< Isaiah 41 >

1 “Ẹ dákẹ́ jẹ́ẹ́ níwájú mi ẹ̀yin erékùṣù! Jẹ́ kí àwọn orílẹ̀-èdè tún agbára wọn ṣe! Jẹ́ kí wọn wá síwájú kí wọn sọ̀rọ̀, jẹ́ kí a pàdé pọ̀ ní ibi ìdájọ́.
Послу́хайте мовчки Мене, острови́, а наро́ди, чекайте навча́ння Мого! Хай піді́йдуть і скажуть: Приступі́мо всі ра́зом на су́д!
2 “Ta ni ó ti ru ẹnìkan sókè láti ìlà-oòrùn wá, tí ó pè é ní olódodo sí iṣẹ́ tirẹ̀? Ó gbé àwọn orílẹ̀-èdè lé e lọ́wọ́ ó sì ṣẹ́gun àwọn ọba níwájú rẹ̀. Ó sọ wọ́n di erùpẹ̀ pẹ̀lú idà rẹ̀, láti kù ú ní ìyàngbò pẹ̀lú ọrun rẹ̀.
Хто зо сходу того пробуди́в, що його супрово́дить в ході́ перемога? Він наро́ди дає перед ним та царів на топта́ння, їхнього меча оберта́є на порох, його лука — в солому розві́яну.
3 Ó ń lépa wọn ó sì ń kọjá ní àlàáfíà, ní ojú ọ̀nà tí ẹsẹ̀ rẹ̀ kò rìn rí.
Він жене їх, спокійно доро́гою йде, якою він не перехо́див нога́ми своїми.
4 Ta ni ó ti ṣe èyí tí ó sì ti jẹ́ kí ó wáyé, tí ó ti pe ìran-ìran láti àtètèkọ́ṣe? Èmi Olúwa pẹ̀lú ẹni kìn-ín-ní wọn àti ẹni tí ó gbẹ̀yìn, Èmi náà ni.”
Хто вчинив та зробив це? Той, хто роди покликав відда́вна: Я, Господь, перший, і з останніми Я той же Самий!
5 Àwọn erékùṣù ti rí i wọ́n bẹ̀rù; ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé wárìrì. Wọ́n súnmọ́ tòsí wọ́n sì wá síwájú;
Бачили це острови́ та жаха́лися, кі́нці землі трипоті́ли, набли́жувались та прихо́дили.
6 èkínní ran èkejì lọ́wọ́ ó sì sọ fún arákùnrin rẹ̀ pé, “Jẹ́ alágbára!”
Один о́дному допомагає і гово́рить до брата свого́: „Будь міцни́й!“
7 Oníṣọ̀nà gba alágbẹ̀dẹ wúrà níyànjú, àti ẹni tí ó fi òòlù dán mú òun lọ́kàn le, àní ẹni tí ó ń lu owú. Ó sọ nípa àjópọ̀ náà pé, “Ó dára.” Ó fi ìṣó kan ère náà mọ́lẹ̀ kí ó má ba à wó lulẹ̀.
І підбадьо́рує ма́йстер золотаря́, а той, хто молотом гла́дить, того, хто б'є на кова́длі, і каже про спо́єння: Добре воно! і його змі́цнює цвяхами, щоб не хита́лось.
8 “Ṣùgbọ́n ìwọ, ìwọ Israẹli, ìránṣẹ́ mi, Jakọbu, ẹni tí mo ti yàn, ẹ̀yin ìran Abrahamu, ọ̀rẹ́ mi,
Та ти, о Ізраїлю, рабе Мій, Якове, що Я тебе ви́брав, насі́ння Авраама, друга Мого,
9 mo mú ọ láti ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé, láti kọ̀rọ̀ rẹ̀ tí ó jìnnà jùlọ ni mo ti pè ọ́. Èmi wí pé, ‘Ìwọ ni ìránṣẹ́ mi’; Èmi ti yàn ọ́ bẹ́ẹ̀ ni èmi kò sì tí ì kọ̀ ọ́ sílẹ̀.
ти, якого Я взяв був із кі́нців землі та покликав тебе із окра́їн її, і сказав був до тебе: Ти раб Мій, Я вибрав тебе й не відки́нув тебе,
10 Nítorí náà má bẹ̀rù, nítorí èmi wà pẹ̀lú rẹ; má ṣe jẹ́ kí àyà kí ó fò ọ́, nítorí èmi ni Ọlọ́run rẹ. Èmi yóò fún ọ lókun èmi ó sì ràn ọ́ lọ́wọ́. Èmi ó gbé ọ ró pẹ̀lú ọwọ́ ọ̀tún òdodo mi.
не бійся, з тобою бо Я, і не озирайсь, бо Я Бог твій! Зміцню́ Я тебе, і тобі поможу́, і прави́цею правди Своєї тебе Я підтри́маю.
11 “Gbogbo àwọn tí ó bínú sí ọ ni ojú yóò tì, tí wọn yóò sì di ẹlẹ́yà; àwọn tó ń bá ọ jà yóò dàbí asán, wọn yóò ṣègbé.
Отож, засоро́мляться та зніякові́ють усі проти тебе запа́лені, стануть нічим та погинуть твої супроти́вники.
12 Bó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ yóò wá àwọn ọ̀tá rẹ, ìwọ kì yóò rí wọn. Gbogbo àwọn tí ó gbóguntì ọ́ yóò dàbí ohun tí kò sí.
Шукатимеш їх, але їх ти не зна́йдеш, своїх супроти́вників; стануть нічим та марно́тою ті, хто прова́дить війну проти те́бе.
13 Nítorí Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ, tí ó di ọwọ́ ọ̀tún rẹ mú tí ó sì sọ fún ọ pé, má ṣe bẹ̀rù; Èmi yóò ràn ọ́ lọ́wọ́.
Бо Я — Господь, Бог твій, що де́ржить тебе за прави́цю й говорить до тебе: Не бійся, — Я тобі поможу́!
14 Má ṣe bẹ̀rù, ìwọ Jakọbu kòkòrò, ìwọ Israẹli kékeré, nítorí Èmi fúnra mi yóò ràn ọ́ lọ́wọ́,” ni Olúwa wí, olùdáǹdè rẹ, Ẹni Mímọ́ ti Israẹli.
Не бійся, ти Яковів че́рве, ти жме́нько Ізраїлева: Я тобі поможу́, говорить Господь, і твій Викупи́тель — Святий Ізраїлів!
15 “Kíyèsi, Èmi yóò sọ ọ́ di òòlù ìpakà tuntun, tí ó mú ti eyín rẹ̀ mú, ìwọ yóò lu àwọn òkè ńlá, ìwọ yóò fọ́ wọn túútúú, a ó sì sọ òkè kékeré di ìyàngbò.
Ось зроблю Я тебе молота́ркою го́строю, ново́ю, зубча́стою, — помоло́тиш ти го́ри та їх поторо́щиш, а підгі́рки поло́вою вчиниш!
16 Ìwọ yóò fẹ́ wọn, afẹ́fẹ́ yóò sì gbá wọn mú, àti ẹ̀fúùfù yóò sì fẹ́ wọn dànù. Ṣùgbọ́n ìwọ yóò yọ̀ nínú Olúwa ìwọ yóò sì ṣògo nínú Ẹni Mímọ́ ti Israẹli.
Перевієш їх ти, й вітер їх рознесе́, і буря їх розпоро́шить, і ти будеш утіша́тися Господом, будеш хвали́тись Святим Ізраїлевим.
17 “Àwọn tálákà àti aláìní wá omi, ṣùgbọ́n kò sí; ahọ́n wọn gbẹ fún òǹgbẹ. Ṣùgbọ́n Èmi Olúwa yóò dá wọn lóhùn; Èmi, Ọlọ́run Israẹli, kì yóò kọ̀ wọ́n sílẹ̀.
Убогі та бідні шукають води, та нема, язик їхній від пра́гнення висох, — Я, Господь, і їх ви́слухаю, Бог Ізраїлів, не лишу́ їх!
18 Èmi yóò mú kí odò kí ó sàn ní ibi gíga àti orísun omi ní àárín àfonífojì. Èmi yóò sọ aṣálẹ̀ di adágún omi, àti ilẹ̀ tí ó gbẹ gidigidi di orísun omi.
Я ріки відкрию на лисих гора́х, а джере́ла — посе́ред долин, оберну́ Я пустиню на о́зеро во́дне, а землю суху́ — на джере́ла!
19 Èmi yóò fi sínú aṣálẹ̀ igi kedari àti kasia, maritili àti olifi. Èmi yóò gbin junifa sí inú aginjù, igi firi àti sípírẹ́ṣì papọ̀
На пустиню дам ке́дра, ака́цію, ми́рта й масли́ну, поста́влю Я ра́зом в степу́ кипари́са та я́вора й бука,
20 tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn ènìyàn yóò fi rí i tí wọn yóò sì fi mọ̀, kí wọn ṣàkíyèsí kí ó sì yé wọn, pé ọwọ́ Olúwa ni ó ti ṣe èyí, àti pé, Ẹni Mímọ́ Israẹli ni ó ti dá èyí.
щоб ра́зом побачили й знали, і пересві́дчились та зрозумі́ли, що Господня рука це зроби́ла, і створив це Святий Ізраїлів!
21 “Mú ẹjọ́ wá,” ni Olúwa wí. “Tẹ́ àwọn àwíjàre rẹ sílẹ̀,” ni ọba Jakọbu wí,
Принесіть свою справу, говорить Господь, припрова́дьте Мені́ свої до́кази, каже Цар Яковів.
22 “Mú àwọn ère òrìṣà rẹ wọlé láti sọ fún wa ohun tí yóò ṣẹlẹ̀. Sọ fún wa ohun tí àwọn nǹkan àtijọ́ jẹ́, kí àwa lè ṣe àgbéyẹ̀wò wọn kí àwa sì mọ àbájáde wọn ní ìparí. Tàbí kí o sọ fún wa ohun tí ó ń bọ̀ wá,
Хай піді́йдуть і хай нам розкажуть, що тра́питься! Ви́ясніть спра́ви минулі, що́ вони є, а ми серце наше на те покладе́мо й пізна́ємо їхній кінець, або сповістіть про майбу́тнє.
23 ẹ sọ fún wa ohun ti ọjọ́ iwájú mú dání kí àwa kí ó lè mọ̀ pé ọlọ́run ni yín. Ẹ ṣe nǹkan kan, ìbá à ṣe rere tàbí búburú, tó bẹ́ẹ̀ tí àyà yóò fi fò wá tí ẹ̀rù yóò sì fi kún inú wa.
Розкажіть напере́д про майбутнє, і пізна́ємо ми, що ви бо́ги. Отож, учиніть ви добро́ чи зробіть що лихе́, щоб ми здивува́лись і ра́зом побачили.
24 Ṣùgbọ́n ẹ̀yìn ko jásí nǹkan kan iṣẹ́ yín ni kò sì wúlò fún ohunkóhun; ẹni tí ó yàn yín jẹ́ ẹni ìríra.
Та ви менш від нічо́го, і менший ваш чин від марно́ти, — гидо́та, хто вас вибирає!
25 “Èmi ti ru ẹnìkan sókè láti àríwá, òun sì ń bọ ẹnìkan láti ìlà-oòrùn tí ó pe orúkọ mi. Òun gun àwọn aláṣẹ mọ́lẹ̀ bí ẹni pé odò ni wọ́n, àfi bí ẹni pé amọ̀kòkò nì ti ń gún amọ̀.
Я з пі́вночі мужа збудив — і прийшов він, зо схід со́нця в Ім'я́ Моє кличе, — і він буде чави́ти князі́в, мов ту грязю́ку, й як ганча́р глину то́пче!
26 Ta ni ó sọ èyí láti ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀, tí àwa kò bá fi mọ̀, tàbí ṣáájú àkókò, tí àwa kò bá fi wí pé, ‘Òun sọ òtítọ́’? Ẹnikẹ́ni kò sọ nípa èyí, ẹnikẹ́ni kò sàsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀, ẹnikẹ́ni kò gbọ́ ọ̀rọ̀ kan láti ọ̀dọ̀ rẹ̀.
Хто сказав це відда́вна, щоб знали те ми, і щоб напере́д ми сказали: „Це правда?“Та ніхто не сказав, і ніхто не пові́в, і ніхто не почув ваших слів.
27 Èmi ni ẹni àkọ́kọ́ tí ó sọ fún Sioni pé, ‘Wò ó, àwọn nìyìí!’ Mo fún Jerusalẹmu ní ìránṣẹ́ ìrò ìròyìn ayọ̀ kan.
Я перший сказав до Сіону: Оце, то вони! А Єрусалимові дам благові́сника.
28 Èmi wò, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan— kò sí ẹnìkan nínú wọn tí ó lè mú ìmọ̀ràn wá, kò sí ẹnìkan tí ó lè dáhùn nígbà tí mo bi wọ́n.
І Я дивлюсь, та ніко́го нема, і немає між ними пора́дника, щоб відповіли́, коли їх запита́ю.
29 Kíyèsi i, irọ́ ni gbogbo wọn! Gbogbo ìṣe wọn jásí asán; àwọn ère wọn kò ṣé kò yà fún afẹ́fẹ́ àti dàrúdàpọ̀.
Тож ніщо́ всі вони, їхні чини — марно́та, вітер та порожне́ча — їхні і́доли!

< Isaiah 41 >