< Isaiah 43 >
1 Ṣùgbọ́n ní ìsinsin yìí, ohun tí Olúwa wí nìyìí, ẹni tí ó dá ọ, ìwọ Jakọbu, ẹni tí ó mọ ọ́, ìwọ Israẹli: “Má bẹ̀rù, nítorí Èmi ti dá ọ nídè; Èmi ti pè ọ́ ní orúkọ; tèmi ni ìwọ ṣe.
But now, you people of Israel, listen to Yahweh, the one who established your nation. The one who caused you to become a nation [DOU] says this: “Do not be afraid, because I previously rescued you. I enabled you to have a personal relationship with me [MTY], and you belong to me.
2 Nígbà tí ìwọ bá ń la omi kọjá, Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ; àti nígbà tí ìwọ bá ń la odò kọjá wọn kì yóò bò ọ́ mọ́lẹ̀. Nígbà tí ìwọ bá la iná kọjá, kò ní jó ọ; ahọ́n iná kò ní jó ọ lára.
When you [experience dangerous situations], and [you feel like] [MET] you are crossing deep rivers, I will be with you. When you have very big troubles/difficulties, you will [LIT] be able to endure them. When [people try to kill you like they tried to kill Daniel’s three friends by] throwing them in a fire, you will not [die, just like Daniel’s three friends were not] burned up,
3 Nítorí Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ, Ẹni Mímọ́ Israẹli Olùgbàlà rẹ; Èmi fi Ejibiti ṣe ìràpadà rẹ, Kuṣi àti Seba dípò rẹ.
because I am Yahweh, your God, the Holy One of Israel, the one who rescues you. I will enable [the army of the emperor of Persia] to conquer Egypt instead of conquering you; similarly I will enable them to conquer Ethiopia, and Seba [in Arabia], in order that you can be saved.
4 Nítorí pé o ṣe iyebíye àti ọ̀wọ́n níwájú mi, àti nítorí pé mo fẹ́ràn rẹ, Èmi yóò fi ènìyàn rọ́pò fún ọ, àti ènìyàn dípò ẹ̀mí rẹ.
I will cause other countries to be conquered, instead of your country; I will trade them for you, in order that you will not be killed, because you are very precious [DOU] to me and because I love you.
5 Má bẹ̀rù nítorí èmi wà pẹ̀lú rẹ; Èmi yóò mú àwọn ọmọ rẹ láti ìlà-oòrùn wá èmi ó sì kó ọ jọ láti ìwọ̀-oòrùn.
Do not be afraid, because I am with you. [Some day] I will gather your descendants from the east and from the west.
6 Èmi yóò sọ fún àríwá pé, ‘Fi wọ́n sílẹ̀!’ Àti fún gúúsù, ‘Má ṣe dá wọn dúró.’ Mú àwọn ọmọkùnrin mi láti ọ̀nà jíjìn wá àti àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin mi láti ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé—
I will command the [rulers of the nations to] the north and to the south, ‘Allow all the people of Israel to return [to their country], from the most distant places on the earth.
7 ẹnikẹ́ni tí a ń pe orúkọ mi mọ́, tí mo dá fún ògo mi, tí mo mọ̀ àti tí mo ṣe.”
Allow all those who belong to me [MTY] to return, because I have caused them to become a nation in order that they would honor me; I am the one who has done that [DOU].’
8 Sin àwọn tí ó ní ojú ṣùgbọ́n tí wọ́n fọ́jú jáde, tí wọ́n ní etí ṣùgbọ́n tí wọn dití.
Summon the people who have eyes but [it is as though] they are blind; summon those who have ears but [because they do not listen to me, it is as though] they are deaf.
9 Gbogbo orílẹ̀-èdè kó ra wọn jọ àwọn ènìyàn sì kó ra wọn papọ̀. Ta ni nínú wọn tó sọ àsọtẹ́lẹ̀ yìí tí ó sì kéde fún wa àwọn nǹkan ti tẹ́lẹ̀? Jẹ́ kí wọ́n mú àwọn ẹlẹ́rìí wọn wọlé wá láti fihàn pé wọ́n tọ̀nà tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn mìíràn yóò gbọ́, tí wọn yóò sọ pé, “Òtítọ́ ni.”
Gather people of all nations together, ones from all people-groups, [and ask them this]: ‘Has any of their idols foretold the things that are happening now? And can any of them predict what will happen in the future?’ Then bring people who will testify and say ‘I heard them predict things, and what they predicted was what happened,’ [but they will be lying].”
10 “Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí mi,” ni Olúwa wí, “Àti ìránṣẹ́ mi tí èmi ti yàn, tó bẹ́ẹ̀ tí ẹ̀yin yóò fi mọ̀ àti tí ẹ̀yin ó fi gbà mí gbọ́ tí yóò sì yé e yín pé èmi ni ẹni náà. Ṣáájú mi kò sí ọlọ́run tí a dá, tàbí a ó wa rí òmíràn lẹ́yìn mi.
But Yahweh says, “You people of Israel (are my witnesses/know what I have done), and you are the ones who serve me. I chose you in order that you would know me, believe in me, and understand that I am the only one who is [truly] God. There is no other [true] God. There was no other [true] God previously, and there will never be another [true] God.
11 Èmi, àní Èmi, Èmi ni Olúwa, yàtọ̀ sí èmi, kò sí olùgbàlà mìíràn.
I, [only] I, am Yahweh, and there is no other one who can save you.
12 Èmi ti fihàn, mo gbàlà mo sì ti kéde Èmi, kì í sì í ṣe àwọn àjèjì òrìṣà láàrín yín. Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí mi,” ni Olúwa wí, “Pé Èmi ni Ọlọ́run.
I said that I would rescue [your ancestors], and then I rescued them, and I proclaimed [that I had done it]. No foreign god among you did that! And you are witnesses that only I, Yahweh, am God.
13 Bẹ́ẹ̀ ni, àti láti ayérayé Èmi ni ẹni náà. Kò sí ẹnikẹ́ni tí ó lè gbà kúrò lọ́wọ́ mi. Nígbà tí mo bá ṣe nǹkan, ta ni ó lè yí i padà?”
I am God, the one who has existed forever and who will exist forever; no one can snatch people from my hand, and no one can alter/change what I have done.”
14 Èyí ni ohun tí Olúwa wí, olùràpadà rẹ, Ẹni Mímọ́ ti Israẹli: “Nítorí rẹ Èmi yóò ránṣẹ́ sí Babeli láti mú wọn sọ̀kalẹ̀ wá gẹ́gẹ́ bí ìsáǹsá, gbogbo ará Babeli, nínú ọkọ̀ ojú omi nínú èyí tí wọ́n fi ń ṣe ìgbéraga.
Yahweh, the Holy One of Israel, is the one who rescues you; and this is what he says: “For your sake, I will send [an army] to [attack] Babylon. They will force the people of that city to flee in ships which they have been proud of.
15 Èmi ni Olúwa, Ẹni Mímọ́ rẹ, Ẹlẹ́dàá Israẹli, ọba rẹ.”
I am Yahweh, your Holy One, the one who caused Israel to become a nation, and the one who is really your king.
16 Èyí ni ohun tí Olúwa wí, Ẹni náà tí ó la ọ̀nà nínú Òkun, ipa ọ̀nà láàrín alagbalúgbú omi,
I am Yahweh, the one who opened a path through the water, making a road through the [Red] Sea.
17 ẹni tí ó wọ́ àwọn kẹ̀kẹ́ àti ẹṣin jáde, àwọn jagunjagun àti ohun ìjà papọ̀, wọ́n sì sùn síbẹ̀, láìní lè dìde mọ́, wọ́n kú pirá bí òwú-fìtílà:
Then I summoned the great army [of Egypt] to come with all their chariots and horses. [But when they tried to pursue my people], I caused the waves to flow over them [and they drowned]; their lives ended [like the light of a candle ends when someone] [MET] snuffs out the wick.
18 “Gbàgbé àwọn ohun àtẹ̀yìnwá; má ṣe gbé nínú ohun àtijọ́.
But do not think [only] about what happened in the past, long ago [DOU].
19 Wò ó, Èmi ń ṣe ohun tuntun! Nísinsin yìí, ó ti yọ sókè; àbí o kò rí i bí? Èmi ń ṣe ọ̀nà kan nínú aṣálẹ̀ àti odò nínú ilẹ̀ ṣíṣá.
Instead, consider the new thing that I am going to do. I have already started to do it; can you see it? I am going to make a road through the desert. And I will cause there to be streams in the wasteland/desert.
20 Àwọn ẹhànnà ẹranko bọ̀wọ̀ fún mi, àwọn ajáko àti àwọn òwìwí, nítorí pé mo pèsè omi nínú aṣálẹ̀ àti odò nínú ilẹ̀ sísá, láti fi ohun mímu fún àwọn ènìyàn mi, àyànfẹ́ mi,
The jackals/wolves and owls and other wild creatures will thank me for giving them water in the desert. I will cause streams to appear in the dry desert in order that my people, the ones whom I have chosen, will have water;
21 àwọn ènìyàn tí mo dá fún ara mi kí wọn kí ó lè kéde ìyìn mi.
I will do that for the people whom I have created [and chosen] to belong to me, and [some day] they will cause many others to praise me.
22 “Síbẹ̀síbẹ̀ ìwọ kò tí ì ké pè mí, ìwọ Jakọbu, àárẹ̀ kò tí ì mú ọ nítorí mi ìwọ Israẹli.
But now, you descendants of Jacob, you refuse to request my help. It seems that you people of Israel have become tired of worshiping me.
23 Ìwọ kò tí ì mú àgùntàn wá fún mi fún ẹbọ sísun, tàbí kí o bọ̀wọ̀ fún mi pẹ̀lú ẹbọ rẹ. Èmi kò tí ì wàhálà rẹ pẹ̀lú ọrẹ ìyẹ̀fun tàbí kí n dààmú rẹ pẹ̀lú ìbéèrè fún tùràrí.
You have not brought to me sheep or goats for offerings that will be completely burned [on the altar]; you have not honored me by [bringing to me any] sacrifices, even though the offerings of grain and incense [that I asked you] to bring to me were not a burden to you.
24 Ìwọ kò tí ì ra kalamusi olóòórùn dídùn fún mi, tàbí kí o da ọ̀rá ẹbọ rẹ bò mí. Ṣùgbọ́n ẹ ti wàhálà mi pẹ̀lú ẹ̀ṣẹ̀ yín ẹ sì ti dààmú mi pẹ̀lú àìṣedéédéé yín.
You have bought for me fragrant reeds, and you have brought me the fat from your sacrifices. But these have not pleased me, because you have burdened me by all the sins that you have committed, and made me weary because of all (your iniquities/the wrong things that you have done).
25 “Èmi, àní Èmi, Èmi ni ẹni tí ó wẹ àwọn àìṣedéédéé rẹ nù, nítorí èmi fún ara mi, tí n kò sì rántí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ mọ́.
I am the one who is able to forgive you for all your sins; I am the only one who can do that, with the result that I will never think about them again.
26 Bojú wo ẹ̀yìn rẹ fún mi, jẹ́ kí a jọ ṣe àríyànjiyàn ọ̀rọ̀ náà papọ̀; ro ẹjọ́ láti fihàn pé o kò lẹ́sẹ̀ lọ́rùn.
Tell me what I have done that you do not like. Do you think that when you state your case, you will prove that you (are innocent/have done nothing wrong) [IRO]?
27 Baba yín àkọ́kọ́ dẹ́ṣẹ̀; àwọn agbẹnusọ yín ṣọ̀tẹ̀ sí mi.
No, [what has happened is that] the first ancestor of you Israelis sinned [against me], and since then, all your leaders have rebelled against me.
28 Nítorí náà, èmi ti sọ àwọn olórí ibi mímọ́ náà di àìmọ́, bẹ́ẹ̀ ni èmi ti fi Jakọbu fún ègún àti Israẹli fún ẹ̀gàn.
That is why I have caused your priests to be disgraced; and I have allowed others to destroy you people of Israel and caused you to be despised.”