< Isaiah 45 >

1 “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún ẹni òróró rẹ̀, sí Kirusi, ọwọ́ ọ̀tún ẹni tí mo dì mú láti dojú àwọn orílẹ̀-èdè bolẹ̀ níwájú rẹ̀ àti láti gba ohun ìjà àwọn ọba lọ́wọ́ wọn, láti ṣí àwọn ìlẹ̀kùn níwájú rẹ̀ tí ó fi jẹ́ pé a kì yóò ti àwọn ẹnu-ọ̀nà.
Angmah situi to bawh moe, a bantang ban ka patawn ih, Cyrus khaeah, prae kaminawk boih a hmaa ah akun hanah, Angraeng mah, siangpahrangnawk ih khukbuen to khring pae moe, khongkhanawk to khah han ai ah, ahmaa ah khongkha hnetto paong pae ah, tiah thuih;
2 Èmi yóò lọ síwájú rẹ, Èmi ó sì tẹ́ àwọn òkè ńlá pẹrẹsẹ Èmi yóò fọ gbogbo ẹnu-ọ̀nà idẹ èmi ó sì gé ọ̀pá irin.
na hmaa ah ka caeh moe, kangkoih ahmuennawk to ka toengsak han; sumkamling hoiah sak ih khongkhanawk to ka phraek moe, takraenghaih sumboengnawk to ka khaeh pae han.
3 Èmi yóò sì fún ọ ní àwọn ọrọ̀ ibi òkùnkùn, ọrọ̀ tí a kó pamọ́ sí àwọn ibi tí ó fi ara sin, tó bẹ́ẹ̀ tí ìwọ yóò fi mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ẹni tí ó pè ọ́ pẹ̀lú orúkọ rẹ.
Kai loe Angraeng, Israel Sithaw, ahmin hoiah nangcae kawkkung ah ka oh, tiah na panoek o thai hanah, kaving thung ih hmuennawk to kang paek moe, panoek ai ih ahmuen ah kanghawk angraenghaih doeh kang paek o han.
4 Nítorí Jakọbu ìránṣẹ́ mi àti Israẹli ẹni tí mo yàn, Mo pè ọ́ pẹ̀lú orúkọ rẹ, mo sì gbé oyè kan kà ọ́ lórí bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ kò gbà mí.
Cyrus, ka tamna Jakob hoi ka qoih ih Israel pongah ni, nang to ahmin hoiah kang kawk; toe kai hae nang panoek ai, toe na hmin hoihaih to kang paek.
5 Èmi ni Olúwa, àti pé kò sí ẹlòmíràn; yàtọ̀ sí èmi kò sí ọlọ́run kan, Èmi yóò fún ọ ní okun, bí o kò tilẹ̀ tí ì gbà mí,
Kai loe Angraeng ah ka oh, kalah roe om ai, kai ai ah loe Sithaw om ai; Kai hae nang panoek ai, toe na kaeng to kacakah kang zaeng pae.
6 tí o fi jẹ́ pé láti ìlà-oòrùn títí dé ibi ìwọ̀ rẹ̀ kí ènìyàn le mọ̀, kò sí ẹnìkan lẹ́yìn mi. Èmi ni Olúwa, lẹ́yìn mi kò sí ẹlòmíràn mọ́.
Ni tacawthaih hoi niduem khoek to, kaminawk mah kai ai ah loe kalah Sithaw roe om ai, tiah panoek o tih. Kai loe Angraeng ah ka oh, kai pacoengah kalah mi doeh om ai boeh.
7 Mo dá ìmọ́lẹ̀, mo sì dá òkùnkùn, Mo mú àlàáfíà wá, Mo sì dá àjálù; Èmi Olúwa ni ó ṣe nǹkan wọ̀nyí.
Aanghaih to ka ohsak moe, vinghaih doeh ka sak; angdaehhaih ka sak moe, amrohaih doeh ka sak; hae hmuennawk boih loe Kai, Angraeng mah ni ka sak.
8 “Ìwọ ọ̀run lókè rọ òjò òdodo sílẹ̀; jẹ́ kí àwọsánmọ̀ kí ó rọ̀ ọ́ sílẹ̀. Jẹ́ kí ilẹ̀ kí ó yanu gbagada, jẹ́ kí ìgbàlà kí ó dìde sókè, jẹ́ kí òdodo kí ó dàgbà pẹ̀lú rẹ̀; Èmi Olúwa ni ó ti dá a.
Nangcae vannawk, ranui bang hoiah kho angzo oh; toenghaih loe van bang hoiah kho baktiah angzosak nasoe; long hae am-ong nasoe loe, pahlonghaih thingthai to athai nasoe; toenghaih loe nawnto tacawt tahang nasoe; Kai, Angraeng mah to hmuen to ka sak boeh.
9 “Ègbé ni fún ènìyàn tí ó ń bá Ẹlẹ́dàá rẹ̀ jà, ẹni tí òun jẹ́ àpáàdì kan láàrín àwọn àpáàdì tí ó wà lórí ilẹ̀. Ǹjẹ́ amọ̀ lè sọ fún amọ̀kòkò, pé: ‘Kí ni ohun tí ò ń ṣe?’ Ǹjẹ́ iṣẹ́ rẹ lè sọ pé, ‘Òun kò ní ọwọ́?’ (questioned)
Angmah Sahkung hoi angzoeh kami loe khosak bing! Anih loe long ah kaom kakoi long laom baktiah ni oh. Amlai long mah laom sahkung khaeah, Timaw na sak? tiah naa thai tih maw? To tih ai boeh loe kai sahkung loe ban tawn ai, tiah thui thai tih maw?
10 Ègbé ni fún ẹni tí ó sọ fún baba rẹ̀ pé, ‘Kí ni o bí?’ tàbí sí ìyá rẹ̀, ‘Kí ni ìwọ ti bí?’
Nawktanawk mah ampa hanah, Kawbaktih hmuen maw na sak? To tih ai boeh loe amno hanah, Kawbaktih hmuen maw na tapen? tiah thui kami loe khosak bing!
11 “Ohun tí Olúwa wí nìyìí, Ẹni Mímọ́ Israẹli, àti Ẹlẹ́dàá rẹ̀. Nípa ohun tí ó ń bọ̀, ǹjẹ́ o ń bi mí léèrè nípa àwọn ọmọ mi, tàbí kí o pàṣẹ fún mi nípa iṣẹ́ ọwọ́ mi bí?
Angraeng, nihcae Sahkung, Ciimcai Israel Sithaw mah hae tiah thuih; angzo han koi hmuennawk, ka capanawk kawng hoi ban hoi ka sak ih hmuennawk kawng pongah, nangcae mah lok nang dueng o han om ai.
12 Èmi ni ẹni tí ó dá ilẹ̀ ayé tí ó sì da ọmọ ènìyàn sórí i rẹ̀. Ọwọ́ mi ni ó ti ta àwọn ọ̀run; mo sì kó àwọn àgbájọ ìràwọ̀ rẹ̀ síta.
Long loe kai mah ni ka sak, a nuiah kaom kami doeh ka sak; Kaimah ih ban hoi roe ah vannawk to ka payuengh moe, cakaehnawk to lok ka paek boih.
13 Èmi yóò gbé Kirusi sókè nínú òdodo mi. Èmi yóò mú kí gbogbo ọ̀nà rẹ̀ kí ó tọ́. Òun yóò tún ìlú mi kọ́ yóò sì tú àwọn àtìpó mi sílẹ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe fún owó tàbí ẹ̀bùn kan, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.”
Toenghaih hoiah anih to ka pathawk tahang, anih caehhaih loklamnawk to ka hnuksak boih han; anih mah ka vangpui to sah ueloe, atho paek ai, tangqum paekhaih doeh om ai ah, naeh ih kaminawk to loisak tih, tiah misatuh kaminawk ih Angraeng mah thuih.
14 Ohun tí Olúwa wí nìyìí: “Àwọn èròjà ilẹ̀ Ejibiti àti àwọn ọjà ilẹ̀ Kuṣi, àti àwọn Sabeani— wọn yóò wá sọ́dọ̀ rẹ wọn yóò sì jẹ́ tìrẹ; wọn yóò máa wọ́ tẹ̀lé ọ lẹ́yìn, wọn yóò máa wá lọ́wọ̀ọ̀wọ́. Wọn yóò máa foríbalẹ̀ níwájú rẹ̀, wọn yóò sì máa bẹ̀bẹ̀ níwájú rẹ pé, ‘Nítòótọ́ Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ kò sì ṣí ẹlòmíràn; kò sí ọlọ́run mìíràn.’”
Angraeng mah hae tiah thuih; Izip prae ah hak o ih hmuenmaenawk, Ethiopia kaminawk hoi somsang kahoih kaminawk mah hmuenmae zawhhaih hoiah hak o ih hmuennawk to nangcae khaeah pha tih, to hmuennawk loe nangcae ih hmuen ah om tih; nihcae loe qui hoi pathlet pacoengah, nangcae hnukah bang o tih; nangcae hmaa ah tabok o ueloe, nangcae khaeah, Sithaw loe oh tangtang; to Sithaw ai ah loe kalah Sithaw roe om ai, tiah nangcae khaeah tahmenhaih hni o tih.
15 Nítòótọ́ ìwọ jẹ́ Ọlọ́run tí ó fi ara rẹ̀ pamọ́, Ìwọ Ọlọ́run àti Olùgbàlà Israẹli,
Aw Israel Sithaw hoi pahlongkung, nang loe kamtueng ah kaom ai Sithaw ah na oh.
16 Gbogbo àwọn tí ó ń gbẹ́ ère ni ojú yóò tì wọn yóò sì kan àbùkù; gbogbo wọn ni yóò bọ́ sínú àbùkù papọ̀.
Krang sah kaminawk loe palungboeng o ueloe, azat o boih tih; azathaih hoiah ahmin sae o tih.
17 Ṣùgbọ́n Israẹli ni a ó gbàlà láti ọwọ́ Olúwa pẹ̀lú ìgbàlà ayérayé; a kì yóò kàn yín lábùkù tàbí kí a dójútì yín, títí ayé àìnípẹ̀kun.
Toe Israel loe Angraeng mah pahlong tih, dungzan pahlonghaih to hnu tih; azathaih tong mak ai, dungzan khoek to azathaih hoi palungboenghaih om mak ai boeh.
18 Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa wí, ẹni tí ó dá àwọn ọ̀run, Òun ni Ọlọ́run; ẹni tí ó mọ tí ó sì dá ayé, Òun ló ṣe é; Òun kò dá a láti wà lófo, ṣùgbọ́n ó ṣe é kí a lè máa gbé ibẹ̀, Òun wí pé: “Èmi ni Olúwa, kò sì ṣí ẹlòmíràn.
Vannawk sahkung, Angraeng mah hae tiah thuih; Long loe Sithaw angmah sak moe, a caksak; azom pui ah oh hanah long hae sah ai; kami oh han ih ni a sak; Kai loe Angraeng ni, Angraeng kalah mi doeh om ai.
19 Èmi kò sọ̀rọ̀ níbi tí ó fi ara sin, láti ibìkan ní ilẹ̀ òkùnkùn, Èmi kò tí ì sọ fún àwọn ìran Jakọbu pé, ‘Ẹ wá mi lórí asán.’ Èmi Olúwa sọ òtítọ́, Mo sì sọ èyí tí ó tọ̀nà.
Kai loe tamquta hoi lok ka thui ai moe, long vinghaih ahmuen hoiah doeh lok ka thui ai; Jakob ih caanawk khaeah, Atho om ai ah kai hae pakrong oh, tiah ka thui ai; Kai, Angraeng loe toenghaih to ka thuih moe, loktang lok ni ka thuih.
20 “Ẹ kó ara yín jọ kí ẹ sì wá; ẹ kórajọ, ẹ̀yin ìsáǹsá láti àwọn orílẹ̀-èdè wá. Aláìmọ̀kan ni àwọn tí ó ń ru ère igi káàkiri, tí wọ́n gbàdúrà sí àwọn òrìṣà tí kò le gba ni.
Angzoh oh loe, maeto ah amkhueng oh; misa loih prae kaminawk boih, nawnto amkhueng oh; thing hoiah krang sah kaminawk, pahlong thai ai sithawnawk khaeah lawkthui kami loe, panoekhaih tidoeh tawn ai kami ah ni oh o.
21 Jẹ́ kí a mọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀, fihàn wá, jẹ́ kí wọn jọ dámọ̀ràn papọ̀. Ta ló ti sọ èyí lọ́jọ́ tí o ti pẹ́, ta ló ti wí èyí láti àtètèkọ́ṣe? Kì í ha á ṣe Èmi, Olúwa? Àti pé kò sí Ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn mi, Ọlọ́run olódodo àti olùgbàlà; kò sí ẹlòmíràn àfi èmi.
Na tok sakhaih to angzo o haih ah loe thui oh; ue, kaminawk to kawk oh, lok nawnto thui o nasoe; canghnii hoiah hae hmuen kawng thui kami loe mi aa? To nathuem hoi kamtong mi mah maw thuih? Kai, Angraeng mah na ai maw ka thuih? Kai ai ah loe Sithaw kalah om ai; Kai loe katoeng Sithaw, pahlongkung ah ka oh; kai ai ah loe kalah Sithaw roe om ai.
22 “Yípadà sí mi kí a sì gbà ọ́ là, ẹ̀yin ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé; nítorí Èmi ni Ọlọ́run kò sì ṣí ẹlòmíràn.
Kai loe Sithaw ah ka oh, kai ai ah loe kalah Sithaw om ai boeh pongah, long boenghaih ah kaom kaminawk, kai hae na khen o ah loe pahlong ah om oh.
23 Nípa èmi tìkára mi ni mo ti búra, ẹnu mi ni ó ti sọ ọ́ pẹ̀lú gbogbo ipá mi, ọ̀rọ̀ náà tí a kì yóò lè parẹ́. Níwájú mi ni gbogbo orúnkún yóò wólẹ̀; nípa mi ni gbogbo ahọ́n yóò búra.
Kami boih ka hmaa ah khokkhu cangkrawn o ueloe, palainawk boih mah lokkamhaih to sah o tih, tiah kaimah hoi kaimah lokkamhaih to ka sak boeh; ka pakha thung hoi tacawt toenghaih lok loe akoep ai ah amlaem let mak ai.
24 Wọn yóò sọ ní ti èmi, ‘Nínú Olúwa nìkan ni òdodo àti agbára wà.’” Gbogbo àwọn tí ó ti bínú sí; yóò wá sọ́dọ̀ rẹ̀ a ó sì dójútì wọn.
Toenghaih hoi thacakhaih loe Angraeng ah ni oh, tiah kami boih mah thui o tih; Angraeng to misa ah suem kaminawk to anih khaeah angzo o ueloe, azathaih hoiah om o tih.
25 Ṣùgbọ́n nínú Olúwa gbogbo àwọn ìran Israẹli ni a ó rí ní òdodo, a o sì gbé wọn ga.
Toe Israel caanawk boih loe Angraeng pongah toenghaih to hnu o ueloe, lensawkhaih hoiah om o tih.

< Isaiah 45 >