< Isaiah 41 >

1 “Ẹ dákẹ́ jẹ́ẹ́ níwájú mi ẹ̀yin erékùṣù! Jẹ́ kí àwọn orílẹ̀-èdè tún agbára wọn ṣe! Jẹ́ kí wọn wá síwájú kí wọn sọ̀rọ̀, jẹ́ kí a pàdé pọ̀ ní ibi ìdájọ́.
خداوند می‌فرماید: «ای سرزمینهای دور دست، ساکت باشید و به من گوش دهید! قویترین دلایل خود را ارائه دهید. نزدیک بیایید و سخن بگویید. دادگاه آمادهٔ شنیدن سخنان شماست.
2 “Ta ni ó ti ru ẹnìkan sókè láti ìlà-oòrùn wá, tí ó pè é ní olódodo sí iṣẹ́ tirẹ̀? Ó gbé àwọn orílẹ̀-èdè lé e lọ́wọ́ ó sì ṣẹ́gun àwọn ọba níwájú rẹ̀. Ó sọ wọ́n di erùpẹ̀ pẹ̀lú idà rẹ̀, láti kù ú ní ìyàngbò pẹ̀lú ọrun rẹ̀.
«چه کسی این مرد را از مشرق آورده است که هر جا قدم می‌گذارد آنجا را فتح می‌کند؟ چه کسی او را بر قومها و پادشاهان پیروز گردانیده است؟ شمشیر او سپاهیان آنان را مثل غبار به زمین می‌اندازد و کمانش آنان را چون کاه پراکنده می‌کند.
3 Ó ń lépa wọn ó sì ń kọjá ní àlàáfíà, ní ojú ọ̀nà tí ẹsẹ̀ rẹ̀ kò rìn rí.
آنان را تا جاهای دور که قبل از آن پایش به آنجا نرسیده بود تعقیب می‌کند و به سلامت پیش می‌رود.
4 Ta ni ó ti ṣe èyí tí ó sì ti jẹ́ kí ó wáyé, tí ó ti pe ìran-ìran láti àtètèkọ́ṣe? Èmi Olúwa pẹ̀lú ẹni kìn-ín-ní wọn àti ẹni tí ó gbẹ̀yìn, Èmi náà ni.”
چه کسی این کارها را کرده است؟ کیست که سیر تاریخ را تعیین نموده است؟ مگر نه من، که یهوه خداوند ازلی و ابدی هستم؟
5 Àwọn erékùṣù ti rí i wọ́n bẹ̀rù; ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé wárìrì. Wọ́n súnmọ́ tòsí wọ́n sì wá síwájú;
«مردم سرزمینهای دور دست وقتی کارهای مرا دیدند از ترس لرزیدند. اینک آنها دور هم جمع شده‌اند
6 èkínní ran èkejì lọ́wọ́ ó sì sọ fún arákùnrin rẹ̀ pé, “Jẹ́ alágbára!”
و یکدیگر را کمک و تشویق می‌کنند
7 Oníṣọ̀nà gba alágbẹ̀dẹ wúrà níyànjú, àti ẹni tí ó fi òòlù dán mú òun lọ́kàn le, àní ẹni tí ó ń lu owú. Ó sọ nípa àjópọ̀ náà pé, “Ó dára.” Ó fi ìṣó kan ère náà mọ́lẹ̀ kí ó má ba à wó lulẹ̀.
تا بُتی بسازند. نجار و زرگر و آهنگر به یاری هم می‌شتابند، قسمتهای مختلف بت را به هم وصل می‌کنند و با میخ آن را به دیوار می‌کوبند تا نیفتد!
8 “Ṣùgbọ́n ìwọ, ìwọ Israẹli, ìránṣẹ́ mi, Jakọbu, ẹni tí mo ti yàn, ẹ̀yin ìran Abrahamu, ọ̀rẹ́ mi,
«اما ای اسرائیل، ای بندهٔ من، تو قوم برگزیدهٔ من هستی. تو از خاندان دوست من ابراهیم هستی.
9 mo mú ọ láti ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé, láti kọ̀rọ̀ rẹ̀ tí ó jìnnà jùlọ ni mo ti pè ọ́. Èmi wí pé, ‘Ìwọ ni ìránṣẹ́ mi’; Èmi ti yàn ọ́ bẹ́ẹ̀ ni èmi kò sì tí ì kọ̀ ọ́ sílẹ̀.
من تو را از اقصای جهان فرا خواندم و گفتم که تو بندهٔ من هستی. من تو را برگزیده‌ام و ترکت نخواهم کرد.
10 Nítorí náà má bẹ̀rù, nítorí èmi wà pẹ̀lú rẹ; má ṣe jẹ́ kí àyà kí ó fò ọ́, nítorí èmi ni Ọlọ́run rẹ. Èmi yóò fún ọ lókun èmi ó sì ràn ọ́ lọ́wọ́. Èmi ó gbé ọ ró pẹ̀lú ọwọ́ ọ̀tún òdodo mi.
نترس، چون من با تو هستم؛ نگران نشو، زیرا من خدای تو هستم. من تو را تقویت خواهم کرد و یاری خواهم داد و تو را حمایت کرده، نجات خواهم بخشید.
11 “Gbogbo àwọn tí ó bínú sí ọ ni ojú yóò tì, tí wọn yóò sì di ẹlẹ́yà; àwọn tó ń bá ọ jà yóò dàbí asán, wọn yóò ṣègbé.
«دشمنانت که بر تو خشمگین هستند رسوا خواهند شد و کسانی که با تو مخالفت می‌کنند هلاک خواهند گردید.
12 Bó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ yóò wá àwọn ọ̀tá rẹ, ìwọ kì yóò rí wọn. Gbogbo àwọn tí ó gbóguntì ọ́ yóò dàbí ohun tí kò sí.
همهٔ آنان از بین خواهند رفت و اثری از آنان باقی نخواهد ماند.
13 Nítorí Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ, tí ó di ọwọ́ ọ̀tún rẹ mú tí ó sì sọ fún ọ pé, má ṣe bẹ̀rù; Èmi yóò ràn ọ́ lọ́wọ́.
من که یهوه، خدای تو هستم دست راستت را گرفته‌ام و می‌گویم نترس، زیرا تو را یاری خواهم داد.»
14 Má ṣe bẹ̀rù, ìwọ Jakọbu kòkòrò, ìwọ Israẹli kékeré, nítorí Èmi fúnra mi yóò ràn ọ́ lọ́wọ́,” ni Olúwa wí, olùdáǹdè rẹ, Ẹni Mímọ́ ti Israẹli.
خداوند می‌گوید: «ای اسرائیل، هر چند کوچک و ضعیف هستی، ولی نترس، زیرا تو را یاری خواهم داد. من، خدای مقدّس اسرائیل، خداوند و نجا‌ت‌دهندۀ تو هستم.
15 “Kíyèsi, Èmi yóò sọ ọ́ di òòlù ìpakà tuntun, tí ó mú ti eyín rẹ̀ mú, ìwọ yóò lu àwọn òkè ńlá, ìwọ yóò fọ́ wọn túútúú, a ó sì sọ òkè kékeré di ìyàngbò.
تو مانند خرمنکوب تازه با دندانه‌های تیز خواهی بود و همهٔ دشمنانت را در هم کوبیده، خرد خواهی کرد و آنها را مانند کاه جمع کرده، کوهی از آنها خواهی ساخت.
16 Ìwọ yóò fẹ́ wọn, afẹ́fẹ́ yóò sì gbá wọn mú, àti ẹ̀fúùfù yóò sì fẹ́ wọn dànù. Ṣùgbọ́n ìwọ yóò yọ̀ nínú Olúwa ìwọ yóò sì ṣògo nínú Ẹni Mímọ́ ti Israẹli.
آنها را به هوا خواهی افشاند و باد همه را خواهد برد و گردباد آنها را پراکنده خواهد ساخت. آنگاه من که خداوند، خدای مقدّس اسرائیل هستم مایهٔ شادمانی تو خواهم بود و تو به من افتخار خواهی کرد.
17 “Àwọn tálákà àti aláìní wá omi, ṣùgbọ́n kò sí; ahọ́n wọn gbẹ fún òǹgbẹ. Ṣùgbọ́n Èmi Olúwa yóò dá wọn lóhùn; Èmi, Ọlọ́run Israẹli, kì yóò kọ̀ wọ́n sílẹ̀.
«وقتی فقرا و نیازمندان دنبال آب بگردند و پیدا نکنند و زبانشان از تشنگی خشک شود، من به دعای ایشان جواب خواهم داد. من که یهوه، خدای اسرائیل هستم هرگز آنان را ترک نخواهم کرد.
18 Èmi yóò mú kí odò kí ó sàn ní ibi gíga àti orísun omi ní àárín àfonífojì. Èmi yóò sọ aṣálẹ̀ di adágún omi, àti ilẹ̀ tí ó gbẹ gidigidi di orísun omi.
بر تپه‌های خشک برای ایشان رودخانه جاری می‌کنم و در میان دره‌ها، به آنان چشمه‌های آب می‌دهم. بیابان را به برکهٔ آب و زمین خشک را به چشمه مبدل می‌سازم.
19 Èmi yóò fi sínú aṣálẹ̀ igi kedari àti kasia, maritili àti olifi. Èmi yóò gbin junifa sí inú aginjù, igi firi àti sípírẹ́ṣì papọ̀
کاری می‌کنم که در زمین بایر، درخت سرو آزاد و آس و زیتون و شمشاد و صنوبر و کاج بروید.
20 tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn ènìyàn yóò fi rí i tí wọn yóò sì fi mọ̀, kí wọn ṣàkíyèsí kí ó sì yé wọn, pé ọwọ́ Olúwa ni ó ti ṣe èyí, àti pé, Ẹni Mímọ́ Israẹli ni ó ti dá èyí.
هر کس این را ببیند و در آن تفکر کند خواهد فهمید که من خداوند، خدای مقدّس اسرائیل این کار را کرده‌ام.»
21 “Mú ẹjọ́ wá,” ni Olúwa wí. “Tẹ́ àwọn àwíjàre rẹ sílẹ̀,” ni ọba Jakọbu wí,
خداوند که پادشاه اسرائیل است چنین می‌گوید: «بگذارید خدایان قومهای دیگر بیایند و قویترین دلایل خود را ارائه دهند!
22 “Mú àwọn ère òrìṣà rẹ wọlé láti sọ fún wa ohun tí yóò ṣẹlẹ̀. Sọ fún wa ohun tí àwọn nǹkan àtijọ́ jẹ́, kí àwa lè ṣe àgbéyẹ̀wò wọn kí àwa sì mọ àbájáde wọn ní ìparí. Tàbí kí o sọ fún wa ohun tí ó ń bọ̀ wá,
بگذارید آنچه را در گذشته اتفاق افتاده برای ما شرح دهند. بگذارید از آینده به ما خبر دهند و پیشگویی کنند تا بدانیم چه پیش خواهد آمد.
23 ẹ sọ fún wa ohun ti ọjọ́ iwájú mú dání kí àwa kí ó lè mọ̀ pé ọlọ́run ni yín. Ẹ ṣe nǹkan kan, ìbá à ṣe rere tàbí búburú, tó bẹ́ẹ̀ tí àyà yóò fi fò wá tí ẹ̀rù yóò sì fi kún inú wa.
بله، اگر آنها براستی خدا هستند بگذارید بگویند که چه اتفاقاتی بعد از این خواهد افتاد. بگذارید معجزه‌ای بکنند که از دیدنش حیران شویم.
24 Ṣùgbọ́n ẹ̀yìn ko jásí nǹkan kan iṣẹ́ yín ni kò sì wúlò fún ohunkóhun; ẹni tí ó yàn yín jẹ́ ẹni ìríra.
اما بدانید آنها هیچ هستند و کاری از دستشان برنمی‌آید، و هر که آنها را انتخاب کند خود را آلوده می‌سازد.
25 “Èmi ti ru ẹnìkan sókè láti àríwá, òun sì ń bọ ẹnìkan láti ìlà-oòrùn tí ó pe orúkọ mi. Òun gun àwọn aláṣẹ mọ́lẹ̀ bí ẹni pé odò ni wọ́n, àfi bí ẹni pé amọ̀kòkò nì ti ń gún amọ̀.
«اما من مردی را از شرق برگزیده‌ام و او را از شمال به جنگ قومها خواهم فرستاد. او نام مرا خواهد خواند و من او را بر پادشاهان مسلط خواهم ساخت. مثل کوزه‌گری که گل را لگدمال می‌کند، او نیز آنها را پایمال خواهد کرد.
26 Ta ni ó sọ èyí láti ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀, tí àwa kò bá fi mọ̀, tàbí ṣáájú àkókò, tí àwa kò bá fi wí pé, ‘Òun sọ òtítọ́’? Ẹnikẹ́ni kò sọ nípa èyí, ẹnikẹ́ni kò sàsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀, ẹnikẹ́ni kò gbọ́ ọ̀rọ̀ kan láti ọ̀dọ̀ rẹ̀.
آیا کسی تا به حال این را پیشگویی کرده است؟ آیا کسی به شما خبر داده که چنین واقعه‌ای رخ خواهد داد تا بگوییم که او درست پیشگویی می‌کند؟
27 Èmi ni ẹni àkọ́kọ́ tí ó sọ fún Sioni pé, ‘Wò ó, àwọn nìyìí!’ Mo fún Jerusalẹmu ní ìránṣẹ́ ìrò ìròyìn ayọ̀ kan.
من اولین کسی بودم که به اورشلیم مژده داده، گفتم: ای اورشلیم، قوم تو به وطن باز خواهند گشت.
28 Èmi wò, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan— kò sí ẹnìkan nínú wọn tí ó lè mú ìmọ̀ràn wá, kò sí ẹnìkan tí ó lè dáhùn nígbà tí mo bi wọ́n.
هیچ‌یک از بتها چیزی برای گفتن نداشتند. وقتی از آنها سؤال کردم جوابی نشنیدم.
29 Kíyèsi i, irọ́ ni gbogbo wọn! Gbogbo ìṣe wọn jásí asán; àwọn ère wọn kò ṣé kò yà fún afẹ́fẹ́ àti dàrúdàpọ̀.
تمام این خدایان اجسام بی‌جان هستند و هیچ کاری از دستشان برنمی‌آید.»

< Isaiah 41 >