< Isaiah 39 >
1 Ní àkókò náà ni Merodaki-Baladani ọmọ Baladani ọba Babeli fi ìwé àti ẹ̀bùn ránṣẹ́ sí Hesekiah, nítorí ó gbọ́ pé ó ṣàìsàn ó sì gbádùn.
En ce temps-là, Marodach Baladan, fils de Baladan, roi de Babylone, envoya à Ézéchias des lettres, des messagers et des présents, parce qu'il avait appris sa maladie mortelle et sa guérison.
2 Hesekiah gba àwọn ikọ̀ yìí tayọ̀tayọ̀, ó sì fi àwọn nǹkan tí ó wà nínú yàrá ìkẹ́rù sí mọ́ hàn wọ́n—fàdákà, wúrà, ohun olóòórùn dídùn, òróró dídára, gbogbo nǹkan ogun rẹ̀ àti ohun gbogbo tí ó wà nínú ìṣúra rẹ̀ kò sí ohunkóhun tí ó wà nínú ààfin rẹ̀ tàbí ní ìjọba rẹ̀ tí Hesekiah kò fihàn wọ́n.
Et à cause d'eux Ézéchias fut réjoui, et il leur montra la maison de Nechotha, et l'or, et l'argent, les parfums, les aromates et la myrrhe, puis l'arsenal et ses magasins, enfin tout ce qui se trouvait dans ses trésors. Et il n'y eut rien qu'Ézéchias ne fit voir dans son palais et dans ses domaines.
3 Lẹ́yìn náà wòlíì Isaiah lọ sí ọ̀dọ̀ Hesekiah ọba ó sì béèrè pé, “Kí ni àwọn ènìyàn wọ̀nyí wí, níbo ni wọ́n sì ti wá?” “Láti ilẹ̀ jíjìnnà,” ni èsì Hesekiah. “Wọ́n wá sọ́dọ̀ mi láti Babeli.”
Mais le prophète Isaïe alla trouver le roi Ézéchias, et il lui dit: Que vous ont dit ces hommes, et d'où sont-ils venus? Ézéchias répondit: Ils sont venus vers moi d'une contrée lointaine, de Babylone.
4 Wòlíì náà sì béèrè pé, “Kí ni wọ́n rí nínú ààfin rẹ?” Hesekiah si dáhùn pe, “Wọ́n rí gbogbo ohun tí ó wà nínú ààfin mi. Kò sí ohun kankan nínú ìṣúra mi tí èmi kò fihàn wọ́n.”
Et le prophète reprit: Qu'ont-ils vu dans ton palais? Et le roi répondit: Ils ont vu tout ce que mon palais renferme; il n'y a rien que je ne leur aie montré, soit dans mon palais, soit dans mes trésors.
5 Lẹ́yìn náà ni Isaiah sọ fún Hesekiah pé, “Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
Et le prophète Isaïe dit à Ézéchias: Écoute la parole du Seigneur des armées.
6 Àsìkò ń bọ̀ nítòótọ́ nígbà tí gbogbo ohun tí ó wà nínú ààfin rẹ, àti ohun gbogbo tí àwọn baba rẹ ti kójọ títí di ọjọ́ òní yóò di kíkó lọ sí Babeli. Ohun kankan kò ní ṣẹ́kù ni Olúwa wí.
Voilà que les jours approchent où tout ce que renferme ton palais, tous les trésors que tes pères ont amassés jusqu'à ce moment, seront pris et iront à Babylone, et ils n'en laisseront rien; ainsi l'a dit Dieu.
7 Àti díẹ̀ nínú àwọn àrọ́mọdọ́mọ rẹ, àwọn ẹ̀jẹ̀ àti ẹran-ara rẹ tí a ó bí fún ọ ni a ó kó lọ, wọn yóò sì di ìwẹ̀fà nínú ààfin ọba Babeli.”
Quant à tes fils que tu as engendrés, ils les prendront, ils les feront eunuques dans le palais du roi de Babylone.
8 Hesekiah wí fún Isaiah pé, “Rere ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ìwọ sọ.” Nítorí ó rò nínú ara rẹ̀ pé, “Àlàáfíà àti ààbò yóò wà ní ìgbà ayé tèmi.”
Et Ézéchias dit à Isaïe: Juste est la parole que le Seigneur a prononcée; mais que la paix et la justice se maintiennent tous les jours de ma vie.