< Isaiah 44 >

1 “Ṣùgbọ́n gbọ́ nísinsin yìí, ìwọ Jakọbu ìránṣẹ́ mi, àti Israẹli, ẹni tí mo ti yàn.
A teraz słuchaj, Jakubie, mój sługo, i ty, Izraelu, którego wybrałem.
2 Ohun tí Olúwa wí nìyìí ẹni tí ó dá ọ, ẹni tí ó ti mọ̀ ọ́n láti inú ìyá rẹ wá, àti ẹni tí yóò ràn ọ́ lọ́wọ́ pẹ̀lú. Má ṣe bẹ̀rù, ìwọ Jakọbu, ìránṣẹ́ mi, Jeṣuruni ẹni tí mo ti yàn.
Tak mówi PAN, który cię uczynił i który cię ukształtował już od łona matki, i który cię wspomaga: Nie bój się, Jakubie, mój sługo, i Jeszurunie, którego wybrałem.
3 Nítorí èmi yóò da omi sí ilẹ̀ tí ń pòǹgbẹ àti àwọn odò ní ilẹ̀ gbígbẹ, Èmi yóò tú Ẹ̀mí mi sí ara àwọn ọmọ rẹ, àti ìbùkún mi sórí àwọn àrọ́mọdọ́mọ rẹ.
Wyleję bowiem wody na spragnionego, a potoki na suchą ziemię. Wyleję mego Ducha na twoje potomstwo i moje błogosławieństwo na twoich potomków.
4 Wọn yóò dàgbàsókè gẹ́gẹ́ bí i koríko nínú pápá oko tútù, àti gẹ́gẹ́ bí igi Poplari létí odò tí ń sàn.
I rozkrzewią się tak jakby pomiędzy trawą i jak wierzby nad potokami wód.
5 Ọ̀kan yóò wí pé, ‘Èmi jẹ́ ti Olúwa’; òmíràn yóò pe ara rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí orúkọ Jakọbu; bẹ́ẹ̀ ni òmíràn yóò kọ ọ́ sí ọwọ́ rẹ̀, ‘Ti Olúwa,’ yóò sì máa jẹ́ orúkọ náà Israẹli.
Jeden powie: Ja należę do PANA, drugi nazwie się imieniem Jakuba, a inny napisze swoją ręką: PANU, i będzie się nazywał imieniem Izraela.
6 “Ohun tí Olúwa wí nìyìí ọba Israẹli àti Olùdáǹdè, àní Olúwa àwọn ọmọ-ogun. Èmi ni ẹni àkọ́kọ́ àti ẹni ìgbẹ̀yìn, lẹ́yìn mi kò sí Ọlọ́run kan.
Tak mówi PAN, Król Izraela i jego Odkupiciel, PAN zastępów: Ja jestem pierwszy i ja jestem ostatni, a oprócz mnie nie ma Boga.
7 Ta ni ó dàbí ì mi? Jẹ́ kí o kéde rẹ̀. Jẹ́ kí ó wí kí ó sì gbé síwájú mi kí ni ó ti ṣẹlẹ̀ láti ìgbà tí mo fi ìdí àwọn ènìyàn ìṣẹ̀ǹbáyé kalẹ̀, àti kí ni ohun tí ń sì ń bọ̀, bẹ́ẹ̀ ni, jẹ́ kí ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ ohun tí ń bọ̀ wá.
Czy od czasów, gdy ustanowiłem pierwszy lud na świecie, znalazł się ktoś, kto jak ja jest w stanie ogłosić i opowiedzieć rzeczy przyszłe? Jeśli tak – niech więc powie, co ma nastąpić.
8 Má ṣe wárìrì, má ṣe bẹ̀rù. Ǹjẹ́ èmi kò ti kéde èyí tí mo sì ti sọ àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀ tipẹ́tipẹ́? Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí mi. Ǹjẹ́ Ọlọ́run kan ha ń bẹ lẹ́yìn mi? Bẹ́ẹ̀ kọ́, kò sí àpáta mìíràn; Èmi kò mọ ọ̀kankan.”
Nie bójcie się i nie lękajcie. Czy od dawna nie oznajmiałem wam [wszystkiego] i nie opowiadałem? Wy sami jesteście moimi świadkami. Czy jest Bóg oprócz mnie? Nie ma innej Skały; nie znam żadnej.
9 Gbogbo àwọn tí ń gbẹ́ ère jásí asán, àti àwọn ohun tí wọn ń kó pamọ́ kò jámọ́ nǹkan kan. Àwọn tí yóò sọ̀rọ̀ fún wọn fọ́ lójú; wọ́n jẹ́ aláìmọ̀kan sí ìtìjú ara wọn.
Wytwórcy rzeźbionych posągów są niczym, a ich piękne dzieła nic im nie pomogą; oni sami sobie są świadkami, że nic nie widzą ani nie rozumieją – ku swemu zawstydzeniu.
10 Ta ni ó mọ òrìṣà kan tí ó sì ya ère, tí kò lè mú èrè kankan wá fún un?
Kto utworzył boga i odlewał posąg, który nie przynosi żadnego pożytku?
11 Òun àti nǹkan rẹ̀ wọ̀nyí ni a ó dójútì; àwọn oníṣọ̀nà kò yàtọ̀, ènìyàn ni wọ́n. Jẹ́ kí gbogbo wọn gbárajọ kí wọ́n sì fi ìdúró wọn hàn; gbogbo wọn ni a ó mú bọ́ sínú ìpayà àti àbùkù.
Oto wszyscy jego towarzysze będą zawstydzeni. Rzemieślnicy są tylko ludźmi. Niech się zbiorą wszyscy i niech staną. Przelęknąć się muszą i razem będą zawstydzeni.
12 Alágbẹ̀dẹ mú ohun èlò, ó fi ń ṣiṣẹ́ nínú èédú; ó fi òòlù ya ère kan, ó ṣe é pẹ̀lú agbára apá rẹ̀, ebi ń pa á, àárẹ̀ sì mú un; kò mu omi rárá, ìrẹ̀wẹ̀sì dé bá a.
Kowal kleszczami pracuje przy węglu, młotami kształtuje posąg i wykonuje go siłą swoich ramion, aż z głodu jego siły opadają, wody nie pije i omdlewa.
13 Gbẹ́nàgbẹ́nà fi ìwọ̀n wọ́n ọ́n ó sì fi lẹ́ẹ̀dì ṣe àmì sí ara rẹ̀, Ó tún fi ìfà fá a jáde ó tún fi òsùwọ̀n ṣe àmì sí i. Ó gbẹ́ ẹ ní ìrí ènìyàn gẹ́gẹ́ bí ènìyàn nínú ògo rẹ̀, kí ó lè máa gbé nínú ilé òrìṣà.
Cieśla zaś rozciąga sznur, wyznacza farbowanym sznurem, ciosa toporem, zaznacza go cyrklem i wykonuje go na podobieństwo człowieka, na podobieństwo pięknego człowieka, aby pozostawał w domu.
14 Ó gé igi kedari lulẹ̀, tàbí bóyá ó mú sípírẹ́ṣì tàbí igi óákù. Ó jẹ́ kí ó dàgbà láàrín àwọn igi inú igbó, ó sì le gbin igi páínì, èyí tí òjò mú kí ó dàgbà.
Narąbie sobie cedrów i bierze cyprys i dąb lub to, co jest najsilniejsze spośród drzew leśnych, wsadzi jesion, który rośnie dzięki deszczom.
15 Ohun èlò ìdáná ni fún ènìyàn; díẹ̀ nínú rẹ̀ ni ó mú láti mú kí ara rẹ̀ lọ́wọ́ọ́rọ́, ó dá iná ó sì fi ṣe àkàrà. Ṣùgbọ́n bákan náà ni ó ṣe òrìṣà tí ó sì ń sìn ín; ó yá ère, ó sì ń foríbalẹ̀ fún un.
Wtedy służy to człowiekowi na opał: bierze z tego, aby się ogrzać, także roznieca ogień, aby upiec chleb, ponadto robi sobie boga i oddaje mu pokłon, czyni z tego posąg i pada przed nim.
16 Ìlàjì igi náà ni ó jó nínú iná; lórí i rẹ̀ ni ó ti ń tọ́jú oúnjẹ rẹ̀, ó dín ẹran rẹ̀ ó sì jẹ àjẹyó. Ó tún mú ara rẹ̀ gbóná ó sì sọ pé, “Á à! Ara mi gbóná, mo rí iná.”
Część tego spala w ogniu, przy drugiej części je mięso – przyrządza pieczeń i syci się. Także grzeje się i mówi: Ach, jak mi ciepło, widziałem ogień.
17 Nínú èyí tí ó kù ni ó ti ṣe òrìṣà, ère rẹ̀; ó foríbalẹ̀ fún un, ó sì sìn ín. Ó gbàdúrà sí i, ó wí pé, “Gbà mí, ìwọ ni Ọlọ́run mi.”
A z reszty tego czyni boga, swój posąg. Pada przed nim, oddaje mu pokłon i modli się do niego, mówiąc: Ratuj mnie, bo ty jesteś moim bogiem.
18 Wọn kò mọ nǹkan kan, nǹkan kan kò yé wọn; a fi ìbòjú bo ojú wọn, wọn kò lè rí nǹkan kan; bẹ́ẹ̀ ni àyà wọn sébọ́, wọn kò lè mọ nǹkan kan.
Nie wiedzą ani nie rozumieją, bo [Bóg] zaślepił ich oczy, aby nie widzieli, i ich serca, aby nie rozumieli.
19 Kò sí ẹni tí ó dúró láti ronú, kò sí ẹni tí ó ní ìmọ̀ tàbí òye láti sọ wí pé, “Ìlàjì rẹ̀ ni mo fi dáná; mo tilẹ̀ ṣe àkàrà lórí èédú rẹ̀, mo dín ẹran, mo sì jẹ ẹ́. Ǹjẹ́ ó wá yẹ kí n ṣe ohun ìríra kan nínú èyí tí ó ṣẹ́kù bí? Ǹjẹ́ èmi yóò ha foríbalẹ̀ fún ìtì igi?”
I nie rozważają tego w swoim sercu, nie mają wiedzy ani rozumu, by powiedzieć: Część tego spaliłem w ogniu, a na węglu z tego wypiekłem chleb, upiekłem mięso i najadłem się. Czyż z reszty tego mam uczynić coś obrzydliwego? Czyż mam padać przed klocem drzewa?
20 Ó ń jẹ eérú, ọkàn ẹlẹ́tàn ni ó ṣì í lọ́nà; òun kò lè gba ara rẹ̀ là, tàbí kí ó wí pé, “Ǹjẹ́ nǹkan tí ó wà lọ́wọ́ ọ̀tún mi yìí irọ́ kọ́?”
Taki się karmi popiołem, jego zwiedzione serce wprowadziło go w błąd, tak że nie może wybawić swojej duszy ani powiedzieć: Czyż nie jest fałszem to, co znajduje się w mojej prawicy?
21 “Rántí àwọn nǹkan wọ̀nyí, ìwọ Jakọbu, nítorí ìránṣẹ́ mi ni ìwọ, ìwọ Israẹli. Èmi ti dá ọ, ìránṣẹ́ mi ni ìwọ ṣe, ìwọ Israẹli, Èmi kì yóò gbàgbé rẹ.
Pamiętaj o tym, Jakubie i Izraelu, gdyż jesteś moim sługą. Stworzyłem cię, jesteś moim sługą. O Izraelu, nie zapomnę o tobie.
22 Èmi ti gbá gbogbo ìkùnà rẹ dànù bí i kurukuru, àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ bí ìrì òwúrọ̀. Padà sọ́dọ̀ mi, nítorí mo ti rà ọ́ padà.”
Zmazałem twoje nieprawości jak obłok, a twoje grzechy jak mgłę. Nawróć się do mnie, bo cię odkupiłem.
23 Kọrin fáyọ̀, ẹ̀yin ọ̀run, nítorí Olúwa ló ti ṣe èyí; kígbe sókè, ìwọ ilẹ̀ ayé nísàlẹ̀. Bú sí orin, ẹ̀yin òkè ńlá, ẹ̀yin igbó àti gbogbo igi yín, nítorí Olúwa ti ra Jakọbu padà, ó ti fi ògo rẹ̀ hàn ní Israẹli.
Śpiewajcie, niebiosa, bo PAN to uczynił. Wykrzykujcie, głębiny ziemi. Rozbrzmiewajcie śpiewaniem góry, lesie wraz ze wszystkimi drzewami; PAN bowiem odkupił Jakuba, a w Izraelu okrył się chwałą.
24 “Ohun tí Olúwa wí nìyìí Olùràpadà rẹ tí ó mọ ọ́ láti inú ìyá rẹ wá: “Èmi ni Olúwa tí ó ti ṣe ohun gbogbo tí òun nìkan ti na àwọn ọ̀run tí o sì tẹ́ ayé pẹrẹsẹ òun tìkára rẹ̀,
Tak mówi PAN, twój Odkupiciel, który cię stworzył już od łona matki: Ja, PAN, wszystko czynię: sam rozciągam niebiosa, rozpościeram ziemię swoją mocą;
25 ta ni ó ba àmì àwọn wòlíì èké jẹ́ tí ó sì sọ àwọn aláfọ̀ṣẹ di òmùgọ̀, tí ó dojú ìmọ̀ àwọn ọlọ́gbọ́n délẹ̀ tí ó sì sọ wọ́n di òmùgọ̀,
Wniwecz obracam znaki kłamców i z wróżbitów czynię szaleńców; mędrców zmuszam do odwrotu, a ich wiedzę czynię głupstwem.
26 ẹni tí ó gbé ọ̀rọ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ jáde tí ó sì mú àsọtẹ́lẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ wá sí ìmúṣẹ, “ẹni tí ó wí nípa ti Jerusalẹmu pé, ‘A ó máa gbé inú rẹ̀,’ àti ní ti àwọn ìlú Juda, ‘A ó tún kọ́,’ àti àwọn ahoro rẹ̀, ‘Èmi yóò mú un bọ̀ sípò,’
Potwierdzam słowa swego sługi i spełniam radę swoich posłańców. Ja mówię do Jerozolimy: Będziesz zamieszkana, do miast Judy: Będziecie odbudowane, bo podniosę jej ruiny;
27 ta ni ó sọ fún omi jíjìn pé, ‘Ìwọ gbẹ, èmi yóò sì mú omi odò rẹ gbẹ,’
To ja mówię głębinie: Wysychaj, ja wysuszę twoje potoki;
28 ta ni ó sọ nípa Kirusi pé, ‘Òun ni Olùṣọ́-àgùntàn mi àti pé òun yóò ṣe ohun gbogbo tí mo fẹ́; òun yóò sọ nípa Jerusalẹmu pé, “Jẹ́ kí a tún kọ́,” àti nípa tẹmpili, “Jẹ́ kí a fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ lé ilẹ̀.”’”
I o Cyrusie mówię: On jest moim pasterzem, bo wypełni całą moją wolę; i mówię do Jerozolimy: Będziesz odbudowana, a do świątyni: Będziesz założona.

< Isaiah 44 >