< Isaiah 45 >

1 “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún ẹni òróró rẹ̀, sí Kirusi, ọwọ́ ọ̀tún ẹni tí mo dì mú láti dojú àwọn orílẹ̀-èdè bolẹ̀ níwájú rẹ̀ àti láti gba ohun ìjà àwọn ọba lọ́wọ́ wọn, láti ṣí àwọn ìlẹ̀kùn níwájú rẹ̀ tí ó fi jẹ́ pé a kì yóò ti àwọn ẹnu-ọ̀nà.
خداوند کوروش را برگزیده و به او توانایی بخشیده تا پادشاه شود و سرزمینها را فتح کند و پادشاهان مقتدر را شکست دهد. خداوند دروازه‌های بابِل را به روی او باز می‌کند؛ دیگر آنها بروی کوروش بسته نخواهند ماند.
2 Èmi yóò lọ síwájú rẹ, Èmi ó sì tẹ́ àwọn òkè ńlá pẹrẹsẹ Èmi yóò fọ gbogbo ẹnu-ọ̀nà idẹ èmi ó sì gé ọ̀pá irin.
خداوند می‌فرماید: «ای کوروش، من پیشاپیش تو حرکت می‌کنم، کوهها را صاف می‌کنم، دروازه‌های مفرغین و پشت‌بندهای آهنی را می‌شکنم.
3 Èmi yóò sì fún ọ ní àwọn ọrọ̀ ibi òkùnkùn, ọrọ̀ tí a kó pamọ́ sí àwọn ibi tí ó fi ara sin, tó bẹ́ẹ̀ tí ìwọ yóò fi mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ẹni tí ó pè ọ́ pẹ̀lú orúkọ rẹ.
گنجهای پنهان شده در تاریکی و ثروتهای نهفته را به تو می‌دهم. آنگاه خواهی فهمید که من یهوه، خدای اسرائیل هستم و تو را به نام خوانده‌ام.
4 Nítorí Jakọbu ìránṣẹ́ mi àti Israẹli ẹni tí mo yàn, Mo pè ọ́ pẹ̀lú orúkọ rẹ, mo sì gbé oyè kan kà ọ́ lórí bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ kò gbà mí.
من تو را برگزیده‌ام تا به اسرائیل که خدمتگزار من و قوم برگزیدهٔ من است یاری نمایی. هنگامی که تو هنوز مرا نمی‌شناختی، من تو را به نام خواندم.
5 Èmi ni Olúwa, àti pé kò sí ẹlòmíràn; yàtọ̀ sí èmi kò sí ọlọ́run kan, Èmi yóò fún ọ ní okun, bí o kò tilẹ̀ tí ì gbà mí,
من یهوه هستم و غیر از من خدایی نیست. زمانی که مرا نمی‌شناختی، من به تو توانایی بخشیدم،
6 tí o fi jẹ́ pé láti ìlà-oòrùn títí dé ibi ìwọ̀ rẹ̀ kí ènìyàn le mọ̀, kò sí ẹnìkan lẹ́yìn mi. Èmi ni Olúwa, lẹ́yìn mi kò sí ẹlòmíràn mọ́.
تا مردم سراسر جهان بدانند که غیر از من خدایی دیگر وجود ندارد، من یهوه هستم و دیگری نیست.
7 Mo dá ìmọ́lẹ̀, mo sì dá òkùnkùn, Mo mú àlàáfíà wá, Mo sì dá àjálù; Èmi Olúwa ni ó ṣe nǹkan wọ̀nyí.
من آفرینندهٔ نور و تاریکی هستم، من پدید آورندهٔ رویدادهای خوب و بد هستم. من که خداوند هستم همهٔ این چیزها را به وجود می‌آورم.
8 “Ìwọ ọ̀run lókè rọ òjò òdodo sílẹ̀; jẹ́ kí àwọsánmọ̀ kí ó rọ̀ ọ́ sílẹ̀. Jẹ́ kí ilẹ̀ kí ó yanu gbagada, jẹ́ kí ìgbàlà kí ó dìde sókè, jẹ́ kí òdodo kí ó dàgbà pẹ̀lú rẹ̀; Èmi Olúwa ni ó ti dá a.
ای آسمان، عدالت را از بالا بباران. زمین بشکافد تا نجات و عدالت با هم برویند. من که خداوند هستم اینها را آفریده‌ام.»
9 “Ègbé ni fún ènìyàn tí ó ń bá Ẹlẹ́dàá rẹ̀ jà, ẹni tí òun jẹ́ àpáàdì kan láàrín àwọn àpáàdì tí ó wà lórí ilẹ̀. Ǹjẹ́ amọ̀ lè sọ fún amọ̀kòkò, pé: ‘Kí ni ohun tí ò ń ṣe?’ Ǹjẹ́ iṣẹ́ rẹ lè sọ pé, ‘Òun kò ní ọwọ́?’ (questioned)
وای بر کسی که با خالق خود می‌جنگد! آیا کوزه با سازندهٔ خود مجادله می‌کند؟ آیا گل به کوزه‌گر می‌گوید: «این چیست که تو می‌سازی؟» یا کوزه سر او فریاد می‌زند: «چقدر بی‌مهارت هستی»؟
10 Ègbé ni fún ẹni tí ó sọ fún baba rẹ̀ pé, ‘Kí ni o bí?’ tàbí sí ìyá rẹ̀, ‘Kí ni ìwọ ti bí?’
وای بر فرزندی که به پدر و مادرش می‌گوید: «چرا مرا به این شکل به دنیا آوردید؟»
11 “Ohun tí Olúwa wí nìyìí, Ẹni Mímọ́ Israẹli, àti Ẹlẹ́dàá rẹ̀. Nípa ohun tí ó ń bọ̀, ǹjẹ́ o ń bi mí léèrè nípa àwọn ọmọ mi, tàbí kí o pàṣẹ fún mi nípa iṣẹ́ ọwọ́ mi bí?
خداوند، خدای مقدّس اسرائیل که آینده در دست اوست، می‌فرماید: «شما حق ندارید دربارهٔ آنچه به وجود آورده‌ام از من بازخواست کنید و یا به من بگویید که چه باید بکنم.
12 Èmi ni ẹni tí ó dá ilẹ̀ ayé tí ó sì da ọmọ ènìyàn sórí i rẹ̀. Ọwọ́ mi ni ó ti ta àwọn ọ̀run; mo sì kó àwọn àgbájọ ìràwọ̀ rẹ̀ síta.
من زمین را ساختم و انسان را بر روی آن خلق کردم. با دست خود آسمانها را گسترانیدم. ماه و خورشید و ستارگان زیر فرمان من هستند.
13 Èmi yóò gbé Kirusi sókè nínú òdodo mi. Èmi yóò mú kí gbogbo ọ̀nà rẹ̀ kí ó tọ́. Òun yóò tún ìlú mi kọ́ yóò sì tú àwọn àtìpó mi sílẹ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe fún owó tàbí ẹ̀bùn kan, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.”
اکنون نیز کوروش را برانگیخته‌ام تا به هدف عادلانهٔ من جامهٔ عمل بپوشاند. من تمام راههایش را راست خواهم ساخت. او بی‌آنکه انتظار پاداش داشته باشد، شهر من اورشلیم را بازسازی خواهد کرد و قوم اسیر مرا آزاد خواهد ساخت.» این است کلام خداوند لشکرهای آسمان.
14 Ohun tí Olúwa wí nìyìí: “Àwọn èròjà ilẹ̀ Ejibiti àti àwọn ọjà ilẹ̀ Kuṣi, àti àwọn Sabeani— wọn yóò wá sọ́dọ̀ rẹ wọn yóò sì jẹ́ tìrẹ; wọn yóò máa wọ́ tẹ̀lé ọ lẹ́yìn, wọn yóò máa wá lọ́wọ̀ọ̀wọ́. Wọn yóò máa foríbalẹ̀ níwájú rẹ̀, wọn yóò sì máa bẹ̀bẹ̀ níwájú rẹ pé, ‘Nítòótọ́ Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ kò sì ṣí ẹlòmíràn; kò sí ọlọ́run mìíràn.’”
خداوند به اسرائیل می‌فرماید: «مصری‌ها، حبشی‌ها، و مردم بلند قد سبا تابع تو خواهند شد و تمام کالاهای تجارتی آنان از آن تو خواهد گردید. آنان در زنجیرهای اسارت نزد تو خواهند آمد و در برابرت زانو زده، خواهند گفت:”یک خدا وجود دارد، آن هم خدای توست!
15 Nítòótọ́ ìwọ jẹ́ Ọlọ́run tí ó fi ara rẹ̀ pamọ́, Ìwọ Ọlọ́run àti Olùgbàlà Israẹli,
ای خدای نجا‌ت‌دهندۀ اسرائیل، براستی کارهایت شگفت‌انگیز است!“»
16 Gbogbo àwọn tí ó ń gbẹ́ ère ni ojú yóò tì wọn yóò sì kan àbùkù; gbogbo wọn ni yóò bọ́ sínú àbùkù papọ̀.
تمام پرستندگان بتها مأیوس و شرمسار خواهند شد.
17 Ṣùgbọ́n Israẹli ni a ó gbàlà láti ọwọ́ Olúwa pẹ̀lú ìgbàlà ayérayé; a kì yóò kàn yín lábùkù tàbí kí a dójútì yín, títí ayé àìnípẹ̀kun.
اما اسرائیل هرگز مأیوس و شرمسار نخواهد شد، زیرا خداوند نجات جاودانی نصیب او خواهد ساخت.
18 Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa wí, ẹni tí ó dá àwọn ọ̀run, Òun ni Ọlọ́run; ẹni tí ó mọ tí ó sì dá ayé, Òun ló ṣe é; Òun kò dá a láti wà lófo, ṣùgbọ́n ó ṣe é kí a lè máa gbé ibẹ̀, Òun wí pé: “Èmi ni Olúwa, kò sì ṣí ẹlòmíràn.
خداوند آسمانها و زمین را آفریده و آنها را استوار نموده است. او جهان را بیهوده نیافریده، بلکه برای سکونت و زندگی آن را ساخته است. او می‌فرماید: «من خداوند هستم و دیگری نیست!
19 Èmi kò sọ̀rọ̀ níbi tí ó fi ara sin, láti ibìkan ní ilẹ̀ òkùnkùn, Èmi kò tí ì sọ fún àwọn ìran Jakọbu pé, ‘Ẹ wá mi lórí asán.’ Èmi Olúwa sọ òtítọ́, Mo sì sọ èyí tí ó tọ̀nà.
من وعده‌هایم را واضح و روشن اعلام می‌کنم و در نهان سخن نمی‌گویم تا همه مقصود مرا بفهمند. من به اسرائیل گفته‌ام که آنچه را به ایشان وعده داده‌ام بی‌شک بجا خواهم آورد. من که یهوه هستم به راستی و صداقت سخن می‌گویم.
20 “Ẹ kó ara yín jọ kí ẹ sì wá; ẹ kórajọ, ẹ̀yin ìsáǹsá láti àwọn orílẹ̀-èdè wá. Aláìmọ̀kan ni àwọn tí ó ń ru ère igi káàkiri, tí wọ́n gbàdúrà sí àwọn òrìṣà tí kò le gba ni.
«ای قومهایی که از دست کوروش می‌گریزید، جمع شوید و نزدیک آیید و به سخنان من گوش دهید. چه نادانند آنانی که بتهای چوبی را با خود حمل می‌کنند و نزد خدایانی که نمی‌توانند نجاتشان دهند، دعا می‌کنند.
21 Jẹ́ kí a mọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀, fihàn wá, jẹ́ kí wọn jọ dámọ̀ràn papọ̀. Ta ló ti sọ èyí lọ́jọ́ tí o ti pẹ́, ta ló ti wí èyí láti àtètèkọ́ṣe? Kì í ha á ṣe Èmi, Olúwa? Àti pé kò sí Ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn mi, Ọlọ́run olódodo àti olùgbàlà; kò sí ẹlòmíràn àfi èmi.
با هم مشورت کنید، و اگر می‌توانید دلیل بیاورید و ثابت کنید که بت‌پرستی عمل درستی است! غیر از من که یهوه هستم، چه کسی گفته که این چیزها در مورد کوروش عملی خواهد شد؟ غیر از من خدایی نیست. من خدای عادل و نجات دهنده هستم و دیگری نیست! تا حال کدام بت به شما گفته است که این وقایع رخ خواهند داد؟
22 “Yípadà sí mi kí a sì gbà ọ́ là, ẹ̀yin ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé; nítorí Èmi ni Ọlọ́run kò sì ṣí ẹlòmíràn.
ای تمام ساکنان زمین نزد من آیید تا نجات یابید، زیرا من خدا هستم و خدایی دیگر نیست.
23 Nípa èmi tìkára mi ni mo ti búra, ẹnu mi ni ó ti sọ ọ́ pẹ̀lú gbogbo ipá mi, ọ̀rọ̀ náà tí a kì yóò lè parẹ́. Níwájú mi ni gbogbo orúnkún yóò wólẹ̀; nípa mi ni gbogbo ahọ́n yóò búra.
به ذات خود قسم خورده‌ام و هرگز از قسم خود برنمی‌گردم که هر زانویی در برابر من خم خواهد شد و هر زبانی به من سوگند وفاداری یاد خواهد کرد.
24 Wọn yóò sọ ní ti èmi, ‘Nínú Olúwa nìkan ni òdodo àti agbára wà.’” Gbogbo àwọn tí ó ti bínú sí; yóò wá sọ́dọ̀ rẹ̀ a ó sì dójútì wọn.
«مردم خواهند گفت:”عدالت و قوت ما از خداوند است.“و کسانی که از من خشمناک بودند، شرمنده خواهند شد.
25 Ṣùgbọ́n nínú Olúwa gbogbo àwọn ìran Israẹli ni a ó rí ní òdodo, a o sì gbé wọn ga.
من تمام بنی‌اسرائیل را نجات خواهم داد و آنان مرا ستایش خواهند کرد.»

< Isaiah 45 >