< Isaiah 38 >
1 Ní ọjọ́ náà ni Hesekiah ṣe àìsàn dé ojú ikú. Wòlíì Isaiah ọmọ Amosi sì lọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, ó sì wí pé, “Ohun tí Olúwa wí nìyìí: Palẹ̀ ilé è rẹ mọ́, bí ó ti yẹ nítorí pé ìwọ yóò kú; ìwọ kì yóò dìde àìsàn yìí.”
Amo esoga agoane, hina bagade Hesigaia da olole, gadenenewane bogoi. Balofede dunu Aisaia (A: imose egefe) da ema ba: la asili, ema amane sia: i, “Hina Gode da dima dia hou amola liligi hahamoma: ne sia: sa. Bai di da hame uhimu. Di bogoma: ne momagema.”
2 Hesekiah yí ojú u rẹ̀ sí ara ògiri, ó sì gba àdúrà sí Olúwa,
Hesigaia da ea odagi dobea amoga delegili, amane sia: ne gadoi,
3 “Rántí, Ìwọ Olúwa, bí mo ti rìn pẹ̀lú òtítọ́ níwájú rẹ, àti bí mo ti fi ọkàn dídúró ṣinṣin ṣe ohun tí ó dára ní ojú ù rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni Hesekiah sì sọkún kíkorò.
“Hina Gode! Dawa: ma! Na da mae fisili, Dia hawa: hamosu hamonanu. Na da Dia hanai hamoma: ne, eso huluane hawa: hamomusa: dawa: i.” Amalalu, e da se nabawane ha: giwane dinanu.
4 Lẹ́yìn náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Isaiah wá pé,
Amalalu, Hina Gode da Aisaia amoma,
5 “Lọ kí o sì sọ fún Hesekiah pé, ‘Ohun tí Olúwa wí nìyìí, Ọlọ́run Dafidi baba rẹ sọ pé, Èmi ti gbọ́ àdúrà rẹ mo sì ti rí omijé rẹ, Èmi yóò fi ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dógún kún ọjọ́ ayé rẹ.
e da Hesigaia amoma bu masa: ne, amola ema agoane sia: ma: ne sia: i, “Na, Hina Godedafa, dia musa: ada Da: ibidi ea Gode, Na da dia sia: ne gadosu nabi, amola dia disu si hano ba: i dagoi. Di da ode eno 15 agoane bu esaloma: ne, Na da logo doasimu.
6 Èmi yóò sì gba ìwọ àti ìlú yìí sílẹ̀ kúrò lọ́wọ́ ọba Asiria. Èmi yóò sì dáàbò bo ìlú yìí.
Asilia hina bagade da di amola Yelusalemega mae hasanasima: ne, Na da gaga: mu, amola gaga: lalumu.”
7 “‘Èyí yìí ni àmì tí Olúwa fún ọ láti fihàn wí pé Olúwa yóò mú ìpinnu rẹ̀ ṣẹ.
Aisaia da Hesigaiama bu adole i, (Hesigaia da Aisaia 38:22 amo ganodini adole ba: i) “Hina Gode da Ea sia: i da dafawaneyale olelema: ne, dima dawa: digisu hahamomu, agoane,
8 Èmi yóò mú òjìji oòrùn kí ó padà sẹ́yìn ní ìṣísẹ̀ mẹ́wàá nínú èyí tí ó fi sọ̀kalẹ̀ ní ibi àtẹ̀gùn ti Ahasi.’” Bẹ́ẹ̀ ni oòrùn padà sẹ́yìn ní ìṣísẹ̀ mẹ́wàá sí ibi tí ó ti dé tẹ́lẹ̀.
hina bagade A: iha: se ea fa: gu gagui, amoga eso baba ea ba: su da delegili, fa: gu bubulufai nabuane amoga buhagimu.” Amola eso ea baba da bu delegili, fa: gu bubulufai nabuane bu sinidigi.
9 Ìwé tí Hesekiah ọba Juda kọ lẹ́yìn àìsàn rẹ̀ nígbà tí ó ti gbádùn tán.
Hesigaia ea oloi da uhini, amo nodosu gesami hea: su dedei,
10 Èmi wí pé, “Ní àárín gbùngbùn ọjọ́ ayé mi èmi ó ha kọjá lọ ní ibodè ikú kí a sì dùn mí ní àwọn ọdún mi tí ó ṣẹ́kù?” (Sheol )
“Na da na esalebe eso amoga, bogoi sogebi amoga masusa: dawa: i galu. Na da na esalebe defei, defele esalumu hame dawa: i. (Sheol )
11 Èmi wí pé, “Èmi kì yóò lè tún rí Olúwa mọ́, àní Olúwa, ní ilẹ̀ àwọn alààyè; èmi kì yóò lè síjú wo ọmọ ènìyàn mọ́, tàbí kí n wà pẹ̀lú àwọn tí ó sì ń gbe orílẹ̀ ayé báyìí.
Na da osobo bagadega (dunu esalebe ilia soge), Hina Gode amola esalebe dunu bu hame ba: musa: dawa: i galu.
12 Gẹ́gẹ́ bí àgọ́ olùṣọ́-àgùntàn, ilé mi ni a ti wó lulẹ̀ tí a sì gbà kúrò lọ́wọ́ mi. Gẹ́gẹ́ bí ahunṣọ mo ti ká ayé mi nílẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni òun sì ti ké mi kúrò lára àṣà; ọ̀sán àti òru ni ìwọ ṣe òpin mi.
Na esalusu da hedofai dagoi ba: i. Abula diasu mugului amola abula amo da amunisu amoga hedofai, na esalusu da amo defele hedofai dagoi ba: i. Gode da na esalusu dagomusa: , na da dawa: i dagoi.
13 Èmi fi sùúrù dúró títí di àfẹ̀mọ́júmọ́, ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí kìnnìún ó ti fọ́ gbogbo egungun mi; ọ̀sán àti òru ni ìwọ fi ṣe òpin mi.
Na da se bagade, laione wa: me da na gasa huluane filalu defele, amo nababeba: le, gasia dinanu. Gode da na esalusu dagolesima: bela: le, na da dawa: i dagoi.
14 Èmi dún gẹ́gẹ́ bí àkọ̀ tàbí alápáǹdẹ̀dẹ̀, èmi káàánú gẹ́gẹ́ bí aṣọ̀fọ̀ àdàbà. Ojú mi rẹ̀wẹ̀sì gẹ́gẹ́ bí mo ti ń wo àwọn ọ̀run. Ìdààmú bá mi, Ìwọ Olúwa, wá fún ìrànlọ́wọ́ mi!”
Na sia: da gasa hame agoai nabi. Na da “dafe” sio defele gogonomasu. Na da Hebene amoga ba: le gadolalebeba: le, na si da helei bagade nabi. Hina Gode! Amo bidi hamosu amoga na gaga: ma!
15 Ṣùgbọ́n kí ni èmi lè sọ? Òun ti bá mi sọ̀rọ̀ àti pé òun tìkára rẹ̀ ló ti ṣe èyí. Èmi yóò máa rìn ní ìrẹ̀lẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ mi nítorí ìpọ́njú ẹ̀mí mi yìí.
Na da adi sia: ma: bela: ? Hina Gode da amo hou hamoi. Na dogo ganodini se naba. Na da golamu hamedei agoane ba: su.
16 Olúwa, nípa nǹkan báwọ̀nyí ni àwọn ènìyàn ń gbé; àti pé ẹ̀mí mi rí iyè nínú wọn pẹ̀lú. Ìwọ dá ìlera mi padà kí o sì jẹ́ kí n wà láààyè.
Hina Gode! Na da Dima hawa: hamoma: ne fawane esalumu. Na oloi uhinisima! Na esaloma: ne, Dia logo fodoma! Uhinisima!
17 Nítòótọ́ fún àlàáfíà ara mi ni, ní ti pé mo ní ìkorò ńlá. Nínú ìfẹ́ rẹ ìwọ pa mí mọ́, kúrò nínú ọ̀gbun ìparun; ìwọ sì ti fi gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi sí ẹ̀yìn rẹ.
Na da: i diosu da sinidigili, olofosu ba: mu. Di da na bidi hamosu huluane mae ba: ma: ne, gaga: sa. Di da na wadela: i hou huluane gogolema: ne olofosa.
18 Nítorí pé isà òkú kò le è yìn ọ́, ipò òkú kò le è kọ orin ìyìn rẹ; àwọn tí ó sọ̀kalẹ̀ sínú ọ̀gbun kò lè ní ìrètí fún òtítọ́ rẹ. (Sheol )
Dunu ilia da bogoi sogebi amoga Dima nodomusa: hame dawa: Bogoi dunu da Dia mae fisili moloidafa hou amo dafawaneyale dawa: ma: ne hame dawa: (Sheol )
19 Alààyè, àwọn alààyè wọ́n ń yìn ọ́, gẹ́gẹ́ bí èmi ti ń ṣe lónìí; àwọn baba sọ fún àwọn ọmọ wọn nípa òtítọ́ rẹ.
Esalebe dunu, ilia fawane da na waha Dima nodosu defele, Dima nodone sia: ne gadosu dawa: Osobo bagade eda ilia da ilia mano ilima Dia mae fisili fidisu hou olelesa.
20 Olúwa yóò gbà mí là bẹ́ẹ̀ ni àwa yóò sì kọrin pẹ̀lú ohun èlò olókùn ní gbogbo ọjọ́ ayé wa nínú tẹmpili ti Olúwa.
Hina Gode! Di da na uhinisi dagoi. Ninia da sani baidama dumu amola Dima nodoma: ne gesami hea: mu. Ninia da Dia Debolo Diasu ganodini, eso huluane ninia esalea, Dima nodone gesami hea: mu.”
21 Isaiah ti sọ pé, “Pèsè ìṣù ọ̀pọ̀tọ́ (ohun gbígbóná tí a dì mọ́ ojú egbò) kí o sì fi sí ojú oówo náà, òun yóò sì gbádùn.”
Aisaia da hina bagade Hesigaiama e da figi goudane, manoma hamoi amo ea dului amoga legelalu, e da uhini dagoi ba: ma: ne sia: i.
22 Hesekiah sì béèrè pé, “Kí ni yóò jẹ́ àmì pé èmi yóò gòkè lọ sí tẹmpili Olúwa?”
Amola hina bagade da musa: ema amane adole ba: i, “Na da Debolo Diasuga heda: mu defele ba: musa: , Hina Gode da adi dawa: digisu hahamosu olelema: bela: ?” (Aisaia 38:7 ba: ma)