< Isaiah 44 >

1 “Ṣùgbọ́n gbọ́ nísinsin yìí, ìwọ Jakọbu ìránṣẹ́ mi, àti Israẹli, ẹni tí mo ti yàn.
Maintenant écoute, Jacob mon serviteur, Israël mon élu.
2 Ohun tí Olúwa wí nìyìí ẹni tí ó dá ọ, ẹni tí ó ti mọ̀ ọ́n láti inú ìyá rẹ wá, àti ẹni tí yóò ràn ọ́ lọ́wọ́ pẹ̀lú. Má ṣe bẹ̀rù, ìwọ Jakọbu, ìránṣẹ́ mi, Jeṣuruni ẹni tí mo ti yàn.
Voici ce que dit le Seigneur Dieu qui t'a créé, qui t'a formé dès les entrailles de ta mère: Tu seras encore secouru; ne crains pas, mon serviteur Jacob, mon bien-aimé, Israël mon élu.
3 Nítorí èmi yóò da omi sí ilẹ̀ tí ń pòǹgbẹ àti àwọn odò ní ilẹ̀ gbígbẹ, Èmi yóò tú Ẹ̀mí mi sí ara àwọn ọmọ rẹ, àti ìbùkún mi sórí àwọn àrọ́mọdọ́mọ rẹ.
Je donnerai de l'eau dans leur soif à ceux qui traversent la terre aride; je ferai descendre mon esprit sur ta semence, et mes bénédictions sur tes enfants.
4 Wọn yóò dàgbàsókè gẹ́gẹ́ bí i koríko nínú pápá oko tútù, àti gẹ́gẹ́ bí igi Poplari létí odò tí ń sàn.
Et ils croîtront comme l'herbe entre les ruisseaux, comme le saule sur le bord d'une eau courante.
5 Ọ̀kan yóò wí pé, ‘Èmi jẹ́ ti Olúwa’; òmíràn yóò pe ara rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí orúkọ Jakọbu; bẹ́ẹ̀ ni òmíràn yóò kọ ọ́ sí ọwọ́ rẹ̀, ‘Ti Olúwa,’ yóò sì máa jẹ́ orúkọ náà Israẹli.
Celui-ci dira: Je suis de Dieu. Celui-là se glorifiera du nom de Jacob; cet autre écrira de sa main: Je suis de Dieu, et se glorifiera du nom d'Israël.
6 “Ohun tí Olúwa wí nìyìí ọba Israẹli àti Olùdáǹdè, àní Olúwa àwọn ọmọ-ogun. Èmi ni ẹni àkọ́kọ́ àti ẹni ìgbẹ̀yìn, lẹ́yìn mi kò sí Ọlọ́run kan.
Voici ce que dit le Dieu, roi d'Israël, le Dieu des armées, rédempteur de Jacob: Je suis le premier, et je suis le dernier; hormis moi, il n'est point de Dieu.
7 Ta ni ó dàbí ì mi? Jẹ́ kí o kéde rẹ̀. Jẹ́ kí ó wí kí ó sì gbé síwájú mi kí ni ó ti ṣẹlẹ̀ láti ìgbà tí mo fi ìdí àwọn ènìyàn ìṣẹ̀ǹbáyé kalẹ̀, àti kí ni ohun tí ń sì ń bọ̀, bẹ́ẹ̀ ni, jẹ́ kí ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ ohun tí ń bọ̀ wá.
Qui est semblable à moi? Que celui-là se présente; qu'il rappelle, proclame et m'explique ce que j'ai fait pour l'homme depuis le commencement des siècles; qu'ils vous fassent connaître d'avance les choses de l'avenir.
8 Má ṣe wárìrì, má ṣe bẹ̀rù. Ǹjẹ́ èmi kò ti kéde èyí tí mo sì ti sọ àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀ tipẹ́tipẹ́? Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí mi. Ǹjẹ́ Ọlọ́run kan ha ń bẹ lẹ́yìn mi? Bẹ́ẹ̀ kọ́, kò sí àpáta mìíràn; Èmi kò mọ ọ̀kankan.”
Ne dissimulez pas, ne divaguez point, dès le commencement n'avez-vous pas ouï cela de vos oreilles? Ne vous l'ai-je pas déclaré? Vous êtes mes témoins; hormis moi, il n'est point de Dieu. Et ils n'existaient pas ainsi,
9 Gbogbo àwọn tí ń gbẹ́ ère jásí asán, àti àwọn ohun tí wọn ń kó pamọ́ kò jámọ́ nǹkan kan. Àwọn tí yóò sọ̀rọ̀ fún wọn fọ́ lójú; wọ́n jẹ́ aláìmọ̀kan sí ìtìjú ara wọn.
Les artisans, les sculpteurs d'idoles, tous insensés, faisant à leur fantaisie des choses qui ne leur serviront de rien. Mais ils seront confondus.
10 Ta ni ó mọ òrìṣà kan tí ó sì ya ère, tí kò lè mú èrè kankan wá fún un?
Tous ceux qui façonnent un dieu, et qui sculptent des choses inutiles,
11 Òun àti nǹkan rẹ̀ wọ̀nyí ni a ó dójútì; àwọn oníṣọ̀nà kò yàtọ̀, ènìyàn ni wọ́n. Jẹ́ kí gbogbo wọn gbárajọ kí wọ́n sì fi ìdúró wọn hàn; gbogbo wọn ni a ó mú bọ́ sínú ìpayà àti àbùkù.
Tous les auteurs de ces vanités ont tous disparu; rassemblez ces hommes sourds, tenez-les réunis; que tous ensemble ils soient humiliés, qu'ils soient tous confondus.
12 Alágbẹ̀dẹ mú ohun èlò, ó fi ń ṣiṣẹ́ nínú èédú; ó fi òòlù ya ère kan, ó ṣe é pẹ̀lú agbára apá rẹ̀, ebi ń pa á, àárẹ̀ sì mú un; kò mu omi rárá, ìrẹ̀wẹ̀sì dé bá a.
L'artisan a aiguisé le fer; il a pris la hache, il a employé la tarière; il a fait son œuvre par l'effort de ses bras; et il aura faim, et il sera sans force, et il n'aura pas d'eau à boire. Ayant choisi
13 Gbẹ́nàgbẹ́nà fi ìwọ̀n wọ́n ọ́n ó sì fi lẹ́ẹ̀dì ṣe àmì sí ara rẹ̀, Ó tún fi ìfà fá a jáde ó tún fi òsùwọ̀n ṣe àmì sí i. Ó gbẹ́ ẹ ní ìrí ènìyàn gẹ́gẹ́ bí ènìyàn nínú ògo rẹ̀, kí ó lè máa gbé nínú ilé òrìṣà.
L'arbre, l'artisan l'a dressé avec la mesure, l'a collé et ajusté; puis il lui a donné la forme d'un mortel et la beauté d'un homme pour le placer dans un temple.
14 Ó gé igi kedari lulẹ̀, tàbí bóyá ó mú sípírẹ́ṣì tàbí igi óákù. Ó jẹ́ kí ó dàgbà láàrín àwọn igi inú igbó, ó sì le gbin igi páínì, èyí tí òjò mú kí ó dàgbà.
Il a abattu un arbre de la forêt, un arbre qu'avait planté le Seigneur, un pin que la pluie avait fait croître
15 Ohun èlò ìdáná ni fún ènìyàn; díẹ̀ nínú rẹ̀ ni ó mú láti mú kí ara rẹ̀ lọ́wọ́ọ́rọ́, ó dá iná ó sì fi ṣe àkàrà. Ṣùgbọ́n bákan náà ni ó ṣe òrìṣà tí ó sì ń sìn ín; ó yá ère, ó sì ń foríbalẹ̀ fún un.
Pour qu'il fût brûlé par les hommes; il en a pris une part et s'en est chauffé; sur la braise ils ont cuit des pains; et avec le reste ils ont façonné des dieux, et ils les adorent.
16 Ìlàjì igi náà ni ó jó nínú iná; lórí i rẹ̀ ni ó ti ń tọ́jú oúnjẹ rẹ̀, ó dín ẹran rẹ̀ ó sì jẹ àjẹyó. Ó tún mú ara rẹ̀ gbóná ó sì sọ pé, “Á à! Ara mi gbóná, mo rí iná.”
Il n'en a pas brûlé la moitié; et sur cette moitié il s'est servi des braises pour faire cuire des pains et rôtir des chairs qu'il a mangées; il s'est rassasié, et après s'être chauffé il a dit: il m'est doux de me chauffer et de voir la flamme.
17 Nínú èyí tí ó kù ni ó ti ṣe òrìṣà, ère rẹ̀; ó foríbalẹ̀ fún un, ó sì sìn ín. Ó gbàdúrà sí i, ó wí pé, “Gbà mí, ìwọ ni Ọlọ́run mi.”
Et avec le reste il a sculpté un dieu; et il l'adorera et le priera, disant: protège-moi, car tu es mon Dieu.
18 Wọn kò mọ nǹkan kan, nǹkan kan kò yé wọn; a fi ìbòjú bo ojú wọn, wọn kò lè rí nǹkan kan; bẹ́ẹ̀ ni àyà wọn sébọ́, wọn kò lè mọ nǹkan kan.
Ils n'ont rien su comprendre; leurs yeux obscurcis ne voient plus; leurs cœurs ne sentent rien.
19 Kò sí ẹni tí ó dúró láti ronú, kò sí ẹni tí ó ní ìmọ̀ tàbí òye láti sọ wí pé, “Ìlàjì rẹ̀ ni mo fi dáná; mo tilẹ̀ ṣe àkàrà lórí èédú rẹ̀, mo dín ẹran, mo sì jẹ ẹ́. Ǹjẹ́ ó wá yẹ kí n ṣe ohun ìríra kan nínú èyí tí ó ṣẹ́kù bí? Ǹjẹ́ èmi yóò ha foríbalẹ̀ fún ìtì igi?”
Et cet homme n'a point raisonné en son âme; il n'a pas su comprendre qu'il a brûlé la moitié de l'arbre, et que sur ses braises il a cuit du pain, il a rôti des chairs dont il s'est nourri, et qu'avec le reste il a fabriqué une abomination qu'on adore.
20 Ó ń jẹ eérú, ọkàn ẹlẹ́tàn ni ó ṣì í lọ́nà; òun kò lè gba ara rẹ̀ là, tàbí kí ó wí pé, “Ǹjẹ́ nǹkan tí ó wà lọ́wọ́ ọ̀tún mi yìí irọ́ kọ́?”
Sache que le cœur de ces dieux n'est que cendre; mais ils sont égarés, et nul d'eux ne peut sauver son âme. Voyez, et ne direz-vous pas: Cette œuvre de ma main n'est qu'un mensonge?
21 “Rántí àwọn nǹkan wọ̀nyí, ìwọ Jakọbu, nítorí ìránṣẹ́ mi ni ìwọ, ìwọ Israẹli. Èmi ti dá ọ, ìránṣẹ́ mi ni ìwọ ṣe, ìwọ Israẹli, Èmi kì yóò gbàgbé rẹ.
Souviens-toi de ces choses, ô Jacob, ô Israël, car tu es mon serviteur; je t'ai créé pour me servir; ô Israël, ne m'oublie pas.
22 Èmi ti gbá gbogbo ìkùnà rẹ dànù bí i kurukuru, àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ bí ìrì òwúrọ̀. Padà sọ́dọ̀ mi, nítorí mo ti rà ọ́ padà.”
Car voilà que j'ai effacé tes péchés comme un nuage; et ton iniquité, comme une vapeur. Reviens à moi, et je te rachèterai.
23 Kọrin fáyọ̀, ẹ̀yin ọ̀run, nítorí Olúwa ló ti ṣe èyí; kígbe sókè, ìwọ ilẹ̀ ayé nísàlẹ̀. Bú sí orin, ẹ̀yin òkè ńlá, ẹ̀yin igbó àti gbogbo igi yín, nítorí Olúwa ti ra Jakọbu padà, ó ti fi ògo rẹ̀ hàn ní Israẹli.
Cieux, réjouissez-vous. Dieu a eu pitié d'Israël; sonnez de la trompette, fondements de la terre; montagnes, poussez des cris d'allégresse; et vous, collines, et vous, arbres qui les couvrez, le Seigneur a racheté Jacob, et Israël sera glorifié.
24 “Ohun tí Olúwa wí nìyìí Olùràpadà rẹ tí ó mọ ọ́ láti inú ìyá rẹ wá: “Èmi ni Olúwa tí ó ti ṣe ohun gbogbo tí òun nìkan ti na àwọn ọ̀run tí o sì tẹ́ ayé pẹrẹsẹ òun tìkára rẹ̀,
Voici ce que dit le Seigneur, qui t'a racheté et qui t'a formé dès les entrailles de ta mère: Je suis le Seigneur qui accomplit toutes choses; seul j'ai tendu les cieux et j'ai affermi la terre.
25 ta ni ó ba àmì àwọn wòlíì èké jẹ́ tí ó sì sọ àwọn aláfọ̀ṣẹ di òmùgọ̀, tí ó dojú ìmọ̀ àwọn ọlọ́gbọ́n délẹ̀ tí ó sì sọ wọ́n di òmùgọ̀,
Quel autre que moi dissipera les signes des magiciens et détournera des cœurs les prédictions des devins? Je suis le Seigneur; c'est moi qui renverse la sagesse des sages, et qui rends vains leurs conseils.
26 ẹni tí ó gbé ọ̀rọ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ jáde tí ó sì mú àsọtẹ́lẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ wá sí ìmúṣẹ, “ẹni tí ó wí nípa ti Jerusalẹmu pé, ‘A ó máa gbé inú rẹ̀,’ àti ní ti àwọn ìlú Juda, ‘A ó tún kọ́,’ àti àwọn ahoro rẹ̀, ‘Èmi yóò mú un bọ̀ sípò,’
C'est moi qui affermis la parole de mon serviteur, qui confirme les conseils de mes messagers, et qui dis à Jérusalem: Tu seras repeuplée; et aux villes de l'Idumée: Vous serez rebâties, et vos champs dévastés refleuriront.
27 ta ni ó sọ fún omi jíjìn pé, ‘Ìwọ gbẹ, èmi yóò sì mú omi odò rẹ gbẹ,’
C'est moi qui dis à l'abîme: Tu seras épuisé, et je dessècherai tes fleuves.
28 ta ni ó sọ nípa Kirusi pé, ‘Òun ni Olùṣọ́-àgùntàn mi àti pé òun yóò ṣe ohun gbogbo tí mo fẹ́; òun yóò sọ nípa Jerusalẹmu pé, “Jẹ́ kí a tún kọ́,” àti nípa tẹmpili, “Jẹ́ kí a fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ lé ilẹ̀.”’”
C'est moi qui dis à Cyrus: Sois prudent, et tu accompliras toutes mes volontés; et qui dis à Jérusalem: Tu seras rebâtie, et je jetterai les fondations de mon saint temple.

< Isaiah 44 >