< Isaiah 37 >
1 Nígbà tí ọba Hesekiah gbọ́ èyí, ó fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì fi aṣọ ọ̀fọ̀ bo ara rẹ̀, ó sì wọ inú tẹmpili Olúwa lọ.
Manghai Hezekiah loh a yaak vaengah a himbai a phen, tlamhni te a bai tih BOEIPA im te a paan.
2 Òun sì rán Eliakimu alákòóso ààfin, Ṣebna akọ̀wé, àti aṣíwájú àwọn àlùfáà, gbogbo wọn nínú aṣọ ọ̀fọ̀ lọ sí ọ̀dọ̀ wòlíì Isaiah ọmọ Amosi.
Te vaengah a im om Eliakim neh cadaek Shebna, khosoih patong rhoek te tlamhni a khuk tih tonghma Amoz capa Isaiah taengla a tueih.
3 Wọ́n sọ fún un pé, “Báyìí ni Hesekiah wí, ọjọ́ òní jẹ́ ọjọ́ ìbànújẹ́, ìbáwí àti ẹ̀gàn gẹ́gẹ́ bí ìgbà ìbí àwọn ọmọdé tí kò sì ṣí agbára láti bí wọn.
Te vaengah a taengah, “Hezekiah loh citcai neh toelthamnah khohnin neh kokhahnah khohnin ni. Camoe om hamla a pha tih a cun ham thadueng a om pawt bangla ka om coeng.
4 Ó lè jẹ́ pé Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò gbọ́ ọ̀rọ̀ ọ̀gágun ẹni tí ọ̀gá rẹ̀ ọba Asiria ti rán láti fi Ọlọ́run alààyè ṣe ẹlẹ́yà, àti pé òun ni yóò bá a wí nítorí àwọn ọ̀rọ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti gbọ́. Nítorí náà gbàdúrà fún àwọn tí ó ṣẹ́kù tí wọ́n sì wà láààyè.”
Khotawt Rabshakeh kah olka te Yahovah na Pathen loh a yaak khaming. Aka hing Pathen veet hamla a boei Assyria manghai loh anih te a tueih coeng. Te ol Yahovah na Pathen loh a yaak coeng dongah a tluung bitni. A meet aka om duen ham khaw thangthuinah neh thothueng laeh,” a ti,” a ti na uh.
5 Nígbà tí àwọn ìjòyè ọba Hesekiah dé ọ̀dọ̀ Isaiah,
Manghai Hezekiah kah sal rhoek te Isaiah taengla a pawk uh vaengah,
6 Isaiah sọ fún wọn pé, “Ẹ sọ fún ọ̀gá yín pé, ‘Ohun tí Olúwa sọ nìyìí. Má ṣe bẹ̀rù ohun tí ẹ ti gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ tí ọba Asiria tí ó wà nínú ìdè ti fi sọ̀rọ̀-òdì sí mi.
amih te Isaiah loh, “Na boei taengah thui pah BOEIPA loh, 'Te ol te rhih boeh, Assyria manghai taengca rhoek loh kai n'hliphen te na yaak uh coeng.
7 Tẹ́tí sílẹ̀! Èmi yóò fi ẹ̀mí kan sínú rẹ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí ó fi jẹ́ pé bí o bá ti gbọ́ ìròyìn kan, òun yóò padà sí orílẹ̀-èdè rẹ̀, níbẹ̀ ni n ó sì ti jẹ́ kí wọn ké e lulẹ̀ pẹ̀lú idà.’”
Anih te mueihla ka paek vaengah olthang a yaak vetih amah kho la mael bitni. Te vaengah anih te amah kho ah cunghang neh ka cungku sak bitni,’ a ti,” a ti nah.
8 Nígbà tí ọ̀gágun gbọ́ pé ọba Asiria ti fi Lakiṣi sílẹ̀, ó padà sẹ́yìn, ó sì bá ọba tí ń bá Libina jà.
Lakhish lamloh a nong te a yaak vaengah khotawt Rabshakeh khaw mael van dae Assyria manghai loh Libnah a vathoh thil te a hmuh.
9 Ní àkókò yìí Sennakeribu gbọ́ ìròyìn kan pé Tirakah ará Kuṣi ọba Ejibiti ń jáde bọ̀ wá bá òun jà. Nígbà tí ó gbọ́ èyí, ó rán oníṣẹ́ sí Hesekiah pẹ̀lú ọ̀rọ̀ wọ̀nyí,
Kusah manghai Tirhakah te a yaak coeng lahko. Nang vathoh thil ham ha pawk coeng a ti lah ko. A yaak tangloeng vaengah tah Hezekiah taengla puencawn a tueih tih,
10 “Ẹ sọ fún Hesekiah ọba Juda pé: Má ṣe jẹ́ kí òrìṣà tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé tàn ọ́ jẹ nígbà tí ó sọ pé, ‘A kì yóò jọ̀wọ́ Jerusalẹmu fún ọba Asiria.’
“Judah manghai Hezekiah te thui pah. 'Na pangtung thil na Pathen loh nang n'rhaithi boel saeh,’ ti nah. 'Jerusalem khaw Assyria manghai kut dongla pawk mahpawh,’ ti nah.
11 Dájúdájú, ìwọ ti gbọ́ ohun tí ọba Asiria ti ṣe sí àwọn orílẹ̀-èdè, tí ó pa wọ́n run pátápátá. Ǹjẹ́ a ó ha dá ọ nídè bí?
Assyria manghai rhoek loh diklai tom te a saii tih amih a thup te namah loh na yaak coeng dongah na loeih uh venim te.
12 Ǹjẹ́ àwọn òrìṣà àwọn orílẹ̀-èdè tí àwọn baba ńlá mi parun ha gbà wọ́n sílẹ̀ bí àwọn òrìṣà Gosani, Harani, Reṣefu àti àwọn ènìyàn Edeni tí wọ́n wà ní Teli-Assari?
A pa rhoek loh a phae Gozan, Haran, Rezeph neh Telassar kah Eden ca rhoek te amih kah namtom pathen loh a huul a?
13 Níbo ni ọba Hamati wà, ọba Arpadi, ọba ìlú Sefarfaimi tàbí Hena tàbí Iffa?”
Khamath manghai neh Arpad manghai, Sepharvaim khopuei, Hena neh Ivvah manghai te ta,” a ti nah.
14 Hesekiah gba ìwé náà lọ́wọ́ àwọn oníṣẹ́ ó sì kà á. Lẹ́yìn náà ni ó gòkè lọ sí tẹmpili Olúwa ó sì tẹ́ ìwé náà sílẹ̀ níwájú Olúwa.
Puencawn kut lamkah ca te Hezekiah loh a doe tih a tae. Te phoeiah BOEIPA im la cet tih BOEIPA mikhmuh ah Hezekiah loh a phaih.
15 Hesekiah sì gbàdúrà sí Olúwa:
Hezekiah tah BOEIPA taengah thangthui tih,
16 Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli, tí ó gúnwà láàrín àwọn kérúbù, ìwọ nìkan ni Ọlọ́run lórí i gbogbo ìjọba orílẹ̀ ayé. Ìwọ ti dá ọ̀run àti ayé.
caempuei BOEIPA Israel Pathen, namah loh cherubim na ngol thil tih, diklai ram boeih soah namah bueng Pathen coeng. Namah loh vaan neh diklai na saii.
17 Tẹ́tí sílẹ̀, ìwọ Olúwa, kí o gbọ́, ya ojú rẹ, Ìwọ Olúwa, kí o rí i; tẹ́tí sí gbogbo ọ̀rọ̀ tí Sennakeribu rán láti fi àbùkù kan Ọlọ́run alààyè.
BOEIPA na hna kaeng lamtah hnatun lah. BOEIPA aw na mik dai lamtah hmu van lah. Sennacherib ol te boeih ya van lah. Aka hing Pathen veet hamla hlang a tueih lah ko te.
18 “Òtítọ́ ni Olúwa pé àwọn ọba Asiria ti sọ àwọn ènìyàn àti ilẹ̀ wọn di asán.
Aw BOEIPA, Assyria manghai rhoek loh diklai boeih neh a khohmuen khaw a khah uh coeng.
19 Wọ́n ti da àwọn òrìṣà wọn sínú iná wọ́n sì ti pa wọ́n run, nítorí àwọn wọ̀nyí kì í ṣe ọlọ́run bí kò ṣe igi àti òkúta lásán, tí a ti ọwọ́ ènìyàn ṣe.
Amih kah pathen te hmai ah a pup pah. Te te pathen moenih. Hlang kut kah bibi thing neh lungto mailai ni, te dongah te rhoek khaw milh uh.
20 Nísinsin yìí, ìwọ Olúwa, Ọlọ́run wa, gbà wá lọ́wọ́ rẹ̀, tí ó fi jẹ́ pé gbogbo ìjọba ilẹ̀ ayé yóò fi mọ̀ pé Ìwọ, Ìwọ nìkan, Olúwa ni Ọlọ́run.”
Kaimih Pathen Yahovah loh kaimih he anih kut lamloh n'khang pawn saeh. Te vaengah diklai ram pum loh nang namah bueng te BOEIPA la m'ming uh saeh,” a ti nah.
21 Lẹ́yìn náà Isaiah ọmọ Amosi rán iṣẹ́ kan sí Hesekiah: “Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli sọ pé, nítorí pé ìwọ ti gbàdúrà sí mi nípa Sennakeribu ọba Asiria,
Te dongah Amoz capa Isaiah loh Hezekiah te a tah tih, “Israel Pathen Yahovah loh, 'Assyria manghai Sennacherib kongah kai taengla na thangthui coeng,’ a ti.
22 èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ nípa rẹ̀: “Wúńdíá ọmọbìnrin Sioni ti kẹ́gàn rẹ, ó sì ti fi ọ ṣe ẹlẹ́yà. Ọmọbìnrin Jerusalẹmu ti mi orí rẹ̀ bí ó ti ń sálọ.
He ol he BOEIPA loh anih ham ni a. thui. Zion nu oila nang te n'hnoelrhoeng tih, n'tamdaeng. Nang hnukah Jerusalem nu loh lu a hinghuen.
23 Ta ni ìwọ ti bú tí ìwọ sì ti sọ̀rọ̀-òdì sí? Sí ta ní ìwọ ti gbé ohùn rẹ sókè tí o sì gbé ojú rẹ sókè ní ìgbéraga? Sí Ẹni Mímọ́ Israẹli!
Unim na veet tih na hliphen dae? Unim ol na huel thil van dae na mik nen tah Israel kah a cim taengah a sang la na huel.
24 Nípa àwọn ìránṣẹ́ rẹ, ìwọ ti sọ̀rọ̀ búburú sí Olúwa. Tì wọ sì wí pé, ‘Pẹ̀lú ọ̀pọ̀ kẹ̀kẹ́ mi ni èmi sì fi dé orí àwọn òkè ńlá, sí ibi gíga jùlọ Lebanoni. Èmi a sì ké igi kedari gíga rẹ̀ lulẹ̀, àti ààyò igi firi rẹ̀. Èmi ti dé ibi rẹ̀ tí ó ga jùlọ, igbó rẹ̀ tí ó dára jùlọ.
Na sal rhoek kah kut loh Boeipa namah te m'veet. Te vaengah ka leng te yet neh Lebanon hlaep kah tlang sang khaw kamah ka yoeng coeng. Lamphai thingsang neh hmaical thinghloe khaw ka top coeng. A khobawt hmuensang kah a cangphill cangngol duup khaw ka pha coeng.
25 Èmi ti gbẹ́ kànga ní ilẹ̀ àjèjì mo sì mu omi ní ibẹ̀, pẹ̀lú àtẹ́lẹsẹ̀ mi Èmi ti gbẹ́ gbogbo omi àwọn odò Ejibiti.’
Kamah loh ka rhawt tih tui ka ok. Egypt sokko boeih ka kho kah khopha neh kak sak.
26 “Ṣé o kò tí ì gbọ́? Tipẹ́tipẹ́ ni mo ti fìdí rẹ̀ mulẹ̀. Láti ìgbà pípẹ́ ni mo ti ṣètò rẹ̀; ní àkókò yìí ni mo mú wá sí ìmúṣẹ, pé o ti sọ àwọn ìlú olódi di àkójọpọ̀ àwọn òkúta.
Hlamat kum lamloh ka nuen te daengrhae daengkhoi la na ya pawt nim. Ka hlom tangtae te ka paan coeng he,” na ti. Te dongah cakrhuek khopuei rhoek khaw hlang aka hnuei lungkuk a thaek bangla na om coeng.
27 Àwọn ènìyàn, tí agbára ti wọ̀ lẹ́wù, ni wọ́n banújẹ́ tí a sì dójútì. Wọ́n dàbí ohun ọ̀gbìn nínú pápá, gẹ́gẹ́ bí ọ̀jẹ̀lẹ̀ èhíhù tuntun, gẹ́gẹ́ bí i koríko tí ó ń hù lórí òrùlé, tí ó jóná kí ó tó dàgbàsókè.
Amih khosa rhoek kah a kut toi tih rhihyawp uh. Te dongah khohmuen kah baelhing khaw yahhat la om. Imphu kah sulrham, toian thingsuep neh canghli kah te khaw mawn loh a boh.
28 “Ṣùgbọ́n mo mọ ibi tí o wà àti ìgbà tí o wá tí o sì lọ àti bí inú rẹ ṣe ru sí mi.
Na om van tih na hlah uh van mai. Na pawk te khaw ka ming ngawn dae kai taengah na tlai hae.
29 Nítorí pé inú rẹ ru sí mi àti nítorí pé orí kunkun rẹ ti dé etí ìgbọ́ mi, Èmi yóò fi ìwọ̀ mi sí ọ ní imú, àti ìjẹ mi sí ọ lẹ́nu, èmi yóò sì jẹ́ kí o padà láti ọ̀nà tí o gbà wá.
Kai taengah na tlai neh na mongkawt te ka hna la ha pawk coeng. Te dongah ka thisum neh na hnarhong ah ka dueh vetih na ka ah ka kamrhui kam ban ni. Te vaengah nang te kam mael puei vetih longpuei ah na pongpa ni.
30 “Èyí ni yóò ṣe àmì fún ọ, ìwọ Hesekiah: “Ní ọdún yìí, ìwọ yóò jẹ ohun tí ó hù fúnra rẹ̀, àti ní ọdún kejì ohun tí ó jáde láti ara rẹ. Ṣùgbọ́n ní ọdún kẹta, ẹ gbìn kí ẹ sì kórè, ẹ gbin ọgbà àjàrà kí ẹ sì jẹ èso wọn.
Te phoeiah hekah he nang ham ah miknoek la om ni. Kum khat pong vetih a kum bae ah anboe te caak ham om. Tedae a kum thum dongah tawn lamtah at bal. Misur te phung lamtah a thaih te ca khaw ca kolo van.
31 Lẹ́ẹ̀kan sí i, àṣẹ́kù láti ilé Juda yóò ta gbòǹgbò nísàlẹ̀ yóò sì ṣo èso lókè.
Judah imkhui kah rhalyong te khaw a thap vetih a laedil kah a yung aka sueng tah a hman ah a thaih cuen ni.
32 Nítorí láti Jerusalẹmu ni àwọn àṣẹ́kù yóò ti wá, àti láti òkè Sioni ni ikọ̀ àwọn tí ó sálà. Ìtara Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni yóò mú èyí ṣẹ.
Te vaengah Jerusalem lamkah a meet neh Zion tlang lamkah rhalyong te khaw ha pawk ni. Te tlam te caempuei BOEIPA kah thatlainah loh a saii ni.
33 “Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa wí nípa ọba Asiria, “Òun kì yóò wọ ìlú yìí wá tàbí ta ẹyọ ọfà kan níhìn-ín Òun kì yóò wá síwájú rẹ pẹ̀lú asà tàbí kí ó kó dágunró sílẹ̀ fún un.
Te ham te BOEIPA loh a thui tangloeng. Assyria manghai te he khopuei khuila kun pawt vetih thaltang pataeng kap mahpawh. photling nen khaw mah pawt vetih tanglung khaw lun thil mahpawh.
34 Nípa ọ̀nà tí ó gbà wá náà ni yóò padà lọ; òun kì yóò wọ inú ìlú yìí,” ni Olúwa wí.
Ha pawk nah longpuei long te mael vetih he khopuei khuila ha kun mahpawh. BOEIPA kah olphong coeng ni.
35 “Èmi yóò dáàbò bo ìlú yìí èmi ó sì gbà á là, nítorí mi àti nítorí Dafidi ìránṣẹ́ mi!”
He khopuei he ka tungaep vetih, kamah ham neh ka sal David ham ka khang ni.
36 Lẹ́yìn náà ni angẹli Olúwa jáde lọ ó sì pa ọ̀kẹ́ mẹ́sàn-án ó lé ẹgbẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ènìyàn ní i ibùdó àwọn Asiria. Nígbà tí àwọn ènìyàn yìí jí ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì gbogbo wọn ti dòkú!
Te dongah BOEIPA kah puencawn loh a paan tih Assyria rhaehhmuen ah thawng ya rhet thawng nga te a ngawn pah. Mincang a thoh uh vaengah tah amih te a rhok la boeih duek uh.
37 Nítorí náà Sennakeribu ọba Asiria fọ́ bùdó ó sì pẹsẹ̀dà. Òun sì padà sí Ninefe, ó sì dúró síbẹ̀.
Te daengah puen uh tih vik cet. Assyria manghai Sennacherib khaw mael tih Nineveh ah kho a sak.
38 Ní ọjọ́ kan, bí ó ti ń jọ́sìn nínú tẹmpili Nisroki òrìṣà rẹ̀, àwọn ọmọ rẹ̀ Adrameleki àti Ṣareseri gé e lulẹ̀ pẹ̀lú idà, wọ́n sì sálọ sí ilẹ̀ Ararati. Bẹ́ẹ̀ ni Esarhadoni ọmọ rẹ̀ sì gba ipò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
Amah a om vaengah a pathen Nisrock im te a bakop thil hatah a ca rhoi Adrammelech neh Sharezer loh cunghang neh a tloek rhoi. Te dongah amih rhoi teArarat kho la poeng rhoi tih ana pa yuengla a capa Esarhaddon te tloep manghai.