< Isaiah 40 >

1 Ẹ tù ú nínú, ẹ tu ènìyàn mi nínú, ni Ọlọ́run yín wí.
E HOOMAHA aku, e hoomaha aku oukou i ko'u poe kanaka, Wahi a ke Akua o oukou.
2 Sọ̀rọ̀ pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ fún Jerusalẹmu kí o sì kéde fún un pé iṣẹ́ àṣekára rẹ̀ ti parí, pé à ti san gbèsè ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, pé ó ti rí i gbà láti ọwọ́ Olúwa ìlọ́po méjì fún gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.
E olelo hoomaha aku i ko Ierusalema, E kahea aku hoi ia ia, ua pau kona kaua ana, Ua kalaia hoi kona hala; No ka mea, ma ka lima o Iehova, Ua loaa papalua ia ia no na hewa ona a pau.
3 Ohùn ẹni tí ń kígbe ní ijù: “Ẹ tún ọ̀nà Olúwa ṣe, ṣe òpópó tí ó tọ́ ní aginjù fún Ọlọ́run wa.
Ka leo o ka mea e kala ana, ma ka waonahele, E hoomakaukau oukou i alanui no Iehova, E hoopololei hoi ma ka waoakua, I kuamoo no ko kakou Akua.
4 Gbogbo àfonífojì ni a ó gbé sókè, gbogbo òkè ńlá àti òkè kékeré ni yóò di pẹ̀tẹ́lẹ̀; wíwọ́ ni a ó sọ di títọ́ àti ọ̀nà pálapàla ni a óò sọ di títẹ́jú pẹrẹsẹ.
E hoopihaia'na na awawa a pau, A e hoohaahaaia'na na mauna a pau, a me na puu; E lilo no ka mea kekee i pololei, A me kahi puupuu i laumania.
5 Ògo Olúwa yóò sì di mí mọ̀, gbogbo ènìyàn lápapọ̀ ni yóò sì rí i. Nítorí ẹnu Olúwa ni ó ti sọ ọ́.”
E hoikeia mai no ka nani o Iehova, A e ike pu aku no na kanaka a pau; No ka mea, na ka waha o Iehova i olelo mai.
6 Ohùn kan wí pé, “Kígbe sókè.” Èmi sì sọ pé, “Igbe kí ni èmi ó ké?” “Gbogbo ènìyàn dàbí i koríko, àti gbogbo ògo wọn dàbí ìtànná igbó.
I mai la ka leo, E kala aku. I aku la ia, Heaha ka'u o kala'i? He mauu no na kanaka a pau, Ua like hoi kona nani a pau me ka pua o ke kula;
7 Koríko ń rọ ìtànná sì ń rẹ̀, nítorí èémí Olúwa ń fẹ́ lù wọ́n. Nítòótọ́ koríko ni àwọn ènìyàn.
Mimino ka mauu, a mae wale ka pua, Ke pa mai ka makani o Iehova maluna ona; He oiaio no, he mauu keia poe kanaka.
8 Koríko ń rọ ìtànná sì ń rẹ̀, ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ Ọlọ́run wa dúró títí láé.”
Mimino ka mauu, a mae wale ka pua; Aka, o ka olelo a ko kakou Akua, e kupaa mau loa no ia.
9 Ìwọ tí o mú ìyìn ayọ̀ wá sí Sioni, lọ sí orí òkè gíga. Ìwọ tí ó mú ìyìn ayọ̀ wá sí Jerusalẹmu, gbé ohùn rẹ sókè pẹ̀lú ariwo, gbé e sókè, má ṣe bẹ̀rù; sọ fún àwọn ìlú u Juda, “Ọlọ́run rẹ nìyìí!”
E ka mea hai i ka olelo maikai no Ziona, E pii aku oe iluna o ka mauna kiekie; E ka mea hai i ka olelo maikai no Ierusalema, E hookiekie oe i kou leo me ka ikaika; E hookiekie hoi, mai makau; E olelo ae i na kulanakauhale o ka Iuda, Aia hoi ko oukou Akua!
10 Wò ó, Olúwa Olódùmarè náà ń bọ̀ wá pẹ̀lú agbára, apá rẹ̀ sì ń jẹ ọba fún un. Wò ó, èrè rẹ̀ sì wà pẹ̀lú rẹ̀, àti ìdápadà rẹ̀ tí ń bá a bọ̀ wá.
Aia hoi, e hele mai ana ka Haku, o Iehova me ka ikaika, Na kona lima no e malama ia; Aia hoi, me ia pu no kana uku mai, A o kana ukuhuna hoi ma kona alo.
11 Ó ń tọ́ àwọn agbo rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́-àgùntàn: Ó kó àwọn ọ̀dọ́-àgùntàn ní apá rẹ̀. Ó sì gbé wọn súnmọ́ oókan àyà rẹ̀; ó sì fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ darí àwọn tí ó ní.
E hanai no oia i kana ohana me he kahuhipa la; E hoiliili no hoi i na keikihipa i kona lima, A hiipoi hoi ia lakou ma kona poli, A alakai i ka poe hanai waiu.
12 Ta ni ó tiwọn omi nínú kòtò ọwọ́ rẹ̀, tàbí pẹ̀lú ìbú ọwọ́ rẹ̀ tí ó wọn àwọn ọ̀run? Ta ni ó ti kó erùpẹ̀ ilẹ̀ ayé jọ nínú apẹ̀rẹ̀, tàbí kí ó wọn àwọn òkè ńlá lórí ìwọ̀n àti òkè kéékèèké nínú òsùwọ̀n?
Owai ka mea i ana i na wai maloko o ka poho o kona lima? A ana aku hoi i na lani ma ke kikoo, A ana no hoi i ka lepo o ka honua iloko o ka mea ana, A kaupaona i na kuahiwi ma na mea kaupaona, A me na mauna hoi maloko o na paonakaulike?
13 Ta ni ó ti mọ ọkàn Olúwa, tàbí tí ó ti tọ́ ọ ṣọ́nà gẹ́gẹ́ bí olùdámọ̀ràn rẹ̀?
Owai ka mea i alakai i ka Uhane o Iehova, A noho i kakaolelo nona, a ao aku ia ia?
14 Ta ni Olúwa ké sí kí ó là á lọ́yẹ àti ta ni ó kọ́ òun ní ọ̀nà tí ó tọ́? Ta ni ẹni náà tí ó kọ́ ọ ní ọgbọ́n tàbí tí ó fi ipa ọ̀nà òye hàn án?
Me wai la oia i kukakuka pu ai? Nawai hoi i ao aku ia ia, A kuhikuhi hoi ia ia i ke ia ala o ka pono, A hoike aku ia ia i ke ala o ka naauao?
15 Nítòótọ́ àwọn orílẹ̀-èdè dàbí i ẹ̀kún omi nínú garawa; a kà wọ́n sí gẹ́gẹ́ bí eruku lórí ìwọ̀n; ó wọn àwọn erékùṣù àfi bí eruku múnúmúnú ni wọ́n.
Aia hoi, ua like na lahuikanaka, me ke kulu hookahi o ka bakeke, A ua manaoia hoi o like me ka huna lepo uuku maloko o na mea kaulike; Kaikai oia i na aina me he mea uuku la.
16 Lebanoni kò tó fún pẹpẹ iná, tàbí kí àwọn ẹranko rẹ̀ kí ó tó fún ẹbọ sísun.
Aole i nui o Lebanona i mea puhi, Aole hoi i nui kolaila holoholona, i mea mohaikuni.
17 Níwájú rẹ̀ ni gbogbo orílẹ̀-èdè dàbí ohun tí kò sí; gbogbo wọn ló kà sí ohun tí kò wúlò tí kò tó ohun tí kò sí.
Me he mea ole la na lahuikanaka a pau imua ona, A ua manaoia lakou e ia ua uuku iho i ka ole, He mea lapuwale loa hoi.
18 Ta ni nígbà náà tí ìwọ yóò fi Ọlọ́run wé? Ère wo ni ìwọ yóò fi ṣe àkàwé rẹ̀?
Me wai oukou e hoohalike ai i ke Akua? Heaha ka mea like, e hoohalike ai oukou me ia?
19 Ní ti ère, oníṣọ̀nà ni ó dà á, ti alágbẹ̀dẹ wúrà sì fi wúrà bò ó tí a sì ṣe ẹ̀wọ̀n ọ̀nà sílífà fún un.
O ka mea hana, hoohehee no oia i akuakii, A o ka mea hana gula, hohola ae la oia i ke gula maluna o ia mea, A hana hoi i na kaula kala.
20 Ọkùnrin kan tí ó tálákà jù kí ó lè mú irú ọrẹ bẹ́ẹ̀ wá, wá igi tí kò le è rà. Ó wá oníṣọ̀nà tí ó láti ṣe àgbékalẹ̀ ère tí kì yóò le è ṣubú.
A o ka mea loaa ole ka mohai no ka hune, Wae no oia i wahi laau popo ole; A imi aku la i kahuna akamai i ka hana, Nana e hoomakaukau i akuakii kalaiia naueue ole.
21 Ǹjẹ́ o kò tí ì mọ̀ ìwọ kò tí ì gbọ́? A kò tí ì sọ fún ọ láti ìbẹ̀rẹ̀ wá? Ìwọ kò tí ì mọ láti ìgbà ìpìlẹ̀ ayé?
Aole anei oukou i ike, aole hoi i lohe? Aole anei i haiia mai ia oukou mai kinohi mai? Aole anei oukou i hoomaopopo, mai ka hookumu ana o ka honua?
22 Òun jókòó lórí ìtẹ́ ní òkè òbírí ilẹ̀ ayé, àwọn ènìyàn rẹ̀ sì dàbí i láńtata. Ó ta àwọn ọ̀run bí ìbòrí ìgúnwà, ó sì nà wọ́n jáde gẹ́gẹ́ bí àgọ́ láti gbé.
Oia no ke noho ma ka poai o ka honua, A ua like hoi kolaila poe e noho ana me na uhini; Nana no e hoopalahalaha aku na lani me he paku la, A hohola no hoi lakou me he hale lole la, kahi e noho ai.
23 Ó sọ àwọn ọmọ ọba di asán àti àwọn aláṣẹ ayé yìí ni ó ti sọ dòfo.
Oia ke hoolilo i na'lii i mea ole, A me na lunakanawai o ka honua, me he mea lapuwale la.
24 Gẹ́rẹ́ tí a ti gbìn wọ́n, kété tí a gbìn wọ́n, kété tí wọ́n fi gbòǹgbò múlẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ó fẹ́ atẹ́gùn lù wọ́n gbogbo wọn sì gbẹ, bẹ́ ni ìjì líle sì gbá wọn lọ gẹ́gẹ́ bí ìyàngbò.
He oiaio, aole lakou e kanuia, Ho oiaio, aole lakou e luluia, He oiaio, aole e paa ka lakou kumu maloko o ka honua; A e puhi mai Oia maluna o lakou, a e mae wale lakou, A e lawe no ka puahiohio ia lakou me he opala la.
25 “Ta ni ẹ ó fi mi wé? Tàbí ta ni ó bá mi dọ́gba?” ni Ẹni Mímọ́ wí.
Me wai la hoi oukou e hoohalike ai ia'u? A e like au me wai? wahi a ka Mea Hemolele.
26 Gbé ojú rẹ sókè kí o sì wo àwọn ọ̀run. Ta ni ó dá àwọn wọ̀nyí? Ẹni tí ó mú àkójọpọ̀ àwọn ìràwọ̀ jáde wá ní ọ̀kọ̀ọ̀kan tí ó sì pè wọ́n ní orúkọ lọ́kọ̀ọ̀kan. Nítorí agbára ńlá àti ipá rẹ̀, ọ̀kan ṣoṣo nínú wọn kò sọnù.
E alawa ae i ko oukou mau maka iluna, E nana hoi i ka Mea nana i hana i kela mau mea, Alakai aku no oia i ko lakou lehulehu a pau ma ka helu ana. Hea aku no oia ia lakou a pau ma ka iuoa, No ka nui loa o kona mana, a me ka mana loa o kona ikaika; Aohe mea o lakou i nalowale.
27 Èéṣe tí o fi sọ, ìwọ Jakọbu? Àti tí o ṣàròyé, ìwọ Israẹli, “Ọ̀nà mi pamọ́ níwájú Olúwa; ìṣe mi ni a kò kọbi ara sí láti ọwọ́ Ọlọ́run mi”?
No ke aha la oe e olelo ai, o Iakoba, A kamailio iho, e ka Iseraela, Ua hunaia ko'u ala, mai o Iehova aku, Ua hoaloia ko'u hoaponoia mai ko'u Akua aku?
28 Ìwọ kò tí ì mọ̀? Ìwọ kò tí ì gbọ́? Olúwa òun ni Ọlọ́run ayérayé, Ẹlẹ́dàá gbogbo ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé. Agara kì yóò da bẹ́ẹ̀ ni kò ní ṣàárẹ̀, àti òye rẹ̀ ni ẹnikẹ́ni kò le ṣe òdínwọ̀n rẹ̀.
Aole anei oe i ike, aole anei oe i lohe? O ke Akua mau loa o Iehova, O ka mea nana i hana i na kukulu o ka honua; Aole ia e maule, aole hoi e luhi; Aohe mea e hiki ke hoomaopopo i kona ike.
29 Ó ń fi agbára fún àwọn aláàárẹ̀ ó sì fi kún agbára àwọn tí agara dá.
Nana no i haawi i ka ikaika i ka mea i maule; A o ka mea ikaika ole, hoomahuahua no ia i ka ikaika.
30 Àní, ó ń rẹ̀ wọ́n àwọn ọ̀dọ́, wọ́n ń rẹ̀wẹ̀sì, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sì ń kọsẹ̀ wọ́n ṣubú;
E maule auanei ka poe ui, a e maloeloe hoi, E kulanalana loa no na kanaka hou:
31 ṣùgbọ́n àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé Olúwa yóò sọ agbára wọn di ọ̀tun. Wọn yóò fìyẹ́ fò lókè bí idì; wọn yóò sáré àárẹ̀ kò ní mú wọn, wọn yóò rìn òòyì kò ní kọ́ wọn.
Aka, o ka poe hilinai aku ia Iehova, e ulu hou no ko lakou ikaika; E pii eheu aku no lakou iluna, e liko me na aito; E holo no lakou, aole hoi e maloeloe, E hele mua no lakou, aole hoi e maule.

< Isaiah 40 >