< Isaiah 39 >

1 Ní àkókò náà ni Merodaki-Baladani ọmọ Baladani ọba Babeli fi ìwé àti ẹ̀bùn ránṣẹ́ sí Hesekiah, nítorí ó gbọ́ pé ó ṣàìsàn ó sì gbádùn.
Na rĩrĩ, ihinda rĩu Merodaki-Baladani mũrũ wa Baladani mũthamaki wa Babuloni nĩatũmĩire Hezekia marũa na kĩheo, tondũ nĩaiguĩte ũhoro wa ndwari yake na kũhona gwake.
2 Hesekiah gba àwọn ikọ̀ yìí tayọ̀tayọ̀, ó sì fi àwọn nǹkan tí ó wà nínú yàrá ìkẹ́rù sí mọ́ hàn wọ́n—fàdákà, wúrà, ohun olóòórùn dídùn, òróró dídára, gbogbo nǹkan ogun rẹ̀ àti ohun gbogbo tí ó wà nínú ìṣúra rẹ̀ kò sí ohunkóhun tí ó wà nínú ààfin rẹ̀ tàbí ní ìjọba rẹ̀ tí Hesekiah kò fihàn wọ́n.
Hezekia akĩamũkĩra andũ arĩa maatũmĩtwo na gĩkeno, na akĩmoonia indo ciothe iria aigĩte makũmbĩ make; akĩmoonia betha, na thahabu na mahuti marĩa manungi wega na maguta marĩa mega mũno, na indo ciake ciothe cia mbaara na indo ciothe iria ciarĩ igĩĩna-inĩ ciake. Gũtirĩ kĩndũ o na kĩmwe thĩinĩ wa nyũmba ya ũthamaki kana kĩarĩ ũthamaki-inĩ wake wothe Hezekia ataamoonirie.
3 Lẹ́yìn náà wòlíì Isaiah lọ sí ọ̀dọ̀ Hesekiah ọba ó sì béèrè pé, “Kí ni àwọn ènìyàn wọ̀nyí wí, níbo ni wọ́n sì ti wá?” “Láti ilẹ̀ jíjìnnà,” ni èsì Hesekiah. “Wọ́n wá sọ́dọ̀ mi láti Babeli.”
Hĩndĩ ĩyo mũnabii Isaia agĩthiĩ kũrĩ Mũthamaki Hezekia, akĩmũũria atĩrĩ, “Andũ acio moiga atĩa, na mekuumĩte kũ?” Nake Hezekia agĩcookia atĩrĩ, “Moimĩte bũrũri wa kũraya; megũkĩte kuuma bũrũri wa Babuloni.”
4 Wòlíì náà sì béèrè pé, “Kí ni wọ́n rí nínú ààfin rẹ?” Hesekiah si dáhùn pe, “Wọ́n rí gbogbo ohun tí ó wà nínú ààfin mi. Kò sí ohun kankan nínú ìṣúra mi tí èmi kò fihàn wọ́n.”
Nake mũnabii akĩũria atĩrĩ, “Nĩ kĩĩ moonire nyũmba-inĩ yaku ya ũthamaki.” Nake Hezekia agĩcookia atĩrĩ, “Moonire indo ciothe cia nyũmba yakwa ya ũthamaki. Gũtirĩ kĩndũ o na kĩmwe kĩrĩ igĩĩna-inĩ ciakwa itanamoonia.”
5 Lẹ́yìn náà ni Isaiah sọ fún Hesekiah pé, “Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
Nake Isaia akĩĩra Hezekia atĩrĩ, “Ta igua kiugo kĩa Jehova Mwene-Hinya-Wothe:
6 Àsìkò ń bọ̀ nítòótọ́ nígbà tí gbogbo ohun tí ó wà nínú ààfin rẹ, àti ohun gbogbo tí àwọn baba rẹ ti kójọ títí di ọjọ́ òní yóò di kíkó lọ sí Babeli. Ohun kankan kò ní ṣẹ́kù ni Olúwa wí.
Ti-itherũ ihinda nĩrĩgakinya, rĩrĩa indo ciothe iria irĩ thĩinĩ wa nyũmba yaku ya ũthamaki, na iria ciothe maithe maku matũire maigĩte nginya ũmũthĩ, igaakuuo itwarwo Babuloni. Gũtirĩ o na kĩmwe gĩgaatigara. Ũguo nĩguo Jehova ekuuga.
7 Àti díẹ̀ nínú àwọn àrọ́mọdọ́mọ rẹ, àwọn ẹ̀jẹ̀ àti ẹran-ara rẹ tí a ó bí fún ọ ni a ó kó lọ, wọn yóò sì di ìwẹ̀fà nínú ààfin ọba Babeli.”
Na andũ amwe a rũciaro rwaku, o arĩa moimĩte mũthiimo waku, o arĩa wee ũgaaciara, nĩmagathaamio, na nĩmakaahakũrwo nĩguo matungatage nyũmba-inĩ ya mũthamaki wa Babuloni.”
8 Hesekiah wí fún Isaiah pé, “Rere ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ìwọ sọ.” Nítorí ó rò nínú ara rẹ̀ pé, “Àlàáfíà àti ààbò yóò wà ní ìgbà ayé tèmi.”
Nake Hezekia agĩcookia atĩrĩ, “Kiugo kĩa Jehova kĩrĩa waria nĩ kĩega,” tondũ eeciiririe atĩrĩ, “Hĩndĩ ĩrĩa ngũtũũra muoyo nĩgũgũkorwo kũrĩ na thayũ na ũgitĩri.”

< Isaiah 39 >