
Спунеци-ле ши адучеци-й ынкоаче, ка сэ се сфэтуяскэ уний ку алций! Чине а пророчит ачесте лукрурь де ла ынчепут ши ле-а вестит демулт? Оаре ну Еу, Домнул? Ну есте алт Думнезеу декыт Мине, Еу сунт сингурул Думнезеу дрепт ши мынтуитор, алт Думнезеу афарэ де Мине ну есте.
22 “Yípadà sí mi kí a sì gbà ọ́ là, ẹ̀yin ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé; nítorí Èmi ni Ọlọ́run kò sì ṣí ẹlòmíràn.
Ынтоарчеци-вэ ла Мине, ши вець фи мынтуиць тоць чей че сунтець ла марӂиниле пэмынтулуй! Кэч Еу сунт Думнезеу, ши ну алтул.
23 Nípa èmi tìkára mi ni mo ti búra, ẹnu mi ni ó ti sọ ọ́ pẹ̀lú gbogbo ipá mi, ọ̀rọ̀ náà tí a kì yóò lè parẹ́. Níwájú mi ni gbogbo orúnkún yóò wólẹ̀; nípa mi ni gbogbo ahọ́n yóò búra.
Пе Мине Ынсумь Мэ жур, адевэрул есе дин гура Мя ши Кувынтул Меу ну ва фи луат ынапой: орьче ӂенункь се ва плека ынаинтя Мя ши орьче лимбэ ва жура пе Мине.
24 Wọn yóò sọ ní ti èmi, ‘Nínú Olúwa nìkan ni òdodo àti agbára wà.’” Gbogbo àwọn tí ó ti bínú sí; yóò wá sọ́dọ̀ rẹ̀ a ó sì dójútì wọn.
‘Нумай ын Домнул’, Ми се ва зиче, ‘локуеск дрептатя ши путеря; ла Ел вор вени ши вор фи ынфрунтаць тоць чей че ерау мынияць ымпотрива Луй.
25 Ṣùgbọ́n nínú Olúwa gbogbo àwọn ìran Israẹli ni a ó rí ní òdodo, a o sì gbé wọn ga.
Ын Домнул вор фи фэкуць неприхэниць ши прослэвиць тоць урмаший луй Исраел.’