< Isaiah 45 >

1 “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún ẹni òróró rẹ̀, sí Kirusi, ọwọ́ ọ̀tún ẹni tí mo dì mú láti dojú àwọn orílẹ̀-èdè bolẹ̀ níwájú rẹ̀ àti láti gba ohun ìjà àwọn ọba lọ́wọ́ wọn, láti ṣí àwọn ìlẹ̀kùn níwájú rẹ̀ tí ó fi jẹ́ pé a kì yóò ti àwọn ẹnu-ọ̀nà.
Tā saka Tas Kungs uz savu svaidīto, Kiru: Es to satveru pie viņa labās rokas, ka Es tautas viņa priekšā metu pie zemes, un atraisu ķēniņu jostas, un atdaru priekš viņa durvis, un vārti nepaliek aizslēgti.
2 Èmi yóò lọ síwájú rẹ, Èmi ó sì tẹ́ àwọn òkè ńlá pẹrẹsẹ Èmi yóò fọ gbogbo ẹnu-ọ̀nà idẹ èmi ó sì gé ọ̀pá irin.
Es iešu tavā priekšā un darīšu līdzenus nelīdzenos ceļus, es salauzīšu vara durvis un sadauzīšu dzelzs aizšaujamos.
3 Èmi yóò sì fún ọ ní àwọn ọrọ̀ ibi òkùnkùn, ọrọ̀ tí a kó pamọ́ sí àwọn ibi tí ó fi ara sin, tó bẹ́ẹ̀ tí ìwọ yóò fi mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ẹni tí ó pè ọ́ pẹ̀lú orúkọ rẹ.
Un Es tev došu mantas, kas tumsā, un apslēpto bagātību, lai tu atzīsti, ka Es esmu Tas Kungs, kas tevi sauc pie vārda, tas Israēla Dievs,
4 Nítorí Jakọbu ìránṣẹ́ mi àti Israẹli ẹni tí mo yàn, Mo pè ọ́ pẹ̀lú orúkọ rẹ, mo sì gbé oyè kan kà ọ́ lórí bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ kò gbà mí.
Jēkaba, Mana kalpa dēļ, un Israēla, Mana izredzētā, dēļ. Un Es tevi saucu pie tava vārda, Es tevi mīlīgi uzrunāju, kad tu Mani vēl nepazini.
5 Èmi ni Olúwa, àti pé kò sí ẹlòmíràn; yàtọ̀ sí èmi kò sí ọlọ́run kan, Èmi yóò fún ọ ní okun, bí o kò tilẹ̀ tí ì gbà mí,
Es esmu Tas Kungs, un cits neviens, dieva nav, kā Es vien. Es tevi esmu apjozis, jebšu tu Mani nepazini,
6 tí o fi jẹ́ pé láti ìlà-oòrùn títí dé ibi ìwọ̀ rẹ̀ kí ènìyàn le mọ̀, kò sí ẹnìkan lẹ́yìn mi. Èmi ni Olúwa, lẹ́yìn mi kò sí ẹlòmíràn mọ́.
Lai zināms top no saules uzlēkšanas un noiešanas, ka neviena nav bez Manis: Es esmu Tas Kungs, un cits neviens.
7 Mo dá ìmọ́lẹ̀, mo sì dá òkùnkùn, Mo mú àlàáfíà wá, Mo sì dá àjálù; Èmi Olúwa ni ó ṣe nǹkan wọ̀nyí.
Es ceļu gaismu un radu tumsu, Es daru mieru un radu ļaunumu. Es Tas Kungs daru to visu.
8 “Ìwọ ọ̀run lókè rọ òjò òdodo sílẹ̀; jẹ́ kí àwọsánmọ̀ kí ó rọ̀ ọ́ sílẹ̀. Jẹ́ kí ilẹ̀ kí ó yanu gbagada, jẹ́ kí ìgbàlà kí ó dìde sókè, jẹ́ kí òdodo kí ó dàgbà pẹ̀lú rẹ̀; Èmi Olúwa ni ó ti dá a.
Piliet, debesis, no augšienes, un padebeši lai izlej taisnību; lai zeme atveras un izdod pestīšanu, un taisnība lai līdz izaug: Es Tas Kungs to esmu radījis.
9 “Ègbé ni fún ènìyàn tí ó ń bá Ẹlẹ́dàá rẹ̀ jà, ẹni tí òun jẹ́ àpáàdì kan láàrín àwọn àpáàdì tí ó wà lórí ilẹ̀. Ǹjẹ́ amọ̀ lè sọ fún amọ̀kòkò, pé: ‘Kí ni ohun tí ò ń ṣe?’ Ǹjẹ́ iṣẹ́ rẹ lè sọ pé, ‘Òun kò ní ọwọ́?’ (questioned)
Vai tam, kas pretī runā savam radītājam, poda gabals starp poda gabaliem no zemes! Vai gan māls saka uz savu taisītāju: ko tu dari? Jeb vai tavs darbs sacīs: viņam nav rokas?
10 Ègbé ni fún ẹni tí ó sọ fún baba rẹ̀ pé, ‘Kí ni o bí?’ tàbí sí ìyá rẹ̀, ‘Kí ni ìwọ ti bí?’
Ak vai, tam, kas saka uz tēvu: kam tu dzemdini? Un uz māti: kam tu dzemdē?
11 “Ohun tí Olúwa wí nìyìí, Ẹni Mímọ́ Israẹli, àti Ẹlẹ́dàá rẹ̀. Nípa ohun tí ó ń bọ̀, ǹjẹ́ o ń bi mí léèrè nípa àwọn ọmọ mi, tàbí kí o pàṣẹ fún mi nípa iṣẹ́ ọwọ́ mi bí?
Tā saka Tas Kungs, tas Svētais iekš Israēla un viņa Radītājs: Vaicājiet no Manis nākamas lietas; Manus bērnus un Manas rokas darbu pavēliet Man.
12 Èmi ni ẹni tí ó dá ilẹ̀ ayé tí ó sì da ọmọ ènìyàn sórí i rẹ̀. Ọwọ́ mi ni ó ti ta àwọn ọ̀run; mo sì kó àwọn àgbájọ ìràwọ̀ rẹ̀ síta.
Es esmu darījis zemi un radījis cilvēku zemes virsū. Es tas esmu, Manas rokas izplātījušas debesis, un Es pavēlu visam viņu spēkam.
13 Èmi yóò gbé Kirusi sókè nínú òdodo mi. Èmi yóò mú kí gbogbo ọ̀nà rẹ̀ kí ó tọ́. Òun yóò tún ìlú mi kọ́ yóò sì tú àwọn àtìpó mi sílẹ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe fún owó tàbí ẹ̀bùn kan, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.”
Es viņu esmu uzmodinājis taisnībā un darīšu visus viņa ceļus līdzenus. Viņš uzcels Manu pilsētu un atlaidīs Manus cietumniekus, ne par maksu un ne par dāvanām, saka Tas Kungs Cebaot.
14 Ohun tí Olúwa wí nìyìí: “Àwọn èròjà ilẹ̀ Ejibiti àti àwọn ọjà ilẹ̀ Kuṣi, àti àwọn Sabeani— wọn yóò wá sọ́dọ̀ rẹ wọn yóò sì jẹ́ tìrẹ; wọn yóò máa wọ́ tẹ̀lé ọ lẹ́yìn, wọn yóò máa wá lọ́wọ̀ọ̀wọ́. Wọn yóò máa foríbalẹ̀ níwájú rẹ̀, wọn yóò sì máa bẹ̀bẹ̀ níwájú rẹ pé, ‘Nítòótọ́ Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ kò sì ṣí ẹlòmíràn; kò sí ọlọ́run mìíràn.’”
Tā saka Tas Kungs: ēģiptiešu padoms, Moru ļaužu manta un Zabieši, vīri garu augumu, nāks pie tevis un tev piederēs, un staigās tev pakaļ; saistīti tie atnāks un klanīsies priekš tevis, tie tevi pielūgs: Patiesi, Dievs ir ar tevi, un nav cita Dieva.
15 Nítòótọ́ ìwọ jẹ́ Ọlọ́run tí ó fi ara rẹ̀ pamọ́, Ìwọ Ọlọ́run àti Olùgbàlà Israẹli,
Patiesi, Tu esi apslēpts Dievs, Israēla Dievs, Pestītājs.
16 Gbogbo àwọn tí ó ń gbẹ́ ère ni ojú yóò tì wọn yóò sì kan àbùkù; gbogbo wọn ni yóò bọ́ sínú àbùkù papọ̀.
Tie taps kaunā un par apsmieklu visi; tie aizies kopā ar kaunu, kas taisa elka dievus.
17 Ṣùgbọ́n Israẹli ni a ó gbàlà láti ọwọ́ Olúwa pẹ̀lú ìgbàlà ayérayé; a kì yóò kàn yín lábùkù tàbí kí a dójútì yín, títí ayé àìnípẹ̀kun.
Bet Israēls top atpestīts caur To Kungu ar mūžīgu pestīšanu; jūs netapsiet kaunā nedz par apsmieklu mūžīgi mūžam.
18 Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa wí, ẹni tí ó dá àwọn ọ̀run, Òun ni Ọlọ́run; ẹni tí ó mọ tí ó sì dá ayé, Òun ló ṣe é; Òun kò dá a láti wà lófo, ṣùgbọ́n ó ṣe é kí a lè máa gbé ibẹ̀, Òun wí pé: “Èmi ni Olúwa, kò sì ṣí ẹlòmíràn.
Jo tā saka Tas Kungs, kas debesis radījis, tas Dievs, kas zemi iztaisījis un darījis; Viņš to ir cēlis, Viņš to nav radījis, ka būtu tukša, bet Viņš to taisījis, lai tur dzīvo: Es esmu Tas Kungs, un cits neviens.
19 Èmi kò sọ̀rọ̀ níbi tí ó fi ara sin, láti ibìkan ní ilẹ̀ òkùnkùn, Èmi kò tí ì sọ fún àwọn ìran Jakọbu pé, ‘Ẹ wá mi lórí asán.’ Èmi Olúwa sọ òtítọ́, Mo sì sọ èyí tí ó tọ̀nà.
Es neesmu slepeni runājis kādā tumšā zemes vietā. Es uz Jēkaba dzimumu neesmu sacījis: meklējiet Mani velti! Es esmu Tas Kungs, kas runā taisnību un sludina patiesību.
20 “Ẹ kó ara yín jọ kí ẹ sì wá; ẹ kórajọ, ẹ̀yin ìsáǹsá láti àwọn orílẹ̀-èdè wá. Aláìmọ̀kan ni àwọn tí ó ń ru ère igi káàkiri, tí wọ́n gbàdúrà sí àwọn òrìṣà tí kò le gba ni.
Sapulcējaties un nāciet, tuvojaties visi līdz, kas izglābti no pagāniem! Tie nezin nenieka, kas apkārt nēsā savus izgrieztos koka tēlus, un pielūdz dievu, kas nevar izpestīt.
21 Jẹ́ kí a mọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀, fihàn wá, jẹ́ kí wọn jọ dámọ̀ràn papọ̀. Ta ló ti sọ èyí lọ́jọ́ tí o ti pẹ́, ta ló ti wí èyí láti àtètèkọ́ṣe? Kì í ha á ṣe Èmi, Olúwa? Àti pé kò sí Ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn mi, Ọlọ́run olódodo àti olùgbàlà; kò sí ẹlòmíràn àfi èmi.
Sludiniet un nāciet klāt, sarunājaties kopā. Kas to ir darījis zināmu no veciem laikiem, kas to sen stāstījis? Vai ne Es, Tas Kungs? Un cita Dieva nav, kā Es vien, taisna Dieva un Pestītāja neviena nav, kā Es vien.
22 “Yípadà sí mi kí a sì gbà ọ́ là, ẹ̀yin ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé; nítorí Èmi ni Ọlọ́run kò sì ṣí ẹlòmíràn.
Griežaties pie Manis, tad jūs tapsiet pestīti, visas pasaules gali, jo Es esmu Dievs, un cits neviens.
23 Nípa èmi tìkára mi ni mo ti búra, ẹnu mi ni ó ti sọ ọ́ pẹ̀lú gbogbo ipá mi, ọ̀rọ̀ náà tí a kì yóò lè parẹ́. Níwájú mi ni gbogbo orúnkún yóò wólẹ̀; nípa mi ni gbogbo ahọ́n yóò búra.
Es esmu zvērējis pie Sevis paša, taisnība no Manas mutes izgājusi, vārds, kas nav pārgrozāms: tiešām, visi ceļi Manā priekšā locīsies, visas mēles Man zvērēs.
24 Wọn yóò sọ ní ti èmi, ‘Nínú Olúwa nìkan ni òdodo àti agbára wà.’” Gbogbo àwọn tí ó ti bínú sí; yóò wá sọ́dọ̀ rẹ̀ a ó sì dójútì wọn.
Par Mani sacīs: tiešām, iekš Tā Kunga ir taisnības darbi un stiprums. Pie Viņa ies. Bet kas Viņam turas pretī, paliks kaunā.
25 Ṣùgbọ́n nínú Olúwa gbogbo àwọn ìran Israẹli ni a ó rí ní òdodo, a o sì gbé wọn ga.
Iekš Tā Kunga taps taisnoti un lielīsies visi, kas no Israēla dzimuma.

< Isaiah 45 >