< Isaiah 42 >

1 “Ìránṣẹ́ mi nìyìí, ẹni tí mo gbéró, àyànfẹ́ mi nínú ẹni tí mo láyọ̀; Èmi yóò fi Ẹ̀mí mi sínú rẹ̀ òun yóò sì mú ìdájọ́ wá sórí àwọn orílẹ̀-èdè.
Jacob mon serviteur, je te protègerai; Israël est mon élu, mon âme l'a agréé; j'ai répandu sur lui mon esprit, et il révèlera mon jugement aux nations.
2 Òun kì yóò pariwo tàbí kígbe sókè, tàbí kí ó gbóhùn rẹ̀ sókè ní òpópónà.
Il ne criera pas, il ne faiblira pas; sa voix au dehors ne sera pas entendue.
3 Koríko odò títẹ̀ kan ni òun kì yóò fọ́, àti òwú-fìtílà tí ń jó tan an lọ lòun kì yóò fẹ́ pa. Ní òdodo ni yóò mú ìdájọ́ wá;
Il ne broiera pas le roseau déjà brisé; il n'éteindra pas la mèche qui fume encore; mais il révèlera le jugement selon la vérité.
4 òun kì yóò kọsẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni kò ní rẹ̀wẹ̀sì títí tí yóò fi fi ìdájọ́ múlẹ̀ ní ayé. Nínú òfin rẹ̀ ni àwọn erékùṣù yóò fi ìrètí wọn sí.”
Il brillera et ne sera point détruit jusqu'à ce qu'il ait placé le jugement sur la terre, et les Gentils mettront leur espérance en son nom.
5 Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run wí Ẹni tí ó dá àwọn ọ̀run tí ó sì tẹ́ wọ́n sóde, tí ó tẹ́ ilẹ̀ ayé àti ohun gbogbo tí ó jáde nínú wọn, Ẹni tí ó fún àwọn ènìyàn rẹ̀ ní èémí àti ẹ̀mí fún gbogbo àwọn tí ń rìn nínú rẹ̀:
Ainsi dit le Seigneur Dieu, qui a créé le ciel et l'a tendu, qui a affermi la terre et tout ce qu'elle contient, qui a donné le souffle au peuple qui l'habite, et la vie à ceux qui y marchent.
6 “Èmi, Olúwa, ti pè ọ́ ní òdodo, Èmi yóò di ọwọ́ rẹ mú. Èmi yóò pa ọ́ mọ́, n ó sì ṣe ọ́ láti jẹ́ májẹ̀mú fún àwọn ènìyàn àti ìmọ́lẹ̀ fún àwọn aláìkọlà
Moi, le Seigneur Dieu, je t'ai appelé avec justice, et je te prendrai par la main, et je te fortifierai, et je t'ai donné d'être l'alliance du genre humain et la lumière des nations;
7 láti la àwọn ojú tí ó fọ́, láti tú àwọn òǹdè kúrò nínú túbú àti láti tú sílẹ̀ kúrò nínú ẹ̀wọ̀n àwọn tí ó jókòó nínú òkùnkùn.
D'ouvrir les yeux aux aveugles, de tirer de la prison les captifs enchaînés et assis dans les ténèbres.
8 “Èmi ni Olúwa; orúkọ mi nìyìí! Èmi kì yóò fi ògo mi fún ẹlòmíràn tàbí ìyìn mi fún ère òrìṣà.
Je suis le Seigneur Dieu, c'est mon nom; je ne donnerai pas ma gloire à un autre, ni mes vertus à des idoles d'argile.
9 Kíyèsi i, àwọn nǹkan àtijọ́ ti wáyé, àti àwọn nǹkan tuntun ni mo ti wí pé; kí wọn tó hù jáde mo ti kéde rẹ̀ fún ọ.”
Voilà que les choses du commencement sont venues, comme viendront les choses nouvelles que je vous annonce, et qui, avant que je les annonce, vous ont été prédites.
10 Kọ orin tuntun sí Olúwa ìyìn rẹ̀ láti òpin ilẹ̀ ayé wá, ẹ̀yin tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sínú Òkun, àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀, ẹ̀yin erékùṣù, àti gbogbo àwọn tí ń gbé inú wọn.
Chantez au Seigneur un cantique nouveau, vous qui êtes son royaume; glorifiez son nom des extrémités de la terre, ô vous qui descendez sur la mer pour y naviguer; et vous, îles, et vous qui les habitez!
11 Jẹ́ kí aginjù àti àwọn ìlú rẹ̀ kí ó gbé ohùn wọn sókè; jẹ́ kí ibùdó ti àwọn ìlú Kedari ń gbé máa yọ̀. Jẹ́ kí àwọn ènìyàn Sela kọrin fún ayọ̀; jẹ́ kí wọn pariwo láti orí òkè.
Désert, réjouis-toi; que tes bourgs se réjouissent et tes hameaux, et le peuple de Cédar; et ceux qui habitent parmi les rochers pousseront des cris de joie.
12 Jẹ́ kí wọn fi ògo fún Olúwa àti kí wọn sì kéde ìyìn rẹ̀ ní erékùṣù.
Ils rendront gloire à Dieu; ils feront connaître aux îles ses vertus.
13 Olúwa yóò rìn jáde gẹ́gẹ́ bí i ọkùnrin alágbára, yóò ru owú sókè bí ológun; yóò kígbe nítòótọ́, òun yóò ké igbe ogun, òun yóò sì ṣẹ́gun àwọn ọ̀tá rẹ̀.
Le Seigneur Dieu des armées s'avancera; il brisera tout à la guerre; il excitera son zèle; il criera avec force contre ses ennemis.
14 “Fún ìgbà pípẹ́ ni mo ti dákẹ́ jẹ́ẹ́, mo ti wà ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́, mo sì kó ara ró. Ṣùgbọ́n ní àkókò yìí, gẹ́gẹ́ bí obìnrin tí ó ń rọbí, mo sọkún, mo sì ń mí hẹlẹ hẹlẹ.
J'ai gardé le silence; mais est-ce que je me tairai et me contiendrai toujours? J'ai souffert avec patience comme une femme qui enfante; je vais tout frapper de stupeur; je vais tout flétrir.
15 Èmi yóò sọ òkè ńlá àti kékeré di ahoro tí n ó sì gbẹ gbogbo ewéko rẹ̀ dànù, Èmi yóò sọ àwọn odò di erékùṣù n ó sì gbẹ àwọn adágún.
Je rendrai désertes les montagnes et les collines; j'y sècherai l'herbe; je changerai les fleuves en îles; je mettrai à sec les étangs.
16 Èmi yóò tọ àwọn afọ́jú ní ọ̀nà tí wọn kò tí ì mọ̀, ní ipa ọ̀nà tí ó ṣàjèjì sí wọn ni èmi yóò tọ́ wọn lọ; Èmi yóò sọ òkùnkùn di ìmọ́lẹ̀ níwájú wọn àti ibi pálapàla ni èmi ó sọ di kíkúnná. Àwọn nǹkan tí máa ṣe nìyìí; Èmi kì yóò kọ̀ wọ́n sílẹ̀.
Je conduirai les aveugles par une voie qu'ils ne connaissaient point; je leur ferai fouler des sentiers inconnus; je ferai que devant eux les ténèbres soient lumière et que les voies tortueuses deviennent droites. Voilà ce que j'accomplirai en leur faveur, et je ne les abandonnerai point.
17 Ṣùgbọ́n àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé òrìṣà, tí wọ́n wí fún ère pé, ‘Ẹ̀yin ni Ọlọ́run wa,’ ni a ó dá padà pẹ̀lú ìtìjú.
Mais arrière ceux qui se sont détournés de moi! Soyez confondus, vous qui mettez votre confiance en des idoles d'argile et qui dites à des statues de fonte: Vous êtes nos dieux.
18 “Gbọ́, ìwọ adití, wò ó, ìwọ afọ́jú, o sì rí!
Sourds, écoutez; aveugles, levez les yeux pour voir.
19 Ta ló fọ́jú bí kò ṣe ìránṣẹ́ mi, àti odi gẹ́gẹ́ bí oníṣẹ́ tí mo rán? Ta ni ó fọ́jú gẹ́gẹ́ bí ẹni tí a fi jìnmí, ó fọ́jú gẹ́gẹ́ bí ìránṣẹ́ Olúwa?
Et qui est aveugle, sinon mes serviteurs? Qui est sourd, sinon ceux qui les gouvernent? Oui, les serviteurs de Dieu sont devenus aveugles.
20 Ẹ̀yin ti rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ nǹkan, ṣùgbọ́n ẹ kò ṣe àkíyèsí; etí yín yà sílẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ kò gbọ́ nǹkan kan.”
Vous avez vu tant de fois, et vous n'y avez pas pris garde; vos oreilles étaient ouvertes, et vous n'avez pas entendu.
21 Ó dùn mọ́ Olúwa nítorí òdodo rẹ̀ láti mú òfin rẹ lágbára àti ògo.
Le Seigneur a pris conseil, afin qu'on reconnût sa justice et qu'on publiât sa louange.
22 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn kan nìyìí tí a jà lógun tí a sì kó lẹ́rú, gbogbo wọn ni ó wà nínú ọ̀gbun, tàbí tí a fi pamọ́ sínú ẹ̀wọ̀n. Wọ́n ti di ìkógun, láìsí ẹnìkan tí yóò gbà wọ́n sílẹ̀; wọ́n ti di ìkógun, láìsí ẹni tí yóò sọ pé, “Dá wọn padà.”
Et j'ai vu, et le peuple était pillé et dispersé. Le filet était tendu dans les retraites, dans les demeures, partout où ils se cachaient; et on les saisissait comme un butin, et nul n'était là pour arracher cette proie, nul n'était là pour dire: Rends-la-moi.
23 Ta ni nínú yín tí yóò tẹ́tí sí èyí tàbí kí ó ṣe àkíyèsí gidi ní àsìkò tí ó ń bọ̀?
Qui de vous recueillera ces choses en ses oreilles? écoutez l'avenir.
24 Ta ni ó fi Jakọbu lélẹ̀ fún ìkógun, àti Israẹli sílẹ̀ fún onísùnmọ̀mí? Kì í ha ṣe Olúwa ni, ẹni tí àwa ti ṣẹ̀ sí? Nítorí pé wọn kò ní tẹ̀lé ọ̀nà rẹ̀; wọn kò mú òfin rẹ̀ ṣẹ.
Qui a livré comme une proie Jacob et Israël à ceux qui l'ont pris? n'est-ce point Dieu, contre qui ils ont péché, refusant de marcher dans sa voie et d'obéir à ses commandements?
25 Nítorí náà ni ó ṣe rọ̀jò ìbínú un rẹ̀ lé wọn lórí, rògbòdìyàn ogun. Èyí tí ó fi ahọ́n iná yí wọn po, síbẹ̀ èdè kò yé wọn; ó jó wọn run, síbẹ̀ wọn kò fi sọ́kàn wọn rárá.
Et il a fait éclater contre eux les transports de sa fureur; et la guerre a prévalu sur eux; et ils ont entouré de flammes; et ils ne l'ont pas compris, et ils n'y ont pas arrêté leur âme.

< Isaiah 42 >