< Isaiah 44 >

1 “Ṣùgbọ́n gbọ́ nísinsin yìí, ìwọ Jakọbu ìránṣẹ́ mi, àti Israẹli, ẹni tí mo ti yàn.
“Şimdi, ey kulum Yakup soyu, Seçtiğim İsrail halkı, dinle!
2 Ohun tí Olúwa wí nìyìí ẹni tí ó dá ọ, ẹni tí ó ti mọ̀ ọ́n láti inú ìyá rẹ wá, àti ẹni tí yóò ràn ọ́ lọ́wọ́ pẹ̀lú. Má ṣe bẹ̀rù, ìwọ Jakọbu, ìránṣẹ́ mi, Jeṣuruni ẹni tí mo ti yàn.
Seni yaratan, rahimde sana biçim veren, Sana yardım edecek olan RAB şöyle diyor: ‘Korkma, ey kulum Yakup soyu, Ey seçtiğim Yeşurun!
3 Nítorí èmi yóò da omi sí ilẹ̀ tí ń pòǹgbẹ àti àwọn odò ní ilẹ̀ gbígbẹ, Èmi yóò tú Ẹ̀mí mi sí ara àwọn ọmọ rẹ, àti ìbùkún mi sórí àwọn àrọ́mọdọ́mọ rẹ.
“‘Susamış toprağı sulayacak, Kurumuş toprakta dereler akıtacağım. Çocuklarının üzerine Ruhum'u dökecek, Soyunu kutsayacağım.
4 Wọn yóò dàgbàsókè gẹ́gẹ́ bí i koríko nínú pápá oko tútù, àti gẹ́gẹ́ bí igi Poplari létí odò tí ń sàn.
Akarsu kıyısında otlar arasında yükselen Kavaklar gibi boy atacaklar.’
5 Ọ̀kan yóò wí pé, ‘Èmi jẹ́ ti Olúwa’; òmíràn yóò pe ara rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí orúkọ Jakọbu; bẹ́ẹ̀ ni òmíràn yóò kọ ọ́ sí ọwọ́ rẹ̀, ‘Ti Olúwa,’ yóò sì máa jẹ́ orúkọ náà Israẹli.
“Kimi, ‘Ben RAB'be aitim’ diyecek, Kimi Yakup adını alacak, Kimi de eline ‘RAB'be ait’ yazıp İsrail adını benimseyecek.”
6 “Ohun tí Olúwa wí nìyìí ọba Israẹli àti Olùdáǹdè, àní Olúwa àwọn ọmọ-ogun. Èmi ni ẹni àkọ́kọ́ àti ẹni ìgbẹ̀yìn, lẹ́yìn mi kò sí Ọlọ́run kan.
RAB, İsrail'in Kralı ve Kurtarıcısı, Her Şeye Egemen RAB diyor ki, “İlk ve son benim, Benden başka Tanrı yoktur.
7 Ta ni ó dàbí ì mi? Jẹ́ kí o kéde rẹ̀. Jẹ́ kí ó wí kí ó sì gbé síwájú mi kí ni ó ti ṣẹlẹ̀ láti ìgbà tí mo fi ìdí àwọn ènìyàn ìṣẹ̀ǹbáyé kalẹ̀, àti kí ni ohun tí ń sì ń bọ̀, bẹ́ẹ̀ ni, jẹ́ kí ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ ohun tí ń bọ̀ wá.
Benim gibi olan var mı? Haber versin. Ezeli halkımı var ettiğimden beri olup bitenleri, Bundan sonra olacakları söyleyip sıralasın, Evet, gelecek olayları bildirsin!
8 Má ṣe wárìrì, má ṣe bẹ̀rù. Ǹjẹ́ èmi kò ti kéde èyí tí mo sì ti sọ àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀ tipẹ́tipẹ́? Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí mi. Ǹjẹ́ Ọlọ́run kan ha ń bẹ lẹ́yìn mi? Bẹ́ẹ̀ kọ́, kò sí àpáta mìíràn; Èmi kò mọ ọ̀kankan.”
Yılmayın, korkmayın! Size çok önceden beri söyleyip açıklamadım mı? Tanıklarım sizsiniz. Benden başka Tanrı var mı? Hayır, başka Kaya yok; Ben bir başkasını bilmiyorum.”
9 Gbogbo àwọn tí ń gbẹ́ ère jásí asán, àti àwọn ohun tí wọn ń kó pamọ́ kò jámọ́ nǹkan kan. Àwọn tí yóò sọ̀rọ̀ fún wọn fọ́ lójú; wọ́n jẹ́ aláìmọ̀kan sí ìtìjú ara wọn.
Putlara biçim verenlerin hepsi boş insanlardır. Değer verdikleri nesneler hiçbir işe yaramaz. Putların tanıkları onlardır; Ne bir şey görür ne de bir şey bilirler. Bunun sonucunda utanç içinde kalacaklar.
10 Ta ni ó mọ òrìṣà kan tí ó sì ya ère, tí kò lè mú èrè kankan wá fún un?
Kim yararsız ilaha biçim vermek, Dökme put yapmak ister?
11 Òun àti nǹkan rẹ̀ wọ̀nyí ni a ó dójútì; àwọn oníṣọ̀nà kò yàtọ̀, ènìyàn ni wọ́n. Jẹ́ kí gbogbo wọn gbárajọ kí wọ́n sì fi ìdúró wọn hàn; gbogbo wọn ni a ó mú bọ́ sínú ìpayà àti àbùkù.
Bakın, bu putlarla uğraşanların hepsi utanacak. Onları yapanlar salt insan. Hepsi toplanıp yargılanmaya gelsin. Dehşete düşecek, utanacaklar birlikte.
12 Alágbẹ̀dẹ mú ohun èlò, ó fi ń ṣiṣẹ́ nínú èédú; ó fi òòlù ya ère kan, ó ṣe é pẹ̀lú agbára apá rẹ̀, ebi ń pa á, àárẹ̀ sì mú un; kò mu omi rárá, ìrẹ̀wẹ̀sì dé bá a.
Demirci aletini alır, Kömür ateşinde çalışır, Çekiçle demire biçim verir. Güçlü koluyla onu işler. Acıkır, güçsüz kalır, su içmeyince tükenir.
13 Gbẹ́nàgbẹ́nà fi ìwọ̀n wọ́n ọ́n ó sì fi lẹ́ẹ̀dì ṣe àmì sí ara rẹ̀, Ó tún fi ìfà fá a jáde ó tún fi òsùwọ̀n ṣe àmì sí i. Ó gbẹ́ ẹ ní ìrí ènìyàn gẹ́gẹ́ bí ènìyàn nínú ògo rẹ̀, kí ó lè máa gbé nínú ilé òrìṣà.
Marangoz iple ölçü alır, Tahtayı tebeşirle çizer. Raspayla tahtayı biçimlendirir, Pergelle işaretler, insan biçimi verir. İnsan güzelliğinde, Evde duracak bir put yapar.
14 Ó gé igi kedari lulẹ̀, tàbí bóyá ó mú sípírẹ́ṣì tàbí igi óákù. Ó jẹ́ kí ó dàgbà láàrín àwọn igi inú igbó, ó sì le gbin igi páínì, èyí tí òjò mú kí ó dàgbà.
İnsan kendisi için sedir ağaçları keser, Palamut, meşe ağaçları alır. Ormanda kendine bir ağaç seçer. Bir çam diker, ama ağacı büyüten yağmurdur.
15 Ohun èlò ìdáná ni fún ènìyàn; díẹ̀ nínú rẹ̀ ni ó mú láti mú kí ara rẹ̀ lọ́wọ́ọ́rọ́, ó dá iná ó sì fi ṣe àkàrà. Ṣùgbọ́n bákan náà ni ó ṣe òrìṣà tí ó sì ń sìn ín; ó yá ère, ó sì ń foríbalẹ̀ fún un.
Sonra ağaç odun olarak kullanılır. İnsan aldığı odunla hem ısınır, Hem tutuşturup ekmek pişirir, Hem de bir ilah yapıp tapınır. Yaptığı putun önünde yere kapanır.
16 Ìlàjì igi náà ni ó jó nínú iná; lórí i rẹ̀ ni ó ti ń tọ́jú oúnjẹ rẹ̀, ó dín ẹran rẹ̀ ó sì jẹ àjẹyó. Ó tún mú ara rẹ̀ gbóná ó sì sọ pé, “Á à! Ara mi gbóná, mo rí iná.”
Odunun bir kısmını yakar, Ateşinde et kızartıp karnını doyurur. Isınınca bir oh çeker, “Isındım, ateşin sıcaklığını duyuyorum” der.
17 Nínú èyí tí ó kù ni ó ti ṣe òrìṣà, ère rẹ̀; ó foríbalẹ̀ fún un, ó sì sìn ín. Ó gbàdúrà sí i, ó wí pé, “Gbà mí, ìwọ ni Ọlọ́run mi.”
Artakalan odundan kendine bir ilah, Oyma put yapar; Önünde yere kapanıp ona tapınır, “Beni kurtar, çünkü ilahım sensin” diye yakarır.
18 Wọn kò mọ nǹkan kan, nǹkan kan kò yé wọn; a fi ìbòjú bo ojú wọn, wọn kò lè rí nǹkan kan; bẹ́ẹ̀ ni àyà wọn sébọ́, wọn kò lè mọ nǹkan kan.
Böyleleri anlamaz, bilmez. Çünkü gözleri de zihinleri de öylesine kapalı ki, Görmez, anlamazlar.
19 Kò sí ẹni tí ó dúró láti ronú, kò sí ẹni tí ó ní ìmọ̀ tàbí òye láti sọ wí pé, “Ìlàjì rẹ̀ ni mo fi dáná; mo tilẹ̀ ṣe àkàrà lórí èédú rẹ̀, mo dín ẹran, mo sì jẹ ẹ́. Ǹjẹ́ ó wá yẹ kí n ṣe ohun ìríra kan nínú èyí tí ó ṣẹ́kù bí? Ǹjẹ́ èmi yóò ha foríbalẹ̀ fún ìtì igi?”
Durup düşünmez, bilmez, Anlamazlar ki şöyle desinler: “Odunun bir kısmını yakıp Ateşinde ekmek pişirdim, et kızartıp yedim. Artakalanından iğrenç bir şey mi yapayım? Bir odun parçasının önünde yere mi kapanayım?”
20 Ó ń jẹ eérú, ọkàn ẹlẹ́tàn ni ó ṣì í lọ́nà; òun kò lè gba ara rẹ̀ là, tàbí kí ó wí pé, “Ǹjẹ́ nǹkan tí ó wà lọ́wọ́ ọ̀tún mi yìí irọ́ kọ́?”
Külle besleniyorlar. Aldanan yürekleri onları saptırıyor. Canlarını kurtaramaz, “Sağ elimdeki şu nesne aldatıcı değil mi?” diyemezler.
21 “Rántí àwọn nǹkan wọ̀nyí, ìwọ Jakọbu, nítorí ìránṣẹ́ mi ni ìwọ, ìwọ Israẹli. Èmi ti dá ọ, ìránṣẹ́ mi ni ìwọ ṣe, ìwọ Israẹli, Èmi kì yóò gbàgbé rẹ.
“Ey Yakup soyu, ey İsrail, Söylediklerimi anımsayın, çünkü kulumsunuz. Size ben biçim verdim, kulumsunuz; Seni unutmam, ey İsrail.
22 Èmi ti gbá gbogbo ìkùnà rẹ dànù bí i kurukuru, àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ bí ìrì òwúrọ̀. Padà sọ́dọ̀ mi, nítorí mo ti rà ọ́ padà.”
İsyanlarınızı bulut gibi, Günahlarınızı sis gibi sildim. Bana dönün, çünkü sizi kurtardım.”
23 Kọrin fáyọ̀, ẹ̀yin ọ̀run, nítorí Olúwa ló ti ṣe èyí; kígbe sókè, ìwọ ilẹ̀ ayé nísàlẹ̀. Bú sí orin, ẹ̀yin òkè ńlá, ẹ̀yin igbó àti gbogbo igi yín, nítorí Olúwa ti ra Jakọbu padà, ó ti fi ògo rẹ̀ hàn ní Israẹli.
Sevinçle haykırın, ey gökler, Çünkü bunu RAB yaptı. Haykırın, ey yerin derinlikleri. Ey dağlar, ey orman, ormandaki her ağaç, Sevinç çığlıklarına katılın. Çünkü RAB Yakup soyunu kurtararak İsrail'de görkemini gösterdi.
24 “Ohun tí Olúwa wí nìyìí Olùràpadà rẹ tí ó mọ ọ́ láti inú ìyá rẹ wá: “Èmi ni Olúwa tí ó ti ṣe ohun gbogbo tí òun nìkan ti na àwọn ọ̀run tí o sì tẹ́ ayé pẹrẹsẹ òun tìkára rẹ̀,
Sizi kurtaran, Size rahimde biçim veren RAB diyor ki, “Her şeyi yaratan, Gökleri yalnız başına geren, Yeryüzünü tek başına seren, Sahte peygamberlerin belirtilerini boşa çıkaran, Falcılarla alay eden, Bilgeleri geri çeviren, Bilgilerini saçmalığa dönüştüren, Kulunun sözlerini yerine getiren, Ulaklarının peygamberlik sözlerini gerçekleştiren, Yeruşalim için, ‘İçinde oturulacak’, Yahuda kentleri için, ‘Yeniden kurulacak, Yıkıntılarını onaracağım’ diyen; Engine, ‘Kuru! Sularını kurutacağım’ diyen, Koreş için, ‘O çobanımdır, Her istediğimi yerine getirecek’, Yeruşalim için, ‘Yeniden kurulacak’, Tapınak için, ‘Temeli atılacak’ diyen RAB benim.”
25 ta ni ó ba àmì àwọn wòlíì èké jẹ́ tí ó sì sọ àwọn aláfọ̀ṣẹ di òmùgọ̀, tí ó dojú ìmọ̀ àwọn ọlọ́gbọ́n délẹ̀ tí ó sì sọ wọ́n di òmùgọ̀,
26 ẹni tí ó gbé ọ̀rọ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ jáde tí ó sì mú àsọtẹ́lẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ wá sí ìmúṣẹ, “ẹni tí ó wí nípa ti Jerusalẹmu pé, ‘A ó máa gbé inú rẹ̀,’ àti ní ti àwọn ìlú Juda, ‘A ó tún kọ́,’ àti àwọn ahoro rẹ̀, ‘Èmi yóò mú un bọ̀ sípò,’
27 ta ni ó sọ fún omi jíjìn pé, ‘Ìwọ gbẹ, èmi yóò sì mú omi odò rẹ gbẹ,’
28 ta ni ó sọ nípa Kirusi pé, ‘Òun ni Olùṣọ́-àgùntàn mi àti pé òun yóò ṣe ohun gbogbo tí mo fẹ́; òun yóò sọ nípa Jerusalẹmu pé, “Jẹ́ kí a tún kọ́,” àti nípa tẹmpili, “Jẹ́ kí a fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ lé ilẹ̀.”’”

< Isaiah 44 >