< Isaiah 44 >

1 “Ṣùgbọ́n gbọ́ nísinsin yìí, ìwọ Jakọbu ìránṣẹ́ mi, àti Israẹli, ẹni tí mo ti yàn.
Na whakarongo, e taku pononga, e Hakopa, e Iharaira, e taku i whiriwhiri ai.
2 Ohun tí Olúwa wí nìyìí ẹni tí ó dá ọ, ẹni tí ó ti mọ̀ ọ́n láti inú ìyá rẹ wá, àti ẹni tí yóò ràn ọ́ lọ́wọ́ pẹ̀lú. Má ṣe bẹ̀rù, ìwọ Jakọbu, ìránṣẹ́ mi, Jeṣuruni ẹni tí mo ti yàn.
Ko te kupu tenei a Ihowa, a tou kaihanga, nana nei koe i whakaahua i roto i te kopu, mana nei koe e awhina, Kaua e wehi, e Hakopa, e taku pononga, e Iehuruna, e taku i whiriwhiri ai.
3 Nítorí èmi yóò da omi sí ilẹ̀ tí ń pòǹgbẹ àti àwọn odò ní ilẹ̀ gbígbẹ, Èmi yóò tú Ẹ̀mí mi sí ara àwọn ọmọ rẹ, àti ìbùkún mi sórí àwọn àrọ́mọdọ́mọ rẹ.
No te mea ka ringihia e ahau he wai ki runga ki te tangata matewai, he awa ki te wahi maroke: ka ringihia e ahau toku wairua ki ou uri, taku manaaki ki tau whanau.
4 Wọn yóò dàgbàsókè gẹ́gẹ́ bí i koríko nínú pápá oko tútù, àti gẹ́gẹ́ bí igi Poplari létí odò tí ń sàn.
A ka tupu ratou i waenga taru, ano he wirou i te taha o nga rerenga wai.
5 Ọ̀kan yóò wí pé, ‘Èmi jẹ́ ti Olúwa’; òmíràn yóò pe ara rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí orúkọ Jakọbu; bẹ́ẹ̀ ni òmíràn yóò kọ ọ́ sí ọwọ́ rẹ̀, ‘Ti Olúwa,’ yóò sì máa jẹ́ orúkọ náà Israẹli.
Ka ki ake tenei, Na Ihowa ahau; ko tetahi atu, karangatia ana e ia ko Hakopa hei ingoa mona; ko tetahi atu, tuhituhi ana tona ringa ki a Ihowa, whakahuatia ake e ia ko Iharaira hei ingoa mona.
6 “Ohun tí Olúwa wí nìyìí ọba Israẹli àti Olùdáǹdè, àní Olúwa àwọn ọmọ-ogun. Èmi ni ẹni àkọ́kọ́ àti ẹni ìgbẹ̀yìn, lẹ́yìn mi kò sí Ọlọ́run kan.
Ko te kupu tenei a Ihowa, a te Kingi o Iharaira, a tona kaihoko ano, a Ihowa o nga mano, Ko ahau te tuatahi ko ahau ano te mutunga; Kahore atu hoki he atua, ko ahau anake.
7 Ta ni ó dàbí ì mi? Jẹ́ kí o kéde rẹ̀. Jẹ́ kí ó wí kí ó sì gbé síwájú mi kí ni ó ti ṣẹlẹ̀ láti ìgbà tí mo fi ìdí àwọn ènìyàn ìṣẹ̀ǹbáyé kalẹ̀, àti kí ni ohun tí ń sì ń bọ̀, bẹ́ẹ̀ ni, jẹ́ kí ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ ohun tí ń bọ̀ wá.
Ko wai hoki hei rite moku, hei karanga, hei whakaatu, hei whakarite kia noho rarangi, mai o toku whakaritenga i te iwi onamata? a ma ratou e whakaatu nga mea meake puta mai, me nga mea ano e puta a mua.
8 Má ṣe wárìrì, má ṣe bẹ̀rù. Ǹjẹ́ èmi kò ti kéde èyí tí mo sì ti sọ àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀ tipẹ́tipẹ́? Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí mi. Ǹjẹ́ Ọlọ́run kan ha ń bẹ lẹ́yìn mi? Bẹ́ẹ̀ kọ́, kò sí àpáta mìíràn; Èmi kò mọ ọ̀kankan.”
Kaua e wehi, kaua e pawera: kihai ianei i korerotia e ahau ki a koe nga mea onamata, i whakaaturia hoki? ko koutou ano hei kaiwhakaatu moku. Tera atu ranei tetahi atua ke? ae ra, kahore he kamaka; kahore ahau e mohio ki tetahi.
9 Gbogbo àwọn tí ń gbẹ́ ère jásí asán, àti àwọn ohun tí wọn ń kó pamọ́ kò jámọ́ nǹkan kan. Àwọn tí yóò sọ̀rọ̀ fún wọn fọ́ lójú; wọ́n jẹ́ aláìmọ̀kan sí ìtìjú ara wọn.
Ko nga kaiwhakaahua o te whakapakoko, he horihori katoa ratou; kahore hoki he pai o a ratou mea ahuareka: ko o ratou kaiwhakaatu kahore e kite, kahore e mohio; e whakama ai ratou.
10 Ta ni ó mọ òrìṣà kan tí ó sì ya ère, tí kò lè mú èrè kankan wá fún un?
Ko wai te kaiwhakaahua o tetahi atua, te kaiwhakarewa ranei o te whakapakoko kahore nei ona pai?
11 Òun àti nǹkan rẹ̀ wọ̀nyí ni a ó dójútì; àwọn oníṣọ̀nà kò yàtọ̀, ènìyàn ni wọ́n. Jẹ́ kí gbogbo wọn gbárajọ kí wọ́n sì fi ìdúró wọn hàn; gbogbo wọn ni a ó mú bọ́ sínú ìpayà àti àbùkù.
Nana, ko ona hoa katoa, ka whakama: ko nga kaimahi ano, he tangata nei ratou: kia huihui mai ratou katoa, tu ai. Ka wehi, ka whakama ngatahi.
12 Alágbẹ̀dẹ mú ohun èlò, ó fi ń ṣiṣẹ́ nínú èédú; ó fi òòlù ya ère kan, ó ṣe é pẹ̀lú agbára apá rẹ̀, ebi ń pa á, àárẹ̀ sì mú un; kò mu omi rárá, ìrẹ̀wẹ̀sì dé bá a.
E hangaia ana e te parakimete he toki, ka mahi i roto i nga waro, whakaahuatia ana e ia ki te hama, puta ana te kaha o tona ringa ki te mahi i taua mea; ka hemo ano ia i te kai, kore noa iho he kaha; kahore e inu i te wai, mauiui noa iho.
13 Gbẹ́nàgbẹ́nà fi ìwọ̀n wọ́n ọ́n ó sì fi lẹ́ẹ̀dì ṣe àmì sí ara rẹ̀, Ó tún fi ìfà fá a jáde ó tún fi òsùwọ̀n ṣe àmì sí i. Ó gbẹ́ ẹ ní ìrí ènìyàn gẹ́gẹ́ bí ènìyàn nínú ògo rẹ̀, kí ó lè máa gbé nínú ilé òrìṣà.
Ko te kamura, whakamarokia mai ana e ia te aho, tuhia iho e ia ki te pene, mahia ana e ia ki te waru; tohungia ana e ia ki te kapehu, mahia ana e ia kia rite ki te ahua o te tangata, ki te ataahua ano o te tangata; hei mea mo roto i te whare.
14 Ó gé igi kedari lulẹ̀, tàbí bóyá ó mú sípírẹ́ṣì tàbí igi óákù. Ó jẹ́ kí ó dàgbà láàrín àwọn igi inú igbó, ó sì le gbin igi páínì, èyí tí òjò mú kí ó dàgbà.
Tuaina ana e ia he hita mana, tikina ana e ia te kaiperi, me te oki, a whakapakaritia ana e ia mana tetahi i roto i nga rakau o te ngahere; whakatokia ana e ia te ahe hei whakatupu ma te ua.
15 Ohun èlò ìdáná ni fún ènìyàn; díẹ̀ nínú rẹ̀ ni ó mú láti mú kí ara rẹ̀ lọ́wọ́ọ́rọ́, ó dá iná ó sì fi ṣe àkàrà. Ṣùgbọ́n bákan náà ni ó ṣe òrìṣà tí ó sì ń sìn ín; ó yá ère, ó sì ń foríbalẹ̀ fún un.
Katahi ka waiho hei wahie ma te tangata: ka tangohia hoki e ia tetahi wahi hei whakamahana i a ia; ina, whakaungia ana e ia, hei tunu taro; na kei te hanga ano ia i tetahi atua, koropikoria atu ana e ia; mahia ana e ia hei whakapakoko, tapapa to nu atu ki reira.
16 Ìlàjì igi náà ni ó jó nínú iná; lórí i rẹ̀ ni ó ti ń tọ́jú oúnjẹ rẹ̀, ó dín ẹran rẹ̀ ó sì jẹ àjẹyó. Ó tún mú ara rẹ̀ gbóná ó sì sọ pé, “Á à! Ara mi gbóná, mo rí iná.”
Ko tetahi wahi o taua rakau, e tahuna ana e ia ki te ahi, ko tetahi wahi, hei mea i te kikokiko hei kai mana; tunua ana e ia tana e tunu ai, a ka makona: ae ra, ka mahana ano ia, a ka mea, Ha, kua mahana ahau, kua kite i te ahi.
17 Nínú èyí tí ó kù ni ó ti ṣe òrìṣà, ère rẹ̀; ó foríbalẹ̀ fún un, ó sì sìn ín. Ó gbàdúrà sí i, ó wí pé, “Gbà mí, ìwọ ni Ọlọ́run mi.”
Ko te toenga, hanga ake e ia hei atua, hei whakapakoko mana: tapapa ana ia, koropiko ana, inoi ana ki taua mea, ka mea, Whakaorangia ahau; ko koe nei hoki toku atua.
18 Wọn kò mọ nǹkan kan, nǹkan kan kò yé wọn; a fi ìbòjú bo ojú wọn, wọn kò lè rí nǹkan kan; bẹ́ẹ̀ ni àyà wọn sébọ́, wọn kò lè mọ nǹkan kan.
Kahore ratou e mohio, kahore e mahara; no te mea kua araia e ia o ratou kanohi kei kite, o ratou ngakau kei matau.
19 Kò sí ẹni tí ó dúró láti ronú, kò sí ẹni tí ó ní ìmọ̀ tàbí òye láti sọ wí pé, “Ìlàjì rẹ̀ ni mo fi dáná; mo tilẹ̀ ṣe àkàrà lórí èédú rẹ̀, mo dín ẹran, mo sì jẹ ẹ́. Ǹjẹ́ ó wá yẹ kí n ṣe ohun ìríra kan nínú èyí tí ó ṣẹ́kù bí? Ǹjẹ́ èmi yóò ha foríbalẹ̀ fún ìtì igi?”
Kahore hoki e anga ake te ngakau o tetahi, kahore e mohio, kahore e matau, e ki ake ai ia, Ko tetahi wahi o tenei i tahunga e ahau ki te ahi; i tunua ano e ahau he taro ki ona ngarahu, tunua ana e ahau he kikokiko, kainga ake e ahau; a kia meing a e ahau te toenga o taua rakau hei mea whakarihariha? me tapapa ranei ahau ki te take rakau?
20 Ó ń jẹ eérú, ọkàn ẹlẹ́tàn ni ó ṣì í lọ́nà; òun kò lè gba ara rẹ̀ là, tàbí kí ó wí pé, “Ǹjẹ́ nǹkan tí ó wà lọ́wọ́ ọ̀tún mi yìí irọ́ kọ́?”
Ko tana kai, he pungarehu; kua tinihangatia tona ngakau, a ngau ke ana ia, te whakaora ia i tona wairua, te ki ake ranei, Kahore ranei he korero teka i toku matau?
21 “Rántí àwọn nǹkan wọ̀nyí, ìwọ Jakọbu, nítorí ìránṣẹ́ mi ni ìwọ, ìwọ Israẹli. Èmi ti dá ọ, ìránṣẹ́ mi ni ìwọ ṣe, ìwọ Israẹli, Èmi kì yóò gbàgbé rẹ.
Kia mahara ki enei, e Hakopa, e Iharaira; he pononga hoki koe naku; naku koe i whai ahua ai, he pononga hoki koe naku: e Iharaira, e kore koe e wareware i ahau.
22 Èmi ti gbá gbogbo ìkùnà rẹ dànù bí i kurukuru, àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ bí ìrì òwúrọ̀. Padà sọ́dọ̀ mi, nítorí mo ti rà ọ́ padà.”
Ko ou he, murua ake e ahau, me te mea he kapua matotoru; ko ou hara, me te mea he kapua: hoki mai ki ahau; naku hoki koe i hoko.
23 Kọrin fáyọ̀, ẹ̀yin ọ̀run, nítorí Olúwa ló ti ṣe èyí; kígbe sókè, ìwọ ilẹ̀ ayé nísàlẹ̀. Bú sí orin, ẹ̀yin òkè ńlá, ẹ̀yin igbó àti gbogbo igi yín, nítorí Olúwa ti ra Jakọbu padà, ó ti fi ògo rẹ̀ hàn ní Israẹli.
Waiata, e nga rangi, he mahi hoki tenei na Ihowa. Hamama, e nga wahi o raro rawa o te whenua. Kia pakaru mai ta koutou waiata, e nga maunga, e te ngahere, e nga rakau katoa o reira; no te mea kua oti a Hakopa te hoko e Ihowa, kua whai kororia ia i a Iharaira.
24 “Ohun tí Olúwa wí nìyìí Olùràpadà rẹ tí ó mọ ọ́ láti inú ìyá rẹ wá: “Èmi ni Olúwa tí ó ti ṣe ohun gbogbo tí òun nìkan ti na àwọn ọ̀run tí o sì tẹ́ ayé pẹrẹsẹ òun tìkára rẹ̀,
Ko te kupu tenei a Ihowa, a tou kaihoko, nana nei koe i whai ahua ai, no roto mai ano i te kopu, Ko Ihowa ahau, ko te kaihanga o nga mea katoa, naku anake nga rangi i hora, naku i takoto ai te whenua: ko wai toku hoa?
25 ta ni ó ba àmì àwọn wòlíì èké jẹ́ tí ó sì sọ àwọn aláfọ̀ṣẹ di òmùgọ̀, tí ó dojú ìmọ̀ àwọn ọlọ́gbọ́n délẹ̀ tí ó sì sọ wọ́n di òmùgọ̀,
Ko nga tohu a te hunga korero teka he ana i a ia, ko nga tohunga tuaahu whakahaurangitia ana e ia; ko te hunga whakaaro nui, whakahokia ana e ia ki muri, ko to ratou matauranga, whakapoauautia iho.
26 ẹni tí ó gbé ọ̀rọ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ jáde tí ó sì mú àsọtẹ́lẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ wá sí ìmúṣẹ, “ẹni tí ó wí nípa ti Jerusalẹmu pé, ‘A ó máa gbé inú rẹ̀,’ àti ní ti àwọn ìlú Juda, ‘A ó tún kọ́,’ àti àwọn ahoro rẹ̀, ‘Èmi yóò mú un bọ̀ sípò,’
Mana pu i a ia te kupu a tana pononga, te whakaaro a ana karere rite rawa i a ia; ko tana kupu ki Hiruharama, Ka nohoia koe; ki nga pa o Hura, Ka hanga koutou; maku ano e whakaara ona wahi kua ururuatia.
27 ta ni ó sọ fún omi jíjìn pé, ‘Ìwọ gbẹ, èmi yóò sì mú omi odò rẹ gbẹ,’
Ko tana kupu ki te rire, Kia mimiti: maku ano e whakamaroke ou awa.
28 ta ni ó sọ nípa Kirusi pé, ‘Òun ni Olùṣọ́-àgùntàn mi àti pé òun yóò ṣe ohun gbogbo tí mo fẹ́; òun yóò sọ nípa Jerusalẹmu pé, “Jẹ́ kí a tún kọ́,” àti nípa tẹmpili, “Jẹ́ kí a fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ lé ilẹ̀.”’”
Ko tana kupu mo Hairuha, He hepara ia naku, ka rite ano i a ia taku katoa i pai ai; mana hoki e ki ki Hiruharama, Ka hanga koe; a ki te temepara, Ka whakatakotoria ou turanga.

< Isaiah 44 >