< Isaiah 37 >
1 Nígbà tí ọba Hesekiah gbọ́ èyí, ó fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì fi aṣọ ọ̀fọ̀ bo ara rẹ̀, ó sì wọ inú tẹmpili Olúwa lọ.
Кынд а аузит ымпэратул Езекия кувинтеле ачестя, шь-а сфышият хайнеле, с-а акоперит ку ун сак ши с-а дус ын Каса Домнулуй.
2 Òun sì rán Eliakimu alákòóso ààfin, Ṣebna akọ̀wé, àti aṣíwájú àwọn àlùfáà, gbogbo wọn nínú aṣọ ọ̀fọ̀ lọ sí ọ̀dọ̀ wòlíì Isaiah ọmọ Amosi.
А тримис пе Елиаким, кэпетения касей ымпэратулуй, пе Шебна, логофэтул, ши пе чей май бэтрынь динтре преоць, акопериць ку сачь, ла пророкул Исая, фиул луй Амоц.
3 Wọ́n sọ fún un pé, “Báyìí ni Hesekiah wí, ọjọ́ òní jẹ́ ọjọ́ ìbànújẹ́, ìbáwí àti ẹ̀gàn gẹ́gẹ́ bí ìgbà ìbí àwọn ọmọdé tí kò sì ṣí agbára láti bí wọn.
Ши й-ау зис: „Аша ворбеште Езекия: ‘Зиуа ачаста есте о зи де неказ, де педяпсэ ши де окарэ, кэч копиий сунт апроапе сэ ясэ дин пынтечеле мамей лор, ши тотушь мамеле н-ау путере сэ наскэ.
4 Ó lè jẹ́ pé Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò gbọ́ ọ̀rọ̀ ọ̀gágun ẹni tí ọ̀gá rẹ̀ ọba Asiria ti rán láti fi Ọlọ́run alààyè ṣe ẹlẹ́yà, àti pé òun ni yóò bá a wí nítorí àwọn ọ̀rọ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti gbọ́. Nítorí náà gbàdúrà fún àwọn tí ó ṣẹ́kù tí wọ́n sì wà láààyè.”
Поате кэ Домнул Думнезеул тэу а аузит кувинтеле луй Рабшаке, пе каре л-а тримис ымпэратул Асирией, стэпынул сэу, сэ батжокоряскэ пе Думнезеул чел виу ши поате кэ Домнул Думнезеул тэу ыл ва педепси пентру кувинтеле пе каре ле-а аузит. Ыналцэ дар о ругэчуне пентру рэмэшица каре а май рэмас.’”
5 Nígbà tí àwọn ìjòyè ọba Hesekiah dé ọ̀dọ̀ Isaiah,
Служиторий ымпэратулуй Езекия с-ау дус деч ла Исая.
6 Isaiah sọ fún wọn pé, “Ẹ sọ fún ọ̀gá yín pé, ‘Ohun tí Olúwa sọ nìyìí. Má ṣe bẹ̀rù ohun tí ẹ ti gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ tí ọba Asiria tí ó wà nínú ìdè ti fi sọ̀rọ̀-òdì sí mi.
Ши Исая ле-а зис: „Ятэ че вець спуне стэпынулуй востру: ‘Аша ворбеште Домнул: «Ну те ынспэймынта де кувинтеле пе каре ле-ай аузит ши прин каре М-ау батжокорит служиторий ымпэратулуй Асирией.
7 Tẹ́tí sílẹ̀! Èmi yóò fi ẹ̀mí kan sínú rẹ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí ó fi jẹ́ pé bí o bá ti gbọ́ ìròyìn kan, òun yóò padà sí orílẹ̀-èdè rẹ̀, níbẹ̀ ni n ó sì ti jẹ́ kí wọn ké e lulẹ̀ pẹ̀lú idà.’”
Кэч вой пуне ын ел ун дух де аша фел ынкыт, ла о весте пе каре о ва прими, се ва ынтоарче ын цара луй ши-л вой фаче сэ кадэ учис де сабие ын цара луй.»’”
8 Nígbà tí ọ̀gágun gbọ́ pé ọba Asiria ti fi Lakiṣi sílẹ̀, ó padà sẹ́yìn, ó sì bá ọba tí ń bá Libina jà.
Рабшаке, ла ынтоарчере, а гэсит пе ымпэратул Асирией луптынд ымпотрива Либней, кэч афласе де плекаря луй дин Лакис.
9 Ní àkókò yìí Sennakeribu gbọ́ ìròyìn kan pé Tirakah ará Kuṣi ọba Ejibiti ń jáde bọ̀ wá bá òun jà. Nígbà tí ó gbọ́ èyí, ó rán oníṣẹ́ sí Hesekiah pẹ̀lú ọ̀rọ̀ wọ̀nyí,
Атунч ымпэратул Асирией а примит о весте деспре Тирхака, ымпэратул Етиопией, прин каре и се спуня: „Ел а порнит сэ-ць факэ рэзбой.” Кум а аузит лукрул ачеста, а тримис соль ла Езекия, зикынду-ле:
10 “Ẹ sọ fún Hesekiah ọba Juda pé: Má ṣe jẹ́ kí òrìṣà tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé tàn ọ́ jẹ nígbà tí ó sọ pé, ‘A kì yóò jọ̀wọ́ Jerusalẹmu fún ọba Asiria.’
„Аша сэ ворбиць луй Езекия, ымпэратул луй Иуда: ‘Ну те лэса амэӂит де Думнезеул тэу, ын каре те ынкрезь ши зичь: «Иерусалимул ну ва фи дат ын мыниле ымпэратулуй Асирией.»
11 Dájúdájú, ìwọ ti gbọ́ ohun tí ọba Asiria ti ṣe sí àwọn orílẹ̀-èdè, tí ó pa wọ́n run pátápátá. Ǹjẹ́ a ó ha dá ọ nídè bí?
Кэч ай аузит че ау фэкут ымпэраций Асирией тутурор цэрилор ши кум ле-ау нимичит ку десэвыршире. Ши ту сэ фий избэвит?
12 Ǹjẹ́ àwọn òrìṣà àwọn orílẹ̀-èdè tí àwọn baba ńlá mi parun ha gbà wọ́n sílẹ̀ bí àwọn òrìṣà Gosani, Harani, Reṣefu àti àwọn ènìyàn Edeni tí wọ́n wà ní Teli-Assari?
Оаре думнезеий нямурилор пе каре ле-ау нимичит пэринций мей ле-ау избэвит ей, ши ануме: Гозанул, Харанул, Рецефул ши фиий луй Еден, каре сунт ла Теласар?
13 Níbo ni ọba Hamati wà, ọba Arpadi, ọba ìlú Sefarfaimi tàbí Hena tàbí Iffa?”
Унде есте ымпэратул Хаматулуй, ымпэратул Арпадулуй ши ымпэратул четэцилор Сефарваим, Хена ши Ива?’”
14 Hesekiah gba ìwé náà lọ́wọ́ àwọn oníṣẹ́ ó sì kà á. Lẹ́yìn náà ni ó gòkè lọ sí tẹmpili Olúwa ó sì tẹ́ ìwé náà sílẹ̀ níwájú Olúwa.
Езекия а луат скрисоаря дин мына солилор ши а читит-о. Апой с-а суит ла Каса Домнулуй, а ынтинс-о ынаинтя Домнулуй
15 Hesekiah sì gbàdúrà sí Olúwa:
ши Й-а фэкут урмэтоаря ругэчуне:
16 Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli, tí ó gúnwà láàrín àwọn kérúbù, ìwọ nìkan ni Ọlọ́run lórí i gbogbo ìjọba orílẹ̀ ayé. Ìwọ ti dá ọ̀run àti ayé.
„Доамне ал оштирилор, Думнезеул луй Исраел, каре шезь пе херувимь! Ту ешть сингурул Думнезеу ал тутурор ымпэрэциилор пэмынтулуй! Ту ай фэкут черуриле ши пэмынтул!
17 Tẹ́tí sílẹ̀, ìwọ Olúwa, kí o gbọ́, ya ojú rẹ, Ìwọ Olúwa, kí o rí i; tẹ́tí sí gbogbo ọ̀rọ̀ tí Sennakeribu rán láti fi àbùkù kan Ọlọ́run alààyè.
Доамне, плякэ-Ць урекя ши аскултэ! Доамне, дескиде-Ць окий ши привеште! Аузь тоате кувинтеле пе каре ле-а тримис Санхериб, ка сэ батжокоряскэ пе Думнезеул чел виу!
18 “Òtítọ́ ni Olúwa pé àwọn ọba Asiria ti sọ àwọn ènìyàn àti ilẹ̀ wọn di asán.
Есте адевэрат, Доамне, кэ ымпэраций Асирией ау пустиит тоате нямуриле ши цэриле лор
19 Wọ́n ti da àwọn òrìṣà wọn sínú iná wọ́n sì ti pa wọ́n run, nítorí àwọn wọ̀nyí kì í ṣe ọlọ́run bí kò ṣe igi àti òkúta lásán, tí a ti ọwọ́ ènìyàn ṣe.
ши кэ ау арункат ын фок пе думнезеий лор, дар ей ну ерау думнезей, чи ерау лукрэрь фэкуте де мыниле омулуй, де лемн ши де пятрэ. Де ачея й-ау нимичит.
20 Nísinsin yìí, ìwọ Olúwa, Ọlọ́run wa, gbà wá lọ́wọ́ rẹ̀, tí ó fi jẹ́ pé gbogbo ìjọba ilẹ̀ ayé yóò fi mọ̀ pé Ìwọ, Ìwọ nìkan, Olúwa ni Ọlọ́run.”
Акум, Доамне, Думнезеул ностру, избэвеште-не дин мына луй Санхериб, ка тоате ымпэрэцииле пэмынтулуй сэ штие кэ нумай Ту, Доамне, ешть Думнезеу!”
21 Lẹ́yìn náà Isaiah ọmọ Amosi rán iṣẹ́ kan sí Hesekiah: “Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli sọ pé, nítorí pé ìwọ ti gbàdúrà sí mi nípa Sennakeribu ọba Asiria,
Атунч Исая, фиул луй Амоц, а тримис сэ спунэ луй Езекия: „Аша ворбеште Домнул Думнезеул луй Исраел: ‘Ам аузит ругэчуня пе каре Мь-ай фэкут-о ку привире ла Санхериб, ымпэратул Асирией.’
22 èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ nípa rẹ̀: “Wúńdíá ọmọbìnrin Sioni ti kẹ́gàn rẹ, ó sì ti fi ọ ṣe ẹlẹ́yà. Ọmọbìnrin Jerusalẹmu ti mi orí rẹ̀ bí ó ti ń sálọ.
Ятэ кувынтул пе каре л-а ростит Домнул ымпотрива луй: ‘Фечоара, фийка Сионулуй, те диспрецуеште ши ышь бате жок де тине; фата Иерусалимулуй дэ дин кап дупэ тине.
23 Ta ni ìwọ ti bú tí ìwọ sì ti sọ̀rọ̀-òdì sí? Sí ta ní ìwọ ti gbé ohùn rẹ sókè tí o sì gbé ojú rẹ sókè ní ìgbéraga? Sí Ẹni Mímọ́ Israẹli!
Пе чине ай батжокорит ши ай окэрыт ту? Ымпотрива куй ць-ай ридикат гласул ши ць-ай ындрептат окий? Ымпотрива Сфынтулуй луй Исраел;
24 Nípa àwọn ìránṣẹ́ rẹ, ìwọ ti sọ̀rọ̀ búburú sí Olúwa. Tì wọ sì wí pé, ‘Pẹ̀lú ọ̀pọ̀ kẹ̀kẹ́ mi ni èmi sì fi dé orí àwọn òkè ńlá, sí ibi gíga jùlọ Lebanoni. Èmi a sì ké igi kedari gíga rẹ̀ lulẹ̀, àti ààyò igi firi rẹ̀. Èmi ti dé ibi rẹ̀ tí ó ga jùlọ, igbó rẹ̀ tí ó dára jùlọ.
прин служиторий тэй ту ай батжокорит пе Домнул ши ай зис: «Ку мулцимя карелор меле м-ам суит пе вырфул мунцилор, пе коастеле Либанулуй, ши вой тэя чедрий луй чей май ыналць, чей май фрумошь кипарошь ай луй, ши вой ажунӂе пе кулмя чя май ыналтэ, ын пэдуря луй, каре есте ка ун помет.
25 Èmi ti gbẹ́ kànga ní ilẹ̀ àjèjì mo sì mu omi ní ibẹ̀, pẹ̀lú àtẹ́lẹsẹ̀ mi Èmi ti gbẹ́ gbogbo omi àwọn odò Ejibiti.’
Ам сэпат извоаре ши ам бэут дин апеле лор, ши ку талпа пичоарелор меле вой сека тоате рыуриле Еӂиптулуй.»
26 “Ṣé o kò tí ì gbọ́? Tipẹ́tipẹ́ ni mo ti fìdí rẹ̀ mulẹ̀. Láti ìgbà pípẹ́ ni mo ti ṣètò rẹ̀; ní àkókò yìí ni mo mú wá sí ìmúṣẹ, pé o ti sọ àwọn ìlú olódi di àkójọpọ̀ àwọn òkúta.
Дар н-ай аузит кэ ам прегэтит ачесте лукрурь де демулт ши кэ ле-ам хотэрыт дин времурь стрэвекь? Акум ынсэ ам дат вое сэ се ымплиняскэ, пентру ка сэ префачь четэць тарь ын ниште мормане де дэрымэтурь.
27 Àwọn ènìyàn, tí agbára ti wọ̀ lẹ́wù, ni wọ́n banújẹ́ tí a sì dójútì. Wọ́n dàbí ohun ọ̀gbìn nínú pápá, gẹ́gẹ́ bí ọ̀jẹ̀lẹ̀ èhíhù tuntun, gẹ́gẹ́ bí i koríko tí ó ń hù lórí òrùlé, tí ó jóná kí ó tó dàgbàsókè.
Ши локуиторий лор сунт непутинчошь, ынспэймынтаць ши улуиць: сунт ка ярба де пе кымп ши вердяца фраӂедэ, ка ярба де пе акоперишурь ши ка грыул каре се усукэ ынаинте де а да ын спик.
28 “Ṣùgbọ́n mo mọ ibi tí o wà àti ìgbà tí o wá tí o sì lọ àti bí inú rẹ ṣe ru sí mi.
Дар Еу штиу кынд стай жос, кынд ешь афарэ, кынд интри ши кынд ешть мыниос ымпотрива Мя.
29 Nítorí pé inú rẹ ru sí mi àti nítorí pé orí kunkun rẹ ti dé etí ìgbọ́ mi, Èmi yóò fi ìwọ̀ mi sí ọ ní imú, àti ìjẹ mi sí ọ lẹ́nu, èmi yóò sì jẹ́ kí o padà láti ọ̀nà tí o gbà wá.
Деч, пентру кэ ешть мыниос ымпотрива Мя ши мындрия та а ажунс пынэ ла урекиле Меле, вой пуне верига Мя ын нэриле тале ши зэбала Мя ынтре бузеле тале ши те вой фаче сэ те ынторчь пе друмул пе каре ай венит.’
30 “Èyí ni yóò ṣe àmì fún ọ, ìwọ Hesekiah: “Ní ọdún yìí, ìwọ yóò jẹ ohun tí ó hù fúnra rẹ̀, àti ní ọdún kejì ohun tí ó jáde láti ara rẹ. Ṣùgbọ́n ní ọdún kẹta, ẹ gbìn kí ẹ sì kórè, ẹ gbin ọgbà àjàrà kí ẹ sì jẹ èso wọn.
Ши ачеста сэ-ць фие семнул, Езекия: анул ачеста вець мынка че ва креште сингур де ла сине ши ын ал дойля ан, че ва рэсэри дин ачаста, дар ын ал трейля ан вець семэна, вець сечера, вець сэди вий ши вець мынка дин родул лор.
31 Lẹ́ẹ̀kan sí i, àṣẹ́kù láti ilé Juda yóò ta gbòǹgbò nísàlẹ̀ yóò sì ṣo èso lókè.
Ши че ва май скэпа дин каса луй Иуда ши че ва май рэмыне ярэшь ва принде рэдэчинь дедесубт ши ва адуче род дясупра.
32 Nítorí láti Jerusalẹmu ni àwọn àṣẹ́kù yóò ti wá, àti láti òkè Sioni ni ikọ̀ àwọn tí ó sálà. Ìtara Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni yóò mú èyí ṣẹ.
Кэч дин Иерусалим ва еши о рэмэшицэ ши дин мунтеле Сионулуй, чей избэвиць. Ятэ че ва фаче рывна Домнулуй оштирилор.
33 “Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa wí nípa ọba Asiria, “Òun kì yóò wọ ìlú yìí wá tàbí ta ẹyọ ọfà kan níhìn-ín Òun kì yóò wá síwájú rẹ pẹ̀lú asà tàbí kí ó kó dágunró sílẹ̀ fún un.
Де ачея аша ворбеште Домнул деспре ымпэратул Асирией: ‘Ел ну ва интра ын четатя ачаста, ну ва арунка сэӂець ын еа, ну-й ва ста ынаинте ку скутурь ши ну ва ридика ынтэритурь де шанцурь ымпотрива ей.
34 Nípa ọ̀nà tí ó gbà wá náà ni yóò padà lọ; òun kì yóò wọ inú ìlú yìí,” ni Olúwa wí.
Чи се ва ынтоарче пе друмул пе каре а венит ши ну ва интра ын четатя ачаста, зиче Домнул,
35 “Èmi yóò dáàbò bo ìlú yìí èmi ó sì gbà á là, nítorí mi àti nítorí Dafidi ìránṣẹ́ mi!”
кэч Еу вой окроти четатя ачаста ка с-о скап, дин причина Мя ши дин причина робулуй Меу Давид!’”
36 Lẹ́yìn náà ni angẹli Olúwa jáde lọ ó sì pa ọ̀kẹ́ mẹ́sàn-án ó lé ẹgbẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ènìyàn ní i ibùdó àwọn Asiria. Nígbà tí àwọn ènìyàn yìí jí ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì gbogbo wọn ti dòkú!
Ынӂерул Домнулуй а ешит ши а учис ын табэра асириенилор о сутэ оптзечь ши чинч де мий де оамень. Ши, кынд с-ау скулат диминяца, ятэ кэ тоць ачештя ерау ниште трупурь моарте.
37 Nítorí náà Sennakeribu ọba Asiria fọ́ bùdó ó sì pẹsẹ̀dà. Òun sì padà sí Ninefe, ó sì dúró síbẹ̀.
Атунч Санхериб, ымпэратул Асирией, шь-а ридикат табэра, а плекат ши с-а ынторс ши а рэмас ла Ниниве.
38 Ní ọjọ́ kan, bí ó ti ń jọ́sìn nínú tẹmpili Nisroki òrìṣà rẹ̀, àwọn ọmọ rẹ̀ Adrameleki àti Ṣareseri gé e lulẹ̀ pẹ̀lú idà, wọ́n sì sálọ sí ilẹ̀ Ararati. Bẹ́ẹ̀ ni Esarhadoni ọmọ rẹ̀ sì gba ipò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
Ши, пе кынд стэтя ку фаца ла пэмынт, ругынду-се ын каса луй Нисрок, думнезеул сэу, фиий сэй Адрамалек ши Шарецер л-ау ловит ку сабия ши ау фуӂит ын цара Арарат. Ши ын локул луй а домнит фиул сэу Есар-Хадон.