< Isaiah 40 >

1 Ẹ tù ú nínú, ẹ tu ènìyàn mi nínú, ni Ọlọ́run yín wí.
Monkyekye, monkyekye me nkurɔfo werɛ. Saa na mo Nyankopɔn se.
2 Sọ̀rọ̀ pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ fún Jerusalẹmu kí o sì kéde fún un pé iṣẹ́ àṣekára rẹ̀ ti parí, pé à ti san gbèsè ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, pé ó ti rí i gbà láti ọwọ́ Olúwa ìlọ́po méjì fún gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.
Monka asomdwoesɛm nkyerɛ Yerusalem, na mompae mu nka nkyerɛ no se ne som dennen no aba awiei, wɔatua ne bɔne no so ka, na wɔanya ne bɔne nyinaa so akatua mmɔho afi Awurade nsam.
3 Ohùn ẹni tí ń kígbe ní ijù: “Ẹ tún ọ̀nà Olúwa ṣe, ṣe òpópó tí ó tọ́ ní aginjù fún Ọlọ́run wa.
Nne bi reteɛ mu se, “Munsiesie ɔkwan mma Awurade wɔ nweatam no so. Monteɛ ɔtempɔn wɔ sare no so mma yɛn Nyankopɔn.
4 Gbogbo àfonífojì ni a ó gbé sókè, gbogbo òkè ńlá àti òkè kékeré ni yóò di pẹ̀tẹ́lẹ̀; wíwọ́ ni a ó sọ di títọ́ àti ọ̀nà pálapàla ni a óò sọ di títẹ́jú pẹrẹsẹ.
Obon biara bɛyɛ ma, bepɔw ne nkoko nyinaa bɛkɔ fam, asase a ɛyɛ abonkyiabonkyi no bɛyɛ tamaa, na mmeae a ɛyɛ akɔntɔnkye no ayɛ tataw.
5 Ògo Olúwa yóò sì di mí mọ̀, gbogbo ènìyàn lápapọ̀ ni yóò sì rí i. Nítorí ẹnu Olúwa ni ó ti sọ ọ́.”
Na Awurade anuonyam bɛda adi, na nnipa nyinaa behu. Efisɛ Awurade na waka!”
6 Ohùn kan wí pé, “Kígbe sókè.” Èmi sì sọ pé, “Igbe kí ni èmi ó ké?” “Gbogbo ènìyàn dàbí i koríko, àti gbogbo ògo wọn dàbí ìtànná igbó.
Nne bi kae se, “Teɛ mu.” Na mekae se, “Menteɛ mu nka dɛn?” “Nnipa nyinaa te sɛ sare, na wɔn anuonyam nyinaa te sɛ afuw so nhwiren.
7 Koríko ń rọ ìtànná sì ń rẹ̀, nítorí èémí Olúwa ń fẹ́ lù wọ́n. Nítòótọ́ koríko ni àwọn ènìyàn.
Sare hyew, na nhwiren twintwam efisɛ Awurade ahomegu fa wɔn so. Nokware, nnipa no yɛ sare.
8 Koríko ń rọ ìtànná sì ń rẹ̀, ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ Ọlọ́run wa dúró títí láé.”
Sare hyew, na nhwiren twintwam, nanso yɛn Nyankopɔn asɛm no tim hɔ daa.”
9 Ìwọ tí o mú ìyìn ayọ̀ wá sí Sioni, lọ sí orí òkè gíga. Ìwọ tí ó mú ìyìn ayọ̀ wá sí Jerusalẹmu, gbé ohùn rẹ sókè pẹ̀lú ariwo, gbé e sókè, má ṣe bẹ̀rù; sọ fún àwọn ìlú u Juda, “Ọlọ́run rẹ nìyìí!”
Wo a wode asɛm pa reba Sion, foro kɔ bepɔw tenten bi so. Wo a wode asɛm pa reba Yerusalem, ma wo nne so na teɛ mu, ma so, nsuro; ka kyerɛ Yuda nkurow se, “Mo Nyankopɔn ni!”
10 Wò ó, Olúwa Olódùmarè náà ń bọ̀ wá pẹ̀lú agbára, apá rẹ̀ sì ń jẹ ọba fún un. Wò ó, èrè rẹ̀ sì wà pẹ̀lú rẹ̀, àti ìdápadà rẹ̀ tí ń bá a bọ̀ wá.
Hwɛ, Asafo Awurade de tumi reba, na nʼabasa bedi hene ama no. Hwɛ, nʼakatua ka ne ho, na ɔde nʼabasobɔde nam.
11 Ó ń tọ́ àwọn agbo rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́-àgùntàn: Ó kó àwọn ọ̀dọ́-àgùntàn ní apá rẹ̀. Ó sì gbé wọn súnmọ́ oókan àyà rẹ̀; ó sì fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ darí àwọn tí ó ní.
Ɔhwɛ ne nguankuw sɛ oguanhwɛfo. Ɔboa nguantenmma no wɔ nʼabasa so oturu wɔn ne koko so; na nguan a wɔwɔ mma no, ɔka wɔn brɛoo.
12 Ta ni ó tiwọn omi nínú kòtò ọwọ́ rẹ̀, tàbí pẹ̀lú ìbú ọwọ́ rẹ̀ tí ó wọn àwọn ọ̀run? Ta ni ó ti kó erùpẹ̀ ilẹ̀ ayé jọ nínú apẹ̀rẹ̀, tàbí kí ó wọn àwọn òkè ńlá lórí ìwọ̀n àti òkè kéékèèké nínú òsùwọ̀n?
Hena na wasusuw obon mu nsu wɔ ne nsam anaa ɔde ne nsateaa asusuw ɔsoro? Hena na ɔde asase so mfutuma agu kɛntɛn mu, anaa wakari mmepɔw wɔ nsania so ne nkoko wɔ nsania apampaa so?
13 Ta ni ó ti mọ ọkàn Olúwa, tàbí tí ó ti tọ́ ọ ṣọ́nà gẹ́gẹ́ bí olùdámọ̀ràn rẹ̀?
Hena na wate Awurade ase, anaa wakyerɛkyerɛ no sɛ ne fotufo?
14 Ta ni Olúwa ké sí kí ó là á lọ́yẹ àti ta ni ó kọ́ òun ní ọ̀nà tí ó tọ́? Ta ni ẹni náà tí ó kọ́ ọ ní ọgbọ́n tàbí tí ó fi ipa ọ̀nà òye hàn án?
Hena na Awurade abisa no sɛ ɔnkyerɛ no biribi ase, na hena na ɔkyerɛɛ no ɔkwan pa no? Hena na ɔmaa no nimdeɛ anaa ɔkyerɛɛ no nhumu kwan?
15 Nítòótọ́ àwọn orílẹ̀-èdè dàbí i ẹ̀kún omi nínú garawa; a kà wọ́n sí gẹ́gẹ́ bí eruku lórí ìwọ̀n; ó wọn àwọn erékùṣù àfi bí eruku múnúmúnú ni wọ́n.
Ampa ara aman no te sɛ nsu sope wɔ bokiti mu; wɔde wɔn toto mfutuma a egu nsania so ho; ɔkari nsupɔw te sɛnea ɛyɛ mfutuma muhumuhu.
16 Lebanoni kò tó fún pẹpẹ iná, tàbí kí àwọn ẹranko rẹ̀ kí ó tó fún ẹbọ sísun.
Lebanon nnɔɔso mma afɔremuka so gya, na ne mmoa renso mma ɔhyew afɔrebɔde.
17 Níwájú rẹ̀ ni gbogbo orílẹ̀-èdè dàbí ohun tí kò sí; gbogbo wọn ló kà sí ohun tí kò wúlò tí kò tó ohun tí kò sí.
Aman nyinaa nsɛ hwee wɔ nʼanim; obu wɔn adehunu bi a wɔnka hwee.
18 Ta ni nígbà náà tí ìwọ yóò fi Ọlọ́run wé? Ère wo ni ìwọ yóò fi ṣe àkàwé rẹ̀?
Afei hena ho na wode Onyankopɔn bɛtoto? Nsɛsode bɛn ho na wode no bɛto?
19 Ní ti ère, oníṣọ̀nà ni ó dà á, ti alágbẹ̀dẹ wúrà sì fi wúrà bò ó tí a sì ṣe ẹ̀wọ̀n ọ̀nà sílífà fún un.
Ohoni de, odwumfo na ɔyɛ, na sikadwumfo de sikakɔkɔɔ agu ho na wasiesie dwetɛ nkɔnsɔnkɔnsɔn ama no.
20 Ọkùnrin kan tí ó tálákà jù kí ó lè mú irú ọrẹ bẹ́ẹ̀ wá, wá igi tí kò le è rà. Ó wá oníṣọ̀nà tí ó láti ṣe àgbékalẹ̀ ère tí kì yóò le è ṣubú.
Ohiani a ɔrentumi mfa saa ayɛyɛde yi mma no kɔhwehwɛ dua a ɛremporɔw. Ɔhwehwɛ odwumfo nyansafo na wayɛ ohoni a ɛremmunum nhwe fam asi hɔ.
21 Ǹjẹ́ o kò tí ì mọ̀ ìwọ kò tí ì gbọ́? A kò tí ì sọ fún ọ láti ìbẹ̀rẹ̀ wá? Ìwọ kò tí ì mọ láti ìgbà ìpìlẹ̀ ayé?
Wunnim ana? Wontee ana? Wɔnnka nkyerɛɛ wo mfii mfiase no ana? Efi bere a wɔbɔɔ asase no, wontee ase ana?
22 Òun jókòó lórí ìtẹ́ ní òkè òbírí ilẹ̀ ayé, àwọn ènìyàn rẹ̀ sì dàbí i láńtata. Ó ta àwọn ọ̀run bí ìbòrí ìgúnwà, ó sì nà wọ́n jáde gẹ́gẹ́ bí àgọ́ láti gbé.
Ɔte ahengua so wɔ asase dantaban no atifi ɛso nnipa te sɛ tɛwtɛw ɔtwe ɔsoro mu te sɛ bamkyinii, na ɔtrɛw mu sɛ ntamadan tena mu.
23 Ó sọ àwọn ọmọ ọba di asán àti àwọn aláṣẹ ayé yìí ni ó ti sọ dòfo.
Ɔma ahemmea yɛ nnipahunu na wiase yi sodifo nso, ɔbrɛ wɔn ase.
24 Gẹ́rẹ́ tí a ti gbìn wọ́n, kété tí a gbìn wọ́n, kété tí wọ́n fi gbòǹgbò múlẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ó fẹ́ atẹ́gùn lù wọ́n gbogbo wọn sì gbẹ, bẹ́ ni ìjì líle sì gbá wọn lọ gẹ́gẹ́ bí ìyàngbò.
Wɔtɛw wɔn ara pɛ, woduaa wɔn ara pɛ, wogyee ntin wɔ asase mu pɛ, na wahome agu wɔn so ama wɔakisa, na mframa abɔ wɔn kɔ te sɛ ntɛtɛ.
25 “Ta ni ẹ ó fi mi wé? Tàbí ta ni ó bá mi dọ́gba?” ni Ẹni Mímọ́ wí.
“Hena ho na wode me bɛto? Anaasɛ hena na ɔne me sɛ?” Ɔkronkronni no na ose.
26 Gbé ojú rẹ sókè kí o sì wo àwọn ọ̀run. Ta ni ó dá àwọn wọ̀nyí? Ẹni tí ó mú àkójọpọ̀ àwọn ìràwọ̀ jáde wá ní ọ̀kọ̀ọ̀kan tí ó sì pè wọ́n ní orúkọ lọ́kọ̀ọ̀kan. Nítorí agbára ńlá àti ipá rẹ̀, ọ̀kan ṣoṣo nínú wọn kò sọnù.
Momma mo ani so nhwɛ ɔsoro: Hena na ɔbɔɔ eyinom nyinaa? Nea oyiyi ɔsoro nsoromma mmaako mmaako, na ɔbɔ obiara din frɛ no. Nʼahoɔden ne ne tumi nti wɔn mu baako mpo nyera.
27 Èéṣe tí o fi sọ, ìwọ Jakọbu? Àti tí o ṣàròyé, ìwọ Israẹli, “Ọ̀nà mi pamọ́ níwájú Olúwa; ìṣe mi ni a kò kọbi ara sí láti ọwọ́ Ọlọ́run mi”?
Adɛn na wunwiinwii, Yakob, na woka se, Israel, “Mʼakwan ahintaw Awurade; na me Nyankopɔn abɔ mʼasɛm agu”?
28 Ìwọ kò tí ì mọ̀? Ìwọ kò tí ì gbọ́? Olúwa òun ni Ọlọ́run ayérayé, Ẹlẹ́dàá gbogbo ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé. Agara kì yóò da bẹ́ẹ̀ ni kò ní ṣàárẹ̀, àti òye rẹ̀ ni ẹnikẹ́ni kò le ṣe òdínwọ̀n rẹ̀.
Wunnim ana? Wontee ana? Awurade yɛ daapem Nyankopɔn, na ɔyɛ asase nyinaa yɛfo. Ɔremmrɛ na ɔrentɔ beraw, na ne nhumu nni nhwehwɛmu.
29 Ó ń fi agbára fún àwọn aláàárẹ̀ ó sì fi kún agbára àwọn tí agara dá.
Ɔma nea watɔ beraw ahoɔden nea wayɛ mmerɛw nso, ɔto nʼahoɔden so.
30 Àní, ó ń rẹ̀ wọ́n àwọn ọ̀dọ́, wọ́n ń rẹ̀wẹ̀sì, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sì ń kọsẹ̀ wọ́n ṣubú;
Mpo, mmabun brɛ, na wɔtɔ beraw, na mmerante hintihintiw hwehwe ase;
31 ṣùgbọ́n àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé Olúwa yóò sọ agbára wọn di ọ̀tun. Wọn yóò fìyẹ́ fò lókè bí idì; wọn yóò sáré àárẹ̀ kò ní mú wọn, wọn yóò rìn òòyì kò ní kọ́ wọn.
Nanso, wɔn a wɔn ani da Awurade so benya ahoɔden foforo. Wɔde ntaban sɛ akɔre de betu akɔ wim; wobetu mmirika, na wɔrentɔ beraw. Wɔbɛnantew, na wɔrentɔ piti.

< Isaiah 40 >