< Isaiah 41 >

1 “Ẹ dákẹ́ jẹ́ẹ́ níwájú mi ẹ̀yin erékùṣù! Jẹ́ kí àwọn orílẹ̀-èdè tún agbára wọn ṣe! Jẹ́ kí wọn wá síwájú kí wọn sọ̀rọ̀, jẹ́ kí a pàdé pọ̀ ní ibi ìdájọ́.
“Atĩrĩrĩ, inyuĩ icigĩrĩra, ta kirai ki mũrĩ mbere yakwa! Nacio ndũrĩrĩ nĩcierũhie hinya wacio! Nĩcikuhĩrĩrie ciarie; nĩtũcemaniei hamwe tũciire.
2 “Ta ni ó ti ru ẹnìkan sókè láti ìlà-oòrùn wá, tí ó pè é ní olódodo sí iṣẹ́ tirẹ̀? Ó gbé àwọn orílẹ̀-èdè lé e lọ́wọ́ ó sì ṣẹ́gun àwọn ọba níwájú rẹ̀. Ó sọ wọ́n di erùpẹ̀ pẹ̀lú idà rẹ̀, láti kù ú ní ìyàngbò pẹ̀lú ọrun rẹ̀.
“Nũũ warahũrĩte mũndũ oime na mwena wa irathĩro, akamwĩta amũtungatagĩre na ũthingu? Aneanaga ndũrĩrĩ kũrĩ we, na agatooria athamaki makamwathĩkagĩra. Amatuuaga o ta rũkũngũ na rũhiũ rwake rwa njora, akamatua maragara na ũta wake nao makombũrwo nĩ rũhuho.
3 Ó ń lépa wọn ó sì ń kọjá ní àlàáfíà, ní ojú ọ̀nà tí ẹsẹ̀ rẹ̀ kò rìn rí.
Amatengʼeragia, akamahĩtũka atagurarĩtio, o na angĩkorwo nĩ njĩra atarĩ agerera na magũrũ make mbere ĩyo.
4 Ta ni ó ti ṣe èyí tí ó sì ti jẹ́ kí ó wáyé, tí ó ti pe ìran-ìran láti àtètèkọ́ṣe? Èmi Olúwa pẹ̀lú ẹni kìn-ín-ní wọn àti ẹni tí ó gbẹ̀yìn, Èmi náà ni.”
Nũũ wĩkĩte ũndũ ũcio na akaũhingia, ageeta njiarwa marĩĩtwa kuuma o kĩambĩrĩria? Niĩ Jehova, nĩ niĩ wa mbere na wa kũrigĩrĩria; niĩ nĩ niĩ we.”
5 Àwọn erékùṣù ti rí i wọ́n bẹ̀rù; ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé wárìrì. Wọ́n súnmọ́ tòsí wọ́n sì wá síwájú;
Icigĩrĩra nĩciĩoneire ũndũ ũcio na igetigĩra; nacio ituri cia thĩ ikainaina. Ikuhagĩrĩria na ikeyumĩria;
6 èkínní ran èkejì lọ́wọ́ ó sì sọ fún arákùnrin rẹ̀ pé, “Jẹ́ alágbára!”
o ũmwe ateithagia ũrĩa ũngĩ, na akeera mũrũ wa nyina atĩrĩ, “Wĩyũmĩrĩrie mũno!”
7 Oníṣọ̀nà gba alágbẹ̀dẹ wúrà níyànjú, àti ẹni tí ó fi òòlù dán mú òun lọ́kàn le, àní ẹni tí ó ń lu owú. Ó sọ nípa àjópọ̀ náà pé, “Ó dára.” Ó fi ìṣó kan ère náà mọ́lẹ̀ kí ó má ba à wó lulẹ̀.
Mũbundi ekagĩra mũturi wa thahabu hinya, nake ũrĩa ũnyorokagia na nyondo ĩrĩa nene omagĩrĩria ũrĩa ũturagĩra ihiga-inĩ rĩa ũturi. Nake akoiga atĩrĩ, “Wĩra ũcio wa kũnyiitithania cuma nĩ mwega.” Akanyiitithania mũhianano ũcio wa kũhooywo na mĩcumarĩ, nĩguo ndũkenyenye, ũgwe.
8 “Ṣùgbọ́n ìwọ, ìwọ Israẹli, ìránṣẹ́ mi, Jakọbu, ẹni tí mo ti yàn, ẹ̀yin ìran Abrahamu, ọ̀rẹ́ mi,
“No rĩrĩ, wee Isiraeli, ndungata yakwa, o wee Jakubu ũrĩa thuurĩte, o inyuĩ njiaro cia Iburahĩmu mũrata wakwa,
9 mo mú ọ láti ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé, láti kọ̀rọ̀ rẹ̀ tí ó jìnnà jùlọ ni mo ti pè ọ́. Èmi wí pé, ‘Ìwọ ni ìránṣẹ́ mi’; Èmi ti yàn ọ́ bẹ́ẹ̀ ni èmi kò sì tí ì kọ̀ ọ́ sílẹ̀.
ndakũrutire kuuma ituri cia thĩ, ngĩgwĩta kuuma koine ciayo iria irĩ kũraya mũno. Ngĩkwĩra atĩrĩ, ‘Wee ũrĩ ndungata yakwa;’ nĩngũthuurĩte na ndikũregete.
10 Nítorí náà má bẹ̀rù, nítorí èmi wà pẹ̀lú rẹ; má ṣe jẹ́ kí àyà kí ó fò ọ́, nítorí èmi ni Ọlọ́run rẹ. Èmi yóò fún ọ lókun èmi ó sì ràn ọ́ lọ́wọ́. Èmi ó gbé ọ ró pẹ̀lú ọwọ́ ọ̀tún òdodo mi.
Nĩ ũndũ ũcio tiga gwĩtigĩra, nĩgũkorwo ndĩ hamwe nawe; tiga kũmaka, nĩgũkorwo niĩ nĩ niĩ Ngai waku. Nĩndĩkuongagĩrĩra hinya na ngũteithagie; na ti-itherũ nĩndĩrĩgũtiiragĩrĩra na guoko gwakwa kwa ũrĩo kwa ũthingu.
11 “Gbogbo àwọn tí ó bínú sí ọ ni ojú yóò tì, tí wọn yóò sì di ẹlẹ́yà; àwọn tó ń bá ọ jà yóò dàbí asán, wọn yóò ṣègbé.
“Andũ arĩa othe makũrakaragĩra magagũũkĩrĩra ti-itherũ nĩmagaconorithio na manyararithio; arĩa marũaga nawe magaatuĩka o ta kĩndũ hatarĩ na mathire biũ.
12 Bó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ yóò wá àwọn ọ̀tá rẹ, ìwọ kì yóò rí wọn. Gbogbo àwọn tí ó gbóguntì ọ́ yóò dàbí ohun tí kò sí.
O na ũngĩgaacaria thũ ciaku, ndũgaaciona. Andũ arĩa mahũũranaga mbaara nawe magaatuĩka o ta kĩndũ hatarĩ.
13 Nítorí Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ, tí ó di ọwọ́ ọ̀tún rẹ mú tí ó sì sọ fún ọ pé, má ṣe bẹ̀rù; Èmi yóò ràn ọ́ lọ́wọ́.
Nĩgũkorwo niĩ nĩ niĩ Jehova, Ngai waku, ũrĩa ũkũnyiitaga guoko kwa ũrĩo, na agakwĩra atĩrĩ, Tiga gwĩtigĩra; nĩngũgũteithia.
14 Má ṣe bẹ̀rù, ìwọ Jakọbu kòkòrò, ìwọ Israẹli kékeré, nítorí Èmi fúnra mi yóò ràn ọ́ lọ́wọ́,” ni Olúwa wí, olùdáǹdè rẹ, Ẹni Mímọ́ ti Israẹli.
Tiga gwĩtigĩra, wee Jakubu kagunyũ gaka, o wee Isiraeli gakundi kanini, niĩ mwene nĩ niĩ ngũgũteithia,” ũguo nĩguo Jehova ekuuga, ũcio Mũkũũri waku, Ũrĩa Mũtheru wa Isiraeli.
15 “Kíyèsi, Èmi yóò sọ ọ́ di òòlù ìpakà tuntun, tí ó mú ti eyín rẹ̀ mú, ìwọ yóò lu àwọn òkè ńlá, ìwọ yóò fọ́ wọn túútúú, a ó sì sọ òkè kékeré di ìyàngbò.
“Atĩrĩrĩ, nĩngagũtua kĩhũũri kĩa ngano, kĩhũũri kĩerũ na kĩũgĩ, kĩna magego maingĩ. Nĩũkahũũra irĩma na ũcihehenje, natuo tũrĩma ũtũtue mũũngũ.
16 Ìwọ yóò fẹ́ wọn, afẹ́fẹ́ yóò sì gbá wọn mú, àti ẹ̀fúùfù yóò sì fẹ́ wọn dànù. Ṣùgbọ́n ìwọ yóò yọ̀ nínú Olúwa ìwọ yóò sì ṣògo nínú Ẹni Mímọ́ ti Israẹli.
Wee nĩũgaacihuha, naruo rũhuho rũcigũrũkie, nakĩo kĩhuhũkanio gĩcihurunje. No rĩrĩ, wee nĩũgakenera Jehova, na wĩrahagĩre Ũrĩa Mũtheru wa Isiraeli.
17 “Àwọn tálákà àti aláìní wá omi, ṣùgbọ́n kò sí; ahọ́n wọn gbẹ fún òǹgbẹ. Ṣùgbọ́n Èmi Olúwa yóò dá wọn lóhùn; Èmi, Ọlọ́run Israẹli, kì yóò kọ̀ wọ́n sílẹ̀.
“Andũ arĩa athĩĩni na abatari methaga maaĩ ma kũnyua, no gũtirĩ; nĩmĩ ciao nĩcingʼarĩtio nĩ nyoota. No rĩrĩ, niĩ Jehova nĩngamacookeria ũhoro; niĩ Ngai wa Isiraeli, ndirĩ hĩndĩ ngaamatiganĩria.
18 Èmi yóò mú kí odò kí ó sàn ní ibi gíga àti orísun omi ní àárín àfonífojì. Èmi yóò sọ aṣálẹ̀ di adágún omi, àti ilẹ̀ tí ó gbẹ gidigidi di orísun omi.
Nĩngatũma njũũĩ itherere kũu rũngʼũrĩ-inĩ kũrĩa gũtũũgĩru, nacio ithima itherũke cianda-inĩ. Nĩngatũma kũu werũ-inĩ kũgĩe tũria twa maaĩ, nakuo kũndũ kũrĩa kũngʼaru ndũme gũtherũke ithima cia maaĩ.
19 Èmi yóò fi sínú aṣálẹ̀ igi kedari àti kasia, maritili àti olifi. Èmi yóò gbin junifa sí inú aginjù, igi firi àti sípírẹ́ṣì papọ̀
Nĩngahaanda mĩtarakwa na mĩgaa, na mĩhandathi na mĩtamaiyũ kũu werũ-inĩ. Na haande mĩbinde kũndũ kũrĩa gũtakũraga kĩndũ, na mĩthengera, na mĩkarakaba o hamwe,
20 tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn ènìyàn yóò fi rí i tí wọn yóò sì fi mọ̀, kí wọn ṣàkíyèsí kí ó sì yé wọn, pé ọwọ́ Olúwa ni ó ti ṣe èyí, àti pé, Ẹni Mímọ́ Israẹli ni ó ti dá èyí.
nĩgeetha andũ mone na mamenye, mecũũranie na mataũkĩrwo, atĩ nĩ guoko kwa Jehova gwĩkĩte maũndũ macio, na atĩ Ũrĩa Mũtheru wa Isiraeli nĩwe wamĩũmbire.”
21 “Mú ẹjọ́ wá,” ni Olúwa wí. “Tẹ́ àwọn àwíjàre rẹ sílẹ̀,” ni ọba Jakọbu wí,
Jehova ekuuga atĩrĩ, “Rehei ciira wanyu ũrĩa mũrĩ naguo. Onaniai ihooto cianyu cia hinya,” ũguo nĩguo Mũthamaki wa Jakubu ekuuga.
22 “Mú àwọn ère òrìṣà rẹ wọlé láti sọ fún wa ohun tí yóò ṣẹlẹ̀. Sọ fún wa ohun tí àwọn nǹkan àtijọ́ jẹ́, kí àwa lè ṣe àgbéyẹ̀wò wọn kí àwa sì mọ àbájáde wọn ní ìparí. Tàbí kí o sọ fún wa ohun tí ó ń bọ̀ wá,
“Rehei ngai cianyu cia mĩhianano ya kũhooywo itwĩre ũrĩa gũkaahaana. Twĩrei ũrĩa maũndũ ma tene maatariĩ, nĩguo twĩcũũranie ũhoro wamo, na tũmenye ũrĩa makaarigĩrĩria. Kana mũtũmenyithie ũhoro wa maũndũ marĩa magooka thuutha,
23 ẹ sọ fún wa ohun ti ọjọ́ iwájú mú dání kí àwa kí ó lè mọ̀ pé ọlọ́run ni yín. Ẹ ṣe nǹkan kan, ìbá à ṣe rere tàbí búburú, tó bẹ́ẹ̀ tí àyà yóò fi fò wá tí ẹ̀rù yóò sì fi kún inú wa.
na mũtwĩre ũrĩa gũgaikara thuutha-inĩ, nĩguo tũmenye atĩ mũrĩ ngai. Ĩkai ũndũ mwega kana mũũru, nĩguo tũmake na tũiyũrwo nĩ guoya.
24 Ṣùgbọ́n ẹ̀yìn ko jásí nǹkan kan iṣẹ́ yín ni kò sì wúlò fún ohunkóhun; ẹni tí ó yàn yín jẹ́ ẹni ìríra.
No rĩrĩ, inyuĩ mũrĩ kĩndũ hatarĩ, na mawĩra manyu matirĩ bata; mũndũ ũrĩa ũmwĩthuurĩire atariĩ o ta kĩndũ kĩrĩ magigi.
25 “Èmi ti ru ẹnìkan sókè láti àríwá, òun sì ń bọ ẹnìkan láti ìlà-oòrùn tí ó pe orúkọ mi. Òun gun àwọn aláṣẹ mọ́lẹ̀ bí ẹni pé odò ni wọ́n, àfi bí ẹni pé amọ̀kòkò nì ti ń gún amọ̀.
“Nĩnjarahũrĩte mũndũ wa kuuma gathigathini, na nĩarooka: mũndũ uumĩte irathĩro rĩa riũa ũrĩa ũkayagĩra rĩĩtwa rĩakwa. Arangagĩrĩria aathani a thĩ o ta marĩ ndaka, akamarangĩrĩria o ta ũrĩa mũmbi akimaga rĩũmba.
26 Ta ni ó sọ èyí láti ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀, tí àwa kò bá fi mọ̀, tàbí ṣáájú àkókò, tí àwa kò bá fi wí pé, ‘Òun sọ òtítọ́’? Ẹnikẹ́ni kò sọ nípa èyí, ẹnikẹ́ni kò sàsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀, ẹnikẹ́ni kò gbọ́ ọ̀rọ̀ kan láti ọ̀dọ̀ rẹ̀.
Nũũ waheanire ũhoro ũcio kuuma o kĩambĩrĩria, nĩguo tũũmenye; kana akĩũheana mbere ĩyo, nĩguo tuuge atĩrĩ, ‘Ũhoro ũcio aarĩtie nĩ wa ma’? Gũtirĩ mũndũ weranire ũhoro ũyũ, na gũtirĩ mũndũ waũheanĩte mbere ĩyo, gũtirĩ mũndũ waiguĩte ũhoro ũyũ kuuma kũrĩ inyuĩ.
27 Èmi ni ẹni àkọ́kọ́ tí ó sọ fún Sioni pé, ‘Wò ó, àwọn nìyìí!’ Mo fún Jerusalẹmu ní ìránṣẹ́ ìrò ìròyìn ayọ̀ kan.
Nĩ niĩ ndaarĩ wa mbere kwĩra Zayuni atĩrĩ, ‘Atĩrĩrĩ, aya marĩ haha!’ Nĩ niĩ ndatũmire mũndũ athiĩ Jerusalemu agatware ũhoro ũrĩa mwega.
28 Èmi wò, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan— kò sí ẹnìkan nínú wọn tí ó lè mú ìmọ̀ràn wá, kò sí ẹnìkan tí ó lè dáhùn nígbà tí mo bi wọ́n.
Ndĩrarora no hatirĩ mũndũ; gũtirĩ mũndũ thĩinĩ wao ũngĩheana kĩrĩra, gũtirĩ mũndũ wa kũnjookeria ũhoro rĩrĩa ingĩmoria kĩũria.
29 Kíyèsi i, irọ́ ni gbogbo wọn! Gbogbo ìṣe wọn jásí asán; àwọn ère wọn kò ṣé kò yà fún afẹ́fẹ́ àti dàrúdàpọ̀.
Atĩrĩrĩ, andũ othe nĩ a maheeni! Ciĩko ciao no cia tũhũ; mĩhianano yao ya gwacũhio ĩhaana o ta rũhuho, na nĩ ya tũhũ mũtheri.

< Isaiah 41 >