< Isaiah 45 >

1 “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún ẹni òróró rẹ̀, sí Kirusi, ọwọ́ ọ̀tún ẹni tí mo dì mú láti dojú àwọn orílẹ̀-èdè bolẹ̀ níwájú rẹ̀ àti láti gba ohun ìjà àwọn ọba lọ́wọ́ wọn, láti ṣí àwọn ìlẹ̀kùn níwájú rẹ̀ tí ó fi jẹ́ pé a kì yóò ti àwọn ẹnu-ọ̀nà.
خداوند به مسیح خویش یعنی به کورش که دست راست او را گرفتم تا به حضور وی امت‌ها را مغلوب سازم و کمرهای پادشاهان را بگشایم تا درها را به حضور وی مفتوح نمایم و دروازه‌ها دیگر بسته نشود چنین می‌گوید۱
2 Èmi yóò lọ síwájú rẹ, Èmi ó sì tẹ́ àwọn òkè ńlá pẹrẹsẹ Èmi yóò fọ gbogbo ẹnu-ọ̀nà idẹ èmi ó sì gé ọ̀pá irin.
که «من پیش روی تو خواهم خرامید وجایهای ناهموار را هموار خواهم ساخت. ودرهای برنجین را شکسته، پشت بندهای آهنین راخواهم برید.۲
3 Èmi yóò sì fún ọ ní àwọn ọrọ̀ ibi òkùnkùn, ọrọ̀ tí a kó pamọ́ sí àwọn ibi tí ó fi ara sin, tó bẹ́ẹ̀ tí ìwọ yóò fi mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ẹni tí ó pè ọ́ pẹ̀lú orúkọ rẹ.
و گنجهای ظلمت و خزاین مخفی را به تو خواهم بخشید تا بدانی که من یهوه که تو رابه اسمت خوانده‌ام خدای اسرائیل می‌باشم.۳
4 Nítorí Jakọbu ìránṣẹ́ mi àti Israẹli ẹni tí mo yàn, Mo pè ọ́ pẹ̀lú orúkọ rẹ, mo sì gbé oyè kan kà ọ́ lórí bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ kò gbà mí.
به‌خاطر بنده خود یعقوب و برگزیده خویش اسرائیل، هنگامی که مرا نشناختی تو را به اسمت خواندم و ملقب ساختم.۴
5 Èmi ni Olúwa, àti pé kò sí ẹlòmíràn; yàtọ̀ sí èmi kò sí ọlọ́run kan, Èmi yóò fún ọ ní okun, bí o kò tilẹ̀ tí ì gbà mí,
من یهوه هستم ودیگری نیست و غیر از من خدایی نی. من کمر تورا بستم هنگامی که مرا نشناختی.۵
6 tí o fi jẹ́ pé láti ìlà-oòrùn títí dé ibi ìwọ̀ rẹ̀ kí ènìyàn le mọ̀, kò sí ẹnìkan lẹ́yìn mi. Èmi ni Olúwa, lẹ́yìn mi kò sí ẹlòmíràn mọ́.
تا از مشرق آفتاب و مغرب آن بدانند که سوای من احدی نیست. من یهوه هستم و دیگری نی.۶
7 Mo dá ìmọ́lẹ̀, mo sì dá òkùnkùn, Mo mú àlàáfíà wá, Mo sì dá àjálù; Èmi Olúwa ni ó ṣe nǹkan wọ̀nyí.
پدیدآورنده نور و آفریننده ظلمت. صانع سلامتی وآفریننده بدی. من یهوه صانع همه این چیزها هستم.۷
8 “Ìwọ ọ̀run lókè rọ òjò òdodo sílẹ̀; jẹ́ kí àwọsánmọ̀ kí ó rọ̀ ọ́ sílẹ̀. Jẹ́ kí ilẹ̀ kí ó yanu gbagada, jẹ́ kí ìgbàlà kí ó dìde sókè, jẹ́ kí òdodo kí ó dàgbà pẹ̀lú rẹ̀; Èmi Olúwa ni ó ti dá a.
‌ای آسمانها از بالا ببارانید تا افلاک عدالت را فرو ریزد و زمین بشکافد تا نجات وعدالت نمو کنند و آنها را با هم برویاند زیرا که من یهوه این را آفریده‌ام.۸
9 “Ègbé ni fún ènìyàn tí ó ń bá Ẹlẹ́dàá rẹ̀ jà, ẹni tí òun jẹ́ àpáàdì kan láàrín àwọn àpáàdì tí ó wà lórí ilẹ̀. Ǹjẹ́ amọ̀ lè sọ fún amọ̀kòkò, pé: ‘Kí ni ohun tí ò ń ṣe?’ Ǹjẹ́ iṣẹ́ rẹ lè sọ pé, ‘Òun kò ní ọwọ́?’ (questioned)
وای برکسی‌که با صانع خود چون سفالی با سفالهای زمین مخاصمه نماید. آیا کوزه به کوزه‌گر بگوید چه چیز راساختی؟ یا مصنوع تو درباره تو بگوید که اودست ندارد؟۹
10 Ègbé ni fún ẹni tí ó sọ fún baba rẹ̀ pé, ‘Kí ni o bí?’ tàbí sí ìyá rẹ̀, ‘Kí ni ìwọ ti bí?’
وای بر کسی‌که به پدر خودگوید: چه چیز را تولید نمودی و به زن که چه زاییدی.۱۰
11 “Ohun tí Olúwa wí nìyìí, Ẹni Mímọ́ Israẹli, àti Ẹlẹ́dàá rẹ̀. Nípa ohun tí ó ń bọ̀, ǹjẹ́ o ń bi mí léèrè nípa àwọn ọmọ mi, tàbí kí o pàṣẹ fún mi nípa iṣẹ́ ọwọ́ mi bí?
خداوند که قدوس اسرائیل و صانع آن می‌باشد چنین می‌گوید: درباره امور آینده ازمن سوال نمایید و پسران مرا و اعمال دستهای مرابه من تفویض نمایید.۱۱
12 Èmi ni ẹni tí ó dá ilẹ̀ ayé tí ó sì da ọmọ ènìyàn sórí i rẹ̀. Ọwọ́ mi ni ó ti ta àwọn ọ̀run; mo sì kó àwọn àgbájọ ìràwọ̀ rẹ̀ síta.
من زمین را ساختم وانسان را بر آن آفریدم. دستهای من آسمانها راگسترانید و من تمامی لشکرهای آنها را امرفرمودم.۱۲
13 Èmi yóò gbé Kirusi sókè nínú òdodo mi. Èmi yóò mú kí gbogbo ọ̀nà rẹ̀ kí ó tọ́. Òun yóò tún ìlú mi kọ́ yóò sì tú àwọn àtìpó mi sílẹ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe fún owó tàbí ẹ̀bùn kan, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.”
من او را به عدالت برانگیختم و تمامی راههایش را راست خواهم ساخت. شهر مرا بناکرده، اسیرانم را آزاد خواهد نمود، اما نه برای قیمت و نه برای هدیه. یهوه صبایوت این رامی گوید.»۱۳
14 Ohun tí Olúwa wí nìyìí: “Àwọn èròjà ilẹ̀ Ejibiti àti àwọn ọjà ilẹ̀ Kuṣi, àti àwọn Sabeani— wọn yóò wá sọ́dọ̀ rẹ wọn yóò sì jẹ́ tìrẹ; wọn yóò máa wọ́ tẹ̀lé ọ lẹ́yìn, wọn yóò máa wá lọ́wọ̀ọ̀wọ́. Wọn yóò máa foríbalẹ̀ níwájú rẹ̀, wọn yóò sì máa bẹ̀bẹ̀ níwájú rẹ pé, ‘Nítòótọ́ Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ kò sì ṣí ẹlòmíràn; kò sí ọlọ́run mìíràn.’”
خداوند چنین می‌گوید: «حاصل مصر وتجارت حبش و اهل سبا که مردان بلند قدمی باشند نزد تو عبور نموده، از آن تو خواهندبود. و تابع تو شده در زنجیرها خواهند آمد وپیش تو خم شده و نزد تو التماس نموده، خواهندگفت: البته خدا در تو است و دیگری نیست وخدایی نی.»۱۴
15 Nítòótọ́ ìwọ jẹ́ Ọlọ́run tí ó fi ara rẹ̀ pamọ́, Ìwọ Ọlọ́run àti Olùgbàlà Israẹli,
‌ای خدای اسرائیل و نجات‌دهنده یقین خدایی هستی که خود را پنهان می‌کنی.۱۵
16 Gbogbo àwọn tí ó ń gbẹ́ ère ni ojú yóò tì wọn yóò sì kan àbùkù; gbogbo wọn ni yóò bọ́ sínú àbùkù papọ̀.
جمیع ایشان خجل و رسوا خواهندشد و آنانی که بتها می‌سازند با هم به رسوایی خواهند رفت.۱۶
17 Ṣùgbọ́n Israẹli ni a ó gbàlà láti ọwọ́ Olúwa pẹ̀lú ìgbàlà ayérayé; a kì yóò kàn yín lábùkù tàbí kí a dójútì yín, títí ayé àìnípẹ̀kun.
اما اسرائیل به نجات جاودانی از خداوند ناجی خواهند شد و تا ابدالاباد خجل و رسوا نخواهند گردید.۱۷
18 Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa wí, ẹni tí ó dá àwọn ọ̀run, Òun ni Ọlọ́run; ẹni tí ó mọ tí ó sì dá ayé, Òun ló ṣe é; Òun kò dá a láti wà lófo, ṣùgbọ́n ó ṣe é kí a lè máa gbé ibẹ̀, Òun wí pé: “Èmi ni Olúwa, kò sì ṣí ẹlòmíràn.
زیرا یهوه آفریننده آسمان که خدا است که زمین را سرشت و ساخت و آن را استوار نمود و آن را عبث نیافرید بلکه به جهت سکونت مصور نمود چنین می‌گوید: «من یهوه هستم و دیگری نیست.۱۸
19 Èmi kò sọ̀rọ̀ níbi tí ó fi ara sin, láti ibìkan ní ilẹ̀ òkùnkùn, Èmi kò tí ì sọ fún àwọn ìran Jakọbu pé, ‘Ẹ wá mi lórí asán.’ Èmi Olúwa sọ òtítọ́, Mo sì sọ èyí tí ó tọ̀nà.
در خفا و درجایی از زمین تاریک تکلم ننمودم. و به ذریه یعقوب نگفتم که مرا عبث بطلبید. من یهوه به عدالت سخن می‌گویم و چیزهای راست را اعلان می‌نمایم.۱۹
20 “Ẹ kó ara yín jọ kí ẹ sì wá; ẹ kórajọ, ẹ̀yin ìsáǹsá láti àwọn orílẹ̀-èdè wá. Aláìmọ̀kan ni àwọn tí ó ń ru ère igi káàkiri, tí wọ́n gbàdúrà sí àwọn òrìṣà tí kò le gba ni.
‌ای رهاشدگان از امت‌ها جمع شده، بیایید و با هم نزدیک شوید. آنانی که چوب بتهای خود را برمی دارند و نزد خدایی که نتواند رهانیددعا می‌نمایند معرفت ندارند.۲۰
21 Jẹ́ kí a mọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀, fihàn wá, jẹ́ kí wọn jọ dámọ̀ràn papọ̀. Ta ló ti sọ èyí lọ́jọ́ tí o ti pẹ́, ta ló ti wí èyí láti àtètèkọ́ṣe? Kì í ha á ṣe Èmi, Olúwa? Àti pé kò sí Ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn mi, Ọlọ́run olódodo àti olùgbàlà; kò sí ẹlòmíràn àfi èmi.
پس اعلان نموده، ایشان را نزدیک آورید تا با یکدیگرمشورت نمایند. کیست که این را از ایام قدیم اعلان نموده و از زمان سلف اخبار کرده است؟ آیا نه من که یهوه هستم و غیر از من خدایی دیگرنیست؟ خدای عادل و نجات‌دهنده و سوای من نیست.۲۱
22 “Yípadà sí mi kí a sì gbà ọ́ là, ẹ̀yin ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé; nítorí Èmi ni Ọlọ́run kò sì ṣí ẹlòmíràn.
‌ای جمیع کرانه های زمین به من توجه نمایید و نجات یابید زیرا من خدا هستم و دیگری نیست.۲۲
23 Nípa èmi tìkára mi ni mo ti búra, ẹnu mi ni ó ti sọ ọ́ pẹ̀lú gbogbo ipá mi, ọ̀rọ̀ náà tí a kì yóò lè parẹ́. Níwájú mi ni gbogbo orúnkún yóò wólẹ̀; nípa mi ni gbogbo ahọ́n yóò búra.
به ذات خود قسم خوردم و این کلام به عدالت از دهانم صادر گشته برنخواهد گشت که هر زانو پیش من خم خواهد شد و هر زبان به من قسم خواهد خورد.۲۳
24 Wọn yóò sọ ní ti èmi, ‘Nínú Olúwa nìkan ni òdodo àti agbára wà.’” Gbogbo àwọn tí ó ti bínú sí; yóò wá sọ́dọ̀ rẹ̀ a ó sì dójútì wọn.
و مرا خواهند گفت عدالت و قوت فقط در خداوند می‌باشد» و بسوی او خواهند آمد و همگانی که به او خشمناکندخجل خواهند گردید. و تمامی ذریت اسرائیل در خداوند عادل شمرده شده، فخر خواهندکرد.۲۴
25 Ṣùgbọ́n nínú Olúwa gbogbo àwọn ìran Israẹli ni a ó rí ní òdodo, a o sì gbé wọn ga.
۲۵

< Isaiah 45 >