< Isaiah 43 >

1 Ṣùgbọ́n ní ìsinsin yìí, ohun tí Olúwa wí nìyìí, ẹni tí ó dá ọ, ìwọ Jakọbu, ẹni tí ó mọ ọ́, ìwọ Israẹli: “Má bẹ̀rù, nítorí Èmi ti dá ọ nídè; Èmi ti pè ọ́ ní orúkọ; tèmi ni ìwọ ṣe.
Ngem ita, kastoy ti kuna ni Yahweh, a namarsua kenka Jacob, ken nangsukog kenka Israel: “Saanka nga agbuteng, gapu ta sinubotka; Inawaganka babaen iti naganmo, kukuaka.
2 Nígbà tí ìwọ bá ń la omi kọjá, Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ; àti nígbà tí ìwọ bá ń la odò kọjá wọn kì yóò bò ọ́ mọ́lẹ̀. Nígbà tí ìwọ bá la iná kọjá, kò ní jó ọ; ahọ́n iná kò ní jó ọ lára.
No lumasatka iti danum addaakto kenka; ken iti panagballasiwmo kadagiti karayan, saankanto a malipus. Inton magnaka iti apuy saankanto a mauram, wenno madangran iti apuy.
3 Nítorí Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ, Ẹni Mímọ́ Israẹli Olùgbàlà rẹ; Èmi fi Ejibiti ṣe ìràpadà rẹ, Kuṣi àti Seba dípò rẹ.
Ta siak ni Yahweh a Diosmo, a Nasantoan a Dios ti Israel, a Mangisalakanmo. Intedko ti Egipto kas pannakasubbotmo, ti Etiopia ken Seba kas kasukatmo.
4 Nítorí pé o ṣe iyebíye àti ọ̀wọ́n níwájú mi, àti nítorí pé mo fẹ́ràn rẹ, Èmi yóò fi ènìyàn rọ́pò fún ọ, àti ènìyàn dípò ẹ̀mí rẹ.
Yantangay ta napateg ken naisangsangayanka iti imatangko, ay-ayatenka; isu nga iyawatko dagiti tattao a kas kasukatmo, ken dagiti dadduma a tattao a kas kasukat ti biagmo.
5 Má bẹ̀rù nítorí èmi wà pẹ̀lú rẹ; Èmi yóò mú àwọn ọmọ rẹ láti ìlà-oòrùn wá èmi ó sì kó ọ jọ láti ìwọ̀-oòrùn.
Saanka nga agbuteng, ta addaak kenka; ummongekto dagiti kaputotam manipud iti daya, ken ummongenkayonto manipud itilaud.
6 Èmi yóò sọ fún àríwá pé, ‘Fi wọ́n sílẹ̀!’ Àti fún gúúsù, ‘Má ṣe dá wọn dúró.’ Mú àwọn ọmọkùnrin mi láti ọ̀nà jíjìn wá àti àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin mi láti ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé—
Ibagakto iti amianan, 'Palubosam ida,' ken iti abagatan, 'Saanmo ida nga igawid;' Iyegmo dagiti annakko a lallaki manipud iti adayo, ken dagiti annakko a babbai manipud kadagiti nasulinek a rehion ti daga,
7 ẹnikẹ́ni tí a ń pe orúkọ mi mọ́, tí mo dá fún ògo mi, tí mo mọ̀ àti tí mo ṣe.”
tunggal maysa a naawagan iti naganko, a pinarsuak a maipaay iti dayagko, a sinukogko, wen, nga inaramidko.
8 Sin àwọn tí ó ní ojú ṣùgbọ́n tí wọ́n fọ́jú jáde, tí wọ́n ní etí ṣùgbọ́n tí wọn dití.
Iruarmo dagiti bulsek a tattao, nga addaan kadagiti mata, ken dagiti tuleng, uray pay addaanda kadagiti lapayag.
9 Gbogbo orílẹ̀-èdè kó ra wọn jọ àwọn ènìyàn sì kó ra wọn papọ̀. Ta ni nínú wọn tó sọ àsọtẹ́lẹ̀ yìí tí ó sì kéde fún wa àwọn nǹkan ti tẹ́lẹ̀? Jẹ́ kí wọ́n mú àwọn ẹlẹ́rìí wọn wọlé wá láti fihàn pé wọ́n tọ̀nà tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn mìíràn yóò gbọ́, tí wọn yóò sọ pé, “Òtítọ́ ni.”
Agguummong amin dagiti nasion, ken agtataripnong dagiti tattao. Adda kadi kadakuada ti nakabael a nangipakaammo iti daytoy ken nakaiwaragawag kadatayo kadagiti mapasamakto iti masakbayan? Bay-anyo nga iyegda dagiti saksida a mangpaneknek a hustoda, bay-anyo a dumngegda ken paneknekanda, ‘Pudno daytoy.'
10 “Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí mi,” ni Olúwa wí, “Àti ìránṣẹ́ mi tí èmi ti yàn, tó bẹ́ẹ̀ tí ẹ̀yin yóò fi mọ̀ àti tí ẹ̀yin ó fi gbà mí gbọ́ tí yóò sì yé e yín pé èmi ni ẹni náà. Ṣáájú mi kò sí ọlọ́run tí a dá, tàbí a ó wa rí òmíràn lẹ́yìn mi.
Dakayo dagiti saksik,” kuna ni Yahweh, “ken dagiti adipenko a pinilik, tapno iti kasta, maammoandak koma ken patiendak, ken maawatanyo a siak isuna. Sakbay kaniak awan ti dios a naaramid, ken awanto ti sumaruno kaniak.
11 Èmi, àní Èmi, Èmi ni Olúwa, yàtọ̀ sí èmi, kò sí olùgbàlà mìíràn.
Siak, Siak ni Yahweh, ket awan ti sabali pay a mangisalakan no di siak.
12 Èmi ti fihàn, mo gbàlà mo sì ti kéde Èmi, kì í sì í ṣe àwọn àjèjì òrìṣà láàrín yín. Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí mi,” ni Olúwa wí, “Pé Èmi ni Ọlọ́run.
Impakpakaunak, nangisalakanak, ken impakammok, ket awan ti sabali pay a dios kadakayo. Dakayo dagiti saksik,” kuna ni Yahweh, “Siak ti Dios.
13 Bẹ́ẹ̀ ni, àti láti ayérayé Èmi ni ẹni náà. Kò sí ẹnikẹ́ni tí ó lè gbà kúrò lọ́wọ́ mi. Nígbà tí mo bá ṣe nǹkan, ta ni ó lè yí i padà?”
Manipud ita siak isuna, ket awan ti makaisalakan iti siasinoman manipud kadagiti imak. Agtigtignayak, ket adda kadi iti makaisubli iti daytoy?”
14 Èyí ni ohun tí Olúwa wí, olùràpadà rẹ, Ẹni Mímọ́ ti Israẹli: “Nítorí rẹ Èmi yóò ránṣẹ́ sí Babeli láti mú wọn sọ̀kalẹ̀ wá gẹ́gẹ́ bí ìsáǹsá, gbogbo ará Babeli, nínú ọkọ̀ ojú omi nínú èyí tí wọ́n fi ń ṣe ìgbéraga.
Kastoy ti kuna ni Yahweh, ti Mannubotyo, a Nasantoan a Dios ti Israel: “Para kadakayo nangibaonak iti mangdarup iti Babilonia a mamagbalin kadakuada amin nga aglemmelemmeng, a mamagbalin kadagiti rag-o ti Babilonia a kankanta a pangdung-aw.
15 Èmi ni Olúwa, Ẹni Mímọ́ rẹ, Ẹlẹ́dàá Israẹli, ọba rẹ.”
Siak ni Yahweh, a Nasantoanyo, a Nangparsua iti Israel, ti Ariyo.”
16 Èyí ni ohun tí Olúwa wí, Ẹni náà tí ó la ọ̀nà nínú Òkun, ipa ọ̀nà láàrín alagbalúgbú omi,
Kastoy ti kuna ni Yahweh (a nangilukat iti dalan iti baybay ken pagnaan kadagiti nadawel a danum,
17 ẹni tí ó wọ́ àwọn kẹ̀kẹ́ àti ẹṣin jáde, àwọn jagunjagun àti ohun ìjà papọ̀, wọ́n sì sùn síbẹ̀, láìní lè dìde mọ́, wọ́n kú pirá bí òwú-fìtílà:
a nangiturong iti karwahe ken kabalio, iti armada ken iti nabileg unay. Limnedda a sangsangkamaysa; ket saandanto a pulos lummung-aw; napaksiatda, naiddep a kasla apuy ti pabilo.)
18 “Gbàgbé àwọn ohun àtẹ̀yìnwá; má ṣe gbé nínú ohun àtijọ́.
Saanyo nga amirisen dagiti napasamak iti naglabas, wenno panunoten dagiti banbanag a napasamak iti nabayagen a panawen.
19 Wò ó, Èmi ń ṣe ohun tuntun! Nísinsin yìí, ó ti yọ sókè; àbí o kò rí i bí? Èmi ń ṣe ọ̀nà kan nínú aṣálẹ̀ àti odò nínú ilẹ̀ ṣíṣá.
Dumngegkayo, mangaramidak iti baro a banag; ita, mapasamaken; saanyo kadi a madmadlaw daytoy? Mangaramidak iti dalan idiay disierto ken pagayusek iti let-ang dagiti danum.
20 Àwọn ẹhànnà ẹranko bọ̀wọ̀ fún mi, àwọn ajáko àti àwọn òwìwí, nítorí pé mo pèsè omi nínú aṣálẹ̀ àti odò nínú ilẹ̀ sísá, láti fi ohun mímu fún àwọn ènìyàn mi, àyànfẹ́ mi,
Dayawendakto dagiti atap nga ayup nga adda kadagiti away, dagiti atap nga aso ken dagiti abestrus, gapu ta mangmangtedak iti danum iti let-ang, ken kadagiti karayan iti disierto, nga inumen dagiti tattao a pinilik,
21 àwọn ènìyàn tí mo dá fún ara mi kí wọn kí ó lè kéde ìyìn mi.
dagitoy a tattao nga inaramidko a para kaniak, tapno ipakaamoda koma dagiti pakaidaydayawak.
22 “Síbẹ̀síbẹ̀ ìwọ kò tí ì ké pè mí, ìwọ Jakọbu, àárẹ̀ kò tí ì mú ọ nítorí mi ìwọ Israẹli.
Ngem saanka nga immawag kaniak, Jacob; naumaka kaniak Israel.
23 Ìwọ kò tí ì mú àgùntàn wá fún mi fún ẹbọ sísun, tàbí kí o bọ̀wọ̀ fún mi pẹ̀lú ẹbọ rẹ. Èmi kò tí ì wàhálà rẹ pẹ̀lú ọrẹ ìyẹ̀fun tàbí kí n dààmú rẹ pẹ̀lú ìbéèrè fún tùràrí.
Saanka a nangidatag kaniak iti uray ania kadagiti karnerom a kas daton a maipuor; wenno pinadayawannak koma babaen kadagiti sakripisiom. Saanka a pinadagsenan gapu kadagiti sagut a trigo, wenno binannog gapu kadagiti sagut nga insenso.
24 Ìwọ kò tí ì ra kalamusi olóòórùn dídùn fún mi, tàbí kí o da ọ̀rá ẹbọ rẹ bò mí. Ṣùgbọ́n ẹ ti wàhálà mi pẹ̀lú ẹ̀ṣẹ̀ yín ẹ sì ti dààmú mi pẹ̀lú àìṣedéédéé yín.
Saannak nga inggatangan iti nabanglo a runo, wenno indaton kaniak ti taba manipud kadagiti ayup a datonmo; ngem ketdi pinadagsenannak kadagiti basbasolmo, binannognak gapu kadagiti dakes nga aramidmo.
25 “Èmi, àní Èmi, Èmi ni ẹni tí ó wẹ àwọn àìṣedéédéé rẹ nù, nítorí èmi fún ara mi, tí n kò sì rántí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ mọ́.
Siak, wen Siak ti mangik-ikkat kadagiti basbasolmo para met laeng kaniak; ken saankon a pulos a lagipen pay dagiti basbasolmo.
26 Bojú wo ẹ̀yìn rẹ fún mi, jẹ́ kí a jọ ṣe àríyànjiyàn ọ̀rọ̀ náà papọ̀; ro ẹjọ́ láti fihàn pé o kò lẹ́sẹ̀ lọ́rùn.
Ipalagipmo kaniak no ania dagiti napasamak. Agrikiarta; ibagam dagiti rasonmo, a mangpaneknek nga awan basolmo.
27 Baba yín àkọ́kọ́ dẹ́ṣẹ̀; àwọn agbẹnusọ yín ṣọ̀tẹ̀ sí mi.
Nagbasol ti immuna nga amam, ken sinukirdak dagiti mangidadaulom.
28 Nítorí náà, èmi ti sọ àwọn olórí ibi mímọ́ náà di àìmọ́, bẹ́ẹ̀ ni èmi ti fi Jakọbu fún ègún àti Israẹli fún ẹ̀gàn.
Ngarud, tulawakto dagiti nasantoan nga opisial; iyawatkonto ti Jacob iti naan-anay a pannakadadael, ken ti Israel iti nakaro a pannakaibabain.”

< Isaiah 43 >