< Isaiah 44 >

1 “Ṣùgbọ́n gbọ́ nísinsin yìí, ìwọ Jakọbu ìránṣẹ́ mi, àti Israẹli, ẹni tí mo ti yàn.
“Na afei tie, Yakob me somfo, Israel, nea mapaw no.
2 Ohun tí Olúwa wí nìyìí ẹni tí ó dá ọ, ẹni tí ó ti mọ̀ ọ́n láti inú ìyá rẹ wá, àti ẹni tí yóò ràn ọ́ lọ́wọ́ pẹ̀lú. Má ṣe bẹ̀rù, ìwọ Jakọbu, ìránṣẹ́ mi, Jeṣuruni ẹni tí mo ti yàn.
Sɛɛ na Awurade se, nea ɔnwen wo, na ɔyɛɛ wo wɔ awotwaa mu, ɔno na ɔbɛboa wo: Nsuro Yakob, me somfo, Yeshurun, a mapaw no.
3 Nítorí èmi yóò da omi sí ilẹ̀ tí ń pòǹgbẹ àti àwọn odò ní ilẹ̀ gbígbẹ, Èmi yóò tú Ẹ̀mí mi sí ara àwọn ọmọ rẹ, àti ìbùkún mi sórí àwọn àrọ́mọdọ́mọ rẹ.
Na mehwie nsu agu asase a awo no so, ne nsuten wɔ asase kesee so; mehwie me Honhom agu wo mma so, ne me nhyira agu wʼasefo so.
4 Wọn yóò dàgbàsókè gẹ́gẹ́ bí i koríko nínú pápá oko tútù, àti gẹ́gẹ́ bí igi Poplari létí odò tí ń sàn.
Wobefifi sɛnea sare fifi wɔ mmoa adidibea, te sɛ mpampuro a ɛwɔ asuten ho.
5 Ọ̀kan yóò wí pé, ‘Èmi jẹ́ ti Olúwa’; òmíràn yóò pe ara rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí orúkọ Jakọbu; bẹ́ẹ̀ ni òmíràn yóò kọ ọ́ sí ọwọ́ rẹ̀, ‘Ti Olúwa,’ yóò sì máa jẹ́ orúkọ náà Israẹli.
Obi bɛka se, ‘Meyɛ Awurade de’; ɔfoforo bɛfrɛ ne ho se Yakob; afoforo bɛkɔ so akyerɛw wɔn nsa ho se, ‘Awurade de,’ na wɔafa din Israel.
6 “Ohun tí Olúwa wí nìyìí ọba Israẹli àti Olùdáǹdè, àní Olúwa àwọn ọmọ-ogun. Èmi ni ẹni àkọ́kọ́ àti ẹni ìgbẹ̀yìn, lẹ́yìn mi kò sí Ọlọ́run kan.
“Sɛɛ na Awurade Israelhene ne Ogyefo, Asafo Awurade se: Mene odikanfo ne okyikafo; Onyankopɔn biara nni hɔ sɛ me.
7 Ta ni ó dàbí ì mi? Jẹ́ kí o kéde rẹ̀. Jẹ́ kí ó wí kí ó sì gbé síwájú mi kí ni ó ti ṣẹlẹ̀ láti ìgbà tí mo fi ìdí àwọn ènìyàn ìṣẹ̀ǹbáyé kalẹ̀, àti kí ni ohun tí ń sì ń bọ̀, bẹ́ẹ̀ ni, jẹ́ kí ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ ohun tí ń bọ̀ wá.
Hena na ɔne me sɛ? Ma ɔmpae mu nka. Ma ɔnka na ɔnkyerɛ wɔ mʼanim nea asisi fi bere a migyee me tete nkurɔfo sii hɔ, ne nea ɛrebɛba. Yiw, ma ɔnhyɛ nea ɛreba ho nkɔm.
8 Má ṣe wárìrì, má ṣe bẹ̀rù. Ǹjẹ́ èmi kò ti kéde èyí tí mo sì ti sọ àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀ tipẹ́tipẹ́? Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí mi. Ǹjẹ́ Ọlọ́run kan ha ń bẹ lẹ́yìn mi? Bẹ́ẹ̀ kọ́, kò sí àpáta mìíràn; Èmi kò mọ ọ̀kankan.”
Mommma mo ho mpopo, munnsuro. Mampae mu anka eyi, manhyɛ ho amfi teteete ana? Mone me nnansefo. Onyankopɔn foforo bi ka me ho ana? Dabi, Ɔbotan foforo bi nni hɔ; minnim baako mpo.”
9 Gbogbo àwọn tí ń gbẹ́ ère jásí asán, àti àwọn ohun tí wọn ń kó pamọ́ kò jámọ́ nǹkan kan. Àwọn tí yóò sọ̀rọ̀ fún wọn fọ́ lójú; wọ́n jẹ́ aláìmọ̀kan sí ìtìjú ara wọn.
Wɔn a wɔyɛ ahoni nyinaa nka hwee, na nneɛma a ɛsom wɔn bo no so nni mfaso. Wɔn a anka wɔkasa ma wɔn no ani afura; wonnim wɔn ankasa animguase ho hwee.
10 Ta ni ó mọ òrìṣà kan tí ó sì ya ère, tí kò lè mú èrè kankan wá fún un?
Hena na ɔbɔ onyame na ogu ohoni, a ne so mma no mfaso biara?
11 Òun àti nǹkan rẹ̀ wọ̀nyí ni a ó dójútì; àwọn oníṣọ̀nà kò yàtọ̀, ènìyàn ni wọ́n. Jẹ́ kí gbogbo wọn gbárajọ kí wọ́n sì fi ìdúró wọn hàn; gbogbo wọn ni a ó mú bọ́ sínú ìpayà àti àbùkù.
Ɔno ne wɔn a wɔte sɛ no nyinaa anim begu ase; adwumfo nyɛ hwee sɛ nnipa. Momma wɔn nyinaa mmɔ mu nsɔre nnyina, ehu ne animguase na ɛbɛka wɔn.
12 Alágbẹ̀dẹ mú ohun èlò, ó fi ń ṣiṣẹ́ nínú èédú; ó fi òòlù ya ère kan, ó ṣe é pẹ̀lú agbára apá rẹ̀, ebi ń pa á, àárẹ̀ sì mú un; kò mu omi rárá, ìrẹ̀wẹ̀sì dé bá a.
Ɔtomfo fa nʼatonnade ɔde hyehyɛ nnyansramma mu; ɔde asae bobɔ so yɛ no ohoni, ɔde nʼabasa mu ahoɔden mmoroso na ɛyɛ; ɔkɔm de no na ɔyɛ mmrɛw; ɔnnom nsu nti ɔtɔ beraw.
13 Gbẹ́nàgbẹ́nà fi ìwọ̀n wọ́n ọ́n ó sì fi lẹ́ẹ̀dì ṣe àmì sí ara rẹ̀, Ó tún fi ìfà fá a jáde ó tún fi òsùwọ̀n ṣe àmì sí i. Ó gbẹ́ ẹ ní ìrí ènìyàn gẹ́gẹ́ bí ènìyàn nínú ògo rẹ̀, kí ó lè máa gbé nínú ilé òrìṣà.
Duadwumfo de hama susuw na ɔde kyerɛwdua sensan; na ɔde pɛe yiyi ho afei ɔde kɔmpaase hyɛ no agyirae. Osen na ɛyɛ sɛ onipa sɛso, ɛyɛ sɛ onipa wɔ nʼanuonyam nyinaa mu, sɛ wɔde besi abosonnan mu.
14 Ó gé igi kedari lulẹ̀, tàbí bóyá ó mú sípírẹ́ṣì tàbí igi óákù. Ó jẹ́ kí ó dàgbà láàrín àwọn igi inú igbó, ó sì le gbin igi páínì, èyí tí òjò mú kí ó dàgbà.
Otwitwaa sida, anaasɛ ebia ɔfaa kwabɔhɔre anaa odum. Ɔma enyinii wɔ kwae mu, anaa oduaa ɔpepaw, na osu ma enyinii.
15 Ohun èlò ìdáná ni fún ènìyàn; díẹ̀ nínú rẹ̀ ni ó mú láti mú kí ara rẹ̀ lọ́wọ́ọ́rọ́, ó dá iná ó sì fi ṣe àkàrà. Ṣùgbọ́n bákan náà ni ó ṣe òrìṣà tí ó sì ń sìn ín; ó yá ère, ó sì ń foríbalẹ̀ fún un.
Ɛyɛ nea onipa de sɔ ogya; ɔde bi ka ne ho hyew, ɔde bi sɔ ogya to brodo. Nanso ɔde bi sen onyame na ɔsɔre no; ɔyɛ ohoni na ɔkotow no.
16 Ìlàjì igi náà ni ó jó nínú iná; lórí i rẹ̀ ni ó ti ń tọ́jú oúnjẹ rẹ̀, ó dín ẹran rẹ̀ ó sì jẹ àjẹyó. Ó tún mú ara rẹ̀ gbóná ó sì sọ pé, “Á à! Ara mi gbóná, mo rí iná.”
Ɔde dua no mu fa sɔ ogya; so na ɔnoa nʼaduan, ɔtoto ne nam wɔ so na wawe amee. Afei ɔka ne ho hyew na ɔka se, Aa! mahu ogya; me ho ayɛ me hyew.
17 Nínú èyí tí ó kù ni ó ti ṣe òrìṣà, ère rẹ̀; ó foríbalẹ̀ fún un, ó sì sìn ín. Ó gbàdúrà sí i, ó wí pé, “Gbà mí, ìwọ ni Ọlọ́run mi.”
Nkae no ɔde yɛ onyame, ne ohoni; ɔkotow no na ɔsɔre no. Ɔbɔ no mpae se, “Gye me; wo ne me nyame.”
18 Wọn kò mọ nǹkan kan, nǹkan kan kò yé wọn; a fi ìbòjú bo ojú wọn, wọn kò lè rí nǹkan kan; bẹ́ẹ̀ ni àyà wọn sébọ́, wọn kò lè mọ nǹkan kan.
Wonnim hwee, na wɔnte hwee ase; wɔatare wɔn ani so nti wonhu ade, wɔato wɔn adwene mu nti wɔnte hwee ase.
19 Kò sí ẹni tí ó dúró láti ronú, kò sí ẹni tí ó ní ìmọ̀ tàbí òye láti sọ wí pé, “Ìlàjì rẹ̀ ni mo fi dáná; mo tilẹ̀ ṣe àkàrà lórí èédú rẹ̀, mo dín ẹran, mo sì jẹ ẹ́. Ǹjẹ́ ó wá yẹ kí n ṣe ohun ìríra kan nínú èyí tí ó ṣẹ́kù bí? Ǹjẹ́ èmi yóò ha foríbalẹ̀ fún ìtì igi?”
Obiara nna nnwen ho, obiara nni nimdeɛ anaa nhumu a ɔde bɛka se, “Mede fa sɔɔ ogya; na mpo metoo brodo wɔ ne nnyansramma so; metotoo nam wɔ so wee. Ɛsɛ sɛ mede nkae no yɛ akyiwade ana? Ɛsɛ sɛ mekotow gyentia ana?”
20 Ó ń jẹ eérú, ọkàn ẹlẹ́tàn ni ó ṣì í lọ́nà; òun kò lè gba ara rẹ̀ là, tàbí kí ó wí pé, “Ǹjẹ́ nǹkan tí ó wà lọ́wọ́ ọ̀tún mi yìí irọ́ kọ́?”
Saa onipa no di nsõ, nnaadaa koma ma no to kwan; ɔrentumi nnye ne ho, anaa nka se, “Nea mikura wɔ me nsa nifa yi nyɛ atoro ana?”
21 “Rántí àwọn nǹkan wọ̀nyí, ìwọ Jakọbu, nítorí ìránṣẹ́ mi ni ìwọ, ìwọ Israẹli. Èmi ti dá ọ, ìránṣẹ́ mi ni ìwọ ṣe, ìwọ Israẹli, Èmi kì yóò gbàgbé rẹ.
“Kae saa nneɛma yi, Yakob, efisɛ, woyɛ me somfo, Israel. Me na meyɛɛ wo, woyɛ me somfo; Ao Israel, me werɛ remfi wo.
22 Èmi ti gbá gbogbo ìkùnà rẹ dànù bí i kurukuru, àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ bí ìrì òwúrọ̀. Padà sọ́dọ̀ mi, nítorí mo ti rà ọ́ padà.”
Mapra wo mfomso agu te sɛ omununkum ne wo bɔne te sɛ anɔpa bosu. San bra me nkyɛn, efisɛ magye wo.”
23 Kọrin fáyọ̀, ẹ̀yin ọ̀run, nítorí Olúwa ló ti ṣe èyí; kígbe sókè, ìwọ ilẹ̀ ayé nísàlẹ̀. Bú sí orin, ẹ̀yin òkè ńlá, ẹ̀yin igbó àti gbogbo igi yín, nítorí Olúwa ti ra Jakọbu padà, ó ti fi ògo rẹ̀ hàn ní Israẹli.
Momfa ahosɛpɛw nto dwom, ɔsorosoro, na Awurade na wayɛ eyi. Mommɔ ose, asase ase. Momma nnwonto so, mo mmepɔw, mo kwae ne emu nnua nyinaa, na Awurade agye Yakob, wada nʼanuonyam adi wɔ Israel.
24 “Ohun tí Olúwa wí nìyìí Olùràpadà rẹ tí ó mọ ọ́ láti inú ìyá rẹ wá: “Èmi ni Olúwa tí ó ti ṣe ohun gbogbo tí òun nìkan ti na àwọn ọ̀run tí o sì tẹ́ ayé pẹrẹsẹ òun tìkára rẹ̀,
“Sɛɛ na Awurade se, wo Gyefo a ɔnwen wo wɔ awotwaa mu no: “Mene Awurade, nea wayɛ nneɛma nyinaa, nea ɔno nko ara trɛw ɔsoro mu nea ɔno nko ara twee asase mu,
25 ta ni ó ba àmì àwọn wòlíì èké jẹ́ tí ó sì sọ àwọn aláfọ̀ṣẹ di òmùgọ̀, tí ó dojú ìmọ̀ àwọn ọlọ́gbọ́n délẹ̀ tí ó sì sọ wọ́n di òmùgọ̀,
nea ɔsɛe atoro adiyifo nsɛnkyerɛnne na ɔma nkɔmhyɛfo yɛ nkwaseafo, nea otutu anyansafo adenim gu na ɔdan no nkwaseasɛm,
26 ẹni tí ó gbé ọ̀rọ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ jáde tí ó sì mú àsọtẹ́lẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ wá sí ìmúṣẹ, “ẹni tí ó wí nípa ti Jerusalẹmu pé, ‘A ó máa gbé inú rẹ̀,’ àti ní ti àwọn ìlú Juda, ‘A ó tún kọ́,’ àti àwọn ahoro rẹ̀, ‘Èmi yóò mú un bọ̀ sípò,’
nea ɔma nʼasomfo nsɛm ba mu nea ɔhyɛ nʼasomafo nkɔmhyɛ mu ma, “nea ɔka fa Yerusalem ho se, ‘Wɔbɛtena mu,’ ne Yuda nkurow ho se, ‘Wɔbɛkyekye,’ ne mmubui ho se, ‘Mɛyɛ no foforo,’
27 ta ni ó sọ fún omi jíjìn pé, ‘Ìwọ gbẹ, èmi yóò sì mú omi odò rẹ gbẹ,’
nea ɔka kyerɛ asubun se, ‘Yow, na mɛma wo nsuwa ayoyow,’
28 ta ni ó sọ nípa Kirusi pé, ‘Òun ni Olùṣọ́-àgùntàn mi àti pé òun yóò ṣe ohun gbogbo tí mo fẹ́; òun yóò sọ nípa Jerusalẹmu pé, “Jẹ́ kí a tún kọ́,” àti nípa tẹmpili, “Jẹ́ kí a fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ lé ilẹ̀.”’”
nea ɔka wɔ Kores ho se, ‘Ɔyɛ me guanhwɛfo na obewie nea mepɛ nyinaa yɛ; ɔbɛka afa Yerusalem ho se, “Ma wɔnkyekyere bio,” na waka afa asɔredan no ho se, “Ma wɔnto ne fapem.”’”

< Isaiah 44 >