< Isaiah 45 >

1 “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún ẹni òróró rẹ̀, sí Kirusi, ọwọ́ ọ̀tún ẹni tí mo dì mú láti dojú àwọn orílẹ̀-èdè bolẹ̀ níwájú rẹ̀ àti láti gba ohun ìjà àwọn ọba lọ́wọ́ wọn, láti ṣí àwọn ìlẹ̀kùn níwájú rẹ̀ tí ó fi jẹ́ pé a kì yóò ti àwọn ẹnu-ọ̀nà.
Voici ce que dit le Seigneur Dieu: J'ai dit à mon christ Cyrus que j'ai pris par la main, avant que les nations lui obéissent: Je briserai la force des rois; j'ouvrirai devant toi les portes, et les villes ne te seront pas fermées.
2 Èmi yóò lọ síwájú rẹ, Èmi ó sì tẹ́ àwọn òkè ńlá pẹrẹsẹ Èmi yóò fọ gbogbo ẹnu-ọ̀nà idẹ èmi ó sì gé ọ̀pá irin.
Je marcherai devant toi; j'aplanirai les montagnes; je briserai les portes d'airain; je broierai les verrous de fer.
3 Èmi yóò sì fún ọ ní àwọn ọrọ̀ ibi òkùnkùn, ọrọ̀ tí a kó pamọ́ sí àwọn ibi tí ó fi ara sin, tó bẹ́ẹ̀ tí ìwọ yóò fi mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ẹni tí ó pè ọ́ pẹ̀lú orúkọ rẹ.
Je te donnerai des trésors enfouis dans les ténèbres; j'ouvrirai pour toi les retraites cachées, invisibles; afin que tu saches que je suis le Seigneur ton Dieu, qui t'appelle par ton nom, le Dieu d'Israël.
4 Nítorí Jakọbu ìránṣẹ́ mi àti Israẹli ẹni tí mo yàn, Mo pè ọ́ pẹ̀lú orúkọ rẹ, mo sì gbé oyè kan kà ọ́ lórí bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ kò gbà mí.
A cause de mon serviteur Jacob, à cause de mon élu Israël, je t'appellerai par ton nom, et je t'agréerai, toi qui cependant ne m'as pas connu.
5 Èmi ni Olúwa, àti pé kò sí ẹlòmíràn; yàtọ̀ sí èmi kò sí ọlọ́run kan, Èmi yóò fún ọ ní okun, bí o kò tilẹ̀ tí ì gbà mí,
Je suis le Seigneur Dieu; et, hormis moi, il n'y a point de Dieu; je t'ai fortifié, et tu ne me connaissais pas.
6 tí o fi jẹ́ pé láti ìlà-oòrùn títí dé ibi ìwọ̀ rẹ̀ kí ènìyàn le mọ̀, kò sí ẹnìkan lẹ́yìn mi. Èmi ni Olúwa, lẹ́yìn mi kò sí ẹlòmíràn mọ́.
Je t'ai fortifié pour que du lever au coucher du soleil on sache qu'il n'y a point de Dieu, hormis moi. Je suis le Seigneur Dieu, et il n'en n'est point d'autre.
7 Mo dá ìmọ́lẹ̀, mo sì dá òkùnkùn, Mo mú àlàáfíà wá, Mo sì dá àjálù; Èmi Olúwa ni ó ṣe nǹkan wọ̀nyí.
C'est moi qui ai préparé la lumière, qui ai formé les ténèbres, qui fais la paix, qui crée les maux; je suis le Seigneur Dieu, qui fais toutes ces choses.
8 “Ìwọ ọ̀run lókè rọ òjò òdodo sílẹ̀; jẹ́ kí àwọsánmọ̀ kí ó rọ̀ ọ́ sílẹ̀. Jẹ́ kí ilẹ̀ kí ó yanu gbagada, jẹ́ kí ìgbàlà kí ó dìde sókè, jẹ́ kí òdodo kí ó dàgbà pẹ̀lú rẹ̀; Èmi Olúwa ni ó ti dá a.
Que du plus haut le ciel se réjouisse; que les nuées répandent la justice comme une rosée. Que la terre produise, qu'elle fasse naître la miséricorde et qu'elle produise en même temps la justice. Moi je suis le Seigneur qui t'ai créé.
9 “Ègbé ni fún ènìyàn tí ó ń bá Ẹlẹ́dàá rẹ̀ jà, ẹni tí òun jẹ́ àpáàdì kan láàrín àwọn àpáàdì tí ó wà lórí ilẹ̀. Ǹjẹ́ amọ̀ lè sọ fún amọ̀kòkò, pé: ‘Kí ni ohun tí ò ń ṣe?’ Ǹjẹ́ iṣẹ́ rẹ lè sọ pé, ‘Òun kò ní ọwọ́?’ (questioned)
Ai-je fait l'argile supérieure au potier? Le laboureur laboure-t-il tout un jour? L'argile dit-elle au potier: Que fais-tu? tu ne travailles pas; n'as-tu pas des mains? Est-ce que l'œuvre parle à l'ouvrier?
10 Ègbé ni fún ẹni tí ó sọ fún baba rẹ̀ pé, ‘Kí ni o bí?’ tàbí sí ìyá rẹ̀, ‘Kí ni ìwọ ti bí?’
C'est comme si on disait à son père: Pourquoi engendrez-vous? et à sa mère: Pourquoi enfantez-vous?
11 “Ohun tí Olúwa wí nìyìí, Ẹni Mímọ́ Israẹli, àti Ẹlẹ́dàá rẹ̀. Nípa ohun tí ó ń bọ̀, ǹjẹ́ o ń bi mí léèrè nípa àwọn ọmọ mi, tàbí kí o pàṣẹ fún mi nípa iṣẹ́ ọwọ́ mi bí?
Voici ce que dit le Seigneur, le Saint d'Israël, le créateur des choses futures: Questionnez-moi sur mes fils; demandez-moi compte des œuvres de mes mains.
12 Èmi ni ẹni tí ó dá ilẹ̀ ayé tí ó sì da ọmọ ènìyàn sórí i rẹ̀. Ọwọ́ mi ni ó ti ta àwọn ọ̀run; mo sì kó àwọn àgbájọ ìràwọ̀ rẹ̀ síta.
C'est moi qui ai créé la terre, et l'homme sur elle; moi qui de ma main ai affermi le ciel; moi qui ai donné des lois à tous les astres.
13 Èmi yóò gbé Kirusi sókè nínú òdodo mi. Èmi yóò mú kí gbogbo ọ̀nà rẹ̀ kí ó tọ́. Òun yóò tún ìlú mi kọ́ yóò sì tú àwọn àtìpó mi sílẹ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe fún owó tàbí ẹ̀bùn kan, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.”
C'est moi qui l'ai suscité; il sera roi selon la justice; toutes ses voies seront droites; il rebâtira ma ville; il fera revenir mon peuple de la captivité, sans rançons, sans présents, dit le Seigneur des armées.
14 Ohun tí Olúwa wí nìyìí: “Àwọn èròjà ilẹ̀ Ejibiti àti àwọn ọjà ilẹ̀ Kuṣi, àti àwọn Sabeani— wọn yóò wá sọ́dọ̀ rẹ wọn yóò sì jẹ́ tìrẹ; wọn yóò máa wọ́ tẹ̀lé ọ lẹ́yìn, wọn yóò máa wá lọ́wọ̀ọ̀wọ́. Wọn yóò máa foríbalẹ̀ níwájú rẹ̀, wọn yóò sì máa bẹ̀bẹ̀ níwájú rẹ pé, ‘Nítòótọ́ Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ kò sì ṣí ẹlòmíràn; kò sí ọlọ́run mìíràn.’”
Voici ce que dit le Seigneur des armées: l'Égypte a travaillé pour toi; les marchandises des Éthiopiens et des hommes superbes de Saba traverseront la mer pour venir te trouver; ils te seront asservis; ils te suivront les fers aux mains, ils t'aborderont, ils se prosterneront devant toi, et t'adresseront leurs prières, parce que Dieu est avec toi. Et, hormis vous, Seigneur, il n'est point de Dieu.
15 Nítòótọ́ ìwọ jẹ́ Ọlọ́run tí ó fi ara rẹ̀ pamọ́, Ìwọ Ọlọ́run àti Olùgbàlà Israẹli,
Car vous êtes Dieu, et nous ne le savions pas, Dieu d'Israël, Dieu Sauveur!
16 Gbogbo àwọn tí ó ń gbẹ́ ère ni ojú yóò tì wọn yóò sì kan àbùkù; gbogbo wọn ni yóò bọ́ sínú àbùkù papọ̀.
Que tous tes adversaires soient humiliés, qu'ils rougissent, qu'ils marchent pleins de honte. Et vous, célébrez des solennités en mon honneur.
17 Ṣùgbọ́n Israẹli ni a ó gbàlà láti ọwọ́ Olúwa pẹ̀lú ìgbàlà ayérayé; a kì yóò kàn yín lábùkù tàbí kí a dójútì yín, títí ayé àìnípẹ̀kun.
Israël est sauvé par le Seigneur, sauvé pour tous les siècles; ses enfants ne seront plus humiliés ni confondus à jamais.
18 Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa wí, ẹni tí ó dá àwọn ọ̀run, Òun ni Ọlọ́run; ẹni tí ó mọ tí ó sì dá ayé, Òun ló ṣe é; Òun kò dá a láti wà lófo, ṣùgbọ́n ó ṣe é kí a lè máa gbé ibẹ̀, Òun wí pé: “Èmi ni Olúwa, kò sì ṣí ẹlòmíràn.
Ainsi dit le Seigneur qui a créé le ciel, le Dieu qui a fait paraître la terre, qui l'a créée, qui lui a donné ses limites; et il ne l'a point formée en vain, mais pour qu'elle fût habitée. Je suis le Seigneur, et il n'en est point d'autre.
19 Èmi kò sọ̀rọ̀ níbi tí ó fi ara sin, láti ibìkan ní ilẹ̀ òkùnkùn, Èmi kò tí ì sọ fún àwọn ìran Jakọbu pé, ‘Ẹ wá mi lórí asán.’ Èmi Olúwa sọ òtítọ́, Mo sì sọ èyí tí ó tọ̀nà.
Je n'ai point parlé en secret, ni dans quelque lieu obscur de la terre; je n'ai point dit à la race de Jacob: En vain cherchez-vous; c'est moi, c'est moi le Seigneur qui parle selon la justice, qui annonce la vérité.
20 “Ẹ kó ara yín jọ kí ẹ sì wá; ẹ kórajọ, ẹ̀yin ìsáǹsá láti àwọn orílẹ̀-èdè wá. Aláìmọ̀kan ni àwọn tí ó ń ru ère igi káàkiri, tí wọ́n gbàdúrà sí àwọn òrìṣà tí kò le gba ni.
Rassemblez-vous, venez, prenez conseil ensemble, vous qui avez été sauvés des nations qui élevaient des sculptures et des statues de bois, qui vivaient dans l'ignorance et priaient des dieux incapables de sauver.
21 Jẹ́ kí a mọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀, fihàn wá, jẹ́ kí wọn jọ dámọ̀ràn papọ̀. Ta ló ti sọ èyí lọ́jọ́ tí o ti pẹ́, ta ló ti wí èyí láti àtètèkọ́ṣe? Kì í ha á ṣe Èmi, Olúwa? Àti pé kò sí Ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn mi, Ọlọ́run olódodo àti olùgbàlà; kò sí ẹlòmíràn àfi èmi.
Si elles ont quelque chose à dire, qu'elles approchent, afin d'apprendre toutes à la fois qui a fait connaître ces choses; vous les avez sues dès lors, vous avez su que je suis Dieu; il n'en est point d'autre que moi; je suis le Dieu juste et sauveur; il n'en est point, hormis moi.
22 “Yípadà sí mi kí a sì gbà ọ́ là, ẹ̀yin ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé; nítorí Èmi ni Ọlọ́run kò sì ṣí ẹlòmíràn.
Convertissez-vous à moi, et vous serez sauvés, ô vous qui venez des extrémités de la terre. C'est moi qui suis Dieu, et il n'en est point d'autre.
23 Nípa èmi tìkára mi ni mo ti búra, ẹnu mi ni ó ti sọ ọ́ pẹ̀lú gbogbo ipá mi, ọ̀rọ̀ náà tí a kì yóò lè parẹ́. Níwájú mi ni gbogbo orúnkún yóò wólẹ̀; nípa mi ni gbogbo ahọ́n yóò búra.
Je le jure par moi-même, la justice seule va sortir de ma bouche, et ma parole ne sera pas vaine. Tout genou fléchira devant moi; toute langue confessera Dieu,
24 Wọn yóò sọ ní ti èmi, ‘Nínú Olúwa nìkan ni òdodo àti agbára wà.’” Gbogbo àwọn tí ó ti bínú sí; yóò wá sọ́dọ̀ rẹ̀ a ó sì dójútì wọn.
Disant: La justice et la gloire viendront à lui, et tous ceux qui se séparent du Seigneur seront confondus.
25 Ṣùgbọ́n nínú Olúwa gbogbo àwọn ìran Israẹli ni a ó rí ní òdodo, a o sì gbé wọn ga.
Et les autres seront justifiés, et toute la postérité des fils d'Israël mettra sa gloire en Dieu.

< Isaiah 45 >