< Isaiah 41 >

1 “Ẹ dákẹ́ jẹ́ẹ́ níwájú mi ẹ̀yin erékùṣù! Jẹ́ kí àwọn orílẹ̀-èdè tún agbára wọn ṣe! Jẹ́ kí wọn wá síwájú kí wọn sọ̀rọ̀, jẹ́ kí a pàdé pọ̀ ní ibi ìdájọ́.
— «I arallar, süküt ⱪilip Mening aldimƣa kelinglar; Hǝlⱪlǝrmu küqini yengilisun! Ular yeⱪin kǝlsun, sɵz ⱪilsun; Toƣra ⱨɵküm ⱪilix üqün ɵzara yeⱪinlixayli!»
2 “Ta ni ó ti ru ẹnìkan sókè láti ìlà-oòrùn wá, tí ó pè é ní olódodo sí iṣẹ́ tirẹ̀? Ó gbé àwọn orílẹ̀-èdè lé e lọ́wọ́ ó sì ṣẹ́gun àwọn ọba níwájú rẹ̀. Ó sọ wọ́n di erùpẹ̀ pẹ̀lú idà rẹ̀, láti kù ú ní ìyàngbò pẹ̀lú ọrun rẹ̀.
«Kim xǝrⱪtiki birsini oyƣitip, Uni ⱨǝⱪⱪaniyliⱪ bilǝn Ɵz hizmitigǝ qaⱪirdi? U ǝllǝrni uning ⱪoliƣa tapxuridu, Uni padixaⱨlar üstidin ⱨɵkümranliⱪ ⱪilduridu; Ularni uning ⱪiliqiƣa tapxurup topa-qangƣa aylanduridu, Ularni uning oⱪyasi aldida xamal uqurƣan pahal-topandǝk ⱪilidu.
3 Ó ń lépa wọn ó sì ń kọjá ní àlàáfíà, ní ojú ọ̀nà tí ẹsẹ̀ rẹ̀ kò rìn rí.
U ularni ⱪoƣliwetip, Putini yǝrgǝ tǝgküzmǝy degüdǝk mangidu, aman-esǝnlik iqidǝ ɵtiweridu;
4 Ta ni ó ti ṣe èyí tí ó sì ti jẹ́ kí ó wáyé, tí ó ti pe ìran-ìran láti àtètèkọ́ṣe? Èmi Olúwa pẹ̀lú ẹni kìn-ín-ní wọn àti ẹni tí ó gbẹ̀yìn, Èmi náà ni.”
Əlmisaⱪtin tartip dǝwrlǝrni «Barliⱪⱪa kǝl» dǝp qaⱪirip, Bularni bekitip ada ⱪilƣan kim? Mǝn Pǝrwǝrdigar Awwal Bolƣuqidurmǝn, Ahiri bolƣanlar bilǝnmu billǝ Bolƣuqidurmǝn; Mǝn degǝn «U»durmǝn.
5 Àwọn erékùṣù ti rí i wọ́n bẹ̀rù; ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé wárìrì. Wọ́n súnmọ́ tòsí wọ́n sì wá síwájú;
Arallar xu ixlarni kɵrüp ⱪorⱪixidu; Jaⱨanning qǝt-qetidikilǝr titrǝp ketidu; Ular bir-birigǝ yeⱪinlixip, aldiƣa kelidu;
6 èkínní ran èkejì lọ́wọ́ ó sì sọ fún arákùnrin rẹ̀ pé, “Jẹ́ alágbára!”
Ularning ⱨǝrbiri ɵz ⱪoxnisiƣa yardǝm ⱪilip, Ɵz ⱪerindixiƣa: «Yürǝklik bol!» — dǝydu.
7 Oníṣọ̀nà gba alágbẹ̀dẹ wúrà níyànjú, àti ẹni tí ó fi òòlù dán mú òun lọ́kàn le, àní ẹni tí ó ń lu owú. Ó sọ nípa àjópọ̀ náà pé, “Ó dára.” Ó fi ìṣó kan ère náà mọ́lẹ̀ kí ó má ba à wó lulẹ̀.
Xuning bilǝn nǝⱪⱪaxqi zǝrgǝrni riƣbǝtlǝndüridu, Metalni yapilaⱪlap bolⱪa oynatⱪuqi sǝndǝlni bazƣan bilǝn soⱪⱪuqini riƣbǝtlǝndürüp: «Kǝpxǝrligini yahxi!» dǝydu; Xuning bilǝn uni lingxip ⱪalmisun dǝp butning putini mihlar bilǝn bekitidu.
8 “Ṣùgbọ́n ìwọ, ìwọ Israẹli, ìránṣẹ́ mi, Jakọbu, ẹni tí mo ti yàn, ẹ̀yin ìran Abrahamu, ọ̀rẹ́ mi,
Biraⱪ sǝn, i ⱪulum Israil, I Ɵzüm talliƣan Yaⱪup, Ibraⱨim Mening dostumning ǝwladi: —
9 mo mú ọ láti ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé, láti kọ̀rọ̀ rẹ̀ tí ó jìnnà jùlọ ni mo ti pè ọ́. Èmi wí pé, ‘Ìwọ ni ìránṣẹ́ mi’; Èmi ti yàn ọ́ bẹ́ẹ̀ ni èmi kò sì tí ì kọ̀ ọ́ sílẹ̀.
Mǝn jaⱨanning ⱪǝridin elip kǝlgǝn, Yǝrning ǝng qǝtliridin qaⱪiriƣinim sǝn ikǝnsǝn; Mǝn sanga «Sǝn mening ⱪulumdursǝn, Mǝn seni talliƣan, Seni ⱨǝrgiz qǝtkǝ ⱪaⱪmaymǝn» — degǝnidim.
10 Nítorí náà má bẹ̀rù, nítorí èmi wà pẹ̀lú rẹ; má ṣe jẹ́ kí àyà kí ó fò ọ́, nítorí èmi ni Ọlọ́run rẹ. Èmi yóò fún ọ lókun èmi ó sì ràn ọ́ lọ́wọ́. Èmi ó gbé ọ ró pẹ̀lú ọwọ́ ọ̀tún òdodo mi.
— Ⱪorⱪma; qünki Mǝn sǝn bilǝn billidurmǝn; Uyan-buyan ⱪarap ⱨoduⱪmanglar; Qünki Mǝn sening Hudayingdurmǝn; Mǝn seni küqǝytimǝn, Bǝrⱨǝⱪ, Mǝn sanga yardǝmdǝ bolimǝn! Bǝrⱨǝⱪ, Mǝn Ɵzümning ⱨǝⱪⱪaniyliⱪimni bildürgüqi ong ⱪolum bilǝn seni yɵlǝymǝn.
11 “Gbogbo àwọn tí ó bínú sí ọ ni ojú yóò tì, tí wọn yóò sì di ẹlẹ́yà; àwọn tó ń bá ọ jà yóò dàbí asán, wọn yóò ṣègbé.
Mana, sanga ⱪarap ƣaljirlixip kǝtkǝnlǝrning ⱨǝmmisi hijil bolup xǝrmǝndǝ bolidu; Sanga xikayǝt ⱪilƣuqilar yoⱪ deyǝrlik bolidu, ⱨalak bolidu.
12 Bó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ yóò wá àwọn ọ̀tá rẹ, ìwọ kì yóò rí wọn. Gbogbo àwọn tí ó gbóguntì ọ́ yóò dàbí ohun tí kò sí.
Sǝn ularni izdisǝng, ⱨeq tapalmaysǝn; Sǝn bilǝn dǝwalaxⱪuqilar — Sanga ⱪarxi urux ⱪilƣuqilar yoⱪ deyǝrlik, ⱨeq bolup baⱪmiƣandǝk turidu.
13 Nítorí Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ, tí ó di ọwọ́ ọ̀tún rẹ mú tí ó sì sọ fún ọ pé, má ṣe bẹ̀rù; Èmi yóò ràn ọ́ lọ́wọ́.
Qünki Mǝn Pǝrwǝrdigar Hudaying ong ⱪolungni tutup turup, sanga: — «Ⱪorⱪma, Mǝn sanga yardǝmdǝ bolimǝn!» dǝymǝn.
14 Má ṣe bẹ̀rù, ìwọ Jakọbu kòkòrò, ìwọ Israẹli kékeré, nítorí Èmi fúnra mi yóò ràn ọ́ lọ́wọ́,” ni Olúwa wí, olùdáǹdè rẹ, Ẹni Mímọ́ ti Israẹli.
Ⱪorⱪma, sǝn ⱪurt bolƣan Yaⱪup, Israilning baliliri! Mǝn sanga yardǝmdǝ bolimǝn!» — dǝydu Pǝrwǝrdigar, yǝni sening Ⱨǝmjǝmǝt-Ⱪutⱪuzƣuqing, Israildiki Muⱪǝddǝs Bolƣuqi.
15 “Kíyèsi, Èmi yóò sọ ọ́ di òòlù ìpakà tuntun, tí ó mú ti eyín rẹ̀ mú, ìwọ yóò lu àwọn òkè ńlá, ìwọ yóò fọ́ wọn túútúú, a ó sì sọ òkè kékeré di ìyàngbò.
Mana, Mǝn seni kɵp ⱨǝm ɵtkür qixliⱪ yengi bir dan ayriƣuqi tirna ⱪilimǝn; Sǝn taƣlarni yanjip, ularni parǝ-parǝ ⱪiliwetisǝn, Dɵnglǝrnimu kɵküm-talⱪanƣa aylanduruwetisǝn.
16 Ìwọ yóò fẹ́ wọn, afẹ́fẹ́ yóò sì gbá wọn mú, àti ẹ̀fúùfù yóò sì fẹ́ wọn dànù. Ṣùgbọ́n ìwọ yóò yọ̀ nínú Olúwa ìwọ yóò sì ṣògo nínú Ẹni Mímọ́ ti Israẹli.
Sǝn ularni soruysǝn, Xamal ularni uqurup ketidu, Ⱪuyun ularni tarⱪitiwetidu; Wǝ sǝn Pǝrwǝrdigar bilǝn xadlinisǝn, Israildiki Muⱪǝddǝs Bolƣuqini iptiharlinip mǝdⱨiyǝlǝysǝn.
17 “Àwọn tálákà àti aláìní wá omi, ṣùgbọ́n kò sí; ahọ́n wọn gbẹ fún òǹgbẹ. Ṣùgbọ́n Èmi Olúwa yóò dá wọn lóhùn; Èmi, Ọlọ́run Israẹli, kì yóò kọ̀ wọ́n sílẹ̀.
Bozǝklǝr wǝ yoⱪsullar su izdǝydu, lekin su yoⱪ; Ularning tili ussuzluⱪtin ⱪaƣjirap ketidu; Mǝn Pǝrwǝrdigar ularni anglaymǝn; Mǝn Israilning Hudasi ulardin waz kǝqmǝymǝn.
18 Èmi yóò mú kí odò kí ó sàn ní ibi gíga àti orísun omi ní àárín àfonífojì. Èmi yóò sọ aṣálẹ̀ di adágún omi, àti ilẹ̀ tí ó gbẹ gidigidi di orísun omi.
Mǝn ⱪaⱪas egizliklǝrdǝ dǝryalarni, Jilƣilar iqidǝ bulaⱪlarni aqimǝn; Dalani kɵlqǝkkǝ aylandurimǝn, Tatirang yǝrdin sularni urƣutup su bilǝn ⱪaplap berimǝn.
19 Èmi yóò fi sínú aṣálẹ̀ igi kedari àti kasia, maritili àti olifi. Èmi yóò gbin junifa sí inú aginjù, igi firi àti sípírẹ́ṣì papọ̀
Dalada kedir, akatsiyǝ, hadas wǝ zǝytun dǝrǝhlirini ɵstürüp berimǝn; Qɵl-bayawanda arqa, ⱪariƣay wǝ boksus dǝrǝhlirini birgǝ tikimǝn;
20 tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn ènìyàn yóò fi rí i tí wọn yóò sì fi mọ̀, kí wọn ṣàkíyèsí kí ó sì yé wọn, pé ọwọ́ Olúwa ni ó ti ṣe èyí, àti pé, Ẹni Mímọ́ Israẹli ni ó ti dá èyí.
Xundaⱪ ⱪilip ular bularni kɵrüp, bilip, oylinip: — «Pǝrwǝrdigarning ⱪoli muxularni ⱪilƣan, Israildiki Muⱪǝddǝs Bolƣuqi uni yaratⱪan!» dǝp tǝng qüxinixidu.
21 “Mú ẹjọ́ wá,” ni Olúwa wí. “Tẹ́ àwọn àwíjàre rẹ sílẹ̀,” ni ọba Jakọbu wí,
— Muⱨakimiliringlarni otturiƣa ⱪoyunglar, dǝydu Pǝrwǝrdigar; — Küqlük sǝwǝbliringlarni qiⱪiringlar, dǝydu Yaⱪupning Padixaⱨi.
22 “Mú àwọn ère òrìṣà rẹ wọlé láti sọ fún wa ohun tí yóò ṣẹlẹ̀. Sọ fún wa ohun tí àwọn nǹkan àtijọ́ jẹ́, kí àwa lè ṣe àgbéyẹ̀wò wọn kí àwa sì mọ àbájáde wọn ní ìparí. Tàbí kí o sọ fún wa ohun tí ó ń bọ̀ wá,
— [Butliringlar] elip kirilsun, Bizgǝ nemilǝrning yüz beridiƣanliⱪini eytsun; Ilgiriki ixlarni, ularning üjür-büjürlirigiqǝ kɵz aldimizda kɵrsǝtsun, Xundaⱪla bulardin qiⱪidiƣan nǝtijilǝrni bizgǝ bildürüx üqün eytip bǝrsun; — Yaki bolmisa, kǝlgüsidiki ixlarni anglap bilǝyli;
23 ẹ sọ fún wa ohun ti ọjọ́ iwájú mú dání kí àwa kí ó lè mọ̀ pé ọlọ́run ni yín. Ẹ ṣe nǹkan kan, ìbá à ṣe rere tàbí búburú, tó bẹ́ẹ̀ tí àyà yóò fi fò wá tí ẹ̀rù yóò sì fi kún inú wa.
Silǝrning ilaⱨliⱪ ikǝnlikinglarni biliximiz üqün, Keyinki yüz beridiƣan ixlarni bizgǝ bayan ⱪilinglar; Ⱪandaⱪla bolmisun, Bizni ⱨang-tang ⱪilip uni tǝng kɵridiƣan ⱪilix üqün, Birǝr yahxi ix yaki yaman bir ixni ⱪilinglar!
24 Ṣùgbọ́n ẹ̀yìn ko jásí nǹkan kan iṣẹ́ yín ni kò sì wúlò fún ohunkóhun; ẹni tí ó yàn yín jẹ́ ẹni ìríra.
Mana, silǝr yoⱪning ariliⱪida, Ixligininglarmu yoⱪ ixtur; Silǝrni talliƣuqi bir lǝnitidur.
25 “Èmi ti ru ẹnìkan sókè láti àríwá, òun sì ń bọ ẹnìkan láti ìlà-oòrùn tí ó pe orúkọ mi. Òun gun àwọn aláṣẹ mọ́lẹ̀ bí ẹni pé odò ni wọ́n, àfi bí ẹni pé amọ̀kòkò nì ti ń gún amọ̀.
Birsini ximal tǝrǝptin ⱪozƣidim, u kelidu; U künqiⱪixtin Mening namimni jakarlap kelidu; U birsi ⱨak layni dǝssigǝndǝk, sapalqi lay qǝyligǝndǝk ǝmǝldarlarning üstigǝ ⱨujum ⱪilidu;
26 Ta ni ó sọ èyí láti ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀, tí àwa kò bá fi mọ̀, tàbí ṣáájú àkókò, tí àwa kò bá fi wí pé, ‘Òun sọ òtítọ́’? Ẹnikẹ́ni kò sọ nípa èyí, ẹnikẹ́ni kò sàsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀, ẹnikẹ́ni kò gbọ́ ọ̀rọ̀ kan láti ọ̀dọ̀ rẹ̀.
Bizgǝ uⱪturux üqün, kim muⱪǝddǝmdin buyan buni eytⱪan? Yaki Bizni «U ⱨǝⱪiⱪǝttur» degüzüp bu ixtin burun uni aldin’ala eytⱪan? Yaⱪ, ⱨeqkim eytmaydu; Bǝrⱨǝⱪ, ⱨeqkim bayan ⱪilmaydu; Sɵzünglarni angliyaliƣuqi bǝrⱨǝⱪ yoⱪtur!
27 Èmi ni ẹni àkọ́kọ́ tí ó sọ fún Sioni pé, ‘Wò ó, àwọn nìyìí!’ Mo fún Jerusalẹmu ní ìránṣẹ́ ìrò ìròyìn ayọ̀ kan.
Mǝn dǝslǝptǝ Zionƣa: — «Muxu ixlarƣa kɵz tikip turunglar! Kɵz tikip turunglar!» dedim, Yerusalemƣa hux hǝwǝrni yǝtküzgüqini ǝwǝtip bǝrdim.
28 Èmi wò, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan— kò sí ẹnìkan nínú wọn tí ó lè mú ìmọ̀ràn wá, kò sí ẹnìkan tí ó lè dáhùn nígbà tí mo bi wọ́n.
Mǝn ⱪarisam, xular arisida ⱨeqkim yoⱪ — Mǝsliⱨǝt bǝrgüdǝk ⱨeqkim yoⱪ, Xulardin sorisam, jawab bǝrgüdǝk ⱨeqkimmu yoⱪ.
29 Kíyèsi i, irọ́ ni gbogbo wọn! Gbogbo ìṣe wọn jásí asán; àwọn ère wọn kò ṣé kò yà fún afẹ́fẹ́ àti dàrúdàpọ̀.
Ⱪaranglar, ular ⱨǝmmisi ⱪuruⱪ; Ularning yasiƣanliri yoⱪ ixtur, Ⱪuyma mǝbudliri ⱪuruⱪ xamaldǝk mǝnisizdur.

< Isaiah 41 >