< Isaiah 45 >

1 “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún ẹni òróró rẹ̀, sí Kirusi, ọwọ́ ọ̀tún ẹni tí mo dì mú láti dojú àwọn orílẹ̀-èdè bolẹ̀ níwájú rẹ̀ àti láti gba ohun ìjà àwọn ọba lọ́wọ́ wọn, láti ṣí àwọn ìlẹ̀kùn níwájú rẹ̀ tí ó fi jẹ́ pé a kì yóò ti àwọn ẹnu-ọ̀nà.
Amah kah a koelh Cyrus te BOEIPA loh, “Namtom rhoek te a mikhmuh ah hnaa hamla a bantang kut te ka moem pah. A mikhmuh ah thohkhaih rhoek te ong hamla manghai rhoek cinghen khaw ka hlam pah ni. Te vaengah vongka te kalh uh mahpawh.
2 Èmi yóò lọ síwájú rẹ, Èmi ó sì tẹ́ àwọn òkè ńlá pẹrẹsẹ Èmi yóò fọ gbogbo ẹnu-ọ̀nà idẹ èmi ó sì gé ọ̀pá irin.
Kamah he na mikhmuh ah ka pongpa vetih ngoem te ka nolh rhoe ka nolh ni. Rhohum thohkhaih te ka thuk vetih thi thohkalh ka tloek ni.
3 Èmi yóò sì fún ọ ní àwọn ọrọ̀ ibi òkùnkùn, ọrọ̀ tí a kó pamọ́ sí àwọn ibi tí ó fi ara sin, tó bẹ́ẹ̀ tí ìwọ yóò fi mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ẹni tí ó pè ọ́ pẹ̀lú orúkọ rẹ.
Hmaisuep khuikah thakvoh neh a huephael kah kawn te nang taengah kam paek bitni. Te daengah ni BOEIPA kamah he na ming neh aka khue Israel Pathen la na ming eh.
4 Nítorí Jakọbu ìránṣẹ́ mi àti Israẹli ẹni tí mo yàn, Mo pè ọ́ pẹ̀lú orúkọ rẹ, mo sì gbé oyè kan kà ọ́ lórí bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ kò gbà mí.
Ka sal Jakob neh ka coelh Israel ham nang te na ming nen ni kang khue. Kai nan ming pawt cakhaw nang kan mingkhaep coeng.
5 Èmi ni Olúwa, àti pé kò sí ẹlòmíràn; yàtọ̀ sí èmi kò sí ọlọ́run kan, Èmi yóò fún ọ ní okun, bí o kò tilẹ̀ tí ì gbà mí,
Kai he Yahovah ni. Kai kah a voelah a tloe a om moenih, pathen tloe khaw a om moenih. Nang te kam poeh mai cakhaw kai nan ming hae moenih.
6 tí o fi jẹ́ pé láti ìlà-oòrùn títí dé ibi ìwọ̀ rẹ̀ kí ènìyàn le mọ̀, kò sí ẹnìkan lẹ́yìn mi. Èmi ni Olúwa, lẹ́yìn mi kò sí ẹlòmíràn mọ́.
Kai Yahovah kamah pawt atah a tloe om pawt tih a tloe a om pawt te khocuk khomik taeng lamloh khotlak duela ming uh saeh.
7 Mo dá ìmọ́lẹ̀, mo sì dá òkùnkùn, Mo mú àlàáfíà wá, Mo sì dá àjálù; Èmi Olúwa ni ó ṣe nǹkan wọ̀nyí.
Vangnah aka hlinsai tih a hmuep aka suen. Rhoepnah aka saii tih boethae aka suen. Te rhoek boeih aka saii khaw BOEIPA kamah ni.
8 “Ìwọ ọ̀run lókè rọ òjò òdodo sílẹ̀; jẹ́ kí àwọsánmọ̀ kí ó rọ̀ ọ́ sílẹ̀. Jẹ́ kí ilẹ̀ kí ó yanu gbagada, jẹ́ kí ìgbàlà kí ó dìde sókè, jẹ́ kí òdodo kí ó dàgbà pẹ̀lú rẹ̀; Èmi Olúwa ni ó ti dá a.
Vaan khaw a so lamkah ha pha lamtah khomong khaw duengnah ha sih saeh. Diklai te ong uh saeh lamtah daemnah loh thaihsu saeh. Duengnah khaw cuen laeh saeh. Te te kai Yahovah long ni ka suen.
9 “Ègbé ni fún ènìyàn tí ó ń bá Ẹlẹ́dàá rẹ̀ jà, ẹni tí òun jẹ́ àpáàdì kan láàrín àwọn àpáàdì tí ó wà lórí ilẹ̀. Ǹjẹ́ amọ̀ lè sọ fún amọ̀kòkò, pé: ‘Kí ni ohun tí ò ń ṣe?’ Ǹjẹ́ iṣẹ́ rẹ lè sọ pé, ‘Òun kò ní ọwọ́?’ (questioned)
Anunae, diklai paikaek lakli kah paikaek pakhat loh amah aka hlinsai te a oelh mai. Amlai loh amah aka picai te, “Nang kah bisai khaw banim na saii dae, a kut khaw om pawt nim?” a ti nah cop a?
10 Ègbé ni fún ẹni tí ó sọ fún baba rẹ̀ pé, ‘Kí ni o bí?’ tàbí sí ìyá rẹ̀, ‘Kí ni ìwọ ti bí?’
Anunae, a napa la, “Balae tih nan sak,” a manu te, “Balae tih nan yom?” aka ti mai.
11 “Ohun tí Olúwa wí nìyìí, Ẹni Mímọ́ Israẹli, àti Ẹlẹ́dàá rẹ̀. Nípa ohun tí ó ń bọ̀, ǹjẹ́ o ń bi mí léèrè nípa àwọn ọmọ mi, tàbí kí o pàṣẹ fún mi nípa iṣẹ́ ọwọ́ mi bí?
Israel kah Yahovah cim neh anih aka hlinsai loh, “Aka thoeng ham te kamah n'dawt lah. Ka ca rhoek ham neh ka kut dongkah bisai ham te kai nan uen mai.
12 Èmi ni ẹni tí ó dá ilẹ̀ ayé tí ó sì da ọmọ ènìyàn sórí i rẹ̀. Ọwọ́ mi ni ó ti ta àwọn ọ̀run; mo sì kó àwọn àgbájọ ìràwọ̀ rẹ̀ síta.
Kai loh diklai khaw diklai hman kah hlang khaw ka saii. Kai loh ka suen tangtae vaan ke khaw kamah kut loh a dih tih a caempuei rhoek khaw boeih ka uen.
13 Èmi yóò gbé Kirusi sókè nínú òdodo mi. Èmi yóò mú kí gbogbo ọ̀nà rẹ̀ kí ó tọ́. Òun yóò tún ìlú mi kọ́ yóò sì tú àwọn àtìpó mi sílẹ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe fún owó tàbí ẹ̀bùn kan, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.”
Anih te duengnah dongah ka haeng vetih a longpuei te boeih ka dueng pah ni. Anih loh kai kah khopuei te a khoeng vetih ka hlangsol la a tueih ni. A phu khaw thui mahpawh, kapbaih khaw hoe mahpawh,” a ti he caempuei BOEIPA long ni a thui.
14 Ohun tí Olúwa wí nìyìí: “Àwọn èròjà ilẹ̀ Ejibiti àti àwọn ọjà ilẹ̀ Kuṣi, àti àwọn Sabeani— wọn yóò wá sọ́dọ̀ rẹ wọn yóò sì jẹ́ tìrẹ; wọn yóò máa wọ́ tẹ̀lé ọ lẹ́yìn, wọn yóò máa wá lọ́wọ̀ọ̀wọ́. Wọn yóò máa foríbalẹ̀ níwájú rẹ̀, wọn yóò sì máa bẹ̀bẹ̀ níwájú rẹ pé, ‘Nítòótọ́ Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ kò sì ṣí ẹlòmíràn; kò sí ọlọ́run mìíràn.’”
BOEIPA loh Egypt kah thaphu khaw, Kusah neh hlang sang Sabean kah a thenpom loh nang te m'paan uh vetih namah taengah om uh ni. Nang hnukah hmaipom neh pongpa uh ni. Nang taengla ha pawk uh vaengah khaw bakop uh ni. Nang taengah te, “Nang taengah Pathen rhep om pai tih hlang tloe a om moenih, pathen tloe a om moenih,” tila thangthui uh ni.
15 Nítòótọ́ ìwọ jẹ́ Ọlọ́run tí ó fi ara rẹ̀ pamọ́, Ìwọ Ọlọ́run àti Olùgbàlà Israẹli,
Namah tah Israel Pathen, khangkung neh muei aka thuh Pathen pai ni.
16 Gbogbo àwọn tí ó ń gbẹ́ ère ni ojú yóò tì wọn yóò sì kan àbùkù; gbogbo wọn ni yóò bọ́ sínú àbùkù papọ̀.
Amih te thikat la boeih yak uh vetih a hmaithae uh bal ni. Muei saii kutthai rhoek te mingthae neh van uh ni.
17 Ṣùgbọ́n Israẹli ni a ó gbàlà láti ọwọ́ Olúwa pẹ̀lú ìgbàlà ayérayé; a kì yóò kàn yín lábùkù tàbí kí a dójútì yín, títí ayé àìnípẹ̀kun.
Israel te BOEIPA loh kumhal loeihnah dongah a khang ni. Kumhal ah a yoeyah la na yak voel pawt vetih na hmaithae voel mahpawh.
18 Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa wí, ẹni tí ó dá àwọn ọ̀run, Òun ni Ọlọ́run; ẹni tí ó mọ tí ó sì dá ayé, Òun ló ṣe é; Òun kò dá a láti wà lófo, ṣùgbọ́n ó ṣe é kí a lè máa gbé ibẹ̀, Òun wí pé: “Èmi ni Olúwa, kò sì ṣí ẹlòmíràn.
He khaw vaan aka suen BOEIPA long ni a thui. Pathen amah loh diklai a hlom tih a saii. Diklai he a hinghong pawt ham a soepsoei phoeiah khosa rhoek ham a suen tih a hlinsai pah. BOEIPA kamah phoeiah a tloe a om moenih.
19 Èmi kò sọ̀rọ̀ níbi tí ó fi ara sin, láti ibìkan ní ilẹ̀ òkùnkùn, Èmi kò tí ì sọ fún àwọn ìran Jakọbu pé, ‘Ẹ wá mi lórí asán.’ Èmi Olúwa sọ òtítọ́, Mo sì sọ èyí tí ó tọ̀nà.
A huephael neh diklai hmaisuep hmuen ah ka thui moenih. Jakob tiingan taengah hinghong la kai n'tlap ka ti nah moenih. Duengnah aka thui BOEIPA kamah loh vanat la ka puen.
20 “Ẹ kó ara yín jọ kí ẹ sì wá; ẹ kórajọ, ẹ̀yin ìsáǹsá láti àwọn orílẹ̀-èdè wá. Aláìmọ̀kan ni àwọn tí ó ń ru ère igi káàkiri, tí wọ́n gbàdúrà sí àwọn òrìṣà tí kò le gba ni.
Namtom hlangyong rhoek te coi uh thae lamtah ha kun uh laeh. Thikat la ha mop uh laeh. Amamih kah mueithuk thing a phueih nawn khaw ming uh pawt tih aka khang thai pawh pathen taengah thangthui uh.
21 Jẹ́ kí a mọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀, fihàn wá, jẹ́ kí wọn jọ dámọ̀ràn papọ̀. Ta ló ti sọ èyí lọ́jọ́ tí o ti pẹ́, ta ló ti wí èyí láti àtètèkọ́ṣe? Kì í ha á ṣe Èmi, Olúwa? Àti pé kò sí Ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn mi, Ọlọ́run olódodo àti olùgbàlà; kò sí ẹlòmíràn àfi èmi.
Puen uh lamtah ha mop uh lah. Tun ah khaw uen uh thae saeh. Hlamat lamloh aka yaak sak tih daengrhae daengkhoi la aka puen te unim? BOEIPA kamah moenih a? Duengnah Pathen kamah pawt atah Pathen tloe om pawh. Kai phoeiah he khangkung a om moenih.
22 “Yípadà sí mi kí a sì gbà ọ́ là, ẹ̀yin ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé; nítorí Èmi ni Ọlọ́run kò sì ṣí ẹlòmíràn.
Diklai khobawt boeih loh kai taengla ha mael uh lamtah khang la om uh lah. Kai Pathen phoeiah Pathen koep a om moenih.
23 Nípa èmi tìkára mi ni mo ti búra, ẹnu mi ni ó ti sọ ọ́ pẹ̀lú gbogbo ipá mi, ọ̀rọ̀ náà tí a kì yóò lè parẹ́. Níwájú mi ni gbogbo orúnkún yóò wólẹ̀; nípa mi ni gbogbo ahọ́n yóò búra.
Kamah loh ka toemngam coeng dongah ka ka lamloh aka thoeng duengnah ol tah balkhong voel mahpawh. Kai taengah khuklu boeih a cungkueng vetih ol boeih a caeng ni.
24 Wọn yóò sọ ní ti èmi, ‘Nínú Olúwa nìkan ni òdodo àti agbára wà.’” Gbogbo àwọn tí ó ti bínú sí; yóò wá sọ́dọ̀ rẹ̀ a ó sì dójútì wọn.
Kai BOEIPA bueng dongah ni duengnah neh a sarhi la a thui eh. Amah taengah aka lungoe rhoek khaw a taengla ha pawk uh vetih boeih yak uh ni.
25 Ṣùgbọ́n nínú Olúwa gbogbo àwọn ìran Israẹli ni a ó rí ní òdodo, a o sì gbé wọn ga.
Israel kah tiingan boeih tah BOEIPA rhangneh tang uh vetih a thangthen uh ni.

< Isaiah 45 >