< Isaiah 43 >

1 Ṣùgbọ́n ní ìsinsin yìí, ohun tí Olúwa wí nìyìí, ẹni tí ó dá ọ, ìwọ Jakọbu, ẹni tí ó mọ ọ́, ìwọ Israẹli: “Má bẹ̀rù, nítorí Èmi ti dá ọ nídè; Èmi ti pè ọ́ ní orúkọ; tèmi ni ìwọ ṣe.
És most, oh Jákób, így szól az Úr, a te Teremtőd, és a te alkotód, Izráel: Ne félj, mert megváltottalak, neveden hívtalak téged, enyém vagy!
2 Nígbà tí ìwọ bá ń la omi kọjá, Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ; àti nígbà tí ìwọ bá ń la odò kọjá wọn kì yóò bò ọ́ mọ́lẹ̀. Nígbà tí ìwọ bá la iná kọjá, kò ní jó ọ; ahọ́n iná kò ní jó ọ lára.
Mikor vizen mégy át, én veled vagyok, és ha folyókon, azok el nem borítnak, ha tűzben jársz, nem égsz meg, és a láng meg nem perzsel téged.
3 Nítorí Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ, Ẹni Mímọ́ Israẹli Olùgbàlà rẹ; Èmi fi Ejibiti ṣe ìràpadà rẹ, Kuṣi àti Seba dípò rẹ.
Mert én vagyok az Úr, a te Istened, Izráelnek Szentje, a te megtartód, adtam váltságodba Égyiptomot, Kúst és Sebát helyetted.
4 Nítorí pé o ṣe iyebíye àti ọ̀wọ́n níwájú mi, àti nítorí pé mo fẹ́ràn rẹ, Èmi yóò fi ènìyàn rọ́pò fún ọ, àti ènìyàn dípò ẹ̀mí rẹ.
Mivel kedves vagy az én szemeimben, becses vagy és én szeretlek: embereket adok helyetted, és népeket a te életedért:
5 Má bẹ̀rù nítorí èmi wà pẹ̀lú rẹ; Èmi yóò mú àwọn ọmọ rẹ láti ìlà-oòrùn wá èmi ó sì kó ọ jọ láti ìwọ̀-oòrùn.
Ne félj, mert én veled vagyok, napkeletről meghozom magodat, és napnyugotról egybegyűjtelek.
6 Èmi yóò sọ fún àríwá pé, ‘Fi wọ́n sílẹ̀!’ Àti fún gúúsù, ‘Má ṣe dá wọn dúró.’ Mú àwọn ọmọkùnrin mi láti ọ̀nà jíjìn wá àti àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin mi láti ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé—
Mondom északnak: add meg; és délnek: ne tartsd vissza, hozd meg az én fiaimat messzünnen, és leányimat a földnek végéről,
7 ẹnikẹ́ni tí a ń pe orúkọ mi mọ́, tí mo dá fún ògo mi, tí mo mọ̀ àti tí mo ṣe.”
Mindent, a ki csak az én nevemről neveztetik, a kit dicsőségemre teremtettem, a kit alkottam és készítettem!
8 Sin àwọn tí ó ní ojú ṣùgbọ́n tí wọ́n fọ́jú jáde, tí wọ́n ní etí ṣùgbọ́n tí wọn dití.
Hozd ki a vak népet, a melynek szemei vannak, és a süketeket, a kiknek füleik vannak!
9 Gbogbo orílẹ̀-èdè kó ra wọn jọ àwọn ènìyàn sì kó ra wọn papọ̀. Ta ni nínú wọn tó sọ àsọtẹ́lẹ̀ yìí tí ó sì kéde fún wa àwọn nǹkan ti tẹ́lẹ̀? Jẹ́ kí wọ́n mú àwọn ẹlẹ́rìí wọn wọlé wá láti fihàn pé wọ́n tọ̀nà tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn mìíràn yóò gbọ́, tí wọn yóò sọ pé, “Òtítọ́ ni.”
Minden népek gyűljenek egybe, és seregeljenek össze a népségek: ki hirdethet közülök ilyet? Vagy a régieket tudassák velünk, állítsák elő tanuikat, hogy igazuk legyen, hogy ezek hallván, ezt mondják: Igaz.
10 “Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí mi,” ni Olúwa wí, “Àti ìránṣẹ́ mi tí èmi ti yàn, tó bẹ́ẹ̀ tí ẹ̀yin yóò fi mọ̀ àti tí ẹ̀yin ó fi gbà mí gbọ́ tí yóò sì yé e yín pé èmi ni ẹni náà. Ṣáájú mi kò sí ọlọ́run tí a dá, tàbí a ó wa rí òmíràn lẹ́yìn mi.
Ti vagytok az én tanuim, így szól az Úr; és szolgám, a kit elválasztottam, hogy megtudjátok és higyjetek nékem és megértsétek, hogy én vagyok az, előttem Isten nem alkottatott, és utánam nem lesz!
11 Èmi, àní Èmi, Èmi ni Olúwa, yàtọ̀ sí èmi, kò sí olùgbàlà mìíràn.
Én, én vagyok az Úr, és rajtam kivül nincsen szabadító!
12 Èmi ti fihàn, mo gbàlà mo sì ti kéde Èmi, kì í sì í ṣe àwọn àjèjì òrìṣà láàrín yín. Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí mi,” ni Olúwa wí, “Pé Èmi ni Ọlọ́run.
Én hirdettem, és megtartottam, és megjelentettem, és nem volt idegen isten köztetek, és ti vagytok az én tanuim, így szól az Úr, hogy én Isten vagyok.
13 Bẹ́ẹ̀ ni, àti láti ayérayé Èmi ni ẹni náà. Kò sí ẹnikẹ́ni tí ó lè gbà kúrò lọ́wọ́ mi. Nígbà tí mo bá ṣe nǹkan, ta ni ó lè yí i padà?”
Mostantól fogva is én az leszek, és nincs, a ki az én kezemből kimentsen; cselekszem, és ki változtatja azt meg?
14 Èyí ni ohun tí Olúwa wí, olùràpadà rẹ, Ẹni Mímọ́ ti Israẹli: “Nítorí rẹ Èmi yóò ránṣẹ́ sí Babeli láti mú wọn sọ̀kalẹ̀ wá gẹ́gẹ́ bí ìsáǹsá, gbogbo ará Babeli, nínú ọkọ̀ ojú omi nínú èyí tí wọ́n fi ń ṣe ìgbéraga.
Így szól az Úr, a ti megváltótok, Izráel Szentje. Ti értetek küldöttem el Bábelbe, és leszállítom mindnyájokat, mint menekülőket a Káldeusokkal együtt vídámságuk hajóiba.
15 Èmi ni Olúwa, Ẹni Mímọ́ rẹ, Ẹlẹ́dàá Israẹli, ọba rẹ.”
Én az Úr vagyok, szent Istenetek, Izráelnek teremtője, királyotok.
16 Èyí ni ohun tí Olúwa wí, Ẹni náà tí ó la ọ̀nà nínú Òkun, ipa ọ̀nà láàrín alagbalúgbú omi,
Így szól az Úr, a ki a tengeren utat csinál, és a hatalmas vizeken ösvényt,
17 ẹni tí ó wọ́ àwọn kẹ̀kẹ́ àti ẹṣin jáde, àwọn jagunjagun àti ohun ìjà papọ̀, wọ́n sì sùn síbẹ̀, láìní lè dìde mọ́, wọ́n kú pirá bí òwú-fìtílà:
A ki kihozott szekeret és lovat, sereget és vitézt; együtt hevernek ottan, nem kelnek föl, kialudtak, mint gyertyabél elhamvadának!
18 “Gbàgbé àwọn ohun àtẹ̀yìnwá; má ṣe gbé nínú ohun àtijọ́.
Ne emlékezzetek a régiekről, és az előbbiekről ne gondolkodjatok!
19 Wò ó, Èmi ń ṣe ohun tuntun! Nísinsin yìí, ó ti yọ sókè; àbí o kò rí i bí? Èmi ń ṣe ọ̀nà kan nínú aṣálẹ̀ àti odò nínú ilẹ̀ ṣíṣá.
Ímé, újat cselekszem; most készül, avagy nem tudjátok még? Igen, a pusztában utat szerzek, és a kietlenben folyóvizeket.
20 Àwọn ẹhànnà ẹranko bọ̀wọ̀ fún mi, àwọn ajáko àti àwọn òwìwí, nítorí pé mo pèsè omi nínú aṣálẹ̀ àti odò nínú ilẹ̀ sísá, láti fi ohun mímu fún àwọn ènìyàn mi, àyànfẹ́ mi,
Dicsőítni fog engem a mező vada, a sakálok és struczok, hogy vizet szereztem a pusztában; a kietlenben folyóvizeket, hogy választott népemnek inni adjak.
21 àwọn ènìyàn tí mo dá fún ara mi kí wọn kí ó lè kéde ìyìn mi.
A nép, a melyet magamnak alkoték, hirdesse dicséretemet!
22 “Síbẹ̀síbẹ̀ ìwọ kò tí ì ké pè mí, ìwọ Jakọbu, àárẹ̀ kò tí ì mú ọ nítorí mi ìwọ Israẹli.
És még sem engem hívtál segítségül Jákób, hanem megfáradtál én bennem Izráel!
23 Ìwọ kò tí ì mú àgùntàn wá fún mi fún ẹbọ sísun, tàbí kí o bọ̀wọ̀ fún mi pẹ̀lú ẹbọ rẹ. Èmi kò tí ì wàhálà rẹ pẹ̀lú ọrẹ ìyẹ̀fun tàbí kí n dààmú rẹ pẹ̀lú ìbéèrè fún tùràrí.
Nem adtad nékem égőáldozatul bárányaidat, és áldozataiddal nem dicsőítettél engem; nem terheltelek ételáldozattal, és tömjénnel nem fárasztottalak.
24 Ìwọ kò tí ì ra kalamusi olóòórùn dídùn fún mi, tàbí kí o da ọ̀rá ẹbọ rẹ bò mí. Ṣùgbọ́n ẹ ti wàhálà mi pẹ̀lú ẹ̀ṣẹ̀ yín ẹ sì ti dààmú mi pẹ̀lú àìṣedéédéé yín.
Nem vettél pénzen nékem jóillatú nádat, és áldozataid kövérével jól nem tartottál, csak bűneiddel terhelél, vétkeiddel fárasztál engemet.
25 “Èmi, àní Èmi, Èmi ni ẹni tí ó wẹ àwọn àìṣedéédéé rẹ nù, nítorí èmi fún ara mi, tí n kò sì rántí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ mọ́.
Én, én vagyok, a ki eltörlöm álnokságaidat enmagamért, és bűneidről nem emlékezem meg!
26 Bojú wo ẹ̀yìn rẹ fún mi, jẹ́ kí a jọ ṣe àríyànjiyàn ọ̀rọ̀ náà papọ̀; ro ẹjọ́ láti fihàn pé o kò lẹ́sẹ̀ lọ́rùn.
Juttasd eszembe, no pereljünk együtt, beszéld el, hogy igaznak találtassál!
27 Baba yín àkọ́kọ́ dẹ́ṣẹ̀; àwọn agbẹnusọ yín ṣọ̀tẹ̀ sí mi.
Az első atyád vétkezett, és tanítóid elpártoltak tőlem!
28 Nítorí náà, èmi ti sọ àwọn olórí ibi mímọ́ náà di àìmọ́, bẹ́ẹ̀ ni èmi ti fi Jakọbu fún ègún àti Israẹli fún ẹ̀gàn.
Ezért én is megfertőztettem a szent fejedelmeket, és veszedelemre adám Jákóbot, és gyalázatra Izráelt!

< Isaiah 43 >