< Isaiah 37 >

1 Nígbà tí ọba Hesekiah gbọ́ èyí, ó fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì fi aṣọ ọ̀fọ̀ bo ara rẹ̀, ó sì wọ inú tẹmpili Olúwa lọ.
Då nu Konung Hiskia detta hörde, ref han sin kläder sönder, och svepte en säck omkring sig, och gick in uti Herrans hus;
2 Òun sì rán Eliakimu alákòóso ààfin, Ṣebna akọ̀wé, àti aṣíwájú àwọn àlùfáà, gbogbo wọn nínú aṣọ ọ̀fọ̀ lọ sí ọ̀dọ̀ wòlíì Isaiah ọmọ Amosi.
Och sände Eliakim, hofmästaren, och Sebna skrifvaren, med de äldsta Presterna, omsvepta med säcker, till Propheten Esaia, Amos son;
3 Wọ́n sọ fún un pé, “Báyìí ni Hesekiah wí, ọjọ́ òní jẹ́ ọjọ́ ìbànújẹ́, ìbáwí àti ẹ̀gàn gẹ́gẹ́ bí ìgbà ìbí àwọn ọmọdé tí kò sì ṣí agbára láti bí wọn.
Att de skulle säga till honom: Så säger Hiskia: Detta är en bedröfvelses, straffs och försmädelses dag, och går såsom när barnen äro komne till födelsen, och ingen magt är till att föda.
4 Ó lè jẹ́ pé Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò gbọ́ ọ̀rọ̀ ọ̀gágun ẹni tí ọ̀gá rẹ̀ ọba Asiria ti rán láti fi Ọlọ́run alààyè ṣe ẹlẹ́yà, àti pé òun ni yóò bá a wí nítorí àwọn ọ̀rọ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti gbọ́. Nítorí náà gbàdúrà fún àwọn tí ó ṣẹ́kù tí wọ́n sì wà láààyè.”
O! att dock Herren din Gud ville höra RabSake ord, hvilken hans herre, Konungen i Assyrien, utsände till att försmäda lefvandes Gud, och till att förlasta med sådana ordom, som Herren din Gud hört hafver; och att du ville upphäfva ena bön för de igenlefda, som ännu för handene äro.
5 Nígbà tí àwọn ìjòyè ọba Hesekiah dé ọ̀dọ̀ Isaiah,
Och Konungens Hiskia tjenare kommo till Esaia.
6 Isaiah sọ fún wọn pé, “Ẹ sọ fún ọ̀gá yín pé, ‘Ohun tí Olúwa sọ nìyìí. Má ṣe bẹ̀rù ohun tí ẹ ti gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ tí ọba Asiria tí ó wà nínú ìdè ti fi sọ̀rọ̀-òdì sí mi.
Men Esaia sade till dem: Så säger edrom herra: Herren säger alltså: Frukta dig intet för de ord, som du hört hafver, med hvilkom Konungens tjenare af Assyrien mig försmädat hafva.
7 Tẹ́tí sílẹ̀! Èmi yóò fi ẹ̀mí kan sínú rẹ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí ó fi jẹ́ pé bí o bá ti gbọ́ ìròyìn kan, òun yóò padà sí orílẹ̀-èdè rẹ̀, níbẹ̀ ni n ó sì ti jẹ́ kí wọn ké e lulẹ̀ pẹ̀lú idà.’”
Si, jag skall göra honom ett annat mod, och han skall något få höra, deraf han skall igen hemfara i sitt land, och jag skall falla honom med svärd uti hans land.
8 Nígbà tí ọ̀gágun gbọ́ pé ọba Asiria ti fi Lakiṣi sílẹ̀, ó padà sẹ́yìn, ó sì bá ọba tí ń bá Libina jà.
Men då RabSake igenkom, fann han Konungen af Assyrien stridandes emot Libna; ty han hade hört, att han var ifrå Lachis dragen.
9 Ní àkókò yìí Sennakeribu gbọ́ ìròyìn kan pé Tirakah ará Kuṣi ọba Ejibiti ń jáde bọ̀ wá bá òun jà. Nígbà tí ó gbọ́ èyí, ó rán oníṣẹ́ sí Hesekiah pẹ̀lú ọ̀rọ̀ wọ̀nyí,
Förty ett rykte kom ifrå Thirhaka, de Ethiopers Konung, sägandes: Han är utdragen emot dig till att strida. Då han nu detta hörde, sände han båd till Hiskia, och lät säga honom:
10 “Ẹ sọ fún Hesekiah ọba Juda pé: Má ṣe jẹ́ kí òrìṣà tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé tàn ọ́ jẹ nígbà tí ó sọ pé, ‘A kì yóò jọ̀wọ́ Jerusalẹmu fún ọba Asiria.’
Säger Hiskia, Juda Konunge, alltså: Låt icke din Gud bedraga dig, den du förlåter dig uppå, och säger: Jerusalem skall icke gifvit varda uti Konungens hand af Assyrien.
11 Dájúdájú, ìwọ ti gbọ́ ohun tí ọba Asiria ti ṣe sí àwọn orílẹ̀-èdè, tí ó pa wọ́n run pátápátá. Ǹjẹ́ a ó ha dá ọ nídè bí?
Si, du hafver hört, hvad de Konungar af Assyrien allom landom gjort hafva, och förderfvat dem; och du skulle friad varda?
12 Ǹjẹ́ àwọn òrìṣà àwọn orílẹ̀-èdè tí àwọn baba ńlá mi parun ha gbà wọ́n sílẹ̀ bí àwọn òrìṣà Gosani, Harani, Reṣefu àti àwọn ènìyàn Edeni tí wọ́n wà ní Teli-Assari?
Hafva ock Hedningarnas gudar undsatt de land, som mine fäder förderfvat hafva; såsom är Gosan, Haran, Rezeph, och Edens barn i Thelassar?
13 Níbo ni ọba Hamati wà, ọba Arpadi, ọba ìlú Sefarfaimi tàbí Hena tàbí Iffa?”
Hvar är Konungen i Hamath, och Konungen i Arphad, och Konungen i den stadenom Sepharvaim, Heva och Iva?
14 Hesekiah gba ìwé náà lọ́wọ́ àwọn oníṣẹ́ ó sì kà á. Lẹ́yìn náà ni ó gòkè lọ sí tẹmpili Olúwa ó sì tẹ́ ìwé náà sílẹ̀ níwájú Olúwa.
Och då Hiskia hade undfått brefvet af båden, och läsit det, gick han upp till Herrans hus, och höll det ut för Herranom.
15 Hesekiah sì gbàdúrà sí Olúwa:
Och Hiskia bad till Herran, och sade:
16 Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli, tí ó gúnwà láàrín àwọn kérúbù, ìwọ nìkan ni Ọlọ́run lórí i gbogbo ìjọba orílẹ̀ ayé. Ìwọ ti dá ọ̀run àti ayé.
Herre Zebaoth, du Israels Gud, som öfver Cherubim sitter, du äst allena Gud öfver all Konungarike på jordene; du hafver gjort himmel och jord.
17 Tẹ́tí sílẹ̀, ìwọ Olúwa, kí o gbọ́, ya ojú rẹ, Ìwọ Olúwa, kí o rí i; tẹ́tí sí gbogbo ọ̀rọ̀ tí Sennakeribu rán láti fi àbùkù kan Ọlọ́run alààyè.
Herre, nederböj din öron, och hör; Herre, låt upp din ögon, och se; hör dock all Sanheribs ord, som han utsändt hafver, till att försmäda lefvandes Gud.
18 “Òtítọ́ ni Olúwa pé àwọn ọba Asiria ti sọ àwọn ènìyàn àti ilẹ̀ wọn di asán.
Sant är det, Herre, Konungarna i Assyrien hafva öde gjort all Konungarike med deras land;
19 Wọ́n ti da àwọn òrìṣà wọn sínú iná wọ́n sì ti pa wọ́n run, nítorí àwọn wọ̀nyí kì í ṣe ọlọ́run bí kò ṣe igi àti òkúta lásán, tí a ti ọwọ́ ènìyàn ṣe.
Och hafva kastat deras gudar uti eld; ty de voro icke gudar, utan menniskohänders verk, trä och sten; de äro förgjorde.
20 Nísinsin yìí, ìwọ Olúwa, Ọlọ́run wa, gbà wá lọ́wọ́ rẹ̀, tí ó fi jẹ́ pé gbogbo ìjọba ilẹ̀ ayé yóò fi mọ̀ pé Ìwọ, Ìwọ nìkan, Olúwa ni Ọlọ́run.”
Men nu, Herre, vår Gud, hjelp oss ifrå hans hand, på det att all Konungarike på jordene måga förnimma, att du äst Herre allena.
21 Lẹ́yìn náà Isaiah ọmọ Amosi rán iṣẹ́ kan sí Hesekiah: “Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli sọ pé, nítorí pé ìwọ ti gbàdúrà sí mi nípa Sennakeribu ọba Asiria,
Då sände Esaia, Amos son, till Hiskia, och lät säga honom: Så säger Herren Israels Gud, om det du mig bedit hafver om Konung Sanherib af Assyrien;
22 èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ nípa rẹ̀: “Wúńdíá ọmọbìnrin Sioni ti kẹ́gàn rẹ, ó sì ti fi ọ ṣe ẹlẹ́yà. Ọmọbìnrin Jerusalẹmu ti mi orí rẹ̀ bí ó ti ń sálọ.
Så är detta det Herren om honom säger: Jungfrun, dottren Zion, föraktar dig, och bespottar dig, och dottren Jerusalem rister hufvudet efter dig.
23 Ta ni ìwọ ti bú tí ìwọ sì ti sọ̀rọ̀-òdì sí? Sí ta ní ìwọ ti gbé ohùn rẹ sókè tí o sì gbé ojú rẹ sókè ní ìgbéraga? Sí Ẹni Mímọ́ Israẹli!
Hvem hafver du förhädt och försmädt? Öfver hvem hafver du upphäfvit röstena? Och du hafver upphäfvit din ögon emot den Heliga i Israel.
24 Nípa àwọn ìránṣẹ́ rẹ, ìwọ ti sọ̀rọ̀ búburú sí Olúwa. Tì wọ sì wí pé, ‘Pẹ̀lú ọ̀pọ̀ kẹ̀kẹ́ mi ni èmi sì fi dé orí àwọn òkè ńlá, sí ibi gíga jùlọ Lebanoni. Èmi a sì ké igi kedari gíga rẹ̀ lulẹ̀, àti ààyò igi firi rẹ̀. Èmi ti dé ibi rẹ̀ tí ó ga jùlọ, igbó rẹ̀ tí ó dára jùlọ.
Genom dina tjenare hafver du försmädat Herran, och säger: Genom mina många vagnar är jag uppdragen uppå bergshöjderna vid Libanons sido, och hafver afhuggit hans höga cedreträ, med de utkorade furoträ, och är kommen öfver höjdena, intill ändan på denna skogen på landena.
25 Èmi ti gbẹ́ kànga ní ilẹ̀ àjèjì mo sì mu omi ní ibẹ̀, pẹ̀lú àtẹ́lẹsẹ̀ mi Èmi ti gbẹ́ gbogbo omi àwọn odò Ejibiti.’
Jag hafver grafvit och druckit vattnet, och mitt fotbjelle hafver uttorkat all förvarad vatten.
26 “Ṣé o kò tí ì gbọ́? Tipẹ́tipẹ́ ni mo ti fìdí rẹ̀ mulẹ̀. Láti ìgbà pípẹ́ ni mo ti ṣètò rẹ̀; ní àkókò yìí ni mo mú wá sí ìmúṣẹ, pé o ti sọ àwọn ìlú olódi di àkójọpọ̀ àwọn òkúta.
Men hafver du icke hört, att jag i förtiden alltså gjort, och af ålder så handlat hafver, och gör desslikes så ännu, att fasto städer förstöras uti stenhopar;
27 Àwọn ènìyàn, tí agbára ti wọ̀ lẹ́wù, ni wọ́n banújẹ́ tí a sì dójútì. Wọ́n dàbí ohun ọ̀gbìn nínú pápá, gẹ́gẹ́ bí ọ̀jẹ̀lẹ̀ èhíhù tuntun, gẹ́gẹ́ bí i koríko tí ó ń hù lórí òrùlé, tí ó jóná kí ó tó dàgbàsókè.
Och deras inbyggare försvagade och förtviflade varda, och på skam komma, och varda till gräs på markene, och till grön ört, såsom hö på taken, hvilket borttorkas, förr än det moget varder?
28 “Ṣùgbọ́n mo mọ ibi tí o wà àti ìgbà tí o wá tí o sì lọ àti bí inú rẹ ṣe ru sí mi.
Men jag känner dina boning väl, ditt uttåg och intåg, och ditt rasande emot mig.
29 Nítorí pé inú rẹ ru sí mi àti nítorí pé orí kunkun rẹ ti dé etí ìgbọ́ mi, Èmi yóò fi ìwọ̀ mi sí ọ ní imú, àti ìjẹ mi sí ọ lẹ́nu, èmi yóò sì jẹ́ kí o padà láti ọ̀nà tí o gbà wá.
Efter du nu rasar emot mig, och ditt högmod är kommet upp för min öron, skall jag sätta dig en ring i dina näso, och ett bett i din mun, och skall föra dig den vägen hem igen, den du kommen äst.
30 “Èyí ni yóò ṣe àmì fún ọ, ìwọ Hesekiah: “Ní ọdún yìí, ìwọ yóò jẹ ohun tí ó hù fúnra rẹ̀, àti ní ọdún kejì ohun tí ó jáde láti ara rẹ. Ṣùgbọ́n ní ọdún kẹta, ẹ gbìn kí ẹ sì kórè, ẹ gbin ọgbà àjàrà kí ẹ sì jẹ èso wọn.
Och detta skall vara dig för ett tecken: Ät i detta året hvad förtrampadt är; uti de andra årena hvad sjelft växer; uti tredje årena sår och uppskärer, planterer vingårdar, och äter deras frukt.
31 Lẹ́ẹ̀kan sí i, àṣẹ́kù láti ilé Juda yóò ta gbòǹgbò nísàlẹ̀ yóò sì ṣo èso lókè.
Ty de frälste af Juda hus, och de öfverblefne, skola åter rota sig nedantill, och ofvantill bära frukt.
32 Nítorí láti Jerusalẹmu ni àwọn àṣẹ́kù yóò ti wá, àti láti òkè Sioni ni ikọ̀ àwọn tí ó sálà. Ìtara Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni yóò mú èyí ṣẹ.
Ty utaf Jerusalem skola ännu utgå de som qvarblefne äro, och de frälste utaf Zions berg. Detta skall Herrans Zebaoths nitälskan göra.
33 “Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa wí nípa ọba Asiria, “Òun kì yóò wọ ìlú yìí wá tàbí ta ẹyọ ọfà kan níhìn-ín Òun kì yóò wá síwájú rẹ pẹ̀lú asà tàbí kí ó kó dágunró sílẹ̀ fún un.
Derföre säger Herren om Konungen af Assyrien alltså: Hall skall icke komma in uti denna staden, och skall ej heller skjuta der en pil in, och icke en sköld komma der före, och skall han ingen skans göra deromkring;
34 Nípa ọ̀nà tí ó gbà wá náà ni yóò padà lọ; òun kì yóò wọ inú ìlú yìí,” ni Olúwa wí.
Utan skall vända den vägen om igen, som han kommen är, så att han uti denna staden intet kommer, säger Herren.
35 “Èmi yóò dáàbò bo ìlú yìí èmi ó sì gbà á là, nítorí mi àti nítorí Dafidi ìránṣẹ́ mi!”
Ty jag vill beskydda denna staden, så att jag skall uthjelpa honom för mina skull, och för min tjenares Davids skull.
36 Lẹ́yìn náà ni angẹli Olúwa jáde lọ ó sì pa ọ̀kẹ́ mẹ́sàn-án ó lé ẹgbẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ènìyàn ní i ibùdó àwọn Asiria. Nígbà tí àwọn ènìyàn yìí jí ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì gbogbo wọn ti dòkú!
Då for ut en Herrans Ängel, och slog uti det Assyriska lägret hundrade fem och åttatio tusend män; och då de om morgonen bittida uppstodo, si, då låg der allt fullt med döda kroppar.
37 Nítorí náà Sennakeribu ọba Asiria fọ́ bùdó ó sì pẹsẹ̀dà. Òun sì padà sí Ninefe, ó sì dúró síbẹ̀.
Och Konungen af Assyrien, Sanherib, bröt upp, drog sina färde, och vände om hem igen, och blef i Nineve.
38 Ní ọjọ́ kan, bí ó ti ń jọ́sìn nínú tẹmpili Nisroki òrìṣà rẹ̀, àwọn ọmọ rẹ̀ Adrameleki àti Ṣareseri gé e lulẹ̀ pẹ̀lú idà, wọ́n sì sálọ sí ilẹ̀ Ararati. Bẹ́ẹ̀ ni Esarhadoni ọmọ rẹ̀ sì gba ipò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
Och det begaf sig, att då han tillbad uti sins guds Nisrochs huse, slogo honom hans söner Adrammelech och SarEzer med svärd, och flydde in uti det landet Ararat; och hans son EsarHaddon vardt Konung i hans stad.

< Isaiah 37 >